< Esodo 6 >

1 Ed il Signore disse a Mosè: Ora vedrai [quel] ch'io farò a Faraone; perciocchè, [sforzato] con potente mano, li lascerà andare; anzi, [sforzato] con potente mano, li caccerà dal suo paese.
Nígbà náà ní Olúwa sọ fún Mose pé, “Ní ìsin yìí, ìwọ yóò rí ohun tí èmi yóò ṣe sí Farao pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá mi ni yóò fi jẹ́ kí wọn lọ; pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá mi, òun yóò lé wọn jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.”
2 Oltre a ciò, Iddio parlò a Mosè, e gli disse:
Ọlọ́run sì tún sọ fún Mose pé, “Èmi ni Olúwa.
3 Io [sono] il Signore. E apparvi ad Abrahamo, ad Isacco, ed a Giacobbe, sotto il [nome di: ] Dio Onnipotente; ma non fui conosciuto da loro sotto il mio nome di: Colui che è.
Mo fi ara hàn Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu bí Ọlọ́run alágbára, ṣùgbọ́n nípa orúkọ mi Olúwa, Èmi kò fi ara mi hàn wọ́n.
4 E, come io fermai il mio patto con loro, di dar loro il paese di Canaan, il paese de' lor pellegrinaggi, nel quale dimorarono come forestieri;
Èmí sì tún fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú wọn láti fún wọn ní ilẹ̀ Kenaani, ilẹ̀ tí wọn gbé gẹ́gẹ́ bí àjèjì.
5 così ancora ho uditi gli stridi de' figliuoli d'Israele, i quali gli Egizj tengono in servitù; e mi son ricordato del mio patto.
Èmi sì ti tún gbọ́ kíkùn àwọn ọmọ Israẹli àwọn tí àwọn ará Ejibiti mú gẹ́gẹ́ bí ẹrú, àti pé èmi sì ti rántí májẹ̀mú mi.
6 Perciò, di' ai figliuoli d'Israele: Io [sono] il Signore; e vi trarrò di sotto alle gravezze degli Egizj, e vi libererò dalla servitù loro, e vi riscuoterò con braccio steso, e con grandi giudicii.
“Sọ fún àwọn ará ilé Israẹli, ‘Èmi ni Olúwa, Èmi yóò sọ yín di òmìnira kúrò nínú àjàgà àwọn ará Ejibiti. Èmi yóò sì gbà yín sílẹ̀ kúrò ní oko ẹrú wọn. Èmi yóò dá a yín sílẹ̀ pẹ̀lú apá nínà (àwọn iṣẹ́ ìyanu) àti pẹ̀lú ìdájọ́ ńlá.
7 E vi prenderò per mio popolo, e sarò vostro Dio; e voi conoscerete ch'io [sono] il Signore Iddio vostro, che vi traggo di sotto alle gravezze degli Egizj.
Èmi yóò mú un yín bí ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, ẹni tí ó mú un yín jáde kúrò nínú àjàgà àwọn ará Ejibiti.
8 E vi condurrò nel paese, del quale io ho alzata la mano che io lo darei ad Abrahamo, ad Isacco, ed a Giacobbe; e vel darò [per] possessione ereditaria. Io [sono] il Signore.
Èmi yóò mú un yín wá ilẹ̀ náà ti èmi ti búra pẹ̀lú ìgbọ́wọ́sókè láti fi fún Abrahamu. Isaaki àti Jakọbu. Èmi yóò fi fún un yín bí ohun ìní, Èmi ni Olúwa.’”
9 E Mosè parlò in quella stessa maniera a' figliuoli d'Israele; ma essi non porsero orecchio a Mosè, per l'angoscia dello spirito [loro], e per la dura servitù.
Mose sì sọ èyí fún àwọn ará Israẹli, ṣùgbọ́n wọn kò fi etí sílẹ̀ sí Mose nítorí ọkàn wọn tó rẹ̀wẹ̀sì àti nítorí ìgbèkùn búburú bí ohun tí ó ti kọ́ sọ kó wọn sí ní oko ẹrú wọn.
10 E il Signore parlò a Mosè, dicendo:
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose.
11 Va', parla a Faraone, re di Egitto, che lasci andare i figliuoli d'Israele dal suo paese.
“Lọ, sọ fún Farao ọba Ejibiti pé kí ó jẹ́ kí àwọn ará Israẹli lọ kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.”
12 E Mosè parlò nel cospetto del Signore, dicendo: Ecco, i figliuoli di Israele non mi hanno porto orecchio; e come mi porgerebbe orecchio Faraone, [essendo] io incirconciso di labbra?
Ṣùgbọ́n Mose sọ fún Olúwa pé, “Nígbà ti àwọn ará Israẹli tó jẹ́ ènìyàn mi kó fetí sí ọ̀rọ̀ mi, báwo ni Farao yóò ṣe fetí sí ọ̀rọ̀ mi, nígbà ti mo jẹ́ akólòlò?”
13 Ma il Signore parlò a Mosè e ad Aaronne, e comandò loro [di andare] ai figliuoli d'Israele, e a Faraone, re di Egitto, per trar fuor del paese di Egitto i figliuoli d'Israele.
Olúwa bá ìran Mose àti Aaroni sọ̀rọ̀ nípa àwọn ará Israẹli àti Farao ọba Ejibiti, ó pàṣẹ fún wọn pé kí wọn kó àwọn Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.
14 QUESTI [sono] i capi delle famiglie paterne di essi: I figliuoli di Ruben, primogenito di Israele, [furono] Henoc, e Pallu, e Hesron, e Carmi. Queste [son] le famiglie de' Rubeniti.
Wọ̀nyí ni olórí ìran wọn: àwọn ọmọ Reubeni àkọ́bí Israẹli ni: Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi. Àwọn wọ̀nyí ni ìdílé Reubeni.
15 E i figliuoli di Simeone [furono] Iemuel, e Iamin, e Ohad, e Iachin, e Sohar, e Saul, figliuolo d'una Cananea. Queste [son] le famiglie de' Simeoniti.
Àwọn ọmọ Simeoni ni: Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu ọmọ obìnrin Kenaani. Àwọn wọ̀nyí ni ìran Simeoni.
16 E questi [sono] i nomi de' figliuoli di Levi, secondo le lor generazioni: Gherson, e Chehat, e Merari. E gli anni della vita di Levi [furono] centrentasette.
Ìwọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ wọn: Gerṣoni, Kohati àti Merari. Lefi lo ẹ̀tàdínlógóje ọdún láyé.
17 I figliuoli di Gherson [furono: ] Libni, e Simi, divisi per le lor generazioni.
Àwọn ọmọ Gerṣoni ni ìran wọn ni: Libni àti Ṣimei.
18 E i figliuoli di Chehat [furono: ] Amram, e Ishar, e Hebron, e Uzziel. E gli anni della vita di Chehat [furono] centrentatre.
Àwọn ọmọ Kohati ni: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli. Kohati lo ẹ̀tàléláádóje ọdún láyé.
19 E i figliuoli di Merari [furono] Mahali, e Musi. Queste [son] le famiglie dei Leviti, [divise] per le lor linee.
Àwọn ọmọ Merari ni: Mahili àti Muṣi. Ìwọ̀nyí ni ìran Lefi gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ wọn.
20 Or Amram prese Iochebed, sua zia, per moglie; ed essa gli partorì Aaronne e Mosè. E gli anni della vita di Amram [furono] centrentasette.
Amramu sì fẹ́ Jokebedi arábìnrin baba rẹ̀ ní ìyàwó. Jokebedi sì bí Aaroni àti Mose fún un. Amramu lo ẹ̀tàdínlógóje ọdún láyé.
21 E i figliuoli di Ishar [furono: ] Core, e Nefeg, e Zicri.
Àwọn ọmọ Isari ni: Kora, Nefegi àti Sikri.
22 E i figliuoli di Uzziel [furono: ] Misael, ed Elsafan, e Zicri.
Àwọn ọmọ Usieli ni: Miṣaeli, Elsafani àti Sitiri.
23 E Aaronne si prese per moglie Eliseba, figliuola di Amminadab, sorella di Nahasson; ed [essa] gli partorì Nadab, e Abihu, ed Eleazar, e Itamar.
Aaroni fẹ́ Eliṣeba ọmọbìnrin Amminadabu tí í ṣe arábìnrin Nahiṣoni, ó sì bí Nadabu, Abihu, Eleasari àti Itamari.
24 E i figliuoli di Core [furono: ] Assir, ed Elcana, e Abiasaf. Queste [son] le famiglie de' Coriti.
Àwọn ọmọ Kora ni: Asiri, Elkana àti Abiasafu. Ìwọ̀nyí ni ìran Kora.
25 Ed Eleazar, figliuolo di Aaronne si prese per moglie [una] delle figliuole di Putiel; ed essa gli partorì Finees. Questi [sono] i capi delle [famiglie] paterne de' Leviti per le loro schiatte.
Eleasari ọmọ Aaroni fẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọbìnrin Putieli ní ìyàwó, ó sì bí Finehasi fún un. Ìwọ̀nyí ni olórí àwọn Lefi ni ìdílé ìdílé.
26 Quest'[è] quell'Aaronne, e quel Mosè, a' quali il Signore disse: Traete fuor del paese di Egitto i figliuoli d'Israele, per le loro schiere.
Aaroni àti Mose yìí kan náà ni Olúwa sọ fún pé, “Ẹ kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti ní ìsọ̀rí ìsọ̀rí.”
27 Essi, [cioè] Mosè ed Aaronne, [furon quelli] che parlarono a Faraone, re di Egitto, per trar fuor di Egitto i figliuoli d'Israele.
Àwọn ni ó bá Farao ọba Ejibiti sọ̀rọ̀ nípa kíkó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni Ejibiti, àní Mose àti Aaroni yìí kan náà ni.
28 OR nel giorno che il Signore parlò a Mosè, nel paese di Egitto,
Nígbà tí Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ni Ejibiti,
29 il Signore gli disse: Io [sono] il Signore; di' a Faraone, re di Egitto, tutto ciò che io ti dico.
Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Èmi ni Olúwa. Sọ ohun gbogbo ti mo ti sọ fún ọ fún Farao ọba Ejibiti.”
30 E Mosè disse nel cospetto del Signore: Ecco, io [sono] incirconciso di labbra; come dunque Faraone mi porgerebbe egli orecchio?
Ṣùgbọ́n Mose sì wí ní iwájú Olúwa pé, “Níwọ́n ìgbà ti mo jẹ́ akólòlò, ọ̀nà dà ti Farao yóò ṣe fi etí sí mi?”

< Esodo 6 >