< Job 40 >

1 L'Eternel prit encore la parole, et dit:
Olúwa dá Jobu lóhùn sí pẹ̀lú, ó sì wí pé,
2 Celui qui conteste avec le Tout-puissant, lui apprendra-t-il quelque chose? Que celui qui dispute avec Dieu, réponde à ceci.
“Ẹni tí ń bá Olódùmarè wíjọ́ yóò ha kọ ní ẹ̀kọ́? Ẹni tí ń bá Ọlọ́run wí jẹ́ kí ó dáhùn!”
3 Alors Job répondit à l'Eternel, et dit:
Nígbà náà ni Jobu dá Olúwa lóhùn wá ó sì wí pé,
4 Voici, je suis un homme vil; que te répondrais-je? Je mettrai ma main sur ma bouche.
“Kíyèsi i, ẹ̀gbin ni èmi—ohun kí ni èmi ó dà? Èmi ó fi ọwọ́ mi le ẹnu mi.
5 J'ai parlé une fois, mais je ne répondrai plus; j'ai même parlé deux fois, mais je n'y retournerai plus.
Ẹ̀ẹ̀kan ní mo sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kì yóò tún sọ mọ́; lẹ́ẹ̀kejì ni, èmi kò sì le ṣe é mọ́.”
6 Et l'Eternel parla encore à Job du milieu d'un tourbillon, et lui dit:
Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àyíká wá, ó sì wí pé,
7 Ceins maintenant tes reins comme un vaillant homme; je t'interrogerai, et tu m'enseigneras.
“Di àmùrè gírí ní ẹgbẹ́ rẹ bí ọkùnrin, èmi ó bi ọ léèrè, kí ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.
8 Anéantiras-tu mon jugement? me condamneras-tu pour te justifier?
“Ìwọ ha fẹ́ mú ìdájọ́ mi di asán? Ìwọ ó sì dá mi lẹ́bi, kí ìwọ lè ṣe olódodo.
9 Et as-tu un bras comme le [Dieu] Fort? tonnes-tu de la voix comme lui?
Ìwọ ni apá bí Ọlọ́run tàbí ìwọ lè fi ohùn sán àrá bí òun?
10 Pare-toi maintenant de magnificence et de grandeur, et revêts-toi de majesté et de gloire.
Fi ọláńlá àti ọlá ìtayọ rẹ̀ ṣe ara rẹ ní ọ̀ṣọ́, tí ó sì fi ògo àti títóbi ọ̀ṣọ́ bo ara ní aṣọ.
11 Répands les ardeurs de ta colère, regarde tout orgueilleux, et l'abats.
Mú ìrunú ìbínú rẹ jáde; kíyèsí gbogbo ìwà ìgbéraga rẹ kí o sì rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
12 Regarde tout orgueilleux, abaisse-le, et froisse les méchants sur la place.
Wo gbogbo ìwà ìgbéraga, ènìyàn kí o sì rẹ ẹ sílẹ̀ kí o sì tẹ ènìyàn búburú mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.
13 Cache-les tous ensemble dans la poudre, et bande leur visage dans un lieu caché.
Sin gbogbo wọn papọ̀ nínú erùpẹ̀, kí o sì di ojú ìkọ̀kọ̀ wọn ní isà òkú.
14 Alors je te donnerai moi-même cette louange, que ta droite t'aura sauvé.
Nígbà náà ní èmi ó yìn ọ́ pé, ọwọ́ ọ̀tún ara rẹ lè gbà ọ́ là.
15 Or voilà le Béhémoth que j'ai fait avec toi; il mange le foin comme le bœuf.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi Behemoti, tí mo dá pẹ̀lú rẹ, òun a máa jẹ koríko bí ọ̀dá màlúù.
16 Voilà maintenant, sa force est en ses flancs, et sa vertu est dans le nombril de son ventre.
Wò o nísinsin yìí, agbára rẹ wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, àti ipa rẹ nínú ìṣàn ìkún rẹ.
17 Il remue sa queue, qui est comme un cèdre; les nerfs de ses épouvantements sont entrelacés.
Òun a máa jù ìrù rẹ̀ bí i igi kedari, iṣan itan rẹ̀ dìjọ pọ̀.
18 Ses os sont des barres d'airain, [et] ses menus os sont comme des barreaux de fer.
Egungun rẹ̀ ní ògùṣọ̀ idẹ, Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá irin.
19 C'est le chef-d'œuvre du [Dieu] Fort; celui qui l'a fait lui a donné son épée.
Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run; síbẹ̀ Ẹlẹ́dàá rẹ̀ fi idà rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
20 Et les montagnes lui rapportent leur revenu, et c'est là que se jouent toutes les bêtes des champs.
Nítòótọ́ òkè ńlá ńlá ní i mu ohun jíjẹ fún un wá, níbi tí gbogbo ẹranko igbó máa ṣiré ní ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀.
21 Il se couche dans les lieux où il y a de l'ombre, au milieu des roseaux et des marécages.
Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótusì, lábẹ́ eèsún àti ẹrẹ̀.
22 Les arbres touffus le couvrent de leur ombre, et les saules des torrents l'environnent.
Igi lótusì síji wọn bò o; igi arọrọ odò yí i káàkiri.
23 Voilà, il engloutit une rivière [en buvant], et il ne s'en retire pas vite; et il ne s'étonnerait pas quand le Jourdain se dégorgerait dans sa gueule.
Kíyèsi i, odò ńlá sàn jọjọ, òun kò sálọ; ó wà láìléwu bí ó bá ṣe pé odò Jordani ti ṣàn lọ sí ẹnu rẹ̀.
24 Il l'engloutit en le voyant, et son nez passe au travers des empêchements qu'il rencontre.
Ẹnìkan ha lè mú un ní ojú rẹ̀, tàbí dẹkùn fún tàbí a máa fi ọ̀kọ̀ gún imú rẹ̀?

< Job 40 >