< 2 Johannes 1 >

1 Der Älteste an die auserwählte Kyria und an ihre Kinder, die ich liebe in Wahrheit, und nicht allein ich, sondern auch alle, welche die Wahrheit erkannt haben,
Alàgbà, Sì àyànfẹ́ obìnrin ọlọ́lá àti àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn tí mo fẹ́ ní òtítọ́, kì í sì í ṣe èmi nìkan, ṣùgbọ́n gbogbo àwọn tí ó mọ òtítọ́ pẹ̀lú;
2 Um der Wahrheit willen, die in uns bleibt und bei uns sein wird in Ewigkeit. (aiōn g165)
nítorí òtítọ́ tí ń gbé inú wa, yóò sì bá wa gbé títí: (aiōn g165)
3 Gnade, Barmherzigkeit, Friede von Gott dem Vater und von dem Herrn Jesus Christus, dem Sohn des Vaters, in Wahrheit und Liebe sei mit dir.
Oore-ọ̀fẹ́, àánú, àti àlàáfíà, láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba, àti láti ọ̀dọ̀ Jesu Kristi, Ọmọ Baba, yóò wà pẹ̀lú wa nínú òtítọ́ àti nínú ìfẹ́.
4 Ich freute mich sehr, daß ich von deinen Kindern solche gefunden habe, die in der Wahrheit wandeln, wie wir das Gebot vom Vater empfangen haben.
Mo yọ̀ gidigidi pé mo rí nínú àwọn ọmọ rẹ tí ń rìn nínú òtítọ́, gẹ́gẹ́ bí Baba ti pa àṣẹ fún wa.
5 Und nun bitte ich dich, Kyria, nicht als ob ich dir ein neu Gebot schriebe, sondern eines, das wir von Anfang an hatten, daß wir einander lieben sollen.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, mo bẹ̀ ọ́, obìnrin ọlọ́lá, kì í ṣe bí ẹni pé èmi ń kọ̀wé òfin tuntun kan sí ọ, bí kò ṣe èyí ti àwa tí ní ní àtètèkọ́ṣe, pé kí àwa fẹ́ràn ara wa.
6 Und das ist die Liebe, daß wir wandeln nach Seinen Geboten. Das ist das Gebot, wie ihr von Anfang angehört habt, daß ihr darin wandeln sollt.
Èyí sì ni ìfẹ́, pé, kí àwa máa rin nípa òfin rẹ̀, èyí ni òfin náà, àní bí ẹ ti gbọ́ ni àtètèkọ́ṣe, pé, kí ẹ̀yin rìn nínú rẹ̀.
7 Denn viele Verführer sind in die Welt gekommen, die Jesus Christus nicht bekennen als in das Fleisch gekommen. Dies ist der Verführer und der Widerchrist.
Nítorí ẹlẹ́tàn púpọ̀ ti jáde wa sínú ayé, àwọn tí kò jẹ́wọ́ pé Jesu Kristi wá nínú ara. Èyí ni ẹlẹ́tàn àti aṣòdì sí Kristi.
8 Seht euch vor, daß wir nicht verlieren, was wir erarbeitet haben, sondern vollen Lohn empfangen.
Ẹ kíyèsára yín, kí ẹ má ba à sọ iṣẹ́ tí ẹ tí ṣe nù, ṣùgbọ́n kí ẹ̀yin lè rí èrè kíkún gbà.
9 Wer darüber hinaus will und nicht bei der Lehre Christi bleibt, der hat Gott nicht; wer aber bei der Lehre Christi bleibt, der hat sowohl den Vater als den Sohn.
Olúkúlùkù ẹni tí ó bá ń rú òfin tí kò si dúró nínú ẹ̀kọ́ Kristi, kò mọ Ọlọ́run. Ẹni tí ó bá dúró nínú ẹ̀kọ́, òun ni ó mọ Baba àti Ọmọ.
10 Wenn einer zu euch kommt und diese Lehre nicht bringt, den nehmt nicht in das Haus und grüßt ihn auch nicht.
Bí ẹnikẹ́ni bá tọ̀ yín wá, tí kò sì mu ẹ̀kọ́ yìí wá, ẹ má ṣe gbà á sí ilé, kí ẹ má sì ṣe kí i kú ààbọ̀.
11 Denn wer ihn begrüßt, der nimmt Teil an seinen bösen Werken.
Nítorí ẹni tí ó bá kí kú ààbọ̀, ó ní ọwọ́ nínú iṣẹ́ búburú rẹ̀.
12 Ich hätte euch noch viel zu schreiben, aber ich wollte nicht mit Papier und Tinte, hoffe aber zu euch zu kommen und mündlich davon zu reden, auf daß unsere Freude vollkommen sei.
Bí mo tilẹ̀ ní ohun púpọ̀ láti ṣe alábápín pẹ̀lú yín, síbẹ̀ èmi kò fẹ́ lo ìwé ìkọ̀wé àti jẹ́lú ìkọ̀wé. Ṣùgbọ́n èmi ní ìrètí láti tọ̀ yín wá àti láti bá a yín sọ̀rọ̀ lójúkojú, kí ayọ̀ yín bá à le è kún.
13 Es grüßen dich die Kinder deiner Schwerster, der Auserwählten. Amen.
Àwọn ọmọ arábìnrin rẹ àyànfẹ́ kí ọ.

< 2 Johannes 1 >