< Sophonie 2 >

1 Examinez-vous, examinez-vous avec soin ô nation qui n'êtes pas aimable!
Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, àní ẹ kó ra yín jọ pọ̀ orílẹ̀-èdè tí kò ní ìtìjú,
2 Avant que le décret enfante, et que le jour passe comme de la balle; avant que l'ardeur de la colère de l'Eternel vienne sur vous, avant que le jour de la colère de l'Eternel vienne sur vous.
kí a tó pa àṣẹ náà, kí ọjọ́ náà tó kọjá bí ìyàngbò ọkà, kí gbígbóná ìbínú Olúwa tó dé bá a yín, kí ọjọ́ ìbínú Olúwa kí ó tó dé bá a yín.
3 Vous, tous les débonnaires du pays, qui faites ce qu'il ordonne, cherchez l'Eternel, cherchez la justice, cherchez la débonnaireté; peut-être serez-vous mis en sûreté au jour de la colère de l'Eternel.
Ẹ wá Olúwa, gbogbo ẹ̀yin onírẹ̀lẹ̀ ilẹ̀ náà, ẹ̀yin tí ń ṣe ohun tí ó bá pàṣẹ. Ẹ wá òdodo, ẹ wá ìrẹ̀lẹ̀ pẹ̀lú, bóyá á ó pa yín mọ́ ní ọjọ́ ìbínú Olúwa.
4 Mais Gaza sera abandonnée, et Askélon sera en désolation; on chassera [les habitants] d'Asdod en plein Midi, et Hékron sera arrachée.
Nítorí pé, a ó kọ Gasa sílẹ̀, Aṣkeloni yóò sì dahoro. Ní ọ̀sán gangan ni a ó lé Aṣdodu jáde, a ó sì fa Ekroni tu kúrò.
5 Malheur aux habitants de la contrée maritime, à la nation des Kéréthiens, la parole de l'Eternel est contre vous; Canaan, [qui es] le pays des Philistins, je te détruirai, tellement que personne n'y habitera.
Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ń gbé etí Òkun, ẹ̀yin ènìyàn ara Kereti; ọ̀rọ̀ Olúwa dojúkọ ọ́, ìwọ Kenaani, ilẹ̀ àwọn ara Filistini. “Èmi yóò pa yín run, ẹnìkan kò sì ní ṣẹ́kù nínú yín.”
6 Et la contrée maritime ne sera que cabanes, que loges de bergers, et parcs de brebis.
Ilẹ̀ náà ní etí Òkun, ni ibùgbé àwọn ará Kereti, ni yóò jẹ́ ibùjókòó fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn àti agbo àgùntàn.
7 Et cette contrée sera pour le reste de la maison de Juda; ils paîtront dans ces lieux-là, et le soir ils feront leur gîte dans les maisons d'Askélon; car l'Eternel leur Dieu les visitera, et il ramènera leurs captifs.
Agbègbè náà yóò sì jẹ́ ti ìyókù àwọn ilé Juda, níbẹ̀ ni wọn yóò sì ti rí koríko fún ẹran. Ní ilé Aṣkeloni ni wọn yóò dùbúlẹ̀ ni àṣálẹ́. Olúwa Ọlọ́run wọn yóò bẹ̀ wọn wò, yóò sì yí ìgbèkùn wọn padà.
8 J'ai ouï les insultes de Moab, et les invectives des enfants de Hammon, dont ils ont diffamé mon peuple, et l'ont bravé sur leur frontière.
“Èmi ti gbọ́ ẹ̀gàn Moabu, àti ẹlẹ́yà àwọn Ammoni, àwọn tó kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi, tí wọ́n sì ti gbé ara wọn ga sí agbègbè wọn.
9 C'est pourquoi, je suis vivant, dit l'Eternel des armées, le Dieu d'Israël, que Moab sera comme Sodome, et les enfants de Mammon comme Gomorrhe, un lieu couvert d'orties, et une carrière de sel et de désolation à jamais; les restes de mon peuple les pilleront, et les restes de [ma] nation les posséderont.
Nítorí náà, bí Èmi tí wà,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí, “nítòótọ́ Moabu yóò dàbí Sodomu, àti Ammoni yóò sì dàbí Gomorra, ibi tí ó kún fún yèrèpè, àti ìhó iyọ̀ àti ìdahoro títí láéláé. Ìyókù àwọn ènìyàn mi yóò kó wọn; àwọn tí ó sì yọ nínú ewu ní orílẹ̀-èdè mi ni yóò jogún ilẹ̀ wọn.”
10 Ceci leur arrivera en échange de leur orgueil, parce qu'ils ont usé d'insultes et de vanteries, contre le peuple de l'Eternel des armées.
Èyí ni ohun tí wọn yóò gbà padà nítorí ìgbéraga wọn, nítorí wọ́n kẹ́gàn, wọn sì ti fi àwọn ènìyàn Olúwa àwọn ọmọ-ogun ṣe ẹlẹ́yà.
11 L'Eternel sera terrible contre eux; car il amaigrira tous les dieux du pays; et on se prosternera devant lui, chacun de son lieu, même toutes les Iles des nations.
Olúwa yóò jẹ́ ìbẹ̀rù fún wọn; nígbà tí Òun bá pa gbogbo òrìṣà ilẹ̀ náà run. Orílẹ̀-èdè láti etí odò yóò máa sìn, olúkúlùkù láti ilẹ̀ rẹ̀ wá.
12 Vous aussi [habitants] de Cus, vous serez blessés à mort par mon épée.
“Ẹ̀yin Etiopia pẹ̀lú, a ó fi idà mi pa yín.”
13 Il étendra aussi sa main sur l'Aquilon, et il détruira l'Assyrie, et mettra Ninive en désolation, en un lieu aride comme un désert.
Òun yóò sì na ọwọ́ rẹ̀ sí apá àríwá, yóò sì pa Asiria run, yóò sì sọ Ninefe di ahoro, àti di gbígbẹ bí aginjù.
14 Et les troupeaux feront leur gîte au milieu d'elle, et toutes les bêtes des nations, même le cormoran, et le butor logeront dans ses porteaux, la voix des oiseaux retentira à la fenêtre, la désolation sera au seuil, parce qu'il en aura abbatu des cèdres.
Agbo ẹran yóò sì dùbúlẹ̀ ni àárín rẹ̀, àti gbogbo ẹranko àwọn orílẹ̀-èdè. Òwìwí aginjù àti ti n kígbe ẹyẹ òwìwí yóò wọ bí ẹyẹ ni ọwọ̀n rẹ̀. Ohùn wọn yóò kọrin ni ojú fèrèsé, ìdahoro yóò wà nínú ìloro ẹnu-ọ̀nà, òun yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá kedari sílẹ̀.
15 C'est là cette ville remplie de joie, qui se tenait assurée, et qui disait en son cœur; c'est moi, et il n'y en a point d'autre que moi. Comment a-t-elle été réduite en désert, pour être le gîte des bêtes? Quiconque passera près d elle se moquera, et branlera sa main.
Èyí ni ìlú aláyọ̀ tí ó ń gbé láìléwu. Ó sì sọ fun ara rẹ̀ pé, “Èmi ni, kò sì sí ẹnìkan tí ó ń bẹ lẹ́yìn mi.” Irú ahoro wo ni òun ha ti jẹ́, ibùgbé fún àwọn ẹranko igbó! Gbogbo ẹni tí ó bá kọjá ọ̀dọ̀ rẹ̀ yóò fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà, wọ́n yóò sì gbọn ẹsẹ̀ wọn.

< Sophonie 2 >