< 2 Samuel 4 >

1 Da Sauls sønn hørte at Abner var død i Hebron, falt han rent sammen, og hele Israel blev forferdet.
Nígbà tí ọmọ Saulu sì gbọ́ pé, Abneri kú ní Hebroni, ọwọ́ rẹ̀ sì rọ, gbogbo Israẹli sì rẹ̀wẹ̀sì.
2 Hos Sauls sønn var der to menn som var høvedsmenn for streif-flokker; den ene hette Ba'ana og den andre Rekab; de var sønner av Rimmon fra Be'erot og hørte til Benjamins barn. For Be'erot regnedes også til Benjamin -
Ọmọ Saulu sì ní ọkùnrin méjì tí í ṣe olórí ẹgbẹ́ ogun: a ń pe orúkọ ọ̀kan ní Baanah, àti orúkọ èkejì ní Rekabu, àwọn ọmọ Rimoni ará Beeroti ti àwọn ọmọ Benjamini (nítorí pé a sì ka Beeroti pẹ̀lú Benjamini).
3 be'erotittene var flyktet til Gitta'im, og der har de holdt til helt til denne dag.
Àwọn ará Beeroti sì ti sálọ sí Gittaimu, wọ́n sì ṣe àtìpó níbẹ̀ títí ó fi di ọjọ́ òní yìí.
4 Jonatan, Sauls sønn, hadde en sønn som var lam i begge føtter; han var fem år gammel da tidenden om Saul og Jonatan kom fra Jisre'el, og den kvinne som passet ham, tok ham og flyktet; men idet hun skyndte sig avsted, falt han ned og blev lam. Hans navn var Mefiboset.
(Jonatani ọmọ Saulu sì ti bí ọmọkùnrin kan tí ẹsẹ̀ rẹ̀ rọ, òun sì jẹ́ ọdún márùn-ún, nígbà tí ìròyìn dé ní ti Saulu àti Jonatani láti Jesreeli wá, olùtọ́ rẹ̀ sì gbé e, o sì sálọ, ó sì ṣe, bí ó sì ti ń yára láti sálọ, òun sì ṣubú, ó sì ya arọ. Orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Mefiboṣeti.)
5 Be'erotitten Rimmons sønner, Rekab og Ba'ana, tok ut og kom på det heteste av dagen til Isbosets hus, mens han hvilte middag.
Àwọn ọmọ Rimoni, ará Beeroti, Rekabu àti Baanah sì lọ wọ́n sì wá síh ilé Iṣboṣeti ní ọ̀sán gangan, òun sì sinmi lórí ibùsùn kan ní ọjọ́-kanrí.
6 De lot som de skulde hente hvete, og kom således helt inn i huset og stakk ham så i underlivet. Derefter slapp Rekab og hans bror Ba'ana bort.
Sì wò ó, bí olùṣọ́ ẹnu-ọ̀nà ilé náà ti ń gbọn àwọn pàǹtí, ó tòògbé ó sì sùn lọ, wọ́n sì wá sí àárín ilé náà, wọ́n sì ṣe bí ẹni pé wọ́n ń fẹ́ mú alikama; wọ́n sì gún un lábẹ́ inú. Rekabu àti Baanah arákùnrin rẹ̀ sì sálọ.
7 De kom inn i huset mens han lå på sin seng i sitt sovekammer, og stakk ham ihjel og hugg hodet av ham; så tok de hans hode og gikk hele natten gjennem ødemarken.
Nígbà tí wọ́n wọ ilé náà lọ, òun sì dùbúlẹ̀ lórí ibùsùn rẹ̀ nínú iyàrá rẹ̀, wọ́n sì pa á, wọ́n sì bẹ́ ẹ lórí, wọ́n gbé orí sálọ, wọ́n sì fi gbogbo òru rìn ni pẹ̀tẹ́lẹ̀ náà.
8 Og de kom med Isbosets hode til David i Hebron og sa til kongen: Se, her er hodet av Isboset, sønn til Saul, din fiende som stod dig efter livet; således har Herren på denne dag gitt min herre kongen hevn over Saul og hans ætt.
Wọ́n sì gbé orí Iṣboṣeti tọ Dafidi wá ní Hebroni, wọ́n sì wí fún ọba pé, “Wò ó, orí Iṣboṣeti ọmọ Saulu ọ̀tá rẹ, tí ó ti ń wá ẹ̀mí rẹ kiri, Olúwa ti gbẹ̀san fún ọba olúwa mi lónìí lára Saulu àti lára irú-ọmọ rẹ̀.”
9 Men David svarte Rekab og hans bror Ba'ana, be'erotitten Rimmons sønner, og sa til dem: Så sant Herren lever, han som har utfridd mig av all trengsel:
Dafidi sì dá Rekabu àti Baanah arákùnrin rẹ̀, àwọn ọmọ Rimoni ará Beeroti lóhùn, ó sì wí fún wọn pé, “Bí Olúwa ti ń bẹ, ẹni tí ó gba ẹ̀mí mi lọ́wọ́ gbogbo ìpọ́njú.
10 Den som kom til mig med tidende om at Saul var død, og som selv mente at han kom med en god tidende, ham grep jeg og lot ham drepe i Siklag - ham som jeg skulde ha gitt lønn for god tidende,
Nígbà tí ẹnìkan rò fún mi pé, ‘Wò ó, Saulu ti kú,’ lójú ara rẹ̀ òun sì jásí ẹni tí ó mú ìyìnrere wá, èmi sì mú un, mo sì pa á ní Siklagi, ẹni tí ó ṣe bí òun ó rí nǹkan gbà nítorí ìròyìn rere rẹ̀.
11 hvor meget mere nu, da ugudelige menn har myrdet en rettferdig mann i hans hus og på hans leie - skulde jeg ikke nu kreve hans blod av eders hånd og utrydde eder av landet?
Mélòó mélòó ni, nígbà tí àwọn ìkà ènìyàn pa olódodo ènìyàn kan ni ilé rẹ̀ lórí ibùsùn rẹ̀—ǹjẹ́ èmi ha sì lè ṣe aláìbéèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ lọ́wọ́ yín bí? Kí èmi sì mú yín kúrò láààyè.”
12 Så bød David sine folk, og de slo dem ihjel og hugg hendene og føttene av dem og hengte dem op ved dammen i Hebron; men Isbosets hode tok de og begravde i Abners grav i Hebron.
Dafidi sì fi àṣẹ fún àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ̀, wọ́n sì pa wọ́n, wọ́n sì gé ọwọ́ àti ẹsẹ̀ wọn, a sì fi wọ́n há lórí igi ní Hebroni. Ṣùgbọ́n wọ́n mú orí Iṣboṣeti, wọ́n sì sin ín ní ibojì Abneri ní Hebroni.

< 2 Samuel 4 >