< Lukács 18 >

1 Monda pedig nékik példázatot is arról, hogy mindig imádkozni kell, és meg nem restülni;
Ó sì pa òwe kan fún wọn láti fi yé wọn pe, ó yẹ kí a máa gbàdúrà nígbà gbogbo, kí a má sì ṣàárẹ̀.
2 Mondván: Volt egy bíró egy városban, a ki Istent nem félt és embert nem becsült.
Wí pé, “Onídàájọ́ kan wà ní ìlú kan, tí kò bẹ̀rù Ọlọ́run, tí kò sì ṣe ojúsàájú ènìyàn.
3 Volt pedig abban a városban egy özvegyasszony, és elméne ahhoz, mondván: Állj bosszút értem az én ellenségemen.
Opó kan sì wà ní ìlú náà, ó sì ń tọ̀ ọ́ wá, wí pé, ‘Gbẹ̀san mi lára ọ̀tá mi!’
4 Az pedig nem akará egy ideig; de azután monda ő magában: Jól lehet Istent nem félek és embert nem becsülök;
“Lákọ̀ọ́kọ́ kò dá a lóhùn, ṣùgbọ́n níkẹyìn ó wí nínú ara rẹ̀ pé, ‘Bí èmi kò tilẹ̀ bẹ̀rù Ọlọ́run, tí èmi kò sì ṣe ojúsàájú ènìyàn,
5 Mindazáltal mivelhogy nékem terhemre van ez az özvegyasszony, megszabadítom őt, hogy szüntelen reám járván, ne gyötörjön engem.
Ṣùgbọ́n nítorí tí opó yìí ń yọ mí lẹ́nu, èmi ó gbẹ̀san rẹ̀, kí ó má ba à fi wíwá rẹ̀ nígbàkígbà dá mi lágara.’”
6 Monda pedig az Úr: Halljátok, mit mond e hamis bíró!
Olúwa sì wí pé, “Ẹ gbọ́ bí aláìṣòótọ́ onídàájọ́ ti wí!
7 Hát az Isten nem áll-é bosszút az ő választottaiért, kik ő hozzá kiáltanak éjjel és nappal, ha hosszútűrő is irántuk?
Ọlọ́run kì yóò ha sì gbẹ̀san àwọn àyànfẹ́ rẹ̀, tí ń fi ọ̀sán àti òru kígbe pè é, tí ó sì mú sùúrù fún wọn?
8 Mondom néktek, hogy bosszút áll értök hamar. Mindazáltal az embernek Fia mikor eljő, avagy talál-é hitet e földön?
Mo wí fún yín, yóò gbẹ̀san wọn kánkán! Ṣùgbọ́n nígbà tí Ọmọ Ènìyàn bá dé yóò ha rí ìgbàgbọ́ ní ayé bí?”
9 Némelyeknek pedig, kik elbizakodtak magukban, hogy ők igazak, és a többieket semmibe sem vették, ezt a példázatot is mondá:
Ó sì pa òwe yìí fún àwọn kan tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé ara wọn pé, àwọn ni olódodo, tí wọ́n sì ń gan àwọn ẹlòmíràn,
10 Két ember méne fel a templomba imádkozni; az egyik farizeus, és a másik vámszedő.
pé, “Àwọn ọkùnrin méjì gòkè lọ sí tẹmpili láti gbàdúrà, ọ̀kan jẹ́ Farisi, èkejì sì jẹ́ agbowó òde.
11 A farizeus megállván, ily módon imádkozék magában: Isten! hálákat adok néked, hogy nem vagyok olyan, mint egyéb emberek, ragadozók, hamisak, paráznák, vagy mint ím e vámszedő is.
Èyí Farisi dìde, ó sì ń gbàdúrà nínú ara rẹ̀ báyìí pé, ‘Ọlọ́run mo dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, nítorí tí èmi kò rí bí àwọn ará ìyókù, àwọn alọ́nilọ́wọ́gbà, aláìṣòótọ́, panṣágà, tàbí bí agbowó òde yìí.
12 Bőjtölök kétszer egy héten; dézsmát adok mindenből, a mit szerzek.
Èmi ń gbààwẹ̀ lẹ́ẹ̀méjì ní ọ̀sẹ̀, mo ń san ìdámẹ́wàá ohun gbogbo tí mo ní.’
13 A vámszedő pedig távol állván, még szemeit sem akarja vala az égre emelni, hanem veri vala mellét, mondván: Isten, légy irgalmas nékem bűnösnek!
“Ṣùgbọ́n agbowó òde dúró lókèèrè, kò tilẹ̀ jẹ́ gbé ojú rẹ̀ sókè ọ̀run, ṣùgbọ́n ó lu ara rẹ̀ ní oókan àyà, ó wí pé, ‘Ọlọ́run ṣàánú fún mi, èmi ẹlẹ́ṣẹ̀!’
14 Mondom néktek, ez megigazulva méne alá az ő házához, inkább hogynem amaz: mert valaki felmagasztalja magát, megaláztatik; és a ki megalázza magát, felmagasztaltatik.
“Mo wí fún yín, ọkùnrin yìí sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀ ní ìdáláre ju èkejì lọ: nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbé ara rẹ̀ ga, òun ni a ó rẹ̀ sílẹ̀; ẹni tí ó bá sì rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀ òun ni a ó gbéga.”
15 Vivének pedig hozzá kis gyermekeket is, hogy illesse azokat; mikor pedig a tanítványok ezt látták, megdorgálák azokat.
Wọ́n sì gbé àwọn ọmọ ọwọ́ tọ̀ ọ́ wá pẹ̀lú, kí ó lè gbé ọwọ́ lé wọn; ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ rí i, wọ́n ń bá wọn wí.
16 De Jézus magához híván őket, monda: Engedjétek, hogy a kis gyermekek én hozzám jőjjenek, és ne tiltsátok el őket; mert ilyeneké az Istennek országa.
Ṣùgbọ́n Jesu pè wọ́n sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ jẹ́ kí àwọn ọmọ kékeré wá sọ́dọ̀ mi, ẹ má sì ṣe dá wọn lẹ́kun, nítorí tí irú wọn ni ìjọba Ọlọ́run.
17 Bizony mondom néktek: A ki nem úgy fogadja az Isten országát, mint gyermek, semmiképen nem megy be abba.
Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹnikẹ́ni tí kò bá gbà ìjọba Ọlọ́run bí ọmọ kékeré, kì yóò wọ inú rẹ̀ bí ó ti wù kí ó rí.”
18 És megkérdé őt egy főember, mondván: Jó Mester, mit cselekedjem, hogy az örökéletet elnyerhessem? (aiōnios g166)
Ìjòyè kan sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, wí pé, “Olùkọ́ rere, kín ni èmi ó ṣe tí èmi ó fi jogún ìyè àìnípẹ̀kun?” (aiōnios g166)
19 Monda pedig néki Jézus: Miért mondasz engem jónak? Nincs senki jó, csak egy, az Isten.
Jesu wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń pè mí ní ẹni rere? Ẹni rere kan kò sí bí kò ṣe ẹnìkan, èyí sì ni Ọlọ́run.
20 A parancsolatokat tudod: Ne paráználkodjál; ne ölj; ne lopj; hamis tanubizonyságot ne tégy; tiszteld atyádat és anyádat.
Ìwọ mọ̀ àwọn òfin: ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe panṣágà, ìwọ kò gbọdọ̀ pànìyàn, ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe jalè, ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe jẹ́rìí èké, bọ̀wọ̀ fún baba àti ìyá rẹ.’”
21 Az pedig monda: Mindezeket ifjúságomtól fogva megtartottam.
Ó sì wí pé, “Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni èmi ti pamọ́ láti ìgbà èwe mi wá.”
22 Jézus ezeket hallván, monda néki: Még egy fogyatkozás van benned: Add el mindenedet, a mid van, és oszd el a szegényeknek, és kincsed lesz mennyországban; és jer, kövess engem.
Nígbà tí Jesu sì gbọ́ èyí, ó wí fún un pé, “Ohun kan ni ó kù fún ọ síbẹ̀: lọ ta ohun gbogbo tí o ní, kí o sì pín in fún àwọn tálákà, ìwọ ó sì ní ìṣúra ní ọ̀run: sì wá, kí o máa tọ̀ mí lẹ́yìn.”
23 Az pedig ezeket hallván, igen megszomorodék; mert igen gazdag vala.
Nígbà tí ó sì gbọ́ èyí, inú rẹ̀ bàjẹ́ gidigidi, nítorí tí ó ní ọrọ̀ púpọ̀.
24 És mikor látta Jézus, hogy az igen megszomorodék, monda: Mily nehezen mennek be az Isten országába, a kiknek gazdagságuk van!
Nígbà tí Jesu rí i pé inú rẹ̀ bàjẹ́ gidigidi, ó wí pé, “Yóò ti ṣòro tó fún àwọn tí ó ní ọrọ̀ láti wọ ìjọba Ọlọ́run!
25 Mert könnyebb a tevének a tű fokán átmenni, hogynem a gazdagnak az Isten országába bejutni.
Nítorí ó rọrùn fún ìbákasẹ láti gba ojú abẹ́rẹ́ wọlé jù fún ọlọ́rọ̀ láti wọ ìjọba Ọlọ́run lọ.”
26 A kik pedig ezt hallották, mondának: Ki idvezülhet tehát?
Àwọn tí ó sì gbọ́ wí pé, “Ǹjẹ́ ta ni ó ha lè là?”
27 Ő pedig monda: A mi embereknél lehetetlen, lehetséges az Istennél.
Ó sì wí pé, “Ohun tí ó ṣòro lọ́dọ̀ ènìyàn kò ṣòro lọ́dọ̀ Ọlọ́run.”
28 És monda Péter: Ímé mi mindent elhagytunk, és követtünk téged!
Peteru sì wí pé, “Sá wò ó, àwa ti fi ilé wa sílẹ̀, a sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn!”
29 Ő pedig monda nékik: Bizony mondom néktek, hogy senki sincs, a ki elhagyta házát, vagy szüleit, vagy testvéreit, vagy feleségét, vagy gyermekeit az Isten országáért,
Ó sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, kò sí ẹni tí ó fi ilé, tàbí aya, tàbí ará, tàbí òbí, tàbí ọmọ sílẹ̀, nítorí ìjọba Ọlọ́run,
30 A ki sokszorta többet ne kapna ebben az időben, a jövendő világon pedig örök életet. (aiōn g165, aiōnios g166)
tí kì yóò gba ìlọ́po púpọ̀ sí i ní ayé yìí, àti ní ayé tí ń bọ̀ ìyè àìnípẹ̀kun.” (aiōn g165, aiōnios g166)
31 És maga mellé vévén a tizenkettőt, monda nékik: Ímé felmegyünk Jeruzsálembe, és beteljesedik minden az embernek Fián, a mit a próféták megírtak.
Nígbà náà ni ó pe àwọn méjìlá sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí fún wọn pé, “Sá wò ó, àwa ń gòkè lọ sí Jerusalẹmu, a ó sì mú ohun gbogbo ṣẹ, tí a ti kọ láti ọwọ́ àwọn wòlíì, nítorí Ọmọ Ènìyàn.
32 Mert a pogányok kezébe adatik, és megcsúfoltatik, és meggyaláztatik, és megköpdöstetik;
Nítorí tí a ó fi lé àwọn aláìkọlà lọ́wọ́, a ó fi ṣe ẹlẹ́yà, a ó sì fi ṣe ẹ̀sín, a ó sì tutọ́ sí i lára.
33 És megostorozván, megölik őt; és harmadnapon feltámad.
Wọn ó sì nà án, wọn ó sì pa á, ní ọjọ́ kẹta yóò sì jíǹde.”
34 Ők pedig ezekből semmit nem értének; és a beszéd ő előlük el vala rejtve, és nem fogták fel a mondottakat.
Ọ̀kan nínú nǹkan wọ̀nyí kò sì yé wọn, ọ̀rọ̀ yìí sì pamọ́ fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì mọ ohun tí a wí.
35 Lőn pedig, mikor Jerikhóhoz közeledett, egy vak ül vala az út mellett koldulván.
Bí ó ti súnmọ́ Jeriko, afọ́jú kan jókòó lẹ́bàá ọ̀nà ó ń ṣagbe.
36 És mikor hallotta a mellette elmenő sokaságot, tudakozódék, mi dolog az?
Nígbà tí ó gbọ́ tí ọ̀pọ̀ ń kọjá lọ, ó béèrè pé, kín ni ìtumọ̀ èyí.
37 Megmondák pedig néki, hogy a Názáretbeli Jézus megy el arra.
Wọ́n sì wí fún un pé, “Jesu ti Nasareti ni ó ń kọjá lọ.”
38 És kiálta, mondván: Jézus, Dávidnak Fia, könyörülj rajtam!
Ó sì kígbe pé, “Jesu, ìwọ ọmọ Dafidi, ṣàánú fún mi!”
39 A kik pedig elől mentek, dorgálák őt, hogy hallgasson; de ő annál inkább kiálta: Dávidnak Fia, könyörülj rajtam!
Àwọn tí ń lọ níwájú bá a wí, pé, kí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́, ṣùgbọ́n òun sì kígbe sókè sí í pé, “Ìwọ Ọmọ Dafidi, ṣàánú fún mi!”
40 És Jézus megállván, parancsolá, hogy vigyék azt hozzá; és mikor közel ért, megkérdé őt,
Jesu sì dúró, ó ní, kí á mú un tọ òun wá nígbà tí ó sì súnmọ́ ọn, ó bi í
41 Mondván: Mit akarsz, hogy cselekedjem veled? Az pedig monda: Uram, hogy az én szemem világa megjőjjön.
wí pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́ kí èmi ṣe fún ọ?” Ó sì wí pé, “Olúwa jẹ́ kí èmi ríran.”
42 És Jézus monda néki: Láss, a te hited téged megtartott.
Jesu sì wí fún un pé, “Ríran; ìgbàgbọ́ rẹ mú ọ láradá.”
43 És azonnal megjöve annak szeme világa, és követé őt, dicsőítvén az Istent az egész sokaság pedig ezt látván, dicsőséget ada az Istennek.
Lójúkan náà ó sì ríran, ó sì ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ó sì ń yin Ọlọ́run lógo àti gbogbo ènìyàn nígbà tí wọ́n rí i, wọ́n fi ìyìn fún Ọlọ́run.

< Lukács 18 >