< Zacharie 9 >

1 La charge de la Parole de l'Eternel contre le pays de Hadrac, laquelle se posera sur Damas; car l'Eternel a l'œil sur les hommes et sur toutes les Tribus d'Israël.
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀. Ọ̀rọ̀ Olúwa kọjú ìjà sí Hadiraki, Damasku ni yóò sì jẹ́ ibi ìsinmi rẹ̀; nítorí ojú Olúwa ń bẹ lára ènìyàn, àti lára gbogbo ẹ̀yà Israẹli.
2 Même aussi Hamath, et Tyr, et Sidon, en seront bornées, quoique chacune d'elles soit fort sage.
Àti Hamati pẹ̀lú yóò ṣe ààlà rẹ̀ Tire àti Sidoni bí o tilẹ̀ ṣe ọlọ́gbọ́n gidigidi.
3 Car Tyr s'est bâti une forteresse, et a amoncelé l'argent comme de la poussière; et le fin or, comme la boue des rues.
Tire sì mọ odi líle fún ara rẹ̀, ó sì kó fàdákà jọ bí eruku, àti wúrà dáradára bí ẹrẹ̀ ìgboro.
4 Voici, le Seigneur l'appauvrira, et en [la] frappant il jettera sa puissance dans la mer, et elle sera consumée par le feu.
Ṣùgbọ́n, Olúwa yóò kó gbogbo ohun ìní rẹ̀ lọ, yóò sì pa agbára rẹ̀ run ní ojú Òkun, a ó sì fi iná jó o run.
5 Askelon le verra, et craindra; Gaza aussi le verra, et en sera comme en travail d'enfant; et Hékron aussi, parce que ce à quoi elle regardait, l'aura rendue confuse; et il n'y aura plus de Roi à Gaza, et Askelon ne fleurira plus.
Aṣkeloni yóò rí í, yóò sì bẹ̀rù; Gasa pẹ̀lú yóò rí í, yóò sì káàánú gidigidi, àti Ekroni: nítorí tí ìrètí rẹ̀ yóò ṣákì í. Gasa yóò pàdánù ọba rẹ̀, Aṣkeloni yóò sì di ahoro.
6 Et le bâtard habitera à Asdod; et je retrancherai l'orgueil des Philistins.
Ọmọ àlè yóò sì gbé inú Aṣdodu, Èmi yóò sì gé ìgbéraga àwọn Filistini kúrò.
7 Mais j'ôterai leur sang de la bouche de chacun d'eux, et leurs abominations d'entre leurs dents; et lui aussi sera réservé pour notre Dieu, qui sera comme chef dans Juda, et Hékron sera comme le Jébusien.
Èmi yóò sì mu ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ kúrò ni ẹnu rẹ̀, àti àwọn ohun èèwọ̀ kúrò láàrín eyín rẹ̀: ṣùgbọ́n àwọn tó ṣẹ́kù yóò jẹ́ tí Ọlọ́run wa, wọn yóò sì jẹ baálẹ̀ ní Juda, àti Ekroni ni yóò rí bí Jebusi.
8 Et je me camperai autour de ma maison, à cause de l'armée, et à cause des allants et venants; et l'exacteur ne passera plus parmi eux; car maintenant je la regarde de mes yeux.
Èmi yóò sì dó yí ilẹ̀ mi ká nítorí ogun àwọn tí wọ́n ń wá ohun tí wọn yóò bàjẹ́ kiri, kò sí aninilára tí yóò bori wọn mọ́: nítorí ni ìsinsin yìí ni mo fi ojú ṣọ́ wọn.
9 Que ta joie soit vive, fille de Sion! Jette des cris de réjouissance, fille de Jérusalem! Voici, ton Roi viendra à toi, [étant] juste, et qui se garantit par soi même, abject, et monté sur un âne, et sur un ânon, poulain d'une ânesse.
Kún fún ayọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Sioni, hó ìhó ayọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu. Wò ó, ọba rẹ ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ: òdodo ni òun, ó sì ní ìgbàlà; ó ní ìrẹ̀lẹ̀, ó sì ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àní ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
10 Et je retrancherai d'Ephraïm les chariots, et de Jérusalem les chevaux; et l'arc de la bataille sera aussi retranché, et le [Roi] parlera de paix aux nations; et sa domination s'étendra depuis une mer jusqu'à l'autre mer, et depuis le fleuve jusqu'aux bouts de la terre.
Èmi ó sì gbé kẹ̀kẹ́ kúrò ni Efraimu, àti ẹṣin ogun kúrò ni Jerusalẹmu, a ó sì ṣẹ́ ọrun ogun. Òun yóò sì kéde àlàáfíà sí àwọn kèfèrí. Ìjọba rẹ̀ yóò sì gbilẹ̀ láti Òkun dé Òkun, àti láti odò títí de òpin ayé.
11 Quant à toi aussi à cause du sang de ton alliance, je mettrai tes prisonniers hors de la fosse où il n'y a point d'eau.
Ní tìrẹ, nítorí ẹ̀jẹ̀ májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ, Èmi ó dá àwọn ìgbèkùn rẹ̀ sílẹ̀ kúrò nínú ọ̀gbun.
12 Retournez à la forteresse, vous prisonniers qui avez espérance, même aujourd'hui je t'annonce que je te rendrai le double.
Ẹ padà sínú odi agbára yín, ẹ̀yin òǹdè ti o ni ìrètí: àní lónìí yìí èmi sọ pé, èmi o san án fún ọ ni ìlọ́po méjì.
13 Après que je me serai tendu Juda [comme] un arc, et que j'aurai rempli Ephraïm [comme un carquois], et que j'aurai, ô Sion! Réveille tes enfants contre tes enfants, ô Javan! Et que je t'aurai mis comme l'épée d'un puissant homme;
Èmi ó fa Juda le bí mo ṣe fa ọrun mi le, mo sì fi Efraimu kún un, Èmi yóò gbé àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin dìde, ìwọ Sioni, sí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, ìwọ Giriki, mo ṣe ọ́ bí idà alágbára.
14 Alors l'Eternel se montrera contre eux, et ses dards partiront comme l'éclair, et le Seigneur l'Eternel, sonnera du cor, et marchera avec les tourbillons du Midi.
Olúwa yóò sì fi ara hàn ní orí wọn; ọfà rẹ̀ yóò sì jáde lọ bí mọ̀nàmọ́ná. Olúwa Olódùmarè yóò sì fọn ìpè, Òun yóò sì lọ nínú atẹ́gùn ìjì gúúsù.
15 L'Eternel des armées sera leur protecteur, et ils mangeront après avoir subjugué [ceux qui tirent] les pierres de fronde; ils boiront en menant du bruit comme des hommes ivres, ils se rempliront de vin comme un bassin, et comme les coins de l'autel.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò dáàbò bò wọ́n; wọn ó sì jẹ ni run, wọn ó sì tẹ òkúta kànnàkànnà mọ́lẹ̀; wọn ó sì mu ẹ̀jẹ̀ wọn bí wáìnì, wọn ó sì kún bí ọpọ́n, wọn ó sì rin ṣinṣin bí àwọn igun pẹpẹ.
16 Et l'Eternel leur Dieu les délivrera en ce jour-là comme étant le troupeau de son peuple; même des pierres couronnées seront élevées sur sa terre.
Olúwa Ọlọ́run wọn yóò sì gbà wọ́n là ni ọjọ́ náà bí agbo ènìyàn rẹ̀: nítorí wọn ó dàbí àwọn òkúta adé, tí a gbé sókè bí àmì lórí ilẹ̀ rẹ̀.
17 Car combien sera grande sa bonté, et sa beauté? Le froment fera croître les jeunes hommes, et le vin doux rendra ses vierges éloquentes.
Nítorí oore rẹ̀ tí tóbi tó, ẹwà rẹ̀ sì tí pọ̀! Ọkà yóò mú ọ̀dọ́mọkùnrin dárayá, àti ọtí wáìnì tuntun yóò mú àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin ṣe bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.

< Zacharie 9 >