< Psaumes 105 >

1 Célébrez l'Eternel, invoquez son Nom, faites connaître parmi les peuples ses exploits.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
2 Chantez-lui, psalmodiez-lui, parlez de toutes ses merveilles.
Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
3 Glorifiez-vous du Nom de sa sainteté, [et] que le cœur de ceux qui cherchent l'Eternel se réjouisse.
Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
4 Recherchez l'Eternel, et sa force; cherchez continuellement sa face.
Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
5 Souvenez-vous de ses merveilles qu'il a faites, de ses miracles, et des jugements de sa bouche.
Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
6 La postérité d'Abraham sont ses serviteurs; les enfants de Jacob sont ses élus;
ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
7 Il est l'Eternel notre Dieu; ses jugements sont sur toute la terre.
Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
8 Il s'est souvenu à toujours de son alliance, de la parole qu'il a commandée en mille générations;
Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
9 Du traité qu'il a fait avec Abraham, et du serment qu'il a fait à Isaac,
májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
10 Lequel il a ratifié pour être une ordonnance à Jacob, [et] à Israël [pour] être une alliance éternelle;
Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
11 En disant: je te donnerai le pays de Canaan, pour le lot de ton héritage;
“Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
12 Encore qu'ils fussent un petit nombre de gens, et qu'ils y séjournassent peu de temps comme étrangers.
Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
13 Car ils allaient de nation en nation, et d'un Royaume vers un autre peuple.
wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
14 Il ne souffrit pas qu'aucun les opprimât: et il a même châtié des Rois pour l'amour d'eux.
Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
15 [Disant]: Ne touchez point à mes Oints, et ne faites point de mal à mes Prophètes.
“Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
16 Il appela aussi la famine sur la terre, [et] rompit tout le bâton du pain.
Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
17 Il envoya un personnage devant eux; Joseph fut vendu pour esclave.
Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
18 On lui enserra les pieds en des ceps, sa personne fut mise aux fers.
Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
19 Jusqu’au temps que sa parole fût venue, et que la parole de l'Eternel l'eût éprouvé.
títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
20 Le Roi envoya, et on le relâcha; le dominateur des peuples [envoya], et on le délia.
Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
21 Il l'établit pour maître sur sa maison, et pour dominateur sur tout son domaine;
Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
22 Pour soumettre les principaux à ses désirs, et pour instruire ses Anciens.
gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
23 Puis Israël entra en Egypte, et Jacob séjourna au pays de Cam.
Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
24 Et l'[Eternel] fit extrêmement multiplier son peuple, et le rendit plus puissant que ceux qui l'opprimaient.
Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
25 Il changea leur cœur, de sorte qu'ils eurent son peuple en haine, jusques à conspirer contre ses serviteurs.
Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
26 Il envoya Moïse son serviteur, [et] Aaron, qu'il avait élu.
Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
27 [Lesquels] accomplirent sur eux les prodiges, et les miracles qu'ils avaient eu charge de faire dans le pays de Cam.
Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
28 Il envoya les ténèbres, et fit obscurcir [l'air]; et ils ne furent point rebelles à ses ordres.
Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
29 Il convertit leurs eaux en sang, et fit mourir leurs poissons.
Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
30 Leur terre produisit en abondance des grenouilles, jusqu’au dedans des cabinets de leurs Rois.
Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
31 Il parla, et une mêlée de bêtes vint, et des poux sur tout leur pays.
Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
32 Il fit que leurs pluies furent de la grêle, [et] qu'il y eut sur leur terre un feu flamboyant.
Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
33 Il frappa leurs vignes, et leurs figuiers, et il brisa les arbres de leur pays.
Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
34 Il commanda, et les sauterelles vinrent, et des hurebecs sans nombre;
Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
35 Qui broutèrent toute l'herbe en leur pays, et qui dévorèrent le fruit de leur terroir.
wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
36 Et il frappa tout premier-né dans leur pays, qui étaient les prémices de toute leur vigueur.
Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
37 Puis il les tira dehors avec de l'or et de l'argent, et il n'y eut aucun qui chancelât parmi ses Tribus.
Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
38 L'Egypte se réjouit à leur départ; car la peur qu'ils avaient d'eux, les avait saisis.
Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
39 Il étendit la nuée pour couverture, et le feu pour éclairer la nuit.
Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
40 [Le peuple] demanda, et il fit venir des cailles, et il les rassasia du pain des cieux.
Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
41 Il ouvrit le rocher, et les eaux en coulèrent; et coururent par les lieux secs, [comme] une rivière.
Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
42 Car il se souvint de la parole de sa sainteté, laquelle il avait donnée à Abraham son serviteur.
Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
43 Et il tira dehors son peuple avec allégresse, et ses élus avec chant de joie.
Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
44 Il leur donna les pays des nations, et ils possédèrent le fruit du travail des peuples.
Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
45 Afin qu'ils gardassent ses statuts, et qu'ils observassent ses lois. Louez l'Eternel.
kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

< Psaumes 105 >