< Ecechiela 28 >

1 Un Tā Kunga vārds uz mani notika sacīdams:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
2 Cilvēka bērns, saki uz Tirus valdnieku: tā saka Tas Kungs Dievs: Tāpēc ka tava sirds lepojās un saka, es esmu dievs, es sēžu uz dieva krēsla jūru vidū, un tu tomēr esi cilvēks un ne Dievs, un tu pacēli savu sirdi, kā Dieva sirdi;
“Ọmọ ènìyàn, sọ fún ọmọ-aládé Tire pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Nítorí tí ọkàn rẹ gbé sókè sí mi, ìwọ wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run; Èmi jókòó sí orí ìtẹ́ òrìṣà, ní àárín gbùngbùn Òkun.” Ṣùgbọ́n ènìyàn ni ọ́, kì i ṣe òrìṣà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ rò pé ìwọ gbọ́n bí Ọlọ́run.
3 Redzi, tu esot gudrāks nekā Daniēls, tev nekas neesot ne apslēpts ne tumšs.
Ìwọ gbọ́n ju Daniẹli lọ bí? Ṣé kò sí àṣírí kan tí ó pamọ́ fún ọ?
4 Caur savu gudrību un caur savu saprašanu tu sev esot dabūjis spēku un krājis zeltu un sudrabu pie savas mantas.
Pẹ̀lú ọgbọ́n àti ìmọ̀ rẹ, ìwọ tí jèrè ọrọ̀ fún ara rẹ, àti àkójọpọ̀ wúrà àti fàdákà, nínú àwọn ilé ìṣúra rẹ.
5 Caur savu lielo gudrību tu tirgodamies esot vairojis savu bagātību, un tava sirds lepojās tavas bagātības dēļ.
Nípa ọgbọ́n rẹ ńlá àti nípa òwò rẹ, ìwọ ti sọ ọrọ̀ rẹ di púpọ̀, àti nítorí ọrọ̀ rẹ di púpọ̀, ọkàn rẹ gbé sókè, nítorí ọrọ̀ rẹ.
6 Tāpēc tā saka Tas Kungs Dievs, tādēļ ka tu savu sirdi esi paaugstinājis, kā Dieva sirdi,
“‘Nítorí náà èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Nítorí pé ìwọ rò pé o gbọ́n, pé ìwọ gbọ́n bí Ọlọ́run.
7 Tad redzi, Es vedīšu svešus pār tevi, tos visbriesmīgākos starp tautām; tie izvilks savus zobenus pār tavu jauko gudrību un apgānīs tavu spožumu.
Èmi yóò mú kí àwọn àjèjì dìde sí ọ, ẹlẹ́rù nínú àwọn orílẹ̀-èdè; wọn yóò yọ idà wọn sí ọ, ẹwà rẹ àti ọgbọ́n rẹ, wọn yóò sì ba dídán rẹ̀ jẹ́.
8 Tie tevi nometīs bedrē, un tu nomirsi kā nokauti mirst pat jūru vidū.
Wọn yóò mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá sínú ihò, ìwọ yóò sì kú ikú gbígbóná, àwọn tí a pa ní àárín Òkun.
9 Vai tu tad sava kāvēja priekšā sacīsi: es esmu dievs, un tu tomēr esi cilvēks un ne Dievs, un esi sava kāvēja rokā?
Ṣé ìwọ yóò wá wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run,” ní ojú àwọn tí ó pa ọ́? Ìwọ yóò jẹ́ ènìyàn, kì í ṣe Ọlọ́run, ní ọwọ́ àwọn ti yóò pa ọ́.
10 Tu nomirsi kā neapgraizītie mirst caur svešu roku; jo Es to esmu runājis, saka Tas Kungs Dievs.
Ìwọ yóò kú ikú aláìkọlà, ní ọwọ́ àwọn àjèjì. Èmi ni ó ti sọ ọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
11 Atkal Tā Kunga vārds notika uz mani sacīdams:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
12 Cilvēka bērns! Sāc raudu dziesmu par Tirus ķēniņu un saki uz viņu: tā saka Tas Kungs Dievs: tu kārtības zieģelis, pilns gudrības un liela skaistuma,
“Ọmọ ènìyàn, pohùnréré ẹkún sórí ọba Tire kí ó sì sọ fún un pé: ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ìwọ jẹ́ àpẹẹrẹ ìjẹ́pípé náà, o kún fún ọgbọ́n, o sì pé ní ẹwà.
13 Tu biji Edenē, Dieva dārzā, visādi dārgi akmeņi bija tavs apsegs: sardi, topāzi, dimanti, turķisi, oniķi, jaspisi, safīri, ametisti, smaragdi un zelts. Tavas bungas un tavas stabules skanēja tavā priekšā, tai dienā, kad tevi (par ķēniņu) cēla, tās bija gatavas.
Ìwọ ti wà ní Edeni, ọgbà Ọlọ́run; onírúurú òkúta oníyebíye ni ìbora rẹ; sardiu, topasi àti diamọndi, berili, óníkìsì, àti jasperi, safire, emeradi, turikuose, àti karbunkili, àti wúrà, ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ àti àwọn òkè rẹ ní a dà, láti ara wúrà, ní ọjọ́ tí á dá ọ ní a pèsè wọn.
14 Tu biji svaidīts ķerubs, kas sargā; Es tevi tā biju iecēlis: tu biji uz Dieva svētā kalna, tu staigāji degošu akmeņu vidū.
A fi àmì òróró yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí olùtọ́jú kérúbù, torí èyí ni mo fi yàn ọ́. Ìwọ wà lórí òkè mímọ́ Ọlọ́run; ìwọ rìn ni àárín òkúta a mú bí iná.
15 Tu biji skaidrs savos ceļos, no tās dienas, kad tevi (par ķēniņu) cēla, kamēr bezdievība pie tevis tapa atrasta.
Ìwọ pé ní ọ̀nà rẹ, láti ọjọ́ tí a ti dá ọ, títí a fi rí àìṣedéédéé ní inú rẹ.
16 Caur tavu lielo tirgošanos tava sirds pildījās ar netaisnību, un tu esi apgrēkojies; tāpēc Es tevi izmetu kā sagānītu no Dieva kalna un izdeldu tevi, to ķerubu, kas sargā, no to degošo akmeņu vidus nost.
Nípa ìtànkálẹ̀ òwò rẹ, ìwọ kún fún ìwà ipá; ìwọ sì dẹ́ṣẹ̀. Nítorí náà ni mo ṣe sọ ọ nù, bí ohun àìlọ́wọ̀ kúrò lórí òkè Ọlọ́run. Èmi sì pa ọ run, ìwọ kérúbù, tí ó bọ́ kúrò ní àárín òkúta a mú bí iná.
17 Tava sirds lepojās tava skaistuma dēļ, tu savu gudrību esi pazaudējis caur savu spožumu, tāpēc Es tevi metu pie zemes un lieku tevi par mācību ķēniņiem.
Ọkàn rẹ gbéraga, nítorí ẹwà rẹ. Ìwọ sì ba ọgbọ́n rẹ jẹ́, nítorí dídára rẹ. Nítorí náà mo le ọ sórí ayé; mo sọ ọ di awòojú níwájú àwọn ọba.
18 Ar savu noziegumu pulku caur savu netaisno tirgošanos tu esi sagānījis savus svētumus. Tāpēc Es lieku ugunij iziet no tava vidus; tas tevi aprīs, un Es tevi daru par pelniem virs zemes, priekš visu acīm, kas tevi ierauga.
Nípa ẹ̀ṣẹ̀ púpọ̀ rẹ àti òwò àìṣòótọ́ rẹ, ìwọ ti ba àwọn ibi mímọ́ rẹ jẹ́. Nítorí náà mo mú kí iná jáde wá, láti inú rẹ, yóò sì jó ọ run, èmi yóò sì sọ ọ́ di eérú lórí ilẹ̀, lójú gbogbo àwọn tí ó ń wò ọ́.
19 Visi, kas tevi pazīst starp tautām, par tevi iztrūcinājās; tu esi galu ņēmis ar briesmām un nebūsi vairs mūžīgi.
Gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó mọ̀ ọ́n, ní ẹnu ń yà sí ọ; ìwọ yóò sì jẹ́ ẹ̀rù, ìwọ kì yóò sì ṣí mọ́ láéláé.’”
20 Atkal Tā Kunga vārds uz mani notika sacīdams:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
21 Cilvēka bērns, griez savu vaigu pret Sidonu un sludini pret to.
“Ọmọ ènìyàn, kọ ojú sí Sidoni; kí o sì sọtẹ́lẹ̀ sí i,
22 Un saki: tā saka Tas Kungs Dievs: redzi, Es celšos pret tevi, Sidona, un pagodināšos tavā vidū, un tie samanīs, ka Es esmu Tas Kungs, kad Es tiesu nesīšu pār viņu un svēts parādīšos pie viņas.
kí ó sì wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi lòdì sí ọ, ìwọ Sidoni, a ó sì ṣe mí lógo láàrín rẹ. Wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá mú ìdájọ́ mi ṣẹ nínú rẹ, tí a sì yá mí sí mímọ́ nínú rẹ.
23 Jo Es sūtīšu mēri pie viņas un asinis pa viņas ielām, un kautie kritīs viņas vidū caur zobenu, kas visapkārt nāks pret viņu, un tie samanīs, ka Es esmu Tas Kungs.
Èmi yóò sì rán àjàkálẹ̀-ààrùn sínú rẹ, èmi yóò sì mú kí ẹ̀jẹ̀ sàn ní ìgboro rẹ, ẹni ti á pa yóò ṣubú ní àárín rẹ, pẹ̀lú idà lára rẹ ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, nígbà náà wọn yóò mọ̀ wí pé èmi ni Olúwa.
24 Un Israēla namam vairs nebūs asu ērkšķu, nedz sāpīgu dadžu no visiem tiem apkārtējiem, kas tos vajā, un tie samanīs, ka Es esmu Tas Kungs Dievs.
“‘Kì yóò sì ṣí ẹ̀gún tí ń gun ni ní ilẹ̀ Israẹli mọ́, tàbí ẹ̀gún bíbani nínú jẹ́ ti gbogbo àwọn tí wọn wà ní àyíká wọn, tí wọ́n sì ń fi ojú yẹpẹrẹ wò wọ́n, nígbà náà ni wọn yóò mọ́ wí pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.
25 Tā saka Tas Kungs Dievs: kad Es Israēla namu sapulcināšu no tām tautām, starp kurām tie izkaisīti, un Es pie viņiem svēts parādīšos priekš pagānu acīm, tad tie dzīvos savā zemē, ko Es savam kalpam Jēkabam esmu devis.
“‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí èmi yóò bá sa àwọn ènìyàn Israẹli jọ kúrò ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti fọ́nká sí, tí a ó sì yà mí sí mímọ́ láàrín wọn lójú àwọn aláìkọlà. Nígbà náà ni wọn yóò gbé ní ilẹ̀ àwọn tìkálára wọn, èyí tí mo fún ìránṣẹ́ mi Jakọbu.
26 Un tie tur dzīvos droši un uztaisīs namus un dēstīs vīna dārzus. Tiešām, tie dzīvos droši, kad Es tiesu nesīšu pret visiem tiem apkārtējiem, kas tos vajājuši, un tie samanīs, ka Es esmu Tas Kungs, viņu Dievs.
Wọn yóò sì máa gbé ní inú rẹ̀ ní àìléwu, wọn yóò sì kọ́lé, wọn yóò sì gbin ọgbà àjàrà; nítòótọ́ wọn yóò wà ní ìbàlẹ̀ àyà, nígbà tí èmi bá ti mú ìdájọ́ mi ṣẹ̀ sí ara àwọn tí ń ṣátá wọn ní gbogbo àyíká wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn.’”

< Ecechiela 28 >