< Amos 4 >

1 Hør dette ord, I Basan-kyr på Samarias fjell, I som undertrykker de ringe, som knuser de fattige, som sier til eders menn: Kom med vin, så vi får drikke!
Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, ẹ̀yin màlúù Baṣani lórí òkè Samaria, ẹ̀yin obìnrin tí ó ń ni tálákà lára, tí ó ń tẹ aláìní mọ́lẹ̀, tí ó wí fún ọkọ rẹ̀, “Gbé wá kí a sì mu!”
2 Herren, Israels Gud, har svoret ved sin hellighet: Se, dager kommer over eder da I skal slepes bort med haker, og den siste levning av eder med fiskekroker,
Olúwa Olódùmarè ti fi ìwà mímọ́ rẹ̀ búra: “Àkókò náà yóò dé nítòótọ́ nígbà tí a ó fi ìwọ̀ mú un yín lọ, ẹni tí ó kẹ́yìn pẹ̀lú ìwọ̀ ẹja.
3 og I skal gå ut gjennem murbruddene, hver rett frem for sig, og I skal bli slengt bort i palasset, sier Herren.
Ẹni kọ̀ọ̀kan yín yóò jáde lọ gba àárín odi yíya a ó sì lé e yín sí Harmoni,” ni Olúwa wí.
4 Gå til Betel og synd, til Gilgal og synd til gagns, og bær hver morgen frem eders slaktoffer, hver tredje dag eders tiender,
“Ẹ lọ sí Beteli láti dẹ́ṣẹ̀; ẹ lọ sí Gilgali kí ẹ sì dẹ́ṣẹ̀ sí i. Ẹ mú ẹbọ sísun yín láràárọ̀ wá, ìdámẹ́wàá yín ní ọdọọdún mẹ́ta.
5 og la røk av syret brød stige op som takkoffer og tillys frivillige offer og kunngjør det! For så vil I jo gjerne ha det, I Israels barn, sier Herren, Israels Gud.
Kí ẹ mú ọ̀rẹ́ ìdúpẹ́ ìyẹ̀fun ìwúkàrà ti a sun kí ẹ sì mú ọrẹ àtinúwá lọ fi wọ́n yangàn, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli, nítorí èyí ni ẹ fẹ́ láti ṣe,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
6 Og jeg har da latt eder gå med tom munn i alle eders byer og latt eder mangle brød i alle eders hjem; men I har ikke omvendt eder til mig, sier Herren.
“Èmi fún un yín ní mímọ́ eyín ní gbogbo ìlú yín, àti àìní oúnjẹ ní gbogbo ibùgbé yín, síbẹ̀, ẹ̀yin kò yípadà sọ́dọ̀ mi,” ni Olúwa wí.
7 Jeg har forholdt eder regnet da det ennu var tre måneder igjen til høsten, og har latt det regne over en by, men ikke over en annen; et stykke land fikk regn, og et annet stykke blev fortørket, fordi det ikke kom regn på det,
“Àti pẹ̀lú mo mú òjò dúró nígbà tí ìkórè ku oṣù mẹ́ta. Mo rán òjò sí ibùgbé kan ṣùgbọ́n kò rọ̀ sí ìlú mìíràn. Oko kan ní òjò; àwọn mìíràn kò ní ó sì gbẹ.
8 og to, tre byer ravet avsted til en og samme by for å drikke vann, men fikk ikke nok; men I har ikke omvendt eder til mig, sier Herren.
Àwọn ènìyàn ń rìn láti ìlú kan sí ìlú mìíràn fún omi wọn kò rí mu tẹ́ wọn lọ́rùn, síbẹ̀ ẹ̀yin kò padà sí ọ̀dọ̀ mi,” ni Olúwa wí.
9 Jeg har slått eder med kornbrand og rust; gresshoppene åt op eders mange haver og vingårder og fikentrær og oljetrær; men I har ikke omvendt eder til mig, sier Herren.
“Lọ́pọ̀ ìgbà ni mo kọlu ọgbà àti ọgbà àjàrà yín mo fi ìrẹ̀dànù àti ìmúwòdù lù wọ́n. Eṣú sì jẹ igi ọ̀pọ̀tọ́ àti igi olifi yín, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
10 Jeg har sendt pest blandt eder likesom dengang i Egypten, jeg har drept eders unge menn med sverdet og latt eders hester bli hærfang, og jeg lot stanken fra eders hær stige op i eders nese; men I har ikke omvendt eder til mig, sier Herren.
“Mo rán àjàkálẹ̀-ààrùn sí i yín bí mo ti ṣe sí Ejibiti. Mo fi idà pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín. Pẹ̀lú àwọn ẹṣin tí a kó ní ìgbèkùn. Mo kún imú yín fún òórùn ibùdó yín, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
11 Jeg har omstyrtet byer iblandt eder, således som Gud omstyrtet Sodoma og Gomorra, og I blev som en brand som er revet ut av ilden; men I har ikke omvendt eder til mig, sier Herren.
“Mo ti bì ṣubú nínú yín, bí Ọlọ́run ti bi Sodomu àti Gomorra ṣubú ẹ̀yin sì dàbí ògúnná tí a fa yọ kúrò nínú iná, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
12 Derfor vil jeg gjøre med dig, Israel, så som jeg har sagt. Og fordi jeg vil gjøre således med dig, så gjør dig rede til å møte din Gud, Israel!
“Nítorí náà, èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí i yín, Israẹli, àti nítorí tí èmi ó ṣe èyí sí i yín, ẹ múra láti pàdé Ọlọ́run yín, ẹ̀yin Israẹli.”
13 For se, han som danner fjellene og skaper vinden og åpenbarer menneskene deres tanker, han som gjør morgenrøden til mørke og farer frem over jordens høider - Herren, hærskarenes Gud, er hans navn.
Ẹni tí ó dá àwọn òkè tí ó dá afẹ́fẹ́ tí ó sì fi èrò rẹ̀ hàn sí ènìyàn, ẹni tí ó yípadà sí òkùnkùn tí ó sì tẹ ibi gíga ayé. Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.

< Amos 4 >