< Lukács 10 >

1 Ezek után pedig rendele az Úr másokat is, hetvenet, és elküldé azokat kettőnként az ő orczája előtt, minden városba és helyre, a hová ő menendő vala.
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Olúwa sì yan méjìléláàádọ́rin ọmọ-ẹ̀yìn mìíràn pẹ̀lú, ó sì rán wọn ní méjì méjì lọ ṣáájú rẹ̀, sí gbogbo ìlú àti ibi tí òun tìkára rẹ̀ yóò sì dé.
2 Monda azért nékik: Az aratni való sok, de a munkás kevés; kérjétek azért az aratásnak Urát, hogy küldjön munkásokat az ő aratásába.
Ó sì wí fún wọn pé, “Ìkórè pọ̀, ṣùgbọ́n àwọn alágbàṣe kò tó nǹkan, nítorí náà ẹ bẹ Olúwa ìkórè, kí ó lè rán àwọn alágbàṣe sínú ìkórè rẹ̀.
3 Menjetek el: Ímé én elbocsátlak titeket, mint bárányokat a farkasok közé.
Ẹ mú ọ̀nà yín pọ̀n: sá wò ó, èmi rán yín lọ bí ọ̀dọ́-àgùntàn sáàrín ìkookò.
4 Ne hordozzatok erszényt, se táskát, se sarut; és az úton senkit ne köszöntsetek.
Ẹ má ṣe mú àpò, ẹ má ṣe mú àpamọ́wọ́, tàbí bàtà: ẹ má sì ṣe kí ẹnikẹ́ni lọ́nà.
5 Valamely házba bementek, először ezt mondjátok: Békesség e háznak!
“Ní ilékílé tí ẹ̀yin bá wọ̀, kí ẹ kọ́ wí pé, ‘Àlàáfíà fún ilé yìí!’
6 És ha lesz ott valaki békességnek fia, a ti békességtek azon marad; ha nem, ti reátok tér vissza.
Bí ọmọ àlàáfíà bá sì wà níbẹ̀, àlàáfíà yín yóò bà lé e: ṣùgbọ́n bí kò bá sí, yóò tún padà sọ́dọ̀ yín.
7 Ugyanazon házban maradjatok pedig, azt evén és iván, a mit ők adnak: mert méltó a munkás az ő jutalmára. Ne járjatok házról-házra.
Ẹ dúró sínú ilé náà, kí ẹ máa jẹ, kí ẹ sì máa mu ohunkóhun tí wọ́n bá fi fún yín, nítorí ọ̀yà alágbàṣe tọ́ sí i. Ẹ má ṣe lọ láti ilé dé ilé.
8 És valamely városba bementek, és befogadnak titeket, azt egyétek, a mit előtökbe adnak:
“Ìlúkílùú tí ẹ̀yin bá wọ̀, tí wọ́n bá sì gbà yín, ẹ jẹ ohunkóhun tí a bá gbé ka iwájú yín.
9 És gyógyítsátok a betegeket, a kik ott lesznek, és mondjátok nékik: Elközelített hozzátok az Isten országa.
Ẹ sì mú àwọn aláìsàn tí ń bẹ nínú rẹ̀ láradá, kí ẹ sì wí fún wọn pé, ‘Ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀ sí yín!’
10 Valamely városba pedig bementek, és titeket be nem fogadnak, annak utczáira kimenvén, ezt mondjátok:
Ṣùgbọ́n ní ìlúkílùú tí ẹ̀yin bá sì wọ̀, tí wọn kò bá sì gbà yín, nígbà tí ẹ̀yin bá sì jáde ní ìgboro ìlú náà, kí ẹ̀yin sì wí pé,
11 Még a port is, a mely reánk ragadt a ti várostokból, itt köztetek letöröljük; mindazáltal ez legyen tudtotokra, hogy az Isten országa elközelített hozzátok.
‘Eruku ìlú yín tí ó kù sí wa lẹ́sẹ̀, a gbọ̀n ọ́n sílẹ̀ fún yín! Ṣùgbọ́n ẹ mọ èyí pé, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀.’
12 Mondom pedig néktek, hogy a Sodomabeliek állapota tűrhetőbb lesz ama napon, hogynem azé a városé.
Ṣùgbọ́n mo wí fún yín, yóò sàn fún Sodomu ní ọjọ́ náà, ju fún ìlú náà lọ.
13 Jaj néked Korazin! Jaj néked Bethsaida! mert ha Tírusban és Sídonban lettek volna azok a csodák, melyek te benned lőnek, régen zsákban és hamuban ülve megtértek volna.
“Ègbé ni fún ìwọ, Korasini! Ègbé ni fún ìwọ Betisaida! Nítorí ìbá ṣe pé a ti ṣe iṣẹ́ agbára tí a ṣe nínú yín, ní Tire àti Sidoni, wọn ìbá ti ronúpìwàdà lọ́jọ́ pípẹ́ sẹ́yìn, wọn ìbá sì jókòó nínú aṣọ ọ̀fọ̀ àti nínú eérú.
14 Hanem Tírusnak és Sídonnak tűrhetőbb lesz állapota az ítéletkor, hogynem néktek.
Ṣùgbọ́n yóò sàn fún Tire àti Sidoni nígbà ìdájọ́ jù fún yín lọ.
15 És te Kapernaum, mely mind az égig felmagasztaltattál, a pokolig fogsz lealáztatni. (Hadēs g86)
Àti ìwọ, Kapernaumu, a ó ha gbé ọ ga dé òkè ọ̀run? A ó rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ dé isà òkú. (Hadēs g86)
16 A ki titeket hallgat, engem hallgat, és a ki titeket megvet, engem vet meg; és a ki engem vet meg, azt veti meg, a ki engem elküldött.
“Ẹni tí ó bá gbọ́ tiyín, ó gbọ́ tèmi. Ẹni tí ó bá sì kọ̀ yín, ó kọ̀ mi. Ẹni tí ó bá sì kọ̀ mi, ó kọ ẹni tí ó rán mi.”
17 Visszatére pedig a hetven tanítvány örömmel, mondván: Uram, még az ördögök is engednek nékünk a te neved által!
Àwọn àádọ́rin náà sì fi ayọ̀ padà, wí pé, “Olúwa, àwọn ẹ̀mí èṣù tilẹ̀ foríbalẹ̀ fún wa ní orúkọ rẹ.”
18 Ő pedig monda nékik: Látám a Sátánt, mint a villámlást lehullani az égből.
Ó sì wí fún wọn pé, “Èmí rí Satani ṣubú bí mọ̀nàmọ́ná láti ọ̀run wá.
19 Ímé adok néktek hatalmat, hogy a kígyókon és skorpiókon tapodjatok, és az ellenségnek minden erején; és semmi nem árthat néktek.
Kíyèsi i, èmí fún yín ní àṣẹ láti tẹ ejò àti àkéekèe mọ́lẹ̀, àti lórí gbogbo agbára ọ̀tá, kò sì ṣí ohun kan bí ó ti wù tí ó ṣe, tí yóò pa yín lára.
20 De azon ne örüljetek, hogy a lelkek néktek engednek; hanem inkább azon örüljetek, hogy a ti neveitek fel vannak írva a mennyben.
Ṣùgbọ́n kí ẹ má ṣe yọ̀ nítorí èyí pé, àwọn ẹ̀mí ń foríbalẹ̀ fún yín; ṣùgbọ́n ẹ kúkú yọ̀, pé; a kọ̀wé orúkọ yín ní ọ̀run!”
21 Azon órában örvendeze Jézus lelkében, és monda: Hálákat adok néked, Atyám, mennynek és földnek Ura, hogy elrejtetted ezeket a bölcsek és értelmesek elől, és a kisdedeknek megjelentetted. Igen, Atyám, mert így volt kedves te előtted.
Ní wákàtí kan náà Jesu yọ̀ nínú Ẹ̀mí mímọ́ ó sì wí pé, “Mo dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, Baba, Olúwa ọ̀run àti ayé, pé, ìwọ pa nǹkan wọ̀nyí mọ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n àti amòye, ìwọ sì fi wọ́n hàn fún àwọn ọmọ ọwọ́. Bẹ́ẹ̀ ni, Baba, bẹ́ẹ̀ ni ó sá à yẹ ní ojú rẹ.
22 Mindent nékem adott az én Atyám: és senki sem tudja, kicsoda a Fiú, csak az Atya; és kicsoda az Atya, hanem csak a Fiú, és a kinek a Fiú akarja megjelenteni.
“Ohun gbogbo ni a ti fi fún mi láti ọ̀dọ̀ Baba mi; kò sì ṣí ẹni tí ó mọ ẹni tí ọmọ jẹ́, bí kò ṣe Baba, àti ẹnikẹ́ni tí ó bá sì wu ọmọ láti fi í hàn fún.”
23 És a tanítványokhoz fordulván, monda ő magoknak: Boldog szemek, a melyek látják azokat, a melyeket ti láttok.
Ó sì yípadà sí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ní apá kan. Ó ní, “Ìbùkún ni fún ojú tí ń rí ohun tí ẹ̀yin ń rí.
24 Mert mondom néktek, hogy sok próféta és király kívánta látni, a miket ti láttok, de nem látták; és hallani, a miket hallotok, de nem hallották.
Nítorí mo wí fún yín, ọ̀pọ̀ àwọn wòlíì àti àwọn ọba ni ó ń fẹ́ láti rí ohun tí ẹ̀yin ń rí, wọn kò sì rí wọn, àti láti gbọ́ ohun tí ẹ̀yin ń gbọ́, wọn kò sì gbọ́ wọn.”
25 És ímé egy törvénytudó felkele, kísértvén őt, és mondván: Mester, mit cselekedjem, hogy az örök életet vehessem? (aiōnios g166)
Sì kíyèsi i amòfin kan dìde, ó ń dán an wò, ó ní, “Olùkọ́, kín ni èmi ó ṣe kí èmi lè jogún ìyè àìnípẹ̀kun?” (aiōnios g166)
26 Ő pedig monda annak: A törvényben mi van megírva? mint olvasod?
Ó sì bi í pé, “Kí ni a kọ sínú ìwé òfin? Báwo ni ìwọ sì ti kà á?”
27 Az pedig felelvén, monda: Szeresd az Urat, a te Istenedet teljes szívedből és teljes lelkedből és minden erődből és teljes elmédből; és a te felebarátodat, mint magadat.
Ó sì dáhùn wí pé, “‘Kí ìwọ fi gbogbo àyà rẹ, àti gbogbo ọkàn rẹ, àti gbogbo agbára rẹ, àti gbogbo inú rẹ fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ’; àti, ‘Ẹnìkejì rẹ bí ara rẹ.’”
28 Monda pedig annak: Jól felelél; ezt cselekedd, és élsz.
Ó sì wí fún un pé, “Ìwọ́ dáhùn rere. Ṣe èyí, ìwọ ó sì yè.”
29 Az pedig igazolni akarván magát, monda Jézusnak: De ki az én felebarátom?
Ṣùgbọ́n ó ń fẹ́ láti da ara rẹ̀ láre, ó wí fún Jesu wí pé, “Ta ha sì ni ẹnìkejì mi?”
30 Jézus pedig felelvén, monda: Egy ember megy vala alá Jeruzsálemből Jerikóba, és rablók kezébe esék, a kik azt kifosztván és megsebesítvén, elmenének, és ott hagyák félholtan.
Jesu sì dáhùn ó wí pé, “Ọkùnrin kan ń ti Jerusalẹmu sọ̀kalẹ̀ lọ sí Jeriko, ó sì bọ́ sí ọwọ́ àwọn ọlọ́ṣà; wọ́n gbà á ní aṣọ, wọ́n sá a lọ́gbẹ́, wọ́n sì fi sílẹ̀ lọ ní àìpatán.
31 Történet szerint pedig megy vala alá azon az úton egy pap, a ki azt látván, elkerülé.
Ní kòńgẹ́ àkókò yìí ni àlùfáà kan sì ń sọ̀kalẹ̀ lọ lọ́nà náà. Nígbà tí ó sì rí i ó kọjá lọ níhà kejì.
32 Hasonlóképen egy Lévita is, mikor arra a helyre ment, és azt látta, elkerülé.
Bẹ́ẹ̀ náà sì ni ọmọ Lefi kan pẹ̀lú, nígbà tí ó dé ibẹ̀, tí ó sì rí i, ó kọjá lọ níhà kejì.
33 Egy samaritánus pedig az úton menvén, odaért, a hol az vala: és mikor azt látta, könyörületességre indula.
Ṣùgbọ́n ará Samaria kan, bí ó ti ń re àjò, ó dé ibi tí ó gbé wà; nígbà tí ó sì rí i, àánú ṣe é.
34 És hozzájárulván, bekötözé annak sebeit, olajat és bort töltvén azokba; és azt felhelyezvén az ő tulajdon barmára, vivé a vendégfogadó házhoz, és gondját viselé néki.
Ó sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì di ọgbẹ́ rẹ̀, ó da òróró àti ọtí wáìnì sí i, ó sì gbé e lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ti òun tìkára rẹ̀, ó sì mú un wá sí ilé èrò, a sì ń ṣe ìtọ́jú rẹ̀.
35 Másnap pedig elmenőben két pénzt kivévén, adá a gazdának, és monda néki: Viselj gondot reá, és valamit ezen fölül reáköltesz, én mikor visszatérek, megadom néked.
Nígbà tí ó sì lọ ní ọjọ́ kejì, ó fi owó idẹ méjì fún olórí ilé èrò ó sì wí fún un pé, ‘Máa tọ́jú rẹ̀; ohunkóhun tí ìwọ bá sì ná kún un, nígbà tí mo bá padà dé, èmi ó san án fún ọ.’
36 E három közül azért kit gondolsz, hogy felebarátja volt annak, a ki a rablók kezébe esett?
“Nínú àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí, ta ni ìwọ rò pé ó jẹ́ ẹnìkejì ẹni tí ó bọ́ sí ọwọ́ àwọn ọlọ́ṣà?”
37 Az pedig monda: Az, a ki könyörült rajta. Monda azért néki Jézus: Eredj el, és te is a képen cselekedjél.
Ó sì dáhùn wí pé, “Ẹni tí ó ṣàánú fún un ni.” Jesu sì wí fún un pé, “Lọ, kí o ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́!”
38 Lőn pedig, mikor az úton menének, hogy ő beméne egy faluba; egy Mártha nevű asszony pedig befogadá őt házába.
Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń lọ, o wọ ìletò kan, obìnrin kan tí a ń pè ní Marta sì gbà á sí ilé rẹ̀.
39 És ennek vala egy Mária nevezetű testvére, ki is Jézus lábainál leülvén, hallgatja vala az ő beszédét.
Ó sì ní arábìnrin kan tí a ń pè ní Maria tí ó sì jókòó lẹ́bàá ẹsẹ̀ Olúwa, tí ó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀.
40 Mártha pedig foglalatos volt a szüntelen való szolgálatban; előállván azért, monda: Uram, nincs-é arra gondod, hogy az én testvérem magamra hagyott engem, hogy szolgáljak? Mondjad azért néki, hogy segítsen nékem.
Ṣùgbọ́n Marta ń ṣe ìyọnu ohun púpọ̀, ó sì tọ̀ ọ́ wá, ó wí pé, “Olúwa, ìwọ kò sì bìkítà sí ti arábìnrin mi pé ó fi mí sílẹ̀ láti máa nìkan ṣe ìránṣẹ́? Wí fún un kí ó ràn mí lọ́wọ́.”
41 Felelvén pedig, monda néki Jézus: Mártha, Mártha, szorgalmas vagy és sokra igyekezel:
Ṣùgbọ́n Olúwa sì dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Marta, Marta, ìwọ ń ṣe àníyàn àti làálàá nítorí ohun púpọ̀.
42 De egy a szükséges dolog: és Mária a jobb részt választotta, mely el nem vétetik ő tőle.
Ṣùgbọ́n ohun kan ni a kò lè ṣe aláìní, Maria sì ti yan ipa rere náà tí a kò lè gbà lọ́wọ́ rẹ̀.”

< Lukács 10 >