< Hakaraia 6 >

1 A ka maranga ake ano oku kanohi, ka kite, na e wha nga hariata e puta mai ana i waenganui o nga maunga e rua; na, ko nga maunga, he maunga parahi.
Mo sì yípadà, mo sì gbé ojú mi sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, kẹ̀kẹ́ mẹ́rin jáde wá láti àárín òkè ńlá méjì, àwọn òkè ńlá náà sì jẹ́ òkè ńlá idẹ.
2 I te hariata tuatahi he whero nga hoiho; i te hariata tuarua he mangu nga hoiho;
Àwọn ẹṣin pupa wà ní kẹ̀kẹ́ èkínní; àti àwọn ẹṣin dúdú ní kẹ̀kẹ́ èkejì.
3 I te toru o nga hariata he ma nga hoiho, i te wha o nga hariata he kopurepure, he pakaka nga hoiho.
Àti àwọn ẹṣin funfun ní kẹ̀kẹ́ ẹ̀kẹta; àti àwọn adíkálà àti alágbára ẹṣin ní kẹ̀kẹ́ ẹ̀kẹrin.
4 Katahi ahau ka oho atu, ka mea ki te anahera i korero ra ki ahau, He aha enei, e toku ariki?
Mo sì dáhùn, mo sì béèrè lọ́wọ́ angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni ìwọ̀nyí, olúwa mi.”
5 Na ka whakahoki mai te anahera, ka mea ki ahau, Ko nga hau e wha enei o te rangi, e haere mai ana i te tu i te aroaro o te Ariki o te whenua katoa.
Angẹli náà si dáhùn ó sì wí fún mi pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀mí mẹ́rin ti ọ̀run, tí wọn ń lọ kúrò lẹ́yìn tí wọ́n ti fi ara wọn hàn níwájú Olúwa gbogbo ayé.
6 Ko te hariata i nga hoiho mangu, e haere ana ratou ki te whenua i te raki; a i haere nga mea ma i muri i a ratou; na ko nga mea kopurepure i ahu pera ki te whenua ki te tonga.
Àwọn ẹṣin dúdú tí ó wà nínú rẹ̀ jáde lọ sí ilẹ̀ àríwá; àwọn funfun sì jáde lọ si ìwọ̀-oòrùn; àwọn adíkálà sì jáde lọ sí ìhà ilẹ̀ gúúsù.”
7 I haere atu ano nga mea pakaka, i whai kia haereere, kia kopikopiko ratou i te whenua: na ka mea ia, Haere atu koe, kopikopiko i te whenua. Na kei te kopikopiko ratou i te whenua.
Àwọn alágbára ẹṣin sì jáde lọ, wọ́n sì ń wá ọ̀nà àti lọ kí wọn bá a lè rìn síyìn-ín sọ́hùn-ún ni ayé; ó sì wí pé, “Ẹ lọ, ẹ lọ rìn síyìn-ín sọ́hùn-ún ní ayé!” Wọ́n sì rín síyìn-ín sọ́hùn-ún ní ayé.
8 Katahi tera ka karanga ki ahau, ka korero mai hoki ki ahau, ka mea, Nana, ko enei i ahu atu nei ki te whenua ki te raki, kua marie i a ratou toku wairua i te whenua ki te raki.
Nígbà náà ni ohùn kan sì ké sí mi, ó sì bá mi sọ̀rọ̀ wí pé, “Wò ó, àwọn wọ̀nyí tí ó lọ síhà ilẹ̀ àríwá ti mú ẹ̀mí mi parọ́rọ́ ni ilẹ̀ àríwá.”
9 I puta mai ano te kupu a Ihowa ki ahau, i mea,
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé:
10 Tangohia ta nga whakarau, ara ta Hererai, ta Topia, ta Ieraia; haere mai ano koe i taua ra, ka tomo ki te whare o Hohia tama a Tepania, ki te whare i tae mai ai ratou i Papurona;
“Mú nínú ìgbèkùn, nínú àwọn Heldai, tí Tobiah, àti ti Jedaiah, tí ó ti Babeli dé, kí ìwọ sì wá ní ọjọ́ kan náà, kí o sì wọ ilé Josiah ọmọ Sefaniah lọ.
11 Ae ra, ka tango i ta ratou hiriwa, koura hoki, ka hanga ai i etahi karauna, a ka potae atu ki te mahunga o te tino tohunga, o Hohua tama a Iohereke;
Kí o sì mú fàdákà àti wúrà, kí o sì fi ṣe adé púpọ̀, sì gbé wọn ka orí Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà.
12 Korero atu hoki ki a ia, mea atu, Ko te kupu tenei a Ihowa o nga mano, e ki ana, Nana, te tangata ko tona ingoa nei ko te Manga; a ka tupu ake ano ia i tona wahi, a mana e hanga te temepara o Ihowa:
Sì sọ fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ wí pé, wo ọkùnrin náà ti orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ẹ̀ka; yóò sì yọ ẹ̀ka láti abẹ́ rẹ̀ wá, yóò si kọ́ tẹmpili Olúwa wa.
13 Mana rawa e hanga te temepara o Ihowa; a mana e waha te kororia, ka noho hoki ia ka whakahaere tikanga i runga i tona torona; a hei tohunga ia i runga i tona torona: a ka whakaaro ngatahi raua mo te rongo mau.
Òun ni yóò sì kọ́ tẹmpili Olúwa òun ni yóò sì wọ̀ ní ògo, yóò sì jókòó, yóò sì jẹ ọba lórí ìtẹ́ rẹ̀; òun ó sì jẹ́ àlùfáà lórí ìtẹ́ rẹ̀; ìmọ̀ àlàáfíà yóò sì wá láàrín àwọn méjèèjì.’
14 Ka ai hoki nga karauna hei whakamahara ki a Hereme ratou ko Topia, ko Ieraia, ko Hene tama a Tepania, i roto i te temepara o Ihowa.
Adé wọ̀nyí yóò sì wà fún Helemu àti fún Tobiah, àti fún Jedaiah, àti fún Heni ọmọ Sefaniah fún ìrántí ni tẹmpili Olúwa.
15 Ka haere mai ano te hunga i tawhiti, ka hanga i roto i te temepara o Ihowa, a ka mohio koutou na Ihowa o nga mano ahau i unga mai ki a koutou. A e puta ano tenei, ki te ata whakarongo koutou ki te reo o Ihowa, o to koutou Atua.
Àwọn tí ó jìnnà réré yóò wá láti kọ́ tẹmpili Olúwa, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rán mi sí yín. Yóò sì rí bẹ́ẹ̀ bí ẹ̀yin yóò bá gbà ohùn Olúwa, Ọlọ́run yín gbọ́ nítòótọ́.”

< Hakaraia 6 >