< Esekiel 39 >

1 Og du menneskesønn! Spå mot Gog og si: Så sier Herren, Israels Gud: Se, jeg kommer over dig, Gog, fyrste over Ros, Mesek og Tubal!
“Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ sí Gogu, kí ó sì wí pé: ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí ọ, Ìwọ Gogu, olórí ọmọ-aládé ti Meṣeki àti Tubali.
2 Og jeg vil vende dig om og drive dig frem og føre dig op fra det ytterste Norden og la dig komme over Israels fjell.
Èmi yóò dá ọ padà, èmi yóò sì darí rẹ. Èmi yóò mú ọ wá láti jìnnàjìnnà ìhà àríwá, Èmi yóò rán ọ lòdì sí orí àwọn òkè gíga Israẹli.
3 Og jeg vil slå din bue ut av din venstre hånd og la dine piler falle ut av din høire hånd.
Nígbà náà èmi yóò lu ọrùn awọ rẹ ní ọwọ́ òsì rẹ, èmi yóò sì mú kí àwọn ọfà rẹ jábọ́ ni ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
4 På Israels fjell skal du falle, du og alle dine skarer og de folkeslag som er med dig; jeg gir dig til føde for allehånde rovfugler og for markens ville dyr.
Ìwọ yóò sì ṣubú ní orí àwọn òkè Israẹli, ìwọ àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà pẹ̀lú rẹ. Èmi yóò fi ọ ṣe oúnjẹ fún àwọn onírúurú ẹyẹ àti fún àwọn ẹranko igbó.
5 På marken skal du falle; for jeg har talt, sier Herren, Israels Gud.
Ìwọ yóò ṣubú ní gbangba pápá, nítorí tì mo ti sọ̀rọ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
6 Og jeg vil sende ild mot Magog og mot dem som bor trygt på øene, og de skal kjenne at jeg er Herren.
Èmi yóò fi iná sí Magogu àti sí àwọn tí ń gbé ní agbègbè ilẹ̀ ibẹ̀ ní àìléwu, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
7 Og jeg vil kunngjøre mitt hellige navn blandt mitt folk Israel og ikke mere la mitt hellige navn bli vanhelliget, og folkene skal kjenne at jeg er Herren, hellig i Israel.
“‘Èmi yóò sọ orúkọ mímọ́ mí di mí mọ̀ láàrín àwọn ènìyàn mì Israẹli. Èmi ki yóò jẹ́ kí orúkọ mímọ́ mi di aláìmọ́ àwọn orílẹ̀-èdè yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa, Èmi ni ẹni mímọ́ ní Israẹli.
8 Se, det kommer, det skjer, sier Herren, Israels Gud; det er dagen som jeg har talt om.
Ó ń bọ̀! Ó dájú pé yóò ṣẹlẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè. Èyí yìí ni ọjọ́ tí mo sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀.
9 Da skal de som bor i Israels byer, gå ut og gjøre op ild og holde den ved like med rustninger og små og store skjold, med buer og piler og staver og spyd, og de skal holde ilden ved like dermed i syv år;
“‘Nígbà náà, àwọn ti ó ń gbé nì àárín àwọn ìlú tí ó wà ni Israẹli yóò jáde, wọn yóò sì lo àwọn ohun ìjà bi epo ìdáná yóò sì jó wọ́n kanlẹ̀—àpáta kéékèèké àti àpáta ńlá, àwọn ọfà, àwọn kùmọ̀ ogun àti ọ̀kọ̀ fún ọdún méje wọn yóò lò wọ́n bi epo ìdáná.
10 de skal ikke hente ved fra marken og ikke hugge i skogene, men med rustningene skal de holde ilden ved like, og de skal røve fra dem som har røvet fra dem, og plyndre dem som har plyndret dem, sier Herren, Israels Gud.
Wọn kò ní nílò láti kó igi jọ láti inú pápá, tàbí gé e láti inú igbó, nítorí pé wọ́n yóò lo òhun ìjà ogun bi epo ìdáná. Wọn yóò sì kógun àwọn tí ó ṣe ìgárá sí wọn, wọn yóò sì bo ilé àwọn tí ó bo ilé wọn, ni Olúwa Olódùmarè.
11 På den dag vil jeg gi Gog et gravsted i Israel, de veifarendes dal østenfor havet, og den skal stenge veien for de veifarende; der skal de begrave Gog og hele hans hop, og de skal kalle den Gog-hopens dal.
“‘Ní ọjọ́ náà èmi yóò sì fi ibi ìsìnkú fún Gogu ní Israẹli, ni àfonífojì àwọn ti ó rìn ìrìnàjò lọ sí agbègbè ilà oòrùn Òkun. Yóò di ojú ọ̀nà àwọn arìnrìn-àjò, nítorí Gogu àti gbogbo ìjọ rẹ̀ ni àwa yóò sin síbẹ̀. Nítorí náà, a yóò pè é ní àfonífojì tí Ammoni Gogu.
12 I syv måneder skal Israels hus holde på med å begrave dem for å rense landet.
“‘Fún oṣù méje ní ilé Israẹli yóò fi máa sìn wọ́n láti ṣe àfọ̀mọ́ ilẹ̀ náà.
13 Alt folket i landet skal være med om å begrave dem, og det skal være dem til navnkundighet på den dag jeg åpenbarer min herlighet, sier Herren, Israels Gud.
Gbogbo ènìyàn ilẹ̀ náà yóò sìn wọ́n, ọjọ́ tí a yìn mi lógo yóò jẹ́ ọjọ́ ìrántí, ní Olúwa Olódùmarè wí.
14 De skal utkåre nogen menn som stadig skal dra gjennem landet, og andre som sammen med dem som drar gjennem landet, skal begrave alle som er blitt liggende igjen på marken rundt om i landet, for å rense det. Når syv måneder er til ende, skal de gjennemsøke det,
“‘Wọn yóò gbà àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́ lóòrèkóòrè láti ṣe àfọ̀mọ́ náà. Ọ̀pọ̀ yóò lọ káàkiri ilẹ̀ náà, ní àfikún pẹ̀lú wọn, àwọn tókù yóò sìn àwọn tí ó kú lórí ilẹ̀. Ní ìparí oṣù keje wọn yóò bẹ̀rẹ̀ wíwá kiri wọn.
15 og når nogen av dem som skal dra gjennem landet, på sin ferd ser et menneskeben, da skal de sette op et merke der, til de som skal begrave, får begravet det i Goghopens dal.
Bí wọ́n n lọ káàkiri ilẹ̀ náà ọ̀kan nínú wọn rí egungun ènìyàn, òun yóò gbé àmì ńlá kalẹ̀ ni ẹ̀gbẹ́ rẹ títí àwọn asìnkú yóò fi sìn ín ní àfonífojì Hamoni Gogu.
16 Også en by der skal ha navnet Hamona. Således skal de rense landet.
Bákan náà ìlú kan tí a ń pè ni Hamona yóò wà níbẹ̀. Nítorí náà wọn yóò wẹ ilẹ̀ náà.’
17 Og du menneskesønn! Så sier Herren, Israels Gud: Si til allehånde fugler og til alle markens ville dyr: Samle eder og kom, samle eder fra alle kanter til det slaktoffer som jeg slakter for eder, et stort slaktoffer på Israels fjell, og I skal ete kjøtt og drikke blod.
“Ọmọ ènìyàn èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí pé, pe gbogbo oríṣìíríṣìí ẹyẹ àti gbogbo àwọn ẹranko igbó jáde, ‘Kí wọn péjọpọ̀ láti gbogbo agbègbè sí ìrúbọ tí mó ń múra rẹ̀ fún ọ, ìrúbọ ńlá náà ní orí òkè gíga tí Israẹli. Níbẹ̀ ẹ̀yin yóò jẹ ẹran, ẹ̀yin yóò sì mú ẹ̀jẹ̀.
18 Kjempers kjøtt skal I ete, og jordens fyrsters blod skal I drikke, værer, lam og bukker og okser, alle sammen gjødd i Basan.
Ẹ̀yin yóò jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn ńlá, ẹ o sì mú ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ-aládé ayé bí ẹni pé wọn jẹ́ àgbò àti ọ̀dọ́-àgùntàn, ewúrẹ́ àti akọ màlúù gbogbo wọn jẹ́ ẹran ọlọ́ràá láti Baṣani.
19 Og I skal ete fett til I blir mette, og drikke blod til I blir drukne, av det slaktoffer som jeg slakter for eder.
Níbi ìrúbọ tí mo ń múra kalẹ̀ fún yín, ẹ̀yin yóò jẹ ọ̀rá títí ẹ̀yin yóò fi jẹ àjẹkì, ẹ̀yin yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ títí ẹ̀yin yóò fi yó.
20 I skal mettes ved mitt bord med ridehester og vognhester, med kjemper og alle slags krigsmenn, sier Herren, Israels Gud.
Ní orí tábìlì mi ni àwa yóò ti fi ẹṣin àti ẹlẹ́ṣin bọ yín yó, pẹ̀lú àwọn alágbára ńlá àti oríṣìíríṣìí jagunjagun,’ ni Olúwa Olódùmarè wí.
21 Og jeg vil åpenbare min herlighet iblandt folkene, og alle folkene skal se den dom som jeg har holdt, og min hånd som jeg har lagt på dem.
“Èmi yóò ṣe àfihàn ògo mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì rí ìyà tí mo fi jẹ wọ́n.
22 Og Israels hus skal kjenne at jeg er Herren deres Gud, fra den dag og fremdeles.
Láti ọjọ́ náà lọ, ilé Israẹli yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn.
23 Og folkene skal skjønne at det var for sin misgjernings skyld Israels hus blev bortført, fordi de var troløse mot mig, så jeg skjulte mitt åsyn for dem og gav dem i deres fienders hånd, og de falt for sverdet alle sammen;
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò sì mọ̀ pé àwọn ènìyàn Israẹli lọ sí ìgbèkùn nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, nítorí pé wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí mi. Nítorí náà mo mú ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn, mo sì fi wọn lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, gbogbo wọn sì ṣubú nípasẹ̀ idà.
24 efter deres urenhet og deres overtredelser gjorde jeg med dem, og jeg skjulte mitt åsyn for dem.
Mo ṣe sí wọn gẹ́gẹ́ bí àìmọ́ àti àìṣedéédéé wọn, mo sì mú ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
25 Derfor sier Herren, Israels Gud, så: Nu vil jeg gjøre ende på Jakobs fangenskap og forbarme mig over hele Israels hus, og jeg vil vise mig nidkjær for mitt hellige navn.
“Nítorí náà èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò mú Jakọbu padà kúrò ní oko ẹrú, èmi yóò ní ìyọ́nú si gbogbo ènìyàn Israẹli, èmi yóò sì ní ìtara fún orúkọ mímọ́ mi.
26 Og de skal bære sin skam og all den troløshet de har vist mot mig, når de bor trygt i sitt land, og ingen forferder dem.
Wọn yóò gbàgbé ìtìjú wọn àti gbogbo àìṣòdodo tí wọ́n fihàn sí mi nígbà tí wọn ń gbé ni àìléwu ni ilẹ̀ wọn níbi tí kò ti sí ẹnikẹ́ni láti dẹ́rùbà wọ́n.
27 Når jeg fører dem tilbake fra folkene og samler dem fra deres fienders land og åpenbarer min hellighet på dem for de mange folks øine,
Nígbà tí mo ti mú wọn padà kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè, tí mo sì kó wọn jọ pọ̀ kúrò ni ìlú àwọn ọ̀tá wọn, èmi yóò fi ara mi hàn ni mímọ́ nípasẹ̀ wọn ní ojú àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀.
28 da skal de kjenne at jeg er Herren deres Gud, fordi jeg har bortført dem til folkene, men igjen samlet dem til deres land og ikke lar nogen av dem bli igjen der.
Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn nítorí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo rán wọn lọ sí ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò kó wọn jọ sí orí ilẹ̀ wọn, láìfi nǹkan kan sẹ́yìn.
29 Og jeg vil ikke mere skjule mitt åsyn for dem, for jeg vil utgyde min Ånd over Israels hus, sier Herren, Israels Gud.
Èmi kì yóò sì fi ojú mi pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn mọ nítorí èmi yóò tú èémí mi jáde sí ilé Israẹli, ní Olúwa Olódùmarè wí.”

< Esekiel 39 >