< I Na Lii 8 >

1 A LAILA hoakoakoa mai la o Solomona i na lunakahiko o ka Iseraela, a me na poo a pau o na ohana, na haku iwaena o na makua o na mamo a Iseraela, io Solomona la ma Ierusalema, e lawe mai lakou i ka pahuberita o Iehova mailoko mai o ke kulanakauhale o Davida, oia o Ziona.
Nígbà náà ni Solomoni pe àwọn àgbàgbà Israẹli àti gbogbo àwọn olórí àwọn ẹ̀yà àti àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Israẹli jọ papọ̀, níwájú Solomoni ọba ní Jerusalẹmu, láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá láti ìlú Dafidi, tí ń ṣe Sioni.
2 Akoakoa mai la na kanaka o Iseraela a pau io Solomona la ke alii, i ka ahaaina, i ka malama Etanima, o ka hiku o ka malama.
Gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli sì pe ara wọn jọ sọ́dọ̀ Solomoni ọba ní àkókò àjọ ọdún ní oṣù Etanimu tí í ṣe oṣù keje.
3 A hele mai na lunakahiko a pau o ka Iseraela, a kaikai ae la na kahuna i ka pahuberita.
Nígbà tí gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli dé, àwọn àlùfáà sì gbé àpótí ẹ̀rí,
4 A lawe mai hoi lakou i ka pahuberita o Iehova, a me ka halelewa o ke anaina, a me na mea laa a pau iloko o ka halelewa, o ia mau mea ka na kahuna a me ka Levi i lawe mai ai.
wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àti àgọ́ àjọ ènìyàn àti gbogbo ohun èlò mímọ́ tí ó wà nínú àgọ́. Àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi sì gbé wọn gòkè wá,
5 A o Solomona ke alii, a o ke anaina a pau o ka Iseraela, i akoakoa mai io na la, me ia pu lakou imua o ka pahuberita, e kaumaha ana i na hipa a me na bipi kauo, aole i haiia, aole e hiki ke heluia no ka lehulehu.
àti Solomoni ọba, àti gbogbo ìjọ ènìyàn tí ó péjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí, wọ́n ń fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àgùntàn àti màlúù tí a kò le mọ iye, àti tí a kò le kà rú ẹbọ.
6 A na na kahuna i hookomo i ka pahuberita o Iehova i kona wahi i kahi e olelo ai o ka hale, i kahi hoano loa, malalo ae hoi o na eheu o na keruba.
Nígbà náà ni àwọn àlùfáà gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa wá sí ipò rẹ̀, sí ibi inú lọ́hùn ún ilé Olúwa, Ibi Mímọ́ Jùlọ, wọ́n gbé e sí abẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù.
7 No ka mea, ua hohola na keruba i na eheu elua maluna o kahi o ka pahuberita, a uhi iho la na keruba i ka pahuberita, a me kona mau laau auamo, maluna ae.
Àwọn kérúbù na ìyẹ́ wọn méjèèjì sí ibi àpótí ẹ̀rí, wọ́n sì bo àpótí ẹ̀rí náà, àti àwọn ọ̀pá rẹ̀ tí a fi ń gbé e.
8 Unuhi ae la lakou i na laau auamo, i ikeia na poo o na laau auamo mai ka mea hoano mai ma ka mua o kahi e olelo ai; aole laua i ikeia mawaho mai, a malaila no laua a hiki i keia la.
Àwọn ọ̀pá yìí ga tó bẹ́ẹ̀ tí a fi le rí orí wọn láti Ibi Mímọ́ níwájú ibi tí a yà sí mímọ́, ṣùgbọ́n a kò sì rí wọn lóde Ibi Mímọ́, wọ́n sì wà níbẹ̀ títí di òní yìí.
9 Aohe mea maloko o ka pahuberita, o na papa pohaku elua wale no a Mose i hahao ai ilaila ma Horeba, kahi i hana'i o Iehova i ka berita me na mamo a Iseraela i ko lakou puka ana mai, mai ka aina mai o Aigupita.
Kò sí ohun kankan nínú àpótí ẹ̀rí bí kò ṣe wàláà òkúta méjì tí Mose ti fi sí ibẹ̀ ní Horebu, níbi tí Olúwa ti bá àwọn ọmọ Israẹli dá májẹ̀mú, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
10 Eia kekahi, i ka puka ana mai o na kahuna mailoko mai o kahi hoano, piha ae la i ke ao ka hale o Iehova;
Nígbà tí àwọn àlùfáà jáde láti Ibi Mímọ́, àwọsánmọ̀ sì kún ilé Olúwa.
11 Aole i hiki i na kahuna ke ku e lawelawe, no ke ao; no ka mea, ua piha ko Iehova hale i ka nani o Iehova.
Àwọn àlùfáà kò sì le ṣiṣẹ́ wọn nítorí àwọsánmọ̀ náà, nítorí ògo Olúwa kún ilé náà.
12 Alaila olelo ae la Solomona, Ua olelo mai o Iehova e noho oia maloko o ka pouli loa.
Nígbà náà ni Solomoni sì wí pé, “Olúwa ti wí pé, òun yóò máa gbé inú òkùnkùn biribiri.
13 Ua hana io ae nei no wau i hale e noho ai nou, kahi kuonoono nou e noho mau loa'i.
Nítòótọ́, èmi ti kọ́ ilé kan fún ọ, ibi tí ìwọ yóò máa gbé títí láéláé.”
14 Haliu mai la ke alii i kona maka; a hoomaikai mai i ke anaina a pau o ka Iseraela, e ku ana no hoi ke anaina a pau o ka Iseraela;
Nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì dúró síbẹ̀, ọba sì yí ojú rẹ̀, ó sì bùkún fún wọn.
15 I aku la hoi oia, E hoomaikaiia'ku o Iehova ke Akua o ka Iseraela, ka mea nana i olelo mai me kona waha ia Davida i o'u makuakane, a ua hooko mai nei me kona lima, i ka i ana mai,
Nígbà náà ni ó wí pé, “Ìbùkún ni fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó ti fi ọwọ́ ara rẹ̀ mú ìlérí tí ó fi ẹnu rẹ̀ sọ fún Dafidi baba mi ṣẹ. Nítorí tí ó wí pé,
16 Mai ka la mai i lawe mai ai au i ko'u poe kanaka ka Iseraela mai loko mai o Aigupita, aole au i koho ae i kulanakauhale no loko mai o na ohana a pau o ka Iseraela e kukulu i ka hale e noho ai ko'u inoa maloko; aka, ua koho no au ia Davida i luna no ko'u lahuikanaka Iseraela.
‘Láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ènìyàn mi Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti, èmi kò tí ì yan ìlú kan nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti kọ́ ilé kan fún orúkọ mi láti wà níbẹ̀, ṣùgbọ́n èmi ti yan Dafidi láti ṣàkóso àwọn Israẹli ènìyàn mi.’
17 A iloko iho no o ka naau o Davida ko'u makuakane ka manao e kukulu i hale no ka inoa o Iehova ke Akua o Iseraela.
“Dafidi baba mi sì ní i lọ́kàn láti kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
18 A olelo mai la hoi o Iehova ia Davida ko'u makuakane, No ka mea, maloko aku no o kou naau e kukulu i hale no ko'u inoa, he pono oe i kou manao ana pela iloko ou.
Ṣùgbọ́n Olúwa sì wí fún Dafidi baba mi pé, ‘Nítorí tí ó wà ní ọkàn rẹ láti kọ́ ilé kan fún orúkọ mi, ó dára láti ní èyí ní ọkàn rẹ.
19 Aka, aole oe o kukulu mai i ka hale: o kau keiki nae, ka mea e puka mai, mailoko mai o kou mau puhaka, oia ke kukulu mai i ka hale no ko'u inoa.
Ṣùgbọ́n, ìwọ kọ́ ni yóò kọ́ ilé náà, ṣùgbọ́n ọmọ rẹ, tí ó tinú ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ jáde; òun ni yóò kọ́ ilé náà fún orúkọ mi.’
20 A ua hooko mai nei no Iehova i ka olelo ana i olelo mai ai, a ua ku ae nei au ma kahi o Davida ko'u makuakane, a ke noho nei au ma ka noho alii o ka Iseraela e like me ka Iehova olelo hoopomaikai, a ua kukulu ae nei au i ka hale no ka inoa o Iehova ke Akua o ka Iseraela.
“Olúwa sì ti pa ìlérí rẹ̀ tí ó ṣe mọ́, èmi sì ti rọ́pò Dafidi baba mi, mo sì jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli báyìí, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ṣèlérí, èmi sì kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
21 A hana aku no wau i wahi no ka pahuberita, maloko olaila ka berita o Iehova ana i hana'i me ko makou mau kupuna, i kona lawe ana mai ia lakou mailoko mai o ka aina o Aigupita.
Èmi sì ti pèsè ibìkan níbẹ̀ fún àpótí ẹ̀rí, èyí tí í ṣe májẹ̀mú Olúwa tí ó ti bá àwọn baba wa dá, nígbà tí ó mú wọn jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá.”
22 Ku ae la hoi o Solomona mamua o ke kuahu o Iehova ma ke alo o ke anaina a pau o ka Iseraela, a hohola ae i kona mau lima i ka lani.
Solomoni sì dúró níwájú pẹpẹ Olúwa, níwájú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli, ó sì na ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sókè ọ̀run.
23 I aku la oia, E Iehova ke Akua o ka Iseraela, aohe akua ma ka lani iluna, aole hoi ma ka honua ilalo nei, e like me oe ka mea nana e malama mai i ka berita a me ke aloha me kau mau kauwa ka poe e hele ana ma kou alo me ko lakou naau a pau;
Ó sì wí pé, “Olúwa Ọlọ́run Israẹli, kò sí Ọlọ́run tí ó dàbí rẹ lókè ọ̀run tàbí ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ìwọ tí ó pa májẹ̀mú àti àánú mọ́ pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí ń fi gbogbo ọkàn wọn rìn níwájú rẹ.
24 Ka mea nana i kaohi me Davida ko'u makuakane i ka mea au i olelo hoopomaikai mai ai ia ia; ua olelo hoi oe me kou waha, a ua hooko ae nei oe me kou lima, me nei i neia la.
O sì ti pa ìlérí rẹ mọ́ fún ìránṣẹ́ rẹ Dafidi baba mi; pẹ̀lú ẹnu rẹ ni ìwọ ṣe ìlérí, o sì mú u ṣẹ pẹ̀lú ọwọ́ rẹ, bí ó ti rí lónìí.
25 Ano hoi, e Iehova ke Akua o ka Iseraela, e kaohi oe me kau kauwa o Davida ko'u makuakane, i ka mea au i olelo hoopomaikai ai ia ia, i ka i ana mai, Aole oe e nele i ke kanaka imua o ko'u alo, e noho maluna o ka nohoalii o ka Iseraela, ke malama kau mau keiki i ko lakou hele ana, e hele imua o'u, me oe i hele ai imua o'u;
“Ǹjẹ́ báyìí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, bá ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi baba mi pa ohun tí ìwọ ti ṣe ìlérí fún un mọ́ wí pé, ìwọ kì yóò kùnà láti ní ènìyàn kan láti jókòó níwájú mi lórí ìtẹ́ Israẹli, kìkì bí àwọn ọmọ rẹ bá lè kíyèsi ohun tí wọ́n ń ṣe láti máa rìn níwájú mi bí ìwọ ti rìn.
26 Ano hoi, e ke Akua o ka Iseraela, e hooiaioia mai kau olelo, au e olelo mai ai i kau kauwa ia Davida ko'u makuakane.
Ǹjẹ́ báyìí, Ọlọ́run Israẹli, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ tí o ti ṣe ìlérí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi baba mi wá sí ìmúṣẹ.
27 Aka hoi, e noho io mai anei ke Akua ma ka honua anei? Aia hoi! aole e hiki i na lani a me na lani o na lani ke apo ia oe; aole loa hoi keia hale a'u i kukulu ae nei.
“Ṣùgbọ́n nítòótọ́, Ọlọ́run yóò máa gbé ayé bí? Ọ̀run àti ọ̀run àwọn ọ̀run kò le gbà ọ́. Kí a má sọ pé ilé yìí tí mo kọ́ fún ọ!
28 Aka hoi, e maliu mai oe i ka pule a kau kauwa, a i kona nonoi ana, e Iehova ko'u Akua, e hoolohe mai i ka ulono ana a me ka pule a kau kauwa nei e haipule ai imua o kou alo i keia la;
Síbẹ̀ ṣe ìfetísílẹ̀ àdúrà ìránṣẹ́ rẹ àti ẹ̀bẹ̀ rẹ fún àánú, Olúwa Ọlọ́run mi. Gbọ́ ẹkún àti àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ̀ ń gbà níwájú rẹ lónìí.
29 E nana mau mai kou mau maka i keia hale i ka po a me ke ao, i kahi au i olelo mai ai, Malaila auanei ko'u inoa, i hoolohe mai hoi oe i ka pule a kau kauwa e haipule ai i keia wahi.
Jẹ́ kí ojú rẹ ṣí sí ilé yìí ní òru àti ní ọ̀sán, ibí yìí tí ìwọ ti wí pé, orúkọ mi yóò wà níbẹ̀, nítorí ìwọ yóò gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ gbà sí ibí yìí.
30 A e hoolohe mai oe i ka nonoi ana o kau kauwa nei, a o kou poe kanaka hoi o Iseraela, i ka wa e pule ai lakou i keia wahi; a e hoolohe mai oe ma kou wahi e noho ai ma ka lani, a lohe oe, e kala mai.
Gbọ́ ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ àti ti Israẹli, ènìyàn rẹ nígbà tí wọ́n bá gbàdúrà sí ibí yìí. Gbọ́ láti ọ̀run wá láti ibùgbé rẹ, àti nígbà tí o bá gbọ́, dáríjì.
31 Ina e hana hewa kekahi kanaka i kona hoalauna, a kau ka hoohiki ana maluna ona i hoohiki oia, a hiki mai ia hoohiki ana ma ke alo o kou kuahu maloko o keia hale;
“Nígbà tí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí ẹnìkejì rẹ̀, tí a sì fi wá lé e láti mú un búra, bí ìbúra náà bá sì dé iwájú pẹpẹ rẹ ní ilé yìí,
32 Alaila, e hoolohe mai oe ma ka lani, a e hana, a e hooponopono mai i kau mau kauwa, e hoahewa ana i ka mea hewa, e hooili ana i kona aoao maluna o kona poo, a e hoapono ana i ka mea pono, e haawi ia ia e like me kona pono.
nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run, kí o sì ṣe. Kí o sì ṣèdájọ́ láàrín àwọn ìránṣẹ́ rẹ, dá ènìyàn búburú lẹ́bi, kí o sì mú wá sí orí òun tìkára rẹ̀ ohun tí ó ti ṣe, dá olóòtítọ́ láre, kí a sì fi ẹsẹ̀ àìlẹ́bi rẹ̀ múlẹ̀.
33 Aia pepehiia iho kou poe kanaka Iseraela imua o ka enemi, no ka lakou hana hewa ana'ku ia oe, a huli hou lakou ia oe, a hooiaio i kou inoa, a e pule hoi me ke nonoi aku ia oe i keia hale;
“Nígbà tí àwọn ọ̀tá bá ṣẹ́gun Israẹli, ènìyàn rẹ, nítorí tí wọ́n ti ṣẹ̀ sí ọ, tí wọ́n bá yípadà sí ọ, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ, tí wọ́n sì gbàdúrà, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ lọ́dọ̀ rẹ nínú ilé yìí
34 Alaila, e hoolohe oe ma ka lani, a e kala mai i ka hewa o kou poe kanaka Iseraela, a e lawe hou mai oe ia lakou i ka aina au i haawi mai ai i ko lakou mau makua.
nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ènìyàn rẹ̀ jì í, kí o sì mú wọn padà wá sí ilẹ̀ tí ìwọ ti fún àwọn baba wọn.
35 Aia hoopaaia ka lani, aole hoi e ua, no ka lakou hana hewa ana ia oe; ina e pule lakou i keia wahi, a e hooiaio i ko inoa, a e haalele hoi i ko lakou mau hewa i kou hookaumaha ana ia lakou,
“Nígbà tí ọ̀run bá sé mọ́, tí kò sí òjò, nítorí tí àwọn ènìyàn rẹ ti ṣẹ̀ sí ọ, bí wọ́n bá gbàdúrà sí ìhà ibí yìí, tí wọ́n sì jẹ́wọ́ orúkọ rẹ, tí wọ́n sì yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn nítorí tí ìwọ ti pọ́n wọn lójú,
36 Alaila e hoolohe mai oe ma ka lani, a e kala mai i ka hewa o kau poe kauwa, a me kou poe kanaka Iseraela, i ao mai oe ia lakou i ka aoao maikai e hele ai lakou, a e haawi mai hoi i ka ua maluna iho o ka aina au i haawi mai ai i waiwai no kou poe kanaka.
nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ jì wọ́n, à ní Israẹli, ènìyàn rẹ. Kọ́ wọn ní ọ̀nà tí ó tọ́ láti máa rìn, kí o sì rọ òjò sí ilẹ̀ tí ìwọ ti fi fún ènìyàn rẹ fún ìní.
37 Ina he wi ma ka aina, ina he mai ahulau, ina he malili, he mae wale, he uhini, a ina he enuhe; a ina e hoopilikiaia e ka enemi ma ka aina o ko lakou mau kulanakauhale, ina he ino, a he mai;
“Nígbà tí ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn bá wá sí ilẹ̀ náà, tàbí ìrẹ̀dànù tàbí ìmúwòdù, eṣú tàbí kòkòrò tí ń jẹ ni run, tàbí nígbà tí àwọn ọ̀tá bá dó tì wọ́n nínú àwọn ìlú wọn, irú ìpọ́njú tàbí ààrùnkárùn tó lè wá,
38 A ina e pule me ke nonoi aku kekahi kanaka, o kou poe kanaka a pau paha o ka Iseraela, ka mea i ike i ke ino o kona naau iho, a e hapai i kona mau lima i keia hale;
nígbà tí àdúrà tàbí ẹ̀bẹ̀ bá ti ọ̀dọ̀ ẹnìkan láti ọ̀dọ̀ gbogbo Israẹli wá, tí olúkúlùkù sì mọ ìbànújẹ́ ọkàn rẹ̀, bí ó bá sì tẹ́ ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sí ìhà ilé yìí,
39 Alaila e hoolohe mai oe ma ka lani kou wahi e noho ai, a e kala, mai, a e hana, a e haawi i kela kanaka keia kanaka e like me kona mau aoao, ua ikeia kona naau e oe; (no ka mea, o oe, o oe wale no ka i ike i na naau o na keiki a pau o kanaka; )
nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, ní ibùgbé rẹ. Dáríjì, kí o sì ṣe sí olúkúlùkù ènìyàn gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí ó ti ṣe, níwọ̀n ìgbà tí ìwọ mọ ọkàn rẹ̀, nítorí ìwọ nìkan ṣoṣo ni ó mọ ọkàn gbogbo ènìyàn.
40 I makau lakou ia oe i na la a pau e ola'i lakou ma ka ili o ka aina au i haawi mai ai i ko lakou mau makua.
Nítorí wọn yóò bẹ̀rù rẹ ní gbogbo ọjọ́ tí wọn yóò wà ní ilẹ̀ tí ìwọ fi fún àwọn baba wa.
41 A, no ka malihini hoi, aole o kou poe kanaka Iseraela, aka, ua hele mai, mai ka aina loihi aku, no kou inoa;
“Ní ti àwọn àlejò tí kì í ṣe Israẹli ènìyàn rẹ, ṣùgbọ́n tí ó ti ilẹ̀ òkèèrè jáde wá nítorí orúkọ rẹ,
42 (No ka mea, e lohe no lakou i kou inoa nui, a me kou lima ikaika, a me kou lima kakauha; ) aia hele mai ia a e pule i keia hale;
nítorí tí àwọn ènìyàn yóò gbọ́ orúkọ ńlá rẹ, àti ọwọ́ agbára rẹ, àti nínà apá rẹ, nígbà tí ó bá sì wá, tí ó sì gbàdúrà sí ìhà ilé yìí,
43 Alaila e hoolohe mai oe ma ka lani kou wahi e noho ai, a e hana e like me ka mea a pau a ka malihini i nonoi ai ia oe; i ike na kanaka a pau o ka honua i kou inoa, e weli weli ia oe e like me kou poe kanaka Iseraela; a i ike hoi ua kapaia ma kou inoa keia hale a'u i kukulu ae nei.
nígbà náà ni kí o gbọ́ láti ọ̀run wá, ní ibùgbé rẹ, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí àlejò náà yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ, kí gbogbo ènìyàn ní ayé lè mọ orúkọ rẹ, kí wọn kí ó sì máa bẹ̀rù rẹ, gẹ́gẹ́ bí Israẹli, ènìyàn rẹ ti ṣe, kí wọn kí ó sì le mọ̀ pé orúkọ rẹ ni a fi pe ilé yìí tí mo kọ́.
44 A ina e hele aku kou poe kanaka e kaua i ko lakou enemi, ma kou wahi e hoouna aku ai ia lakou, a e pule aku lakou ia Iehova i ke kulanakauhale au i koho ai, a i ka hale a'u i kukulu ae nei no kou inoa;
“Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ bá jáde lọ sí ogun sí àwọn ọ̀tá wọn, níbikíbi tí ìwọ bá rán wọn, nígbà tí wọ́n bá gbàdúrà sí Olúwa sí ìhà ìlú tí ìwọ ti yàn àti síhà ilé tí mo ti kọ́ fún orúkọ rẹ,
45 Alaila e hoolohe oe i ka lakou pule me ko lakou nonoi ana, a e kokua mamuli o ko lakou pono.
nígbà náà ni kí o gbọ́ àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ wọn láti ọ̀run, kí o sì mú ọ̀rọ̀ wọn dúró.
46 Ina e hana hewa lakou ia oe, (no ka mea, aole kanaka hana hewa ole, ) a huhu mai oe ia lakou, a haawi aku oe ia lakou imua o ka enemi, a lawe pio aku lakou ia lakou i ka aina o ko lakou enemi, he loihi aku paha, he kokoke mai paha;
“Nígbà tí wọ́n bá ṣẹ̀ sí ọ, nítorí kò sí ẹnìkan tí kì í ṣẹ̀, tí ìwọ sì bínú sí wọn, tí ìwọ sì fi wọ́n lé ọ̀tá lọ́wọ́, tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ sí ilẹ̀ wọn, jíjìnnà tàbí nítòsí;
47 Ina e manao lakou i ko lakou naau, ma ka aina i lawe pio ia'ku ai lakou, a mihi lakou, a e nonoi aku ia oe ma ka aina o ka poe e lawe pio aku ia lakou, e i ana, Ua hewa makou, a ua hana ino, ua lawehala makou:
bí wọ́n bá ní ìyípadà ọkàn ní ilẹ̀ níbi tí a kó wọn ní ìgbèkùn lọ, tí wọ́n bá sì ronúpìwàdà, tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ sí ọ ní ilẹ̀ àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, wí pé, ‘Àwa ti ṣẹ̀, àwa ti ṣe ohun tí kò tọ́, àwa ti ṣe búburú’;
48 A e hoi mai lakou ia oe me ko lakou naau a pau, a me ko lakou uhane a pau, ma ka aina o ko lakou poe enemi naua lakou i alakai pio aku, a e pule aku ia oe i ko lakou aina au i haawi mai ai i ko lakou mau makua, i ke kulanakauhale au i koho mai ai, a i ka hale a'u i kukulu ae nei no kou inoa;
bí wọ́n bá sì fi gbogbo àyà àti gbogbo ọkàn wọn yípadà sí ọ, ní ilẹ̀ àwọn ọ̀tá wọn, tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ, tí wọ́n sì gbàdúrà sí ọ sí ìhà ilẹ̀ wọn tí ìwọ ti fi fún àwọn baba wọn, ìlú tí ìwọ ti yàn, àti ilé tí èmi kọ́ fún orúkọ rẹ;
49 Alaila e hoolohe mai oe ma ka lani kou wahi e noho ai, i ka lakou pule a me ko lakou nonoi ana, a e kokua mamuli o ko lakou pono.
nígbà náà ni kí ìwọ kí ó gbọ́ àdúrà wọn àti ẹ̀bẹ̀ wọn ní ọ̀run, ní ibùgbé rẹ, kí o sì mú ọ̀ràn wọn dúró.
50 A e kala mai i kou poe kanaka i hana hewa aku ia oe, a me ko lakou lawehala ana a pau i hana hewa aku ai lakou ia oe, a e haawi mai ia lakou i ke aloha, imua o ka poe i lawe pio aku ia lakou, i aloha mai lakou ia lakou nei;
Kí o sì dáríjì àwọn ènìyàn rẹ, tí wọ́n ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ; dárí gbogbo ìrékọjá wọn tí wọ́n ṣe sí ọ jì, kí o sì bá àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn lọ wí, kí wọn kí ó lè ṣàánú fún wọn;
51 No ka mea, o kou poe kanaka, a o kou waiwai hoi lakou au i lawe ai mai Aigupita mai, mai waena konu o ka umu no ka hao:
nítorí ènìyàn rẹ àti ìní rẹ ni wọ́n, àwọn ẹni tí ìwọ ti mú ti Ejibiti jáde wá, láti inú irin ìléru.
52 I kaakaa kou mau maka i ka pule a kau kauwa, a i ka nonoi ana o kou poe kanaka, i luhe mai i ka mea a pau a lakou e noi ai ia oe.
“Jẹ́ kí ojú rẹ ṣí sí ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ, àti sí ẹ̀bẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ Israẹli, kí o sì tẹ́tí sílẹ̀ sí wọn nígbà tí wọ́n bá kégbe sí ọ.
53 No ka mea, ua hookaawale mai oe ia lakou mai na lahuikanaka a pau o ka honua, i hooilina nou, me Kau i olelo mai ai ma ka lima o Mose o kau kauwa, i ka wa i lawe mai ai oe i ko makou mau kupuna, mai Aigupita mai, e Iehova ka Haku.
Nítorí tí ìwọ ti yà wọ́n kúrò nínú gbogbo orílẹ̀-èdè ayé, láti máa jẹ́ ìní rẹ, bí ìwọ ti sọ láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ, nígbà tí ìwọ Olúwa Olódùmarè, mú àwọn baba wa ti Ejibiti jáde wá.”
54 Eia hoi keia, i ka pau ana'e o ka Solomona haipule ana i keia pule, me keia nonoi ana a pau ia Iehova, ku ae la ia iluna mai mua mai o ke kuahu o Iehova, mai ke kukuli ana ma kona mau kuli me kona mau lima i hohola ae i ka lani.
Nígbà tí Solomoni ti parí gbogbo àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ yìí sí Olúwa tán, ó dìde kúrò lórí eékún rẹ̀ níwájú pẹpẹ Olúwa níbi tí ó ti kúnlẹ̀ tí ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí òkè ọ̀run
55 Ku mai la ia, a hoomaikai mai la i ke anaina a pau o ka Iseraela me ka leo nui,
Ó sì dìde dúró ó sì fi ohùn rara súre fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli wí pé,
56 E hoomaikaiia'ku o Iehova ka mea nana i haawi mai i ka maha i kona poe kanaka Iseraela, e like me kana olelo hoopomaikai a pau; aole haule kekahi hua o kana olelo hoopomaikai hemolele a pau ana i olelo ai ma ka lima o Mose kana kauwa.
“Ìbùkún ni fún Olúwa tí ó ti fi ìsinmi fún Israẹli, ènìyàn rẹ̀ bí ó ti ṣèlérí. Kò sí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kan tí ó kùnà nínú gbogbo ìlérí rere tí ó ti ṣe láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ̀ wá.
57 E noho Iehova ko kakou Akua me kakou e like me ia i noho ai me ko kakou mau makua; aole e haalele mai ia kakou, aole hoi e kiola ia kakou.
Kí Olúwa Ọlọ́run wa kí ó wà pẹ̀lú wa bí ó ti wà pẹ̀lú àwọn baba wa; kí ó má sì ṣe fi wá sílẹ̀ tàbí kọ̀ wá sílẹ̀.
58 E hoohaliu ae oia i ko kakou naau ia ia e hele ma kona mau aoao a pau, a malama i kana mau kauoha, a me kona mau kanawai, a me kona mau kapu, ana i kauoha mai ai i ko kakou poe kupuna.
Kí ó fa ọkàn wa sí ọ̀dọ̀ ara rẹ̀, láti máa rìn nínú gbogbo ọ̀nà rẹ̀, àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti àṣẹ rẹ̀, àti ìlànà rẹ̀, tí ó ti pàṣẹ fún àwọn baba wa.
59 A o keia mau olelo a'u i pule ai au ma ke alo o Iehova, e kokoke ae ia io Iehova la ko kakou Akua i ke ao a me ka po, e kokua mau oia mamuli o ka pono o kana kauwa, a me ka pono o kona poe kanaka Iseraela, ma ka mea o ka la i kona la iho;
Àti kí ó sì jẹ́ kí àwọn ọ̀rọ̀ mi wọ̀nyí, tí mo ti gbà ní àdúrà níwájú Olúwa, kí ó wà nítòsí Olúwa Ọlọ́run wa ní ọ̀sán àti ní òru, kí ó lè mú ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ dúró àti ọ̀rọ̀ Israẹli ènìyàn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí àìní wa ojoojúmọ́,
60 I ike na kanaka a pau o ka honua, o Iehova ke Akua, aohe e ae.
kí gbogbo ènìyàn ayé lè mọ̀ pé Olúwa òun ni Ọlọ́run, kò sì sí ẹlòmíràn.
61 Nolaila, e hemolele mai ko oukou mau naau ia Iehova ko kakou Akua, e hele ma kona mau kanawai, a e malama hoi i kana mau kauoha, me ia i keia la,
Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí ọkàn yín pé pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run wa, láti máa rìn nínú àṣẹ rẹ̀ àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, bí i ti òní yìí.”
62 Kaumaha aku la ke alii, me ia pu ka Iseraela a pau, i na mohai ma ke alo o Iehova.
Nígbà náà ni ọba àti gbogbo Israẹli rú ẹbọ níwájú Olúwa.
63 Kaumaha aku la hoi o Solomona i ka alana mohnihoomalu, ana i kaumaha ai no Iehova, he iwakalua kumamalua tausani bipi kauo, a he haneri me ka iwakalua tausani hipa: pela i hoolaa aku ai o Solomona, a me na mamo a pau a Iseraela, i ka hale o Iehova.
Solomoni rú ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa: ẹgbẹ̀rún méjìlélógún màlúù, àti ọ̀kẹ́ mẹ́fà àgùntàn. Bẹ́ẹ̀ ni ọba àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ya ilé Olúwa sí mímọ́.
64 Ia la no, i hoolaa ai ke alii i ka waena o ka pahale ma ke alo o ka hale o Iehova; no ka mea, malaila i kaumaha ai oia i na mohaikuni, a me na mohaiai, a me ke kaikea o na mohaihoomalu; no ka mea, o ke kuahu keleawe ka mea ma ke alo o Iehova, he uuku ia i ole ai e hiki ia ia na mohaikuni, a me na mohaiai, a me ke kaikea o na mohaihoomalu.
Ní ọjọ́ kan náà ni ọba ya àgbàlá àárín tí ń bẹ níwájú ilé Olúwa sí mímọ́, níbẹ̀ ni ó sì rú ẹbọ sísun àti ọrẹ oúnjẹ, àti ẹbọ àlàáfíà, nítorí pẹpẹ idẹ tí ń bẹ níwájú Olúwa kéré jù láti gba ẹbọ sísun, àti ọrẹ oúnjẹ, àti ọrẹ ẹbọ àlàáfíà.
65 Ia manawa, ahaaina ae la o Solomona, a me ia pu ka Iseraela a pau, he anaina nui, mai ke komo ana o Hamota a hiki i ka muliwai o Aigupita, ma ke alo o Iehova, ko kakou Akua, ehiku la, a ehiku la, he umikumamaha mau la.
Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni ṣe àpéjọ nígbà náà, àti gbogbo Israẹli pẹ̀lú rẹ̀, àjọ ńlá ńlá ni, láti ìwọ Hamati títí dé odò Ejibiti. Wọ́n sì ṣàjọyọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ní ọjọ́ méje àti ọjọ́ méje sí i, ọjọ́ mẹ́rìnlá papọ̀.
66 A i ka walu o ka la hookuu ae la oia i na kanaka; a hoomaikai aku la lakou i ke alii, a hele aku i, ko lakou mau hale lole, e hauoli ana me ka olioli o ka naau no ka pono a pau a Iehova i hana mai ai no Davida i kana kauwa, a me ka Iseraela i kona poe kanaka.
Ní ọjọ́ kẹjọ ó rán àwọn ènìyàn lọ. Wọ́n súre fún ọba, wọ́n sì lọ sí ilé wọn pẹ̀lú ayọ̀ àti inú dídùn fún gbogbo ohun rere tí Olúwa ti ṣe fún Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀, àti fún Israẹli ènìyàn rẹ̀.

< I Na Lii 8 >