< Isaia 45 >

1 PENEI o Iehova i olelo mai ai no kona mea i poniia, No Kuro, nona ka lima akau a'u i hooikaika ai, E hoopio i na lahuikanaka imua ona; A e kala no hoi au i ko na puhaka o na'lii, I hamama na puka imua ona, Aole hoi e paniia na pukapa.
“Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún ẹni òróró rẹ̀, sí Kirusi, ọwọ́ ọ̀tún ẹni tí mo dì mú láti dojú àwọn orílẹ̀-èdè bolẹ̀ níwájú rẹ̀ àti láti gba ohun ìjà àwọn ọba lọ́wọ́ wọn, láti ṣí àwọn ìlẹ̀kùn níwájú rẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé a kì yóò ti àwọn ẹnu-ọ̀nà.
2 E hele no wau imua ou, a e hoolaumania i na wahi apuupuu, E wawahi no au i na pani puka keleawe, A e uhaki ia'u na kaola hao.
Èmi yóò lọ síwájú rẹ, Èmi ó sì tẹ́ àwọn òkè ńlá pẹrẹsẹ Èmi yóò fọ gbogbo ẹnu-ọ̀nà idẹ èmi ó sì gé ọ̀pá irin.
3 E haawi aku no au ia oe i ka waiwai o ka pouli, A me ka ukana i hunaia ma kahi nalowale, I ike ai oe, owau no Iehova, ka mea i hea aku ia oe ma ka inoa, Ke Akua hoi o ka Iseraela.
Èmi yóò sì fún ọ ní àwọn ọrọ̀ ibi òkùnkùn, ọrọ̀ tí a kó pamọ́ sí àwọn ibi tí ó fi ara sin, tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ yóò fi mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ.
4 No ka'u kauwa, no Iakoba, No ka Iseraela hoi, ka mea a'u i wae ai, Ua hea aku no au ia oe; Ma kou inoa ua hea aku au ia oe, Aole nae oe i ike mai ia'u.
Nítorí Jakọbu ìránṣẹ́ mi àti Israẹli ẹni tí mo yàn, Mo pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ, mo sì gbé oyè kan kà ọ́ lórí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò gbà mí.
5 Owau no Iehova, aohe mea e ae, Aohe Akua e ae, ke kaawale au; Na'u no e kaei aku ia oe, aole nae oe i ike mai ia'u;
Èmi ni Olúwa, àti pé kò sí ẹlòmíràn; yàtọ̀ sí èmi kò sí ọlọ́run kan, Èmi yóò fún ọ ní okun, bí o kò tilẹ̀ tí ì gbà mí,
6 I ike lakou, mai ka puka ana a ka la mai, A mai ke komohana mai hoi, Aohe mea e ae, ke kaawale au; Owau no o Iehova, aohe mea e ae.
tí o fi jẹ́ pé láti ìlà-oòrùn títí dé ibi ìwọ̀ rẹ̀ kí ènìyàn le mọ̀, kò sí ẹnìkan lẹ́yìn mi. Èmi ni Olúwa, lẹ́yìn mi kò sí ẹlòmíràn mọ́.
7 Ka mea nana i hana ka malamalama, A nana hoi i hana ka pouli, Nana i hana ka pomaikai, Nana hoi i hana ka poino, Owau no Iehova, ka mea nana e hana keia mau mea a pau.
Mo dá ìmọ́lẹ̀, mo sì dá òkùnkùn, Mo mú àlàáfíà wá, Mo sì dá àjálù; Èmi Olúwa ni ó ṣe nǹkan wọ̀nyí.
8 E hoonakulukulu oukou, e na lani, mai luna mai, E hanini hoi na aouli i ka pono; E hamama hoi ka honua, a e hua mai i ke ola, E ulu pu mai no me ka pono; Na'u, na Iehova ia i hana.
“Ìwọ ọ̀run lókè rọ òjò òdodo sílẹ̀; jẹ́ kí àwọsánmọ̀ kí ó rọ̀ ọ́ sílẹ̀. Jẹ́ kí ilẹ̀ kí ó yanu gbagada, jẹ́ kí ìgbàlà kí ó dìde sókè, jẹ́ kí òdodo kí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀; Èmi Olúwa ni ó ti dá a.
9 Auwe ke kanaka paio aku i kona mea nana ia i hana? Na mea lepo me na mea lepo o ka honua! E olelo anei ka lepokiaha, i ka mea nana ia e hooponopono, Heaha kau e hana nei? A o ka mea au i hana'i, Aole ona lima?
“Ègbé ni fún ènìyàn tí ó ń bá Ẹlẹ́dàá rẹ̀ jà, ẹni tí òun jẹ́ àpáàdì kan láàrín àwọn àpáàdì tí ó wà lórí ilẹ̀. Ǹjẹ́ amọ̀ lè sọ fún amọ̀kòkò, pé: ‘Kí ni ohun tí ò ń ṣe?’ Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ lè sọ pé, ‘Òun kò ní ọwọ́?’ (questioned)
10 Auwe ka mea olelo i ka makuakane, Heaha kau e hoohanau ai? A i ka makuwahine hoi, Ua hanau oe i ke aha?
Ègbé ni fún ẹni tí ó sọ fún baba rẹ̀ pé, ‘Kí ni o bí?’ tàbí sí ìyá rẹ̀, ‘Kí ni ìwọ ti bí?’
11 Ke olelo mai nei o Iehova, ka Mea Hemolele o ka Iseraela, penei, O ka Mea hoi nana ia i hana, E ninau mai oukou ia'u i na mea e hiki mai ana no ka'u mau keiki, A e kauoha mai oukou ia'u ma ka hana a kuu mau lima.
“Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Ẹni Mímọ́ Israẹli, àti Ẹlẹ́dàá rẹ̀. Nípa ohun tí ó ń bọ̀, ǹjẹ́ o ń bi mí léèrè nípa àwọn ọmọ mi, tàbí kí o pàṣẹ fún mi nípa iṣẹ́ ọwọ́ mi bí?
12 Na'u no i hana ka honua nei, A hana no hoi au i na kanaka maluna iho; Na kuu mau lima no i hohola aku i na lani, A na'u hoi i kauoha aku i ko lakou lehulehu a pau.
Èmi ni ẹni tí ó dá ilẹ̀ ayé tí ó sì da ọmọ ènìyàn sórí i rẹ̀. Ọwọ́ mi ni ó ti ta àwọn ọ̀run; mo sì kó àwọn àgbájọ ìràwọ̀ rẹ̀ síta.
13 Ua hoala no au ia ia, no ka pono, Na'u no e hoopololei i kona mau aoao, Nana no e hana i ko'u kulanakauhale, A nana no e hookuu aku i ko'u poe pio; Aole no ka uku, a me ka waiwai kipe, Wahi a Iehova o na kaua.
Èmi yóò gbé Kirusi sókè nínú òdodo mi. Èmi yóò mú kí gbogbo ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́. Òun yóò tún ìlú mi kọ́ yóò sì tú àwọn àtìpó mi sílẹ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún owó tàbí ẹ̀bùn kan, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
14 Ke i mai nei o Iehova penei, E hele mai no ianei, iou la, Ka waiwai o Aigupita, a me ka mea kuai o Aitiopa, A me ko Seba, ka poe kanaka nunui, a e lilo lakou nou. E hahai no lakou ia oe; me ka paa ana i na kaula hao lakou e hele mai ai, A e moe no lakou ilalo imua ou, E nonoi aku no lakou ia oe, me ka olelo iho, He oiaio no, me oe no ke Akua, aohe Akua e ae.
Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Àwọn èròjà ilẹ̀ Ejibiti àti àwọn ọjà ilẹ̀ Kuṣi, àti àwọn Sabeani— wọn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ wọn yóò sì jẹ́ tìrẹ; wọn yóò máa wọ́ tẹ̀lé ọ lẹ́yìn, wọn yóò máa wá lọ́wọ̀ọ̀wọ́. Wọn yóò máa foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀, wọn yóò sì máa bẹ̀bẹ̀ níwájú rẹ pé, ‘Nítòótọ́ Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ kò sì ṣí ẹlòmíràn; kò sí ọlọ́run mìíràn.’”
15 He oiaio no, o ke Akua no oe nana i huna ia oe iho, E ke Akua o ka Iseraela, ka mea e ola'i.
Nítòótọ́ ìwọ jẹ́ Ọlọ́run tí ó fi ara rẹ̀ pamọ́, Ìwọ Ọlọ́run àti Olùgbàlà Israẹli,
16 Ua hilahila, a ua hoopalaimaka lakou a pau; Holo pu no iloko o ka hilahila, ka poe hana akuakii.
Gbogbo àwọn tí ó ń gbẹ́ ère ni ojú yóò tì wọn yóò sì kan àbùkù; gbogbo wọn ni yóò bọ́ sínú àbùkù papọ̀.
17 E hoolaia no o ka Iseraela maloko o Iehova, me ke ola mau loa; Aole oukou e hilahila, aole hoi e hoopalaimaka, ia ao aku, ia ao aku.
Ṣùgbọ́n Israẹli ni a ó gbàlà láti ọwọ́ Olúwa pẹ̀lú ìgbàlà ayérayé; a kì yóò kàn yín lábùkù tàbí kí a dójútì yín, títí ayé àìnípẹ̀kun.
18 No ka mea, penei ka olelo ana mai a Iehova, Ka mea nana i hana na lani; Oia ke Akua, ka mea nana i hana ka honua, a kukulu hoi, Ka mea nana ia i hoopaa, aole hoi ia i hana makehewa ia mea, Hana no oia ia i wahi e nohoia'i; Owau no Iehova, aohe mea e ae,
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí, ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run, Òun ni Ọlọ́run; ẹni tí ó mọ tí ó sì dá ayé, Òun ló ṣe é; Òun kò dá a láti wà lófo, ṣùgbọ́n ó ṣe é kí a lè máa gbé ibẹ̀, Òun wí pé: “Èmi ni Olúwa, kò sì ṣí ẹlòmíràn.
19 Aole au i olelo ma kahi malu, ma kahi pouli o ka honua; Aole au i olelo aku i na pua a Iakoba, E imi makehewa oukou ia'u. Owau o Iehova, ka mea e olelo ana ma ka pono, Ka mea e hai. aku ana i na mea pololei.
Èmi kò sọ̀rọ̀ níbi tí ó fi ara sin, láti ibìkan ní ilẹ̀ òkùnkùn, Èmi kò tí ì sọ fún àwọn ìran Jakọbu pé, ‘Ẹ wá mi lórí asán.’ Èmi Olúwa sọ òtítọ́, Mo sì sọ èyí tí ó tọ̀nà.
20 E hoakoakoa oukou, a hele mai, E houluulu pu oukou, e ka poe i pakele o na aina. He poe ike ole ka poe kukulu i ka laau o ko lakou akua kalaiia, A pule aku i ke akua hiki ole ke hoola.
“Ẹ kó ara yín jọ kí ẹ sì wá; ẹ kórajọ, ẹ̀yin ìsáǹsá láti àwọn orílẹ̀-èdè wá. Aláìmọ̀kan ni àwọn tí ó ń ru ère igi káàkiri, tí wọ́n gbàdúrà sí àwọn òrìṣà tí kò le gba ni.
21 E hai aku, e lawe mai hoi ia lakou; Oia, e kukakuka pa lakou. Nawai i hai i keia, mai kahiko mai, A hoikeike hoi ia, mai kela wa mai? Aole anei owau. o Iehova? Aole hoi he Akua e ae, ke Kaawale au; O ke Akua pono, ka mea e ola'i, aohe mea e ae.
Jẹ́ kí a mọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀, fihàn wá, jẹ́ kí wọn jọ dámọ̀ràn papọ̀. Ta ló ti sọ èyí lọ́jọ́ tí o ti pẹ́, ta ló ti wí èyí láti àtètèkọ́ṣe? Kì í ha á ṣe Èmi, Olúwa? Àti pé kò sí Ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi, Ọlọ́run olódodo àti olùgbàlà; kò sí ẹlòmíràn àfi èmi.
22 E haliu mai oukou ia'u a e hoolaia no oukou, E na kukulu o ka honua; No ka mea, owau no ke Akua, aohe mea e ae.
“Yípadà sí mi kí a sì gbà ọ́ là, ẹ̀yin ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé; nítorí Èmi ni Ọlọ́run kò sì ṣí ẹlòmíràn.
23 Ua hoohiki au ia'u iho, Ua puka aku hoi ka olelo, mai ko'u waha aku ma ka pono, Aole ia i hoi hou, no ka mea, la'u no e kukuli ai na kuli a pau, a e hoohiki no hoi na elelo a pau.
Nípa èmi tìkára mi ni mo ti búra, ẹnu mi ni ó ti sọ ọ́ pẹ̀lú gbogbo ipá mi, ọ̀rọ̀ náà tí a kì yóò lè parẹ́. Níwájú mi ni gbogbo orúnkún yóò wólẹ̀; nípa mi ni gbogbo ahọ́n yóò búra.
24 He oiaio, e olelo mai ia'u, maloko o Iehova na mea pono, a me ka ikaika, Ia ia no lakou e hele mai ai; A e hilahila auanei ka poe a pau i inaina aku ia ia.
Wọn yóò sọ ní ti èmi, ‘Nínú Olúwa nìkan ni òdodo àti agbára wà.’” Gbogbo àwọn tí ó ti bínú sí; yóò wá sọ́dọ̀ rẹ̀ a ó sì dójútì wọn.
25 Maloko o Iehova e hoaponoia'i na pua a pau o ka Iseraela, A malaila hoi e hoonani ai.
Ṣùgbọ́n nínú Olúwa gbogbo àwọn ìran Israẹli ni a ó rí ní òdodo, a o sì gbé wọn ga.

< Isaia 45 >