< Sprueche 2 >

1 Mein Sohn, wenn du meine Reden animmstund meine Gebote bei dir verwahrst,
Ọmọ mi, bí ìwọ bá gba ọ̀rọ̀ mi, tí ìwọ sì pa òfin mi mọ́ sí inú rẹ,
2 so daß du der Weisheit aufmerksam dein Ohr leihst, dein Herz der Vernunft zuneigst -
tí ìwọ dẹtí rẹ sílẹ̀ sí ọgbọ́n tí ìwọ sì fi ọkàn rẹ sí òye,
3 ja, wenn du der Einsicht rufst, nach der Vernunft hin deine Stimme erschallen lässest,
àní, bí ìwọ bá ké tọ ìmọ̀ lẹ́yìn, tí ìwọ sì gbé ohùn rẹ sókè fún òye
4 wenn du sie suchst wie Silberund nach ihr forschest wie nach verborgenen Schätzen -
bí ìwọ bá ṣàfẹ́rí rẹ̀ bí i fàdákà tí ìwọ sì wa kiri bí ìṣúra tí a fi pamọ́.
5 alsdann wirst du die Furcht Jahwes verstehenund Erkenntnis Gottes gewinnen.
Nígbà náà ni ìwọ yóò bẹ̀rù Olúwa, ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run.
6 Denn Jahwe allein verleiht Weisheit, aus seinem Munde kommt Erkenntnis und Vernunft.
Nítorí Olúwa ni ó ń fún ni ní ọgbọ́n, láti ẹnu rẹ̀ sì ni ìmọ̀ àti òye ti ń wá.
7 Er spart den Rechtschaffenen Heil auf, beschirmt die, die unsträflich wandeln,
Ó to ìgbàlà fún àwọn olódodo, Òun ni asà fún àwọn tí ń rìn déédé,
8 so daß er die Pfade des Rechts behütetund den Weg seiner Frommen bewahrt.
Ó pa ipa ọ̀nà ìdájọ́ mọ́ Ó sì ń pa ọ̀nà àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ mọ́.
9 Alsdann wirst du Gerechtigkeit und Recht verstehenund Geradheit, jede Bahn des Guten.
Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ òdodo àti ìdájọ́, àti àìṣègbè—gbogbo ipa ọ̀nà rere.
10 Denn Weisheit wird in dein Herz einziehenund Erkenntnis wird deiner Seele lieblich sein;
Nítorí ọgbọ́n yóò wọ inú ọkàn rẹ ìmọ̀ yóò sì jẹ́ ìtura fún ọkàn rẹ.
11 Umsicht wird dich bewahren, Vernunft deine Hüterin sein, -
Ìmòye yóò pa ọ mọ́ òye yóò sì máa ṣọ́ ọ.
12 daß sie dich vom Wege des Bösen errette, von den Leuten, die Verkehrtes reden,
Ọgbọ́n yóò gbà ọ́ là kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú, lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn tí ọrọ̀ ọ wọn jẹ́ àyídáyidà,
13 die der Geradheit Pfade verlassen, um auf den Wegen der Finsternis zu wandeln,
ẹni tí ó kúrò ní ọ̀nà ìdúró ṣinṣin láti rìn ní ọ̀nà tí ó ṣókùnkùn,
14 die sich freuen, Böses zu thun, über schlimme Verkehrtheit frohlocken,
ẹni tí ó yọ̀ nínú ṣíṣe búburú, tí ó ṣe inú dídùn sí àyídáyidà àwọn ènìyàn ibi,
15 die ihre Pfade krumm machenund in ihren Bahnen auf Abwege geraten -
ọ̀nà ẹni tí ó wọ́ tí wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ní ọ̀nà wọn.
16 daß sie dich von dem fremden Weibe errette, von der Auswärtigen, die einschmeichelnd redet,
Yóò gba ìwọ pẹ̀lú là kúrò lọ́wọ́ àwọn àjèjì obìnrin, àní, lọ́wọ́ obìnrin àjèjì tí ń fi ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ tannijẹ,
17 die den Freund ihrer Jugend im Stiche gelassenund den von ihrem Gotte geordneten Bund vergessen hat.
ẹni tí ó ti kọ ọkọ àkọ́fẹ́ ìgbà èwe rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì gbàgbé májẹ̀mú tí ó ti dá níwájú Ọlọ́run rẹ̀.
18 Denn zum Tode sinkt ihr Haus hinab, und zu den Schatten führen ihre Bahnen.
Nítorí ilé rẹ̀ jẹ́ ọ̀nà sí ikú ipa ọ̀nà rẹ̀ sọ́dọ̀ àwọn òkú.
19 Alle, die zu ihr eingehen, kehren nicht wiederund erreichen nicht des Lebens Pfade -
Kò sẹ́ni tó lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ tí ó padà bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í dé ọ̀nà ìyè.
20 damit du auf dem Wege der Guten wandelstund die Pfade der Frommen einhaltest.
Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò rìn ní ọ̀nà àwọn ènìyàn rere kí ìwọ kí ó sì pa ọ̀nà àwọn olódodo mọ́.
21 Denn die Rechtschaffenen werden das Land bewohnen, und die Unsträflichen darin übrig bleiben.
Nítorí ẹni dídúró ṣinṣin yóò gbé ní ilé náà àwọn aláìlẹ́gàn sì ni yóò máa wà nínú rẹ̀.
22 Aber die Gottlosen werden aus dem Lande ausgerottet, und die Treulosen aus ihm herausgerissen werden.
Ṣùgbọ́n a ó ké ènìyàn búburú kúrò lórí ilẹ̀ náà a ó sì fa àwọn aláìṣòótọ́ tu kúrò lórí rẹ̀.

< Sprueche 2 >