< Giosué 15 >

1 OR [questa] fu la sorte della tribù de' figliuoli di Giuda, per le lor nazioni: L'estremità [del lor paese] verso il Mezzodì fu il deserto di Sin, a' confini di Edom, verso il Mezzodì.
Ìpín fún ẹ̀yà Juda, ní agbo ilé agbo ilé, títí dé agbègbè Edomu, títí dé aginjù Sini ní òpin ìhà gúúsù.
2 Così ebbero per confine dal Mezzodì, l'estremità del mar salso, dalla punta che riguarda verso il Mezzodì.
Ààlà wọn ní ìhà gúúsù bẹ̀rẹ̀ láti etí òpin ìhà gúúsù Òkun Iyọ̀,
3 E [questo confine] procedeva verso il Mezzodì, alla salita di Acrabbim, e passava fino a Sin; e dal Mezzodì saliva a Cades-barnea, e passava in Hesron; e [di là] saliva in Adar, e poi si volgeva verso Carcaa;
ó sì gba gúúsù Akrabbimu lọ, títí dé Sini àti sí iwájú ìhà gúúsù Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà ó sì tún kọjá Hesroni lọ sí Adari, ó sì tún yípo yíká lọ sí Karka.
4 poi passava verso Asmon, e si stendeva fino al Torrente di Egitto, e questo confine faceva capo al mare. Questo sarà, [disse Giosuè], il vostro confine meridionale.
Ó tún kọjá lọ sí Asmoni, ó sì papọ̀ mọ́ Wadi ti Ejibiti, ó parí sí Òkun. Èyí ni ààlà wọn ní ìhà gúúsù.
5 E il confine orientale [fu] il mar salso, fino all'estremità del Giordano. E il confine dal lato settentrionale [fu] dalla punta di quel mare, [la quale è] all'estremità del Giordano.
Ààlà wọn ní ìhà ìlà-oòrùn ní Òkun Iyọ̀ títí dé ẹnu Jordani. Ààlà àríwá bẹ̀rẹ̀ láti etí òkun ní ẹnu Jordani,
6 E questo confine saliva in Bet-hogla, e passava dal lato settentrionale di Bet-araba, e [di là] saliva al Sasso di Bohan Rubenita;
ààlà náà sì tún dé Beti-Hogla, ó sì lọ sí ìhà àríwá Beti-Araba. Ààlà náà sì tún dé ibi Òkúta Bohani ti ọmọ Reubeni.
7 poi saliva in Debir, dalla valle di Acor; e dal Settentrione riguardava verso Ghilgal, che [è] dirimpetto alla salita di Adummim, che [è] dal lato meridionale del torrente; poi questo confine passava alle acque di En-semes, e faceva capo ad En-roghel.
Ààlà náà gòkè lọ títí dé Debiri láti àfonífojì Akori, ó sì yípadà sí àríwá Gilgali, èyí tí ń bẹ ní iwájú òkè Adummimu, tí ń bẹ ní ìhà gúúsù odò náà. Ó sì tẹ̀síwájú sí apá omi En-Ṣemeṣi, ó sì jáde sí En-Rogeli.
8 Poi questo confine saliva alla valle de' figliuoli di Hinnom, allato [alla città] de' Gebusei, dal Mezzodì, [la quale] è Gerusalemme; e [di là] saliva alla sommità del monte, che [è] dirimpetto alla valle di Hinnom, verso l'Occidente, il quale [è] all'estremità della valle de' Rafei, verso il Settentrione.
Ààlà náà sì tún gòkè lọ sí àfonífojì Beni-Hinnomu ní ìhà gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ gúúsù ti Jebusi (tí í ṣe Jerusalẹmu). Ó sì gòkè lọ sí orí òkè tí ó wà lórí àfonífojì Hinnomu tí ń bẹ ní ìpẹ̀kun àfonífojì Refaimu ní ìhà àríwá.
9 Poi questo confine girava dalla sommità di quel monte, verso la fonte delle acque di Neftoa, e procedeva verso le città del monte di Efron; poi girava verso Baala, [che] è Chiriat-iearim.
Ààlà náà sì lọ láti orí òkè lọ sí ìsun omi Nefitoa, ó sì jáde sí ìlú òkè Efroni, ó sì lọ sí apá ìsàlẹ̀ Baalahi (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu).
10 Poi questo confine si volgeva da Baala verso Occidente, al monte di Seir, e passava fino allato al monte di Iearim dal Settentrione, [nel luogo detto] Chesalon; poi scendeva in Bet-semes, e passava in Timna.
Ààlà tí ó yípo láti Baalahi lọ sí ìhà ìwọ̀-oòrùn sí òkè Seiri, ó sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Jearimu (tí í ṣe, Kesaloni), ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Beti-Ṣemeṣi, ó sì kọjá lọ sí Timna.
11 Poi questo confine procedeva al canto di Ecron, verso il Settentrione, e girava verso Siccheron, e passava al monte Baala, e si stendeva fino a Iabneel, e faceva capo al mare.
Ààlà náà sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Ekroni, ó sì yípadà lọ sí Ṣikkeroni, ó sì yípadà lọ sí òkè Baalahi, ó sì dé Jabneeli, ààlà náà sì parí sí Òkun.
12 E il confine dall'Occidente [era] il mar grande, e i confini. Questi [furono] i confini de' figliuoli di Giuda d'ogni intorno, secondo le lor nazioni.
Ààlà ìwọ̀-oòrùn sì jẹ́ agbègbè Òkun Ńlá. Ìwọ̀nyí ni ààlà àyíká ènìyàn Juda ní agbo ilé wọn.
13 Or [Giosuè] avea data a Caleb, figliuolo di Gefunne, una porzione nel mezzo dei figliuoli di Giuda, secondo il comandamento fattogli dal Signore, [cioè: ] Chiriat-Arba, [il quale Arba fu] padre di Anac; essa [è] Hebron.
Gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí Olúwa pa fún Joṣua, ó fi ìpín fún Kalebu ọmọ Jefunne, ìpín ní Juda—Kiriati-Arba, tí í ṣe Hebroni. (Arba sì ní baba ńlá Anaki.)
14 E Caleb scacciò di là i tre figliuoli di Anac, Sesai, ed Ahiman, e Talmai, nati di Anac.
Kalebu sì lé àwọn ọmọ Anaki mẹ́ta jáde láti Hebroni; Ṣeṣai, Ahimani, àti Talmai, ìran Anaki.
15 E di là egli salì agli abitanti di Debir, il cui nome per addietro [era stato] Chiriat-sefer.
Ó sì wọ́de ogun láti ibẹ̀ lọ bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Debiri (tí à ń pè ní Kiriati-Seferi nígbà kan rí).
16 E Caleb disse: Chi percoterà Chiriat-sefer, e la prenderà, io gli darò Asca, mia figliuola, per moglie.
Kalebu sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọbìnrin mi Aksa fún ọkùnrin tí ó bá kọlu Kiriati-Seferi, tí ó sì gbà á ní ìgbéyàwó.”
17 E Otniel, figliuolo di Chenaz, fratello di Caleb, la prese; e Caleb gli diede Acsa, sua figliuola, per moglie.
Otnieli ọmọ Kenasi, arákùnrin Kalebu, sì gbà á, báyìí ni Kalebu sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ Aksa fún un ní ìyàwó.
18 E quando ella venne [a marito], indusse Otniel a domandare un campo a suo padre; poi ella si gittò giù d'in su l'asino; e Caleb le disse: Che hai?
Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Aksa lọ sí ọ̀dọ̀ Otnieli, ó rọ̀ ọ́ kí ó béèrè ilẹ̀ oko lọ́wọ́ baba rẹ̀. Nígbà náà ni Aksa sọ̀kalẹ̀ ní orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, Kalebu sì béèrè pé, “Kí ni kí èmi ṣe fún ọ?”
19 Ed ella disse: Fammi un dono; conciossiachè tu m'abbi data una terra asciutta, dammi anche delle fonti d'acque. Ed egli le donò delle fonti ch'erano disopra, e delle fonti ch'erano disotto.
Ó sì dáhùn pé, “Mo ń fẹ́ kí o ṣe ojúrere kan fún mi, nígbà ti o ti fún mi ní ilẹ̀ ní gúúsù, fún mi ní ìsun omi náà pẹ̀lú.” Kalebu sì fún un ní ìsun òkè àti ìsun ìsàlẹ̀.
20 Quest'[è] l'eredità della tribù de' figliuoli di Giuda, secondo le lor nazioni.
Èyí ni ilẹ̀ ìní ẹ̀yà àwọn ọmọ Juda gẹ́gẹ́ bi ìdílé wọn.
21 Nell'estremità [della contrada] della tribù de' figliuoli di Giuda, a' confini di Edom, verso il Mezzodì, v'erano queste città: Cabseel, ed Eder, e Iagur;
Ìlú ìpẹ̀kun gúúsù ti ẹ̀yà Juda ní gúúsù ní ààlà Edomu nìwọ̀nyí: Kabṣeeli, Ederi, Jaguri,
22 e China, e Dimona, e Adada;
Kina, Dimona, Adada,
23 e Chedes, e Hasor, e Itnan;
Kedeṣi, Hasori, Itina,
24 e Zif, e Telem, e Bealot;
Sifi, Telemu, Bealoti,
25 e Hasor-hadatta e Cheriot (Hesron è Hasor);
Hasori Hadatta, Kerioti Hesroni (tí í ṣe Hasori),
26 e Amam e Sema, e Molada;
Amamu, Ṣema, Molada,
27 e Hasar-gadda, e Hesmon, e Betpelet;
Hasari Gada, Heṣmoni, Beti-Peleti,
28 e Hasar-sual, e Beerseba, e Biziotia; e Baala, e Iim, ed Esem;
Hasari-Ṣuali, Beerṣeba, Bisiotia,
29 ed Eltolad, e Chesil, e Horma;
Baalahi, Limu, Esemu,
30 e Siclag, e Madmanna,
Eltoladi, Kesili, Horma,
31 e Sansanna;
Siklagi, Madmana, Sansanna,
32 e Labaot, e Silhim, e Ain, e Rimmon; in tutto ventinove città, con le lor villate.
Leboati, Ṣilhimu, Aini àti Rimoni, àpapọ̀ ìlú mọ́kàndínlọ́gbọ̀n àti àwọn ìletò wọn.
33 Nella pianura [v'erano queste città: ] Estaol, e Sorea, e Asna;
Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ẹsẹ̀ òkè: Eṣtaoli, Sora, Aṣna,
34 e Zanoa, ed En-gannim, e Tappua, ed Enam;
Sanoa, Eni-Gannimu, Tapua, Enamu,
35 e Iarmut, e Adullam, e Soco, e Azeca;
Jarmatu, Adullamu, Soko, Aseka,
36 e Saaraim, e Aditaim, e Ghedera, e Ghederotaim; quattordici città, con le lor villate.
Ṣaaraimu, Adittaimu àti Gedera (tàbí Gederotaimu). Ìlú mẹ́rìnlá àti àwọn ìletò wọn.
37 [Poi] Senan, e Hadasa, e Migdal-Gad;
Senani, Hadaṣa, Migdali Gadi,
38 e Dilan, e Mispe, e Iocteel;
Dileani, Mispa, Jokteeli,
39 e Lachis, e Boscat, ed Eglon;
Lakiṣi, Boskati, Egloni,
40 e Cabbon, e Lamas, e Chitlis;
Kabboni, Lamasi, Kitlisi,
41 e Ghederot, e Bet-Dagon, e Naama, e Maccheda; sedici città con le lor villate.
Gederoti, Beti-Dagoni, Naama àti Makkeda, ìlú mẹ́rìndínlógún àti ìletò wọn.
42 [Poi] Libna, ed Eter, e Asan;
Libina, Eteri, Aṣani,
43 e Ifta, e Asna, e Nesib;
Hifita, Aṣna, Nesibu,
44 e Cheila, e Aczib, e Maresa; nove città, con le lor villate;
Keila, Aksibu àti Meraṣa: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò wọn.
45 [poi] Ecron, e le terre del suo territorio, e le sue villate;
Ekroni, pẹ̀lú ibùgbé àti àwọn ìletò rẹ̀ tó yí i ká,
46 da Ecron, e verso il mare, tutte [le città] che [sono] presso di Asdod, con le lor villate.
ìwọ̀-oòrùn Ekroni, gbogbo èyí tí ń bẹ nítòsí Aṣdodu, pẹ̀lú àwọn ìletò wọn,
47 [Poi] Asdod, e le terre del suo territorio, e le sue villate; Gaza, e le terre del suo territorio, e le sue villate, infino al Torrente di Egitto, e al mar grande, e i confini.
Aṣdodu, agbègbè ìlú rẹ̀ àti ìletò; àti Gasa, ìlú rẹ̀ àti ìletò, títí ó fi dé odò Ejibiti àti agbègbè Òkun Ńlá.
48 E nel monte [v'erano queste città: ] Samir, e Iattir, e Soco;
Ní ilẹ̀ òkè náà: Ṣamiri, Jattiri, Soko,
49 e Danna, e Chiriat-sanna, [che] è Debir;
Dannah, Kiriati-Sannnah (tí í ṣe Debiri),
50 e Anab, ed Estemo, e Anim;
Anabu, Eṣitemo, Animu,
51 e Gosen, e Holon, e Ghilo; undici città, con le lor villate.
Goṣeni, Holoni àti Giloni, ìlú mọ́kànlá àti ìletò wọn.
52 [Poi] Arab, e Duma, ed Esan;
Arabu, Duma, Eṣani,
53 e Ianum, e Bet-tappua, e Afeca;
Janimu, Beti-Tapua, Afeka,
54 e Humta, e Chiriat-Arba, [che] è Hebron, e Sior; nove città, con le lor villate.
Hamuta, Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni) àti Ṣiori: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò rẹ̀
55 [Poi] Maon, e Carmel, e Zif, e Iuta;
Maoni, Karmeli, Sifi, Jutta,
56 e Izreel, e Iocdeam, e Zanoa;
Jesreeli, Jokdeamu, Sanoa,
57 e Cain, e Ghibea, e Timna; dieci città, con le lor villate;
Kaini, Gibeah àti Timna: ìlú mẹ́wàá àti àwọn ìletò wọn.
58 [poi] Halhul, e Bet-sur, e Ghedor;
Halhuli, Beti-Suri, Gedori,
59 e Maarat, e Bet-anot, ed Eltecon; sei città, con le lor villate.
Maarati, Beti-Anoti àti Eltekoni: ìlú mẹ́fà àti àwọn ìletò wọn.
60 [Poi] Chiriat-baal, [che] è Chiriat-iearim, e Rabba; due città, con le lor villate.
Kiriati-Baali (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu) àti Rabba ìlú méjì àti ìletò wọn.
61 Nel deserto [v'erano queste città: ] Bet-araba, e Middin, e Secaca;
Ní aginjù: Beti-Araba, Middini, Sekaka,
62 e Nibsan, e la Città del sale, ed Enghedi; sei città, con le lor villate.
Nibṣani, Ìlú Iyọ̀ àti En-Gedi: ìlú mẹ́fà àti ìletò wọn.
63 Or i figliuoli di Giuda non poterono scacciare i Gebusei che abitavano in Gerusalemme; perciò i Gebusei son dimorati in Gerusalemme co' figliuoli di Giuda, infino a questo giorno.
Juda kò lè lé àwọn ọmọ Jebusi jáde, tí wọ́n ń gbé ní Jerusalẹmu. Àwọn ará Jebusi sì ń gbé pẹ̀lú àwọn ènìyàn Juda títí dí òní.

< Giosué 15 >