< Zacharie 1 >

1 Le huitième mois de la seconde année de Darius, la parole de l'Eternel fut [adressée] à Zacharie, fils de Barachie, fils d'Hiddo, le Prophète, en disant:
Ní oṣù kẹjọ ọdún kejì ọba Dariusi, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah ọmọ Berekiah, ọmọ Iddo pé:
2 L'Eternel a été extrêmement indigné contre vos pères.
“Olúwa ti bínú sí àwọn baba ńlá yín.
3 C'est pourquoi tu leur diras: Ainsi a dit l'Eternel des armées: Retournez-vous vers moi, dit l'Eternel des armées; et je me retournerai vers vous, dit l'Eternel des armées.
Nítorí náà sọ fún àwọn ènìyàn. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Ẹ padà sí ọ̀dọ̀ mi,’ báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘èmi náà yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
4 Ne soyez point comme vos pères, auxquels les Prophètes qui ont été ci-devant criaient, en disant: Ainsi a dit l'Eternel des armées: Détournez-vous maintenant de votre mauvais train, et de vos mauvaises actions; mais ils n'ont pas écouté, et n'ont pas été attentifs à ce que je leur disais, dit l'Eternel.
Ẹ má dàbí àwọn baba yín, àwọn tí àwọn wòlíì ìṣáájú ti ké sí wí pé, báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín,’ àti kúrò nínú ìwà búburú yín; ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí ti èmi, ni Olúwa wí.
5 Vos pères où sont-ils? Et ces Prophètes-là devaient-ils vivre à toujours?
Àwọn baba yín, níbo ni wọ́n wà? Àti àwọn wòlíì, wọ́n ha wà títí ayé?
6 Cependant mes paroles et mes ordonnances que j'avais enjointes aux Prophètes mes serviteurs, n'ont-elles pas atteint vos pères? De sorte que, s'étant convertis, ils ont dit: Comme l'Eternel des armées avait pensé de nous faire selon notre train, et selon nos actions, ainsi nous a-t-il fait.
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi àti ìlànà mi, ti mo pa ní àṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì, kò ha tún bá àwọn baba yín? “Wọ́n sì padà wọ́n wí pé, ‘Gẹ́gẹ́ bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rò láti ṣe sí wa, gẹ́gẹ́ bi ọ̀nà wa, àti gẹ́gẹ́ bí ìṣe wa, bẹ́ẹ̀ ní o ti ṣe sí wa.’”
7 Le vingt-quatrième jour du onzième mois, qui est le mois de Sébat, en la seconde année de Darius, la parole de l'Eternel fut [adressée] à Zacharie, fils de Barachie, fils d'Hiddo, le Prophète, comme s'ensuit.
Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kọkànlá, tí ó jẹ́, oṣù Sebati, ní ọdún kejì Dariusi, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah, ọmọ Berekiah ọmọ Iddo wá, pé.
8 J'eus de nuit une vision: et voici, un homme était monté sur un cheval roux, et il se tenait entre des myrtes qui étaient en un lieu profond; et après lui il y avait des chevaux roux, des chevaux pommelés et des blancs.
Mo rí ìran kan ni òru, si wò ó, ọkùnrin kan ń gun ẹṣin pupa kan, òun sì dúró láàrín àwọn igi maritili tí ó wà ní ibi òòji; lẹ́yìn rẹ̀ sì ni ẹṣin pupa, adíkálà, àti funfun gbé wà.
9 Et je dis: Mon Seigneur! Que [signifient] ces choses? Et l’Ange qui parlait avec moi me dit: Je te montrerai ce que ces choses [signifient].
Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni wọ̀nyí olúwa mi?” Angẹli tí ń ba mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Èmi ó fi ohun tí àwọn wọ̀nyí jẹ́ hàn ọ́.”
10 Et l'homme qui se tenait entre les myrtes, répondit, et dit: Ce sont ici ceux que l'Eternel a envoyés pour parcourir la terre.
Ọkùnrin tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili sì dáhùn ó sì wí pé, “Wọ̀nyí ní àwọn tí Olúwa ti rán láti máa rìn sókè sódò ni ayé.”
11 Et ils répondirent à l'Ange de l'Eternel qui se tenait entre les myrtes, et dirent: Nous avons parcouru la terre; et voici, toute la terre est habitée, et est en repos.
Wọ́n si dá angẹli Olúwa tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili náà lóhùn pé, “Àwa ti rìn sókè sódò já ayé, àwa sí ti rí i pé gbogbo ayé wà ní ìsinmi àti àlàáfíà.”
12 Alors l'Ange de l'Eternel répondit, et dit: Eternel des armées, jusqu'à quand n'auras-tu point compassion de Jérusalem et des villes de Juda, contre lesquelles tu as été indigné pendant ces soixante et dix années?
Nígbà náà ni angẹli Olúwa náà dáhùn ó sì wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ kì yóò fi ṣàánú fún Jerusalẹmu, àti fún àwọn ìlú ńlá Juda, ti ìwọ ti bínú sí ni àádọ́rin ọdún wọ̀nyí?”
13 Et l'Eternel répondit à l'Ange qui parlait avec moi, de bonnes paroles, des paroles de consolation.
Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ rere àti ọ̀rọ̀ ìtùnú dá angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ lóhùn.
14 Puis l'Ange qui parlait avec moi, me dit: Crie, en disant: Ainsi a dit l'Eternel des armées: Je suis ému d'une grande jalousie pour Jérusalem et pour Sion.
Angẹli ti ń bá mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Ìwọ kígbe wí pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Èmi ń fi ìjowú ńlá jowú fún Jerusalẹmu àti fún Sioni.
15 Et je suis extrêmement indigné contre les nations qui sont à leur aise; car j'étais indigné pour un peu [de temps], et ils ont aidé au mal.
Èmi sì bínú púpọ̀púpọ̀ si àwọn orílẹ̀-èdè tí ó rò wí pé òun ní ààbò. Nítorí nígbà tí mo bínú díẹ̀, wọ́n ran ìparun lọ́wọ́ láti tẹ̀síwájú.’
16 C'est pourquoi ainsi a dit l'Eternel: Je me suis retourné vers Jérusalem par compassion, et ma maison sera rebâtie dans elle, dit l'Eternel des armées; et le niveau sera étendu sur Jérusalem.
“Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: ‘Mo padà tọ Jerusalẹmu wá pẹ̀lú àánú; ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, a ó kọ́ ilé mi sínú rẹ̀, a o sí ta okùn ìwọ̀n kan jáde sórí Jerusalẹmu.’
17 Crie encore, en disant: Ainsi a dit l'Eternel des armées: Mes villes regorgeront encore de biens, et l'Eternel consolera encore Sion, et élira encore Jérusalem.
“Máa ké síbẹ̀ pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘A o máa fi ìre kún ìlú ńlá mi síbẹ̀; Olúwa yóò sì máa tu Sioni nínú síbẹ̀, yóò sì yan Jerusalẹmu síbẹ̀.’”
18 Puis j'élevai mes yeux, et regardai; et voici quatre cornes.
Mo si gbé ojú sókè, mo sì rí, sì kíyèsi i, ìwo mẹ́rin.
19 Alors je dis à l'Ange qui parlait avec moi: Que veulent dire ces choses? Et il me répondit: Ce sont les cornes qui ont dissipé Juda, Israël et Jérusalem.
Mo sì sọ fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni nǹkan wọ̀nyí?” Ó si dà mí lóhùn pé, “Àwọn ìwo wọ̀nyí ni ó tí tú Juda, Israẹli, àti Jerusalẹmu ká.”
20 Puis l'Eternel me montra quatre forgerons.
Olúwa sì fi alágbẹ̀dẹ mẹ́rin kan hàn mí.
21 Et je dis: Que viennent faire ceux-ci? Et il répondit, et dit: Ce sont là les cornes qui ont dissipé Juda, tellement que personne ne levait la tête; mais ceux-ci sont venus pour les effrayer, et pour abattre les cornes des nations qui ont élevé la corne contre le pays de Juda, pour le dissiper.
Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni àwọn wọ̀nyí wá ṣe?” O sì sọ wí pé, “Àwọn wọ̀nyí ni ìwo tí ó ti tú Juda ká, tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnikẹ́ni kò fi gbé orí rẹ̀ sókè? Ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí wá láti dẹ́rùbà wọ́n, láti lé ìwo àwọn orílẹ̀-èdè jáde, ti wọ́n gbé ìwo wọn sórí ilẹ̀ Juda láti tú ènìyàn rẹ̀ ká.”

< Zacharie 1 >