< 1 Krønikebok 18 >

1 Derefter slo David filistrene og ydmyket dem, og han tok Gat med tilhørende småbyer ut av filistrenes hender.
Ní àkókò kan, Dafidi kọlu àwọn ará Filistini, ó sì ṣẹ́gun wọn. Ó sì mú Gati àti àwọn ìletò agbègbè rẹ̀ kúrò lábẹ́ ìdarí àwọn ará Filistini.
2 Han slo også moabittene, og moabittene blev Davids tjenere og måtte svare ham skatt.
Dafidi borí àwọn ará Moabu, wọ́n sì di ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, wọ́n sì mú owó òde wá.
3 Likeledes slo David kongen i Soba Hadareser ved Hamat, da han drog avsted for å styrke sitt herredømme ved Frat-elven.
Síbẹ̀, Dafidi sì kọlu Hadadeseri ọba Soba ní Hamati, bí ó ti ń lọ láti fi ìdí ìjọba rẹ̀ múlẹ̀ létí odò Eufurate.
4 Og David tok fra ham tusen vognhester og syv tusen hestfolk og tyve tusen mann fotfolk; og David lot skjære fotsenene over på alle vognhestene; bare hundre vognhester sparte han.
Dafidi fi agbára gba ẹgbẹ̀rún kẹ̀kẹ́ rẹ̀, ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin agun-kẹ̀kẹ́ àti ogún ẹgbẹ̀rún ológun ilẹ̀. Ó sì já gbogbo ọgọ́rùn-ún iṣan ẹsẹ̀ àwọn kẹ̀kẹ́-ẹṣin náà.
5 Syrerne fra Damaskus kom for å hjelpe Hadareser, kongen i Soba; men David slo to og tyve tusen mann av dem.
Nígbà ti àwọn ará Siria ti Damasku wá láti ran Hadadeseri ọba Soba lọ́wọ́, Dafidi lu ẹgbẹ̀rún méjìlélógún wọn bọ lẹ̀.
6 Og David la krigsmannskap i det damaskenske Syria, og syrerne blev Davids tjenere og måtte svare ham skatt. Således hjalp Herren David overalt hvor han drog frem.
Ó sì fi àwọn ọ̀wọ́ ọmọ-ogun rẹ sínú ìjọba Siria ti Damasku, àwọn ará Siria sì ń sìn ní abẹ́ rẹ̀, wọ́n sì mú owó ìṣákọ́lẹ̀ wá. Olúwa sì ń fún Dafidi ní ìṣẹ́gun ní ibi gbogbo tí ó bá lọ.
7 David tok de gullskjold som Hadaresers tjenere hadde båret, og førte dem til Jerusalem.
Dafidi mú àpáta wúrà tí àwọn ìjòyè Hadadeseri gbé, ó sì gbé wọn wá sí Jerusalẹmu.
8 Og fra Hadaresers byer Tibhat og Kun tok David en stor mengde kobber; av det gjorde Salomo kobberhavet og søilene og kobberkarene.
Láti Tibhati àti Kuni, àwọn ìlú Hadadeseri, Dafidi kó ọ̀pọ̀lọpọ̀ idẹ tí Solomoni lò láti fi ṣe okùn idẹ, àwọn òpó àti oríṣìí ohun èlò idẹ.
9 Da kongen i Hamat To'u hørte at David hadde slått hele Soba-kongen Hadaresers hær,
Nígbà tí Tou ọba Hamati gbọ́ pé Dafidi ti borí gbogbo ọmọ-ogun Hadadeseri ọba Soba.
10 sendte han sin sønn Hadoram til kong David for å hilse på ham og ønske ham til lykke, fordi han hadde stridt mot Hadareser og slått ham; for Hadareser hadde jevnlig ført krig mot To'u. Han sendte også alle slags gullkar og sølvkar og kobberkar.
Ó rán ọmọ rẹ̀ Hadoramu sí ọba Dafidi láti kí i àti láti lọ bá a yọ̀ lórí ìṣẹ́gun rẹ̀ nínú ogun lórí Hadadeseri, tí ó wà lójú ogun pẹ̀lú Tou. Hadoramu mú oríṣìíríṣìí ohun èlò ti wúrà àti fàdákà àti idẹ wá.
11 Også dem helliget kong David til Herren sammen med det sølv og gull han hadde tatt fra alle hedningefolkene: fra Edom og fra Moab og fra Ammons barn og fra filistrene og fra amalekittene.
Ọba Dafidi ya ohun èlò wọ́n yí sí mímọ́ fún Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe pẹ̀lú fàdákà àti wúrà tí ó ti mú láti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí: Edomu àti Moabu, ará Ammoni àti àwọn ará Filistini àti Amaleki.
12 Det var Absai, Serujas sønn, som slo edomittene i Saltdalen, atten tusen mann.
Abiṣai ọmọ Seruiah lu ẹgbàá mẹ́sàn ará Edomu bolẹ̀ ní àfonífojì Iyọ̀.
13 Så la han krigsmannskap i Edom, og alle edomittene blev Davids tjenere. Således hjalp Herren David overalt hvor han drog frem.
Ó fi ẹgbẹ́ ogun sí Edomu, gbogbo àwọn ará Edomu sì ń sìn ní abẹ́ Dafidi. Olúwa fún Dafidi ní ìṣẹ́gun ní gbogbo ibí tí ó bá lọ.
14 Så regjerte nu David over hele Israel, og han gjorde rett og rettferdighet mot hele sitt folk.
Dafidi jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli, ó sì ṣe òdodo àti ohun tí ó yẹ fún gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀.
15 Joab, Serujas sønn, var høvding over hæren, og Josafat, Akiluds sønn, historieskriver;
Joabu ọmọ Seruiah jẹ́ olórí ẹgbẹ́ ọmọ-ogun; Jehoṣafati ọmọ Ahiludi jẹ́ akọ̀wé ìrántí;
16 Sadok, Akitubs sønn, og Abimelek, Ebjatars sønn, var prester og Savsa statsskriver;
Sadoku ọmọ Ahitubu àti Abimeleki ọmọ Abiatari jẹ́ àwọn àlùfáà; Ṣafṣa jẹ́ akọ̀wé;
17 Benaja, Jojadas sønn, var høvding over livvakten, og Davids sønner var de første ved kongens side.
Benaiah ọmọ Jehoiada jẹ́ olórí àwọn Kereti àti Peleti; àwọn ọmọ Dafidi sì ni àwọn olóyè oníṣẹ́ ní ọ̀dọ̀ ọba.

< 1 Krønikebok 18 >