< Esra 2 >

1 Dies sind die Angehörigen des Bezirks, die aus der Exulantenschar heraufgezogen und die Babels König Nebukadrezar nach Babel geführt hatte. Sie kehrten heim nach Jerusalem und Juda, jeder in seine Stadt.
Lákòókò náà, wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn agbègbè Juda tí ó gòkè wá láti ìgbèkùn láàrín àwọn tí a kó lọ, ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli ti fi agbára mú ní ìgbèkùn lọ sí Babeli (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀.
2 Sie, die mit Zerubbabel, Jesua, Nechemja, Seraja, Reelaja, Mordekai, Bilsan, Mispar, Bigwai, Rechum und Baana gekommen waren. Das ist die Zahl der Männer des Volkes Israel:
Àwọn wọ̀nyí bá Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Seraiah, Reelaiah, Mordekai, Bilṣani, Mispari, Bigfai, Rehumu àti Baanah wá). Iye àwọn ọkùnrin àwọn ènìyàn Israẹli.
3 die Söhne des Paros 2.172,
Àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
4 die Söhne des Saphatja 372,
Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
5 die Söhne des Arach 775,
Arah jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n
6 die Söhne des Tachat Moab, nämlich die Söhne des Jesua Joab, 2.812,
Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ àwọn ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì àti ẹgbẹ̀rin lé méjìlá
7 die Söhne des Elam 1.245,
Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
8 die Söhne des Zattu 945,
Sattu jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rún ó lé márùn-ún
9 die Söhne des Zakkai 760,
Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
10 die Söhne des Bani 642,
Bani jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì
11 die Söhne des Bebai 623,
Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mẹ́tàlélógún
12 die Söhne des Azgad 1.222,
Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé méjìlélógún
13 die Söhne des Adonikam 666,
Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́fà
14 die Söhne des Bigwai 2.056,
Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
15 die Söhne des Adin 459,
Adini jẹ́ àádọ́ta lé ní irinwó ó lé mẹ́rin
16 die Söhne des Ater von Jechizkija 98,
Ateri (nípasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́run
17 die Söhne des Besai 323,
Besai jẹ́ ọrùndínnírinwó ó lé mẹ́ta
18 die Söhne des Jora 112,
Jora jẹ́ méjìléláàádọ́fà
19 die Söhne des Chasum 223,
Haṣumu jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
20 die Söhne des Gibbar 95,
Gibbari jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
21 die Söhne von Bethlehem 23,
Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
22 die Männer von Netopha 56,
Netofa jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
23 die Männer von Anatot 128,
Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
24 die Söhne des Azmawet 42,
Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
25 die Söhne Kirjat Arim, Kephira undBeerot 743,
Kiriati-Jearimu, Kefira àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
26 die Söhne der Rama und von Geba 621,
Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
27 die Männer von Mikmas 122,
Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
28 die Männer von Betel und dem Ai 223,
Beteli àti Ai jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
29 die Söhne des Nebo 52,
Nebo jẹ́ méjìléláàádọ́ta
30 die Söhne des Maglis 156,
Magbiṣi jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́jọ
31 die Söhne des Neu-Elam 1.254,
Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
32 die Söhne des Charim 320,
Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó.
33 die Söhne des Lod, Chadid und Ano 725,
Lodi, Hadidi àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
34 die Söhne von Jericho 345,
Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún
35 die Söhne Senaas 3.630.
Senaa jẹ́ egbèji dín lógún ó lé ọgbọ̀n.
36 Die Priester: die Söhne Jedajas vom Hause Jesua 973,
Àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
37 die Söhne des Immer 1052,
Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
38 die Söhne des Paschur 1247,
Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
39 die Söhne des Charim 1017.
Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
40 Die Leviten: die Söhne des Jesua und des Kadmiel vom Hause Hodawja 74.
Àwọn ọmọ Lefi. Àwọn ọmọ Jeṣua àti Kadmieli (ti ìdílé Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
41 Die Sänger: die Söhne Asaphs, 128.
Àwọn akọrin. Àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádóje.
42 Die Torhüter: die Söhne Sallums, die Söhne Talmons, die Söhne Akkubs, die Söhne Chatitas, die Söhne Sobais, insgesamt 1.391.
Àwọn aṣọ́bodè. Àwọn ará Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita àti Ṣobai jẹ́ mọ́kàndínlógóje.
43 Die Tempelsklaven: die Söhne des Sicha, die Söhne des Chasupha, die des Tabbaot,
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ. Siha, Hasufa, Tabboati,
44 die Söhne des Keros, die des Siaha, die des Padon,
Kerosi, Siaha, Padoni,
45 die Söhne des Lebana, die des Chaguba, die des Akkub,
Lebana, Hagaba, Akkubu,
46 die Söhne des Chagab, die des Samlai, die des Chanan,
Hagabu, Ṣalmai, Hanani,
47 die Söhne des Giddel, die des Gachar, die des Reaja,
Giddeli, Gahari, Reaiah,
48 die Söhne des Resin, die des Nekoda, die des Gazzam,
Resini, Nekoda, Gassamu,
49 die Söhne des Uzza, die des Paseach, die des Besai,
Ussa, Pasea, Besai,
50 die Söhne des Asna, die der Mëuniter, die der Nephusiter,
Asna, Mehuni, Nefisimu,
51 die Söhne des Bakbuk, die des Chakupha, die des Charchur,
Bakbu, Hakufa, Harhuri.
52 die Söhne des Baslut, die des Mechida, die des Charsa,
Basluti, Mehida, Harṣa,
53 die Söhne des Barkos, die des Sisera, die des Tamach,
Barkosi, Sisera, Tema,
54 die Söhne des Nesiach die des Chatipha.
Nesia àti Hatifa.
55 Die Söhne der Sklaven Salomos: die Söhne des Sotai, die der Schreiberin, die des Peruda,
Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni. Àwọn ọmọ Sotai, Sofereti, Peruda,
56 die Söhne des Jaala, die des Darkon, die des Giddel,
Jaala, Darkoni, Giddeli,
57 die Söhne des Sephatja, die des Chattil, die Söhne der Pokeret der Gazellen, die des Ami,
Ṣefatia, àwọn ọmọ Hattili, Pokereti ti Haṣebaimu àti àwọn ọmọ Ami.
58 all die Tempelsklaven und Söhne der Sklaven Salomos 393.
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
59 Und dies sind die, die aus Tel Melach und Tel Charsa, Cherub, Addan und Immer hergezogen waren, aber nicht dartun konnten, ob ihr Haus und ihre Abstammung echt israelitisch seien:
Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
60 Die Söhne des Delaja, die des Tobia und die des Nekoda 652.
Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
61 Und von den Priestersöhnen die Söhne des Chabaja und die des Hakkos, die Söhne Barzillais, der sich eine der Töchter des Gileaditers Barzillai zum Weibe genommen hatte und dann nach ihrem Namen benannt ward.
Àti nínú àwọn ọmọ àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ: Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi a sì ń fi orúkọ náà pè é).
62 Diese suchten die Schrift ihres Geschlechtsnachweises. Sie fand sich aber nicht vor, und so wurden sie vom Priestertum ausgeschlossen.
Àwọn wọ̀nyí wá ìwé ìrántí ìdílé wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí i, bẹ́ẹ̀ ni a kò kà wọ́n kún ara àlùfáà nítorí, a kà wọ́n sí aláìmọ́.
63 Der Tirsata sprach zu ihnen, sie dürften vom Hochheiligen nicht essen, bis ein Priester für Urim und Tummim erstünde.
Baálẹ̀ pa á láṣẹ fún wọn pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ nínú oúnjẹ mímọ́ jùlọ títí tí àlùfáà kan yóò fi ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu.
64 Die ganze Gemeinde belief sich auf 42.360,
Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó.
65 ohne ihre Sklaven und Sklavinnen, an Zahl 7.337. Auch hatten sie 200 Sänger und Sängerinnen.
Yàtọ̀ sí ẹgbẹ̀rin dín lẹ́gbàárin ó dín mẹ́tàlélọ́gọ́ta ìránṣẹ́ ọkùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin; wọ́n ní igba akọrin ọkùnrin àti obìnrin.
66 Die Zahl der Pferde betrug 736, die ihrer Maultiere 245,
Wọ́n ní ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin ẹṣin; ìbáaka òjìlélúgba ó lé márùn-ún,
67 ihrer Kamele 435, ihrer Esel 6.720.
ràkunmí jẹ́ irinwó ó lé márùndínlógójì àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rin lé lọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
68 Von den Familienhäuptern hatten manche, als sie zum Hause des Herrn in Jerusalem kamen, Spenden für das Gotteshaus gegeben, um es auf seiner Stelle zu errichten.
Ní ìgbà tí wọ́n dé ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, díẹ̀ nínú àwọn olórí àwọn ìdílé fi ọrẹ àtinúwá sílẹ̀ fún ṣíṣe àtúnkọ́ ilé Ọlọ́run ní ààyè rẹ̀.
69 Sie hatten für den Bauschatz je nach ihrer Habe an Gold 61.000 Drachmen gegeben, an Silber 5.000 Minen und 100 Priesterkleider.
Gẹ́gẹ́ bí agbára wọn, wọ́n fún ilé ìṣúra fún iṣẹ́ yìí ní ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ́gbẹ̀rún ìwọ̀n dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún márùn-ún fàdákà àti ọgọ́rùn-ún ẹ̀wù àlùfáà.
70 Die Priester, die Leviten und manche vom Volk, die Sänger, Torhüter und Tempelsklaven siedelten sich darin in ihren Städten an, ebenso das ganze übrige Israel in seinen Städten.
Àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́bodè àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa ṣe àtìpó sínú àwọn ìlú wọn, pẹ̀lú àwọn ènìyàn mìíràn, àti ìyókù àwọn ọmọ Israẹli ṣe àtìpó sínú ìlú u wọn.

< Esra 2 >