< Sog̒u 21 >

1 Bet Israēla vīri Micpā bija zvērējuši sacīdami: neviens no mums lai nedod Benjaminiešiem savu meitu par sievu.
Àwọn ọkùnrin Israẹli ti búra ní Mispa pé, “Kò sí ẹnìkan nínú wa tí yóò fi ọmọ obìnrin rẹ̀ fún ẹ̀yà Benjamini ní ìyàwó.”
2 Tad tie ļaudis nāca uz Bēteli un tur palika līdz vakaram Dieva priekšā un pacēla savas balsis un raudāja gauži raudādami,
Àwọn ènìyàn náà lọ sí Beteli: ilé Ọlọ́run, níbi tí wọ́n jókòó níwájú Ọlọ́run títí di àṣálẹ́, wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún kíkorò.
3 Un tie sacīja: ak Kungs, Tu Israēla Dievs! Kāpēc tas ir noticis iekš Israēla, ka šodien Israēls par vienu cilti ir mazāks kļuvis?
Wọ́n sọkún wí pé, “Háà! Olúwa Ọlọ́run Israẹli, èéṣe tí nǹkan yìí fi ṣẹlẹ̀ sí Israẹli? Èéṣe tí ẹ̀yà kan yóò fi run nínú Israẹli lónìí?”
4 Otrā dienā tie ļaudis cēlās agri un tur uztaisīja altāri, un upurēja dedzināmos upurus un pateicības upurus.
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì àwọn ènìyàn náà mọ pẹpẹ kan wọ́n sì rú ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà.
5 Un Israēla bērni sacīja: kurš tas ir, kas no visām Israēla ciltīm nav atnācis tai draudzes sapulcē pie Tā Kunga? Jo par to, kas nebūtu atnācis pie Tā Kunga uz Micpu, bija ar lielu zvērestu noteikts, ka tam bija tapt nokautam.
Àwọn ọmọ Israẹli sì béèrè wí pé, “Èwo nínú ẹ̀yà Israẹli ni ó kọ̀ láti péjọ síwájú Olúwa?” Torí pé wọ́n ti fi ìbúra ńlá búra pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti péjọ níwájú Olúwa ní Mispa pípa ni àwọn yóò pa á.
6 Un Israēla bērniem bija žēl par Benjaminu, savu brāli, un tie sacīja: šodien viena cilts no Israēla ir izdeldēta.
Àwọn ọmọ Israẹli sì banújẹ́ fún àwọn arákùnrin wọn, àwọn ẹ̀yà Benjamini. Wọ́n wí pé, “A ti ké ẹ̀yà kan kúrò lára Israẹli lónìí.”
7 Ko mēs tiem darīsim, ka tie atlikušie dabū sievas? Jo mēs pie Tā Kunga esam zvērējuši, ka tiem no savām meitām nevienu negribam dot par sievu.
Báwo ni a yóò ṣe rí aya fún àwọn tí ó ṣẹ́kù, nítorí àwa ti fi Olúwa búra láti má fi ọ̀kankan nínú àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya.
8 Un tie sacīja: vai kāds nav no Israēla ciltīm, kas nav atnācis pie Tā Kunga uz Micpu? Un redzi, no Jabesas Gileādā neviens nebija lēģerī nācis draudzes sapulcē.
Wọ́n sì béèrè wí pé, “Èwo ni nínú ẹ̀yà Israẹli ni ó kọ̀ láti bá àwọn ènìyàn péjọ níwájú Olúwa ní Mispa?” Wọ́n rí i pé kò sí ẹnikẹ́ni tí ó wa láti Jabesi Gileadi tí ó wá sí ibùdó fún àjọ náà.
9 Jo tie ļaudis tapa skaitīti un redzi, tur nebija neviena no tiem, kas Jabesā Gileādā dzīvoja.
Nítorí pé nígbà tí wọ́n ka àwọn ènìyàn, wọ́n rí i pé kò sí ẹnìkankan láti inú àwọn ará Jabesi Gileadi tí ó wà níbẹ̀.
10 Tad tā draudze uz turieni sūtīja divpadsmit tūkstoš vīrus no tiem stiprākiem un tiem pavēlēja un sacīja: ejat un kaujiet tos, kas Jabesā Gileādā dzīvo ar zobena asmeni līdz ar sievām un bērniņiem.
Àwọn ìjọ ènìyàn náà sì rán ẹgbàá mẹ́fà àwọn jagunjagun ọkùnrin, lọ sí Jabesi Gileadi wọ́n fún wọn ní àṣẹ pé, ẹ lọ fi idà kọlu gbogbo àwọn tí ó wà níbẹ̀, pẹ̀lú àwọn obìnrin àti àwọn ọmọ wẹ́wẹ́.
11 Bet šī ir tā lieta, ko jums būs darīt: visus no vīriešu kārtas un visas sievas, kas pie vīra gulējušas, jums būs izdeldēt.
Wọ́n ní, “Èyí ni ẹ̀yin yóò ṣe, ẹ pa gbogbo ọkùnrin àti gbogbo obìnrin tí kì í ṣe wúńdíá.”
12 Un tie atrada starp tiem iedzīvotājiem Jabesā Gileādā četrsimt meitas, jaunavas, kas vīru nebija atzinušas, nedz pie vīriem gulējušas, un tās veda uz lēģeri Šīlo, kas ir Kanaāna zemē.
Wọ́n rí àwọn irinwó ọ̀dọ́bìnrin tí kò mọ ọkùnrin rí nínú àwọn olùgbé Jabesi Gileadi, wọ́n sì mú wọn lọ sí ibùdó ní Ṣilo àwọn ará Kenaani.
13 Tad visa draudze nosūtīja un runāja uz Benjamina bērniem, kas bija pie Rimona klints, un tiem lika mieru pasludināt.
Gbogbo ìjọ àwọn ènìyàn sì ránṣẹ́ àlàáfíà sí àwọn Benjamini ní ihò àpáta Rimoni.
14 Tā tanī laikā Benjaminieši griezās atpakaļ; un tie viņiem deva tās sievas, ko tie bija dzīvas pametuši no Jabesas sievām Gileādā, bet tur viņiem nepietika,
Àwọn ẹ̀yà Benjamini náà sì padà ní àkókò náà, wọ́n sì fún wọn ní àwọn obìnrin Jabesi Gileadi. Ṣùgbọ́n wọn kò kárí gbogbo wọn.
15 Tad tiem ļaudīm bija žēl par Benjaminu, ka Tas Kungs plaisu bija darījis Israēla ciltīs.
Àwọn ènìyàn náà sì káàánú nítorí ẹ̀yà Benjamini, nítorí Olúwa fi àlàfo kan sílẹ̀ nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
16 Un tie draudzes vecaji sacīja: ko mēs darīsim, ka tie atlikušie sievas dabū? Jo tās sievas no Benjamina ir izdeldētas.
Àwọn olórí ìjọ àwọn ènìyàn náà wí pé, “Kí ni àwa yóò ṣe láti rí aya fún àwọn ọkùnrin tí ó kù nígbà tí a ti pa gbogbo àwọn obìnrin Benjamini run?”
17 Tad tie sacīja: Benjaminiešu zemes daļu pienākas iemantot tiem, kas izglābušies, lai neviena Israēla cilts netop izdeldēta.
Wọ́n sì wí pé, “Àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n là nínú àwọn ẹ̀yà Benjamini ní láti ní ogún àti àrólé, kí ẹ̀yà kan nínú Israẹli má ṣe di píparun kúrò ní orí ilẹ̀.
18 Bet mēs tiem no savām meitām sievas nevaram dot, jo Israēla bērni ir apzvērējušies sacīdami: nolādēts lai ir, kas Benjaminiešiem dod sievu.
Àwa kò le fi àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya, nítorí tí àwa ọmọ Israẹli ti ṣe ìbúra yìí pé, ‘Ègún ni fún ẹnikẹ́ni tí ó fi aya fún ẹnikẹ́ni nínú ẹ̀yà Benjamini.’”
19 Un tie sacīja: redzi, Šīlo ir Tā Kunga svētki ik gadus, Bētelei pret ziemeļa pusi, pret rītiem tam ceļam, kur iet no Bēteles uz Šehemi un pret dienas vidu Libonai.
Wọ́n sì wí pé, “Kíyèsi i ayẹyẹ ọlọ́dọọdún fún Olúwa wà ní Ṣilo ní ìhà àríwá Beteli àti ìhà ìlà-oòrùn òpópó náà tí ó gba Beteli kọjá sí Ṣekemu, àti sí ìhà gúúsù Lebona.”
20 Un tie pavēlēja Benjamina bērniem un sacīja: ejat un paslēpjaties vīna kalnos.
Wọ́n sì fi àṣẹ fún àwọn ará Benjamini pé, “Ẹ lọ kí ẹ sì fi ara pamọ́ nínú àwọn ọgbà àjàrà
21 Un skatāties, un redzi, kad Šīlo meitas diedamas ar stabulēm iznāks, tad izejiet jūs no tiem vīna kalniem un sagrābiet ikviens sev sievu no Šīlo meitām un noejat uz Benjamina zemi.
kí ẹ sì wà ní ìmúrasílẹ̀. Nígbà tí àwọn ọmọbìnrin Ṣilo bá jáde láti lọ darapọ̀ fún ijó, kí ẹ yára jáde láti inú àwọn ọgbà àjàrà wọ̀n-ọn-nì kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbé aya kan nínú àwọn ọmọbìnrin Ṣilo kí ẹ padà sí ilẹ̀ Benjamini.
22 Un kad viņu tēvi vai viņu brāļi nāks mūsu priekšā tiesāties, tad mēs uz tiem sacīsim: atvēliet mums tās, jo mēs ikvienam sievu ar karošanu neesam dabūjuši; jo jūs viņiem tās neesat devuši; tad jums tagad būtu vaina.
Nígbà tí àwọn baba wọn tàbí àwọn arákùnrin wọn bá fi ẹjọ́ sùn wá, àwa yóò wí fún wọn pé, ‘Ẹ ṣe wá ní oore nípa ríràn wọ́n lọ́wọ́, nítorí àwa kò rí aya fún wọn ní àkókò ogun, ẹ̀yin kò sì ní jẹ̀bi, nítorí pé ẹ̀yin kọ́ ni ó fi àwọn ọmọbìnrin yín fún wọn bí aya.’”
23 Un Benjamina bērni darīja tā un ņēma sievas pēc sava skaita no tām, kas tur dejoja; tās tie laupīja. Un nogāja un griezās atpakaļ uz savām mājām, un uztaisīja pilsētas un dzīvoja iekš tām.
Èyí sì ni ohun tí àwọn ẹ̀yà Benjamini ṣe. Nígbà tí àwọn ọmọbìnrin náà ń jó lọ́wọ́, ọkùnrin kọ̀ọ̀kan mú ọmọbìnrin kọ̀ọ̀kan, wọ́n sì gbé e lọ láti di aya rẹ̀. Wọ́n sì padà sí ilẹ̀ ìní wọn, wọ́n sì tún àwọn ìlú náà kọ́, wọ́n sì tẹ̀dó sínú wọn.
24 Un Israēla bērni tanī laikā no turienes cēlās ikviens pie savas cilts un pie saviem radiem, un izgāja no turienes ikviens uz savām mājām.
Ní àkókò náà, àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní ibẹ̀, wọ́n lọ sí ilé àti ẹ̀yà rẹ̀ olúkúlùkù sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
25 Tanīs dienās ķēniņa nebija iekš Israēla; ikviens darīja, kā tam patika.
Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, kò sí ọba ní ilẹ̀ Israẹli; olúkúlùkù sì ń ṣe bí ó ti tọ́ ní ojú ara rẹ̀.

< Sog̒u 21 >