< Psaumes 2 >

1 Pourquoi se mutinent les nations, et pourquoi les peuples projettent-ils des choses vaines?
Èéṣe tí àwọn orílẹ̀-èdè fi ń dìtẹ̀, àti tí àwọn ènìyàn ń ṣe rìkíṣí asán?
2 Les Rois de la terre se trouvent en personne, et les Princes consultent ensemble contre l'Eternel, et contre son Oint.
Àwọn ọba ayé péjọpọ̀ àti àwọn ìjòyè gbìmọ̀ pọ̀ sí Olúwa àti sí ẹni àmì òróró rẹ̀.
3 Rompons, [disent-ils], leurs liens, et jetons loin de nous leurs cordes.
Wọ́n sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí a fa ẹ̀wọ̀n wọn já, kí a sì ju ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ wọn nù.”
4 Celui qui habite dans les cieux se rira d'eux; le Seigneur s'en moquera.
Ẹni tí ó gúnwà lórí ìtẹ́ lọ́run rẹ́rìn-ín; Olúwa fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà.
5 Alors il leur parlera en sa colère, et il les remplira de terreur par la grandeur de son courroux.
Nígbà náà ni yóò bá wọn wí ní ìbínú rẹ̀ yóò sì dẹ́rùbà wọ́n ní ìrunú rẹ̀, ó wí pé,
6 Et moi, [dira-t-il], j'ai sacré mon Roi sur Sion, la montagne de ma Sainteté.
“Èmi ti fi ọba mi sí ipò lórí Sioni, òkè mímọ́ mi.”
7 Je vous réciterai quel a été ce sacre; l'Eternel m'a dit: tu es mon Fils, je t'ai aujourd'hui engendré.
Èmi yóò sì kéde ìpinnu Olúwa: Ó sọ fún mi pé, “Ìwọ ni ọmọ mi; lónìí, èmi ti di baba rẹ.
8 Demande-moi, et je te donnerai pour ton héritage les nations, et pour ta possession les bouts de la terre.
Béèrè lọ́wọ́ mi, Èmi yóò jẹ́ kí orílẹ̀-èdè di ìní rẹ, òpin ilé ayé yóò sì jẹ́ ogún rẹ.
9 Tu les briseras avec un sceptre de fer, et tu les mettras en pièces comme un vaisseau de potier.
Ìwọ yóò fi ọ̀pá irin ṣe àkóso wọn ìwọ yóò sì rún wọn wómúwómú bí ìkòkò amọ̀.”
10 Maintenant donc, ô Rois! ayez de l'intelligence; Juges de la terre, recevez instruction.
Nítorí náà, ẹ̀yin ọba, ẹ jẹ́ ọlọ́gbọ́n; ẹ gbọ́ ìkìlọ̀ ẹ̀yin alákòóso ayé.
11 Servez l'Eternel avec crainte, et égayez-vous avec tremblement.
Ẹ sin Olúwa pẹ̀lú ìbẹ̀rù ẹ sì máa yọ̀ pẹ̀lú ìwárìrì.
12 Baisez le Fils, de peur qu'il ne s'irrite, et que vous ne périssiez dans cette conduite, quand sa colère s'embrasera tant soit peu. Ô que bienheureux sont tous ceux qui se confient en lui!
Fi ẹnu ko ọmọ náà ní ẹnu, kí ó má ba à bínú, kí ó má ba à pa yín run ní ọ̀nà yín, nítorí ìbínú rẹ̀ lè ru sókè ní ẹ̀ẹ̀kan. Ìbùkún ni fún gbogbo àwọn tí ó fi í ṣe ibi ìsádi wọn.

< Psaumes 2 >