< Luc 17 >

1 Il dit à ses disciples: «Il est impossible qu'il n'y ait pas de scandales; mais malheur à celui par qui ils arrivent!
Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Kò le ṣe kí ohun ìkọ̀sẹ̀ máa wa, ṣùgbọ́n ègbé ni fún ẹni tí ó ti ipasẹ̀ rẹ̀ dé.
2 Il vaudrait mieux pour lui, qu'on lui mît au cou une pierre de moulin, et qu'on le jetât dans la mer, que d'être une occasion de chute pour un seul de ces petits.
Ìbá sàn fún un kí a so ọlọ mọ́ ọn ní ọrùn, kí a sì gbé e jù sínú Òkun, ju kí ó mú ọ̀kan nínú àwọn kékeré wọ̀nyí kọsẹ̀.
3 Prenez donc garde à vous-mêmes. Si ton frère t'a offensé, reprends-le; et, s'il se repent pardonne-lui;
Ẹ máa kíyèsára yín. “Bí arákùnrin rẹ bá ṣẹ̀, bá a wí; bí ó bá sì ronúpìwàdà, dáríjì ín.
4 et quand il t'offenserait sept fois en un jour, s'il revient sept fois te dire «je me repens, » tu lui pardonneras.»
Bí ó bá sì ṣẹ̀ ọ́ ní igba méje ní òòjọ́, tí ó padà tọ̀ ọ́ wá ní ìgbà méje ní òòjọ́ pé, ‘Mo ronúpìwàdà,’ dáríjì ín.”
5 Les apôtres dirent au Seigneur: «Augmente-nous la foi.»
Àwọn aposteli sì wí fún Olúwa pé, “Bù sí ìgbàgbọ́ wa.”
6 Mais le Seigneur leur dit: «Si vous aviez de la foi gros comme un grain de moutarde, vous diriez à ce sycomore: «Déracine-toi, et va te planter dans la mer; » et il vous obéirait.
Olúwa sì wí pé, “Bí ẹ̀yin bá ní ìgbàgbọ́ bí hóró irúgbìn musitadi, ẹ̀yin yóò lè wí fún igi sikamine yìí pé, ‘Di fi fà á tu, kí a sì gbìn ọ́ sínú Òkun,’ yóò sì gbọ́ tiyín.
7 «Qui de vous, ayant un serviteur occupé à labourer ou à paître ses troupeaux, lui dira, à son retour des champs: «Viens vite te mettre à table?»
“Ṣùgbọ́n ta ni nínú yín, tí ó ní ọmọ ọ̀dọ̀, tí ó ń tulẹ̀, tàbí tí ó ń bọ́ ẹran, tí yóò wí fún un lójúkan náà tí ó bá ti oko dé pé, ‘Lọ í jókòó láti jẹun’?
8 Ne lui dira-t-il pas au contraire: «Prépare-moi à souper, et ceins-toi pour me servir, jusqu’à ce que j'aie mangé et bu; après quoi, tu mangeras et boiras?»
Tí kì yóò kúkú wí fún un pé, ‘Pèsè ohun tí èmi yóò jẹ, sì di àmùrè, kí ìwọ kí ó máa ṣe ìránṣẹ́ fún mi, títí èmi ó fi jẹ kí èmi ó sì mu tán; lẹ́yìn náà ni ìwọ ó sì jẹ, tí ìwọ ó sì mu’?
9 A-t-il de l'obligation à son serviteur, parce qu'il a fait ce qui lui était commandé?
Òun ó ha máa dá ọpẹ́ lọ́wọ́ ọmọ ọ̀dọ̀ náà, nítorí ó ṣe ohun tí a pàṣẹ fún un bí? Èmi kò rò bẹ́ẹ̀.
10 Je ne le pense pas. Vous de même, quand vous aurez fait tout ce qui vous est commandé, dites: «Nous sommes des serviteurs inutiles; nous n'avons fait que ce que nous devions faire.»
Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin pẹ̀lú, nígbà tí ẹ bá ti ṣe ohun gbogbo tí a pàṣẹ fún yín tán, ẹ wí pé, ‘Aláìlérè ọmọ ọ̀dọ̀ ni wá: èyí tí í ṣe iṣẹ́ wa láti ṣe, ní àwa ti ṣe.’”
11 En se rendant à Jérusalem, il lui arriva de passer sur les confins de la Samarie et de la Galilée;
Ó sì ṣe, bí ó ti ń lọ sí Jerusalẹmu, ó kọjá láàrín Samaria Galili.
12 et, comme il entrait dans un village, il rencontra dix lépreux qui se tenaient à distance,
Bí ó sì ti ń wọ inú ìletò kan lọ, àwọn ọkùnrin adẹ́tẹ̀ mẹ́wàá pàdé rẹ̀, wọ́n dúró ní òkèrè,
13 et qui lui crièrent: «Jésus, Maître, aie pitié de nous.»
wọ́n sì kígbe sókè wí pé, “Jesu, Olùkọ́, ṣàánú fún wa.”
14 Jésus les ayant vus, leur dit: «Allez vous montrer aux sacrificateurs; » et, en y allant, ils furent nettoyés de leur lèpre.
Nígbà tí ó rí wọn, ó wí fún wọn pé, “Ẹ lọ í fi ara yín hàn fún àwọn àlùfáà.” Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń lọ, wọ́n sì di mímọ́.
15 L'un d'eux, se voyant guéri, revint sur ses pas, glorifiant Dieu à haute voix;
Nígbà tí ọ̀kan nínú wọn rí i pé a mú òun láradá ó padà, ó sì fi ohùn rara yin Ọlọ́run lógo.
16 il se jeta aux pieds de Jésus, la face contre terre, et lui rendit grâces: c'était un Samaritain.
Ó sì wólẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ̀, ó ń dúpẹ́ ní ọwọ́ rẹ̀: ará Samaria ni òun í ṣe.
17 Alors Jésus dit: «Les dix n'ont-ils pas tous été rendus nets? où sont les neuf autres?
Jesu sì dáhùn wí pé, “Àwọn mẹ́wàá kí a sọ di mímọ́? Àwọn mẹ́sàn-án ìyókù ha dà?
18 N'y a-t-il que cet étranger qu'on ait vu revenir donner gloire à Dieu?»
A kò rí ẹnìkan tí ó padà wá fi ògo fún Ọlọ́run, bí kò ṣe àlejò yìí?”
19 Et il lui dit: » Lève-toi, va; ta foi t'a guéri.»
Ó sì wí fún un pé, “Dìde, kí o sì máa lọ, ìgbàgbọ́ rẹ mú ọ láradá.”
20 Les pharisiens lui ayant demandé quand le royaume de Dieu devait venir, il leur répondit: «Le royaume de Dieu ne vient pas d'une manière qui frappe les regards,
Nígbà tí àwọn Farisi bi í pé, nígbà wo ni ìjọba Ọlọ́run yóò dé, ó dá wọn lóhùn pé, “Ìjọba Ọlọ́run kì í wá pẹ̀lú àmì.
21 et l'on ne dira pas: «il est ici, » ou «il est là; » car voici, le royaume de Dieu est au dedans de vous.»
Bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò wí pé, ‘Kíyèsi i níhìn-ín!’ tàbí ‘Kíyèsi i lọ́hùn ún ni!’ sá à wò ó, ìjọba Ọlọ́run ń bẹ nínú yín.”
22 Il dit à ses disciples: «Le temps viendra où vous souhaiterez de voir un jour, un seul des jours du Fils de l'homme, et vous ne le verrez pas.
Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Ọjọ́ ń bọ̀, nígbà tí ẹ̀yin yóò fẹ́ láti rí ọ̀kan nínú ọjọ́ Ọmọ Ènìyàn, ẹ̀yin kì yóò sì rí i.
23 On vous dira: «Il est là; il est ici; » n'y allez pas, n'y courez pas;
Wọ́n sì wí fún yín pé, ‘Wò ó níhìn-ín!’ tàbí ‘Wò ó lọ́hùn ún!’ Ẹ máa lọ, ẹ má ṣe tẹ̀lé wọn.
24 car comme l'éclair qui luit, brille d'un bout du ciel à l'autre, ainsi en sera-t-il du Fils de l'homme en son jour.
Nítorí gẹ́gẹ́ bí mọ̀nàmọ́ná ti í kọ ní apá kan lábẹ́ ọ̀run, tí sì í mọ́lẹ̀ ní apá kejì lábẹ́ ọ̀run, bẹ́ẹ̀ ni Ọmọ Ènìyàn yóò sì rí ní ọjọ́ rẹ̀.
25 Mais il faut auparavant qu'il souffre beaucoup, et qu'il soit rejeté par cette génération.
Ṣùgbọ́n kò lè ṣàìmá kọ́ jìyà ohun púpọ̀, kí a sì kọ̀ ọ́ lọ́dọ̀ ìran yìí.
26 «Et ce qui se passa au temps de Noé, se passera de même au temps du Fils de l'homme:
“Bí ó ti rí ní ọjọ́ Noa, bẹ́ẹ̀ ni yóò rí ní ọjọ́ Ọmọ Ènìyàn.
27 on mangeait, on buvait, on prenait et l'on donnait en mariage, jusqu'au jour où Noé entra dans l'arche; et le déluge vint qui les fit tous périr.
Wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n ń gbéyàwó, wọ́n sì ń fa ìyàwó fún ni, títí ó fi di ọjọ́ ti Noa wọ inú ọkọ̀ lọ, kíkún omi sì dé, ó sì run gbogbo wọn.
28 Et comme au temps de Loth, on mangeait, on buvait, on achetait, on vendait, on plantait, on bâtissait,
“Bí ó sì ti rí ní ọjọ́ Lọti; wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n ń rà, wọ́n ń tà, wọ́n ń gbìn, wọ́n ń kọ́lé,
29 mais le jour où Loth quitta Sodome, il tomba du ciel une pluie de feu et de soufre qui les fit tous périr,
ṣùgbọ́n ní ọjọ́ náà tí Lọti jáde kúrò ní Sodomu, òjò iná àti sulfuru rọ̀ láti ọ̀run wá, ó sì run gbogbo wọn.
30 de même en sera-t-il le jour où le Fils de l'homme paraîtra.
“Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni yóò rí ní ọjọ́ náà tí Ọmọ Ènìyàn yóò farahàn.
31 «En ce jour-là, que celui qui sera sur le toit ne descende pas prendre ses effets qui sont dans la maison; de même, que celui qui est aux champs, ne revienne pas en arrière:
Ní ọjọ́ náà, ẹni tí ó bá wà lórí ilé, tí ẹrù rẹ̀ sì ń bẹ ní ilẹ̀, kí ó má ṣe sọ̀kalẹ̀ láti wá kó o; ẹni tí ó bá sì wà ní oko, kí ó má ṣe padà sẹ́yìn.
32 souvenez- vous de la femme de Loth.
Ẹ rántí aya Lọti.
33 Celui qui cherchera à conserver sa vie, la perdra; et celui qui l'aura perdue, la retrouvera.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń wá àti gba ẹ̀mí rẹ̀ là yóò sọ ọ́ nù; ẹnikẹ́ni tí ó bá sì sọ ọ́ nù yóò gbà á là.
34 Je vous le dis, en cette nuit-là, de deux personnes qui seront dans un même lit, l’une sera prise, l'autre, laissée;
Mo wí fún yín, ní òru ọjọ́ náà, ènìyàn méjì yóò wà lórí àkéte kan; a ó mú ọ̀kan, a ó sì fi èkejì sílẹ̀.
35 de deux femmes qui moudront ensemble, l'une sera prise, l'autre, laissée.»
Ènìyàn méjì yóò sì máa lọ ọlọ pọ̀; a ó mú ọ̀kan, a ó sì fi èkejì sílẹ̀.”
36 [de deux hommes qui seront aux champs; l’un sera pris, l’autre laissé].
37 Alors ses disciples prenant la parole, lui dirent: «où sera-ce, Seigneur?» Il leur répondit: «Là où sera le cadavre, là aussi s'assembleront les vautours.»
Wọ́n sì dá a lóhùn, wọ́n bi í pé, “Níbo, Olúwa?” Ó sì wí fún wọn pé, “Níbi tí òkú bá gbé wà, níbẹ̀ pẹ̀lú ni igún ìkójọpọ̀ sí.”

< Luc 17 >