< Zsoltárok 25 >

1 Dávidé. Hozzád emelem, Uram, lelkemet!
Ti Dafidi. Olúwa, ìwọ ni mo gbé ọkàn mi sókè sí.
2 Istenem, benned bízom; ne szégyenüljek meg; ne örüljenek rajtam ellenségeim.
Ọlọ́run, èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ; má ṣe jẹ́ kí ojú ó tì mí má ṣe jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi ó yọ̀ mí.
3 Senki se szégyenüljön meg, a ki téged vár; szégyenüljenek meg, a kik ok nélkül elpártolnak tőled.
Ẹni tí ó dúró tì ọ́ ojú kì yóò tì í, àwọn tí ń ṣẹ̀ láìnídìí ni kí ojú kí ó tì.
4 Útjaidat, Uram, ismertesd meg velem, ösvényeidre taníts meg engem.
Fi ọ̀nà rẹ hàn mí, Olúwa, kọ mi ní ipa tìrẹ;
5 Vezess engem a te igazságodban és taníts engem, mert te vagy az én szabadító Istenem, mindennap várlak téged.
ṣe amọ̀nà mi nínú òtítọ́ ọ̀ rẹ, kí o sì kọ́ mi, nítorí ìwọ ni Ọlọ́run ìgbàlà mi; ìwọ ni mo dúró tì ní gbogbo ọjọ́.
6 Emlékezzél meg, Uram, irgalmasságodról és kegyelmedről, mert azok öröktől fogva vannak.
Rántí, Olúwa àánú àti ìfẹ́ ẹ̀ rẹ̀ ńlá, torí pé wọ́n ti wà ní ìgbà àtijọ́.
7 Ifjúságomnak vétkeiről és bűneimről ne emlékezzél meg; kegyelmed szerint emlékezzél meg rólam, a te jóvoltodért, Uram!
Má ṣe rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ìgbà èwe mi tàbí ìrékọjá mi; gẹ́gẹ́ bí i ìfẹ́ ẹ rẹ̀ rántí mi nítorí tí ìwọ dára, Ìwọ! Olúwa.
8 Jó és igaz az Úr, azért útba igazítja a vétkezőket.
Rere àti ẹni ìdúró ṣinṣin ní Olúwa: nítorí náà, ó kọ́ àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni ọ̀nà náà.
9 Igazságban járatja az alázatosokat, és az ő útjára tanítja meg az alázatosokat.
Ó ṣe amọ̀nà àwọn onírẹ̀lẹ̀ ni ohun tí ó dára, ó sì kọ́ àwọn onírẹ̀lẹ̀ ní ọ̀nà rẹ̀.
10 Az Úrnak minden útja kegyelem és hűség azoknak, a kik szövetségét és bizonyságait megtartják.
Gbogbo ipa ọ̀nà Olúwa ni ìfẹ́ àti òdodo tí ó dúró ṣinṣin, fún àwọn tí ó pa májẹ̀mú àti ẹ̀rí rẹ̀ mọ́.
11 A te nevedért, Uram, bocsásd meg bűnömet, mert sok az.
Nítorí orúkọ rẹ, Olúwa, dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí, nítorí tí ó tóbi.
12 Kicsoda az, a ki féli az Urat? Megmutatja annak az útat, a melyet válaszszon.
Àwọn wo ni ó bẹ̀rù Olúwa? Yóò kọ́ wọn ní ọ̀nà èyí tí wọn yóò yàn.
13 Annak lelke megmarad a jóban, és magzatja örökli a földet.
Wọn yóò lo ọjọ́ wọn nínú àlàáfíà, àwọn ọmọ wọn yóò sì gba ilẹ̀ náà.
14 Az Úr bizodalmas az őt félőkhöz, és szövetségével oktatja őket.
Olúwa fi ọkàn tán, àwọn tí o bẹ̀rù u rẹ̀; ó sọ májẹ̀mú rẹ̀ di mí mọ̀ fún wọn.
15 Szemeim mindenha az Úrra néznek, mert ő húzza ki a tőrből lábamat.
Ojú mi gbé sókè sọ́dọ̀ Olúwa, nítorí pé yóò yọ ẹsẹ̀ mi kúrò nínú àwọ̀n náà.
16 Tekints reám és könyörülj rajtam, mert árva és szegény vagyok.
Yípadà sí mi, kí o sì ṣe oore fún mi; nítorí pé mo nìkan wà, mo sì di olùpọ́njú.
17 Eláradtak szívemnek szorongásai, nyomorúságaimból szabadíts meg engem.
Tì mí lẹ́yìn kúrò nínú ìpọ́njú àyà mi; kí o sì fà mí yọ kúrò nínú ìpọ́njú mi.
18 Lásd meg szegénységemet és gyötrelmemet; bocsásd meg minden bűnömet.
Kíyèsi ìjìyà àti wàhálà mi, kí o sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi jì.
19 Lásd meg ellenségeimet, mert megsokasodtak, és gyilkos gyűlölséggel gyűlölnek engem.
Kíyèsi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀tá mi, tí wọn kórìíra mi pẹ̀lú ìwà ìkà wọn.
20 Őrizd meg lelkemet és szabadíts meg engem; ne szégyenüljek meg, hogy benned bíztam.
Pa ọkàn mi mọ́, kí o sì gbà mí sílẹ̀; má ṣe jẹ́ kí a fi mí sínú ìtìjú, nítorí pé ìwọ ni ibi ìsádi mi.
21 Ártatlanság és becsület védelmezzenek meg engem, mert téged várlak.
Jẹ́ kí òtítọ́ inú àti ìdúró ṣinṣin kí ó pa mí mọ́; nítorí pé mo dúró tì ọ́.
22 Mentsd ki, Isten, Izráelt minden bajából.
Ra Israẹli padà, Ìwọ Ọlọ́run, nínú gbogbo ìṣòro rẹ̀!

< Zsoltárok 25 >