< Ehekiera 12 >

1 I puta mai ano te kupu a Ihowa ki ahau, i mea,
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 E te tama a te tangata, kei te noho koe i waenganui i te whare whakakeke, he kanohi nei o ratou hei titiro, heoi kahore e titiro, he taringa o ratou e rongo ai, heoi kahore e rongo; no te mea he whare whakakeke ratou.
“Ọmọ ènìyàn, ìwọ ń gbé ní àárín ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn. Wọ́n lójú láti fi ríran, ṣùgbọ́n wọn kò ríran, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n létí láti fi gbọ́rọ̀ ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́rọ̀, torí pé ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn ni wọ́n.
3 Mo reira whakapaingia etahi mea mau, e te tama a te tangata, mo te heke, ka heke i te awatea i ta ratou tirohanga; me heke atu i tou wahi ki tetahi atu wahi i ta ratou tirohanga; tera pea ratou e mahara iho, ahakoa he whare whakakeke ratou.
“Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, palẹ̀ ẹrù rẹ mọ́ láti lọ sí ìgbèkùn, ní ọ̀sán gangan ní ojú wọn, kúrò láti ibi tí ìwọ wà lọ sí ibòmíràn. Bóyá bí wọ́n bá rí ọ, wọn yóò sì ronú bó tilẹ̀ jẹ́ pé ọlọ̀tẹ̀ ilé ni wọ́n.
4 Whakaputaina mai ano au mea ki waho i te awatea i ta ratou tirohanga, kia rite ki nga mea a te heke: me haere atu koe i te ahiahi i ta ratou tirohanga, kia rite ki te haerenga o te heke.
Di ẹrù ìgbèkùn rẹ lójú wọn ní ọ̀sán án gangan, nígbà tí ó bá sì di alẹ́, ní ojú wọn, máa lọ sí ìgbèkùn gẹ́gẹ́ bí àwọn tí ó lọ ìgbèkùn ṣe máa ń ṣe.
5 Pokaia e koe te taiepa i ta ratou tirohanga, a maua atu tau kawenga ma reira.
Dá ògiri lu ní ojú wọn, kí ìwọ sì gba ibẹ̀ kó ẹrù rẹ jáde.
6 I a ratou e titiro ana, amohia e koe i runga i tou pokohiwi, me mau atu i te pouri; ko tou mata hipoki rawa, kei kite koe i te whenua; no te mea kua whakaturia koe e ahau hei tohu ki te whare o Iharaira.
Gbé ẹrù rẹ lé èjìká ní ojú wọn, bo ojú rẹ, kí ìwọ má ba à rí ilẹ̀, sì ru ẹrù rẹ lọ ní alẹ́ nítorí pé mo fi ọ́ ṣe àmì fún ilé Israẹli.”
7 Na mahia ana e ahau nga mea i whakahaua mai ai ahau; whakaputaina ana e ahau aku mea i te awatea, nga mea a te heke, a i te ahiahi ka pokaia e ahau te taiepa he mea mea na toku ringa; i whakaputaina e ahau i te pouri, amohia ana e ahau i runga i toku pokohiwi i ta ratou tirohanga.
Mo ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún mi. Mo kó ẹrù mi jáde ní ọ̀sán án láti lọ fun ìgbèkùn. Nígbà tó di ìrọ̀lẹ́, mo dá ògiri lu pẹ̀lú ọwọ́ mi. Mo sì gbe ẹrù mi lé èjìká nínú òkùnkùn ní ojú wọn.
8 Na i te ata ka puta mai te kupu a Ihowa ki ahau; i mea ia,
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
9 E te tama a te tangata, kihai ianei te whare o Iharaira, te whare whakakeke, i mea ki a koe, E aha ana koe?
“Ọmọ ènìyàn, ǹjẹ́ ọlọ̀tẹ̀ ilé Israẹli tilẹ̀ bi ọ́ pé, ‘Kí ni ohun tí o ń ṣe túmọ̀ sí?’
10 Ki atu ki a ratou, Ko te kupu tenei a te Ariki, a Ihowa; Mo te rangatira i Hiruharama tenei pikaunga, mo te whare katoa o Iharaira e noho nei ratou i reira.
“Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ yìí kan àwọn ọmọ-aládé Jerusalẹmu àti gbogbo ilé Israẹli tí ó wà ní àárín rẹ.
11 Ki atu, hei tohu ahau ki a koutou; ka penei i taku i mea nei, ka peratia ano ki a ratou; ka heke atu ratou, ka riro i te whakarau.
Sọ fún wọn pé, Èmi jẹ́ àmì fún yín’. “Gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí wọn. Wọn ó kó lọ sí ìgbèkùn. Gẹ́gẹ́ bí ẹni ti a dè ní ìgbèkùn.
12 Ko te rangatira i roto i a ratou ka amo te pokohiwi i te pouri, ka haere atu; ka pokaia te taiepa hei whakaputanga atu; ko tona mata hipoki rawa, no te mea e kore ia e kite i te whenua ki ona kanohi.
“Ọmọ-aládé tí ó wà ní àárín wọn yóò di ẹrù rẹ̀ lé èjìká ní alẹ́ yóò sì jáde lọ, òun náà yóò da ògiri lu kí ó le gba ibẹ̀ jáde. Yóò sì bo ojú rẹ̀ kí ó má ba à rí ilẹ̀.
13 Ka taupokina ano ia e ahau ki taku kupenga, ka mau i taku rore; ka kawea ano ia e ahau ki Papurona, ki te whenua o nga Karari; otiia e kore ia e kite i reira, ahakoa ka mate ia ki reira.
Èmi yóò ta àwọ̀n mi lé e lórí, yóò sì kó sínú okùn, Èmi yóò sì mú lọ sí Babeli, ní ilẹ̀ Kaldea, ṣùgbọ́n kò ní fojúrí ilẹ̀ náà ibẹ̀ ni yóò kú sí.
14 A ka titaritaria atu e ahau ki nga hau katoa te hunga katoa i tetahi taha ona, i tetahi taha, hei awhina i a ia, ratou ko ona ropu katoa; ka maunu ano i ahau te hoari hei whai i a ratou.
Gbogbo àwọn tó yí i ká láti ràn án lọ́wọ́ ọ̀pá ìtẹ̀lẹ̀ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ ni Èmi yóò túká sí afẹ́fẹ́, èmi yóò sì tún fi idà lé wọn kiri.
15 A ka mohio ratou ko Ihowa ahau, ina whakamararatia ratou e ahau ki roto ki nga tauiwi, ina titaritaria ki nga whenua.
“Wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa nígbà tí mo bá tú wọn ká ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè, tí mo sì fọ́n wọn ká sí ilẹ̀ káàkiri.
16 Ka whakatoea ano ia etahi o ratou e ahau, he hunga torutoru, i te hoari, i te hemokai, i te mate uruta; kia korero ai ratou i a ratou mea whakarihariha katoa i roto i nga iwi ka haere atu nei ratou ki reira, a ka mohio ratou ko Ihowa ahau.
Ṣùgbọ́n èmi yóò ṣẹ́ díẹ̀ kù lára wọn, ní ọwọ́ idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, kí wọn le jẹ́wọ́ gbogbo ìṣe ìríra wọn ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè yìí. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.”
17 I puta mai ano te kupu a Ihowa ki ahau, i mea,
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
18 E te tama a te tangata, e wiri koe ina kai i tau taro, inumia hoki tou wai i runga i te ohooho, i te manukanuka;
“Ọmọ ènìyàn, jẹ oúnjẹ rẹ pẹ̀lú ìwárìrì, sì mu omi rẹ pẹ̀lú ìwárìrì àti àìbalẹ̀ àyà.
19 Ki atu hoki ki te iwi o te whenua, Ko te kupu tenei a te Ariki, a Ihowa mo nga tangata o Hiruharama, mo te oneone o Iharaira: Ka kainga e ratou ta ratou taro i runga i te manukanuka, ka inumia hoki to ratou wai i runga i te miharo, he mea kia ta koto kau ai tona whenua i ona mea maha, mo te tutu o nga tangata katoa e noho ana i reira.
Sọ fún àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí fún àwọn olùgbé Jerusalẹmu àti ilẹ̀ Israẹli pé, pẹ̀lú àìbalẹ̀ àyà ni wọn yóò máa jẹun wọn, wọn yóò sì mu omi pẹ̀lú àìnírètí, kí ilẹ̀ wọn lè di ahoro torí ìwà ipá àwọn tó ń gbé ibẹ̀.
20 Na, ko nga pa e nohoia ana, ka waiho hei koraha, ka ururuatia ano te whenua; a ka mohio koutou ko Ihowa ahau.
Ìlú tó jẹ́ ibùgbé ènìyàn tẹ́lẹ̀ yóò di òfo, ilẹ̀ náà yóò sì di ahoro. Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
21 I puta mai ano te kupu a Ihowa ki ahau, i mea:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
22 E te tama a te tangata, he aha tena whakatauki a koutou i te whenua o Iharaira, e mea na, Ka roa nei nga ra, kua kore ano he kitenga?
“Ọmọ ènìyàn, irú òwe wo ni ẹ pa nílẹ̀ Israẹli pé: ‘A fa ọjọ́ gùn, gbogbo ìran di asán’?
23 Mo reira ki atu ki a ratou, Ko te kupu tenei a te Ariki, a Ihowa, Ka mutu i ahau tenei whakatauki, e kore ano e whakataukitia e ratou a muri ake nei i roto i a Iharaira; mea atu ia ki a ratou, Ka tata nga ra, me te meatanga ano o nga kitenga kat oa.
Nítorí náà wí fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò fi òpin sí òwe yìí, wọn kò ní ipa mọ́ ní Israẹli.’ Sọ fún wọn, ‘Ọjọ́ náà súnmọ́ tòsí nígbà tí gbogbo ìran àti ìsọtẹ́lẹ̀ yóò sì wá sí ìmúṣẹ.
24 No te mea i muri nei kahore he kitenga teka, kahore he poropititanga tinihanga i roto i te whare o Iharaira.
Nítorí kò ní sí ìran asán tàbí àfọ̀ṣẹ tí ó ń pọ́n ni mọ́ ní àárín ilé Israẹli.
25 Ko Ihowa hoki ahau; ka korero ahau, a ko te kupu e korerotia e ahau, ka oti; e kore e kumea kia roa i muri nei: no te mea i o koutou ra nei, e te whare whakakeke, ka korerotia e ahau, ka mahia ano te kupu, e ai ta te Ariki, ta Ihowa.
Ṣùgbọ́n, Èmi Olúwa yóò sọ̀rọ̀, ọ̀rọ̀ tí mo sọ yóò sì ṣẹ láì falẹ̀. Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ní àsìkò yín, ẹ̀yin ọlọ̀tẹ̀ ilé ni Èmi yóò mú ọ̀rọ̀ yówù tí mo bá sọ ṣẹ.’”
26 I puta mai ano te kupu a Ihowa ki ahau, i mea,
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
27 E te tama a te tangata, nana, e ki ana te whare o Iharaira, Mo nga ra maha te kitenga e kitea nei e ia, ko nga wa i tawhiti rawa tana e poropiti nei.
“Ọmọ ènìyàn, ilé Israẹli ń wí pé, ‘Ìran ọjọ́ pípẹ́ ni ìwọ rí, ìwọ sì sọtẹ́lẹ̀ nípa àsìkò tó jìnnà réré.’
28 Mo reira ki atu ki a ratou, Ko te kupu tenei a te Ariki, a Ihowa, E kore tetahi o aku kupu e kumea kia roa a muri nei; engari ko te kupu e korerotia e ahau ka oti, e ai ta te ariki, ta Ihowa.
“Nítorí náà sọ fún wọn, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, kò sí ọ̀kan nínú ọ̀rọ̀ mi tí yóò sún síwájú mọ́; ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ tí mo bá sọ yóò ṣẹ.’”

< Ehekiera 12 >