< 1 Chronik 8 >

1 Und Benjamin erzeugte Bela, seinen Erstgeborenen, Asbel, den zweiten, Ahrah, den dritten,
Benjamini jẹ́ baba: Bela àkọ́bí rẹ̀, Aṣbeli ọmọkùnrin ni ẹ̀ẹ̀kejì, Ahara ẹ̀ẹ̀kẹ́ta,
2 Noha, den vierten, und Rapha den fünften.
Noha ẹ̀ẹ̀kẹrin àti Rafa ẹ̀karùnún.
3 Und Bela hatte folgende Söhne: Addar, Gera, Abihud,
Àwọn ọmọ Bela ni, Adari, Gera, Abihudi,
4 Abisua, Naahman, Ahoah,
Abiṣua, Naamani, Ahoa,
5 Gera, Sephuphan und Huram.
Gera, Ṣefufani àti Huramu.
6 Und dies sind die Söhne Ehuds (Diese sind Familienhäupter der Bewohner von Geba, und sie führten sie als Gefangene hinweg nach Manahath;
Wọ̀nyí ni àwọn ìran ọmọ Ehudu, tí wọ́n jẹ́ olórí àwọn ìdílé tí ó ń gbé ní Geba tí a sì lé kúrò lọ sí Manahati:
7 Naaman, Ahia und Gera, der führte sie hinweg) und er erzeugte Ussa und Ahihud.
Naamani Ahijah àti Gera, tí ó lé wọn kúrò ní ìlú, àti tí ó sì jẹ́ baba Ussa àti Ahihudu.
8 Saharaim aber erzeugte im Gefilde der Moabiter, nachdem er sie verstoßen hatte - seine Weiber Husim und Baara -,
A bí àwọn ọmọkùnrin fún Ṣaharaimu ní Moabu lẹ́yìn tí ó ti kọ àwọn ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀, Huṣimu àti Baara.
9 da erzeugte er mit seinem Weibe Hodes: Jobab, Zibja, Mesa, Malkam,
Nípasẹ̀ ìyàwó rẹ̀ Hodeṣi ó ní Jobabu Sibia, Meṣa, Malkamu,
10 Jenz, Sochja und Mirma. Das sind seine Söhne, Familienhäupter.
Jeusi, Sakia àti Mirma. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, olórí àwọn ìdílé.
11 Und mit Husim erzeugte er Abitub und Elpaal.
Nípasẹ̀ Huṣimu ó ní Abitubu àti Elipali.
12 Die Söhne Elpaals waren: Eber, Miseam und Semer. Dieser erbaute Ono und Lod samt den zugehörigen Ortschaften.
Àwọn ọmọ Elipali: Eberi, Miṣamu, Ṣemedu (ẹni tí ó kọ́ Ono àti Lodi pẹ̀lú àwọn ìletò àyíká rẹ̀.)
13 Und Beria und Sema (das sind die Familienhäupter der Bewohner Ajalons; diese verjagten die Bewohner von Gath)
Pẹ̀lú Beriah àti Ṣema, tí wọ́n jẹ́ olórí àwọn ìdílé ti àwọn tí ó ń gbé ní Aijaloni àti àwọn tí ó lé àwọn olùgbé Gati kúrò.
14 und sein Bruder Elpaal und Sasak und Jeremoth.
Ahio, Ṣasaki, Jeremoti,
15 Und Sebadja, Arad, Eder,
Sebadiah, Aradi, Ederi
16 Michael, Jispa und Joha waren die Söhne Berias.
Mikaeli, Iṣifa àti Joha jẹ́ àwọn ọmọ Beriah.
17 Und Sebadja, Mesullam, Hiski, Heber,
Sebadiah, Meṣullamu, Hiski, Heberi
18 Jismerai, Jislia und Jobab waren die Söhne Elpaals.
Iṣimerai, Isiliahi àti Jobabu jẹ́ àwọn ọmọ Elipali.
19 Und Jakim, Sichri, Sabdi,
Jakimu, Sikri, Sabdi,
20 Elienai, Zillethai, Eliel,
Elienai, Siletai, Elieli,
21 Adaja, Beraja und Simrath waren die Söhne Simeis.
Adaiah, Beraiah àti Ṣimrati jẹ́ àwọn ọmọ, Ṣimei.
22 Und Jispan, Eber, Eliel,
Iṣipani Eberi, Elieli,
23 Abdon, Sichri, Hanon,
Abdoni, Sikri, Hanani,
24 Hananja, Elam, Anthothija,
Hananiah, Elamu, Anitotijah,
25 Jiphdeja und Penuel waren die Söhne Sasaks.
Ifediah àti Penueli jẹ́ àwọn ọmọ Ṣasaki.
26 Und Samserai, Seharja, Athalja,
Ṣamṣerai, Ṣeharaiah, Ataliah
27 Jaaresja, Elia und Sichri waren die Söhne Jerohams.
Jareṣiah, Elijah àti Sikri jẹ́ àwọn ọmọ Jerohamu.
28 Diese waren Familienhäupter in ihren Geschlechtern, Oberhäupter; diese wohnten zu Jerusalem.
Gbogbo àwọn wọ̀nyí jẹ́ olórí àwọn ìdílé, olóyè gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ lẹ́sẹẹsẹ nínú ìtàn ìran wọn, wọ́n sì ń gbé ní Jerusalẹmu.
29 Und zu Gibeon wohnten: der Vater von Gibeon, Jeiel, und sein Weib hieß Maacha.
Jeieli, baba Gibeoni ń gbé ní Gibeoni. Ìyàwó o rẹ̀ a má jẹ́ Maaka,
30 Und sein erstgeborener Sohn war Abdon, und Zur, Kis, Baal, Ner, Nadab,
àkọ́bí rẹ̀ a sì máa jẹ́ Abdoni wọ̀nyí sì ń tẹ̀lé Suri, Kiṣi, Baali, Neri, Nadabu,
31 Gedor, Ahjo und Secher.
Gedori Ahio, Sekeri
32 Mikloth aber erzeugte Simea. Und auch sie wohnten ihren Brüdern gegenüber in Jerusalem bei ihren Brüdern.
pẹ̀lú Mikiloti, tí ó jẹ́ baba Ṣimea. Wọ́n ń gbé ní ẹ̀bá ìbátan wọn ní Jerusalẹmu.
33 Und Ner erzeugte Abner, und Kis erzeugte Saul, und Saul erzeugte Jonathan, Malchisua, Abinadab und Esbaal.
Neri jẹ́ baba Kiṣi, Kiṣi baba Saulu àti Saulu baba Jonatani, Malikiṣua, Abinadabu àti Eṣi-Baali.
34 Und der Sohn Jonathans war Meribaal, und Meribaal erzeugte Micha.
Ọmọ Jonatani: Meribu-Baali tí ó jẹ́ baba Mika.
35 Und die Söhne Michas waren Pithon, Melech, Tharea und Ahas.
Àwọn ọmọ Mika: Pitoni, Meleki, Tarea, àti Ahasi.
36 Ahas aber erzeugte Joadda, Joadda erzeugte Alemeth, Asmaweth und Simri. Simri erzeugte Moza,
Ahasi jẹ́ baba a Jeheada, Jeheada jẹ́ baba a Alemeti, Asmafeti àti Simri, Simri sì jẹ́ baba Mosa.
37 Moza erzeugte Binea; dessen Sohn war Rapha, dessen Sohn war Eleasa, dessen Sohn war Azel.
Mosa jẹ́ baba Binea; Rafa sì jẹ́ ọmọ rẹ̀, Eleasa ọmọ rẹ̀ àti Aseli ọmọ rẹ̀.
38 Azel aber hatte sechs Söhne; die hießen: Asrikam, Bochru, Ismael, Searja, Obadja und Hanan. Diese alle waren Söhne Azels.
Aseli ní ọmọ mẹ́fà pẹ̀lú wọ̀nyí ni orúkọ wọn: Asrikamu, Bokeru, Iṣmaeli, Ṣeariah, Obadiah àti Hanani. Gbogbo wọ̀nyí ni ọmọ Aseli.
39 Und die Söhne seines Bruders Esek waren: Ulam, sein Erstgeborener, Jeus, der zweite, und Eliphelet, der dritte.
Àwọn ọmọ arákùnrin rẹ̀ Eseki: Ulamu àkọ́bí rẹ̀, Jeuṣi ọmọkùnrin ẹ̀ẹ̀kejì àti Elifeleti ẹ̀ẹ̀kẹ́ta.
40 Und die Söhne Ulams waren kriegstüchtige Männer, die den Bogen zu spannen wußten, und hatten zahlreiche Söhne und Enkel, 150 an der Zahl. Diese alle gehören zu den Benjaminiten.
Àwọn ọmọ Ulamu jẹ́ ògboyà jagunjagun tí ó lè gbá orin mú. Wọ́n ní ọ̀pọ̀ ọmọkùnrin àti ọmọ ọmọkùnrin áàdọ́jọ ní gbogbo rẹ̀. Gbogbo wọ̀nyí ni àwọn ìdílé ìran ọmọ Benjamini.

< 1 Chronik 8 >