< Job 34 >

1 Elihu donc reprit la parole, et dit:
Nígbà náà ni Elihu dáhùn, ó sì wí pé,
2 Vous sages écoutez mes discours, et vous qui avez de l'intelligence, prêtez-moi l'oreille.
“Ẹ̀yin ọlọ́gbọ́n ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, kí ẹ sì fi etí sílẹ̀ sí mi ẹ̀yin tí ẹ ní ìmòye.
3 Car l'oreille juge des discours, ainsi que le palais savoure ce que l'on mange.
Nítorí pé etí a máa dán ọ̀rọ̀ wò, bí adùn ẹnu ti ń tọ́ oúnjẹ wò.
4 Choisissons [de quoi nous devons disputer comme en] jugement, [puis] nous connaîtrons entre nous ce qui est bon.
Ẹ jẹ́ kí a mọ òye ohun tí o tọ́ fún ara wa; ẹ jẹ́ kí a mọ ohun tí ó dára láàrín wa.
5 Car Job a dit: Je suis juste, et cependant le [Dieu] Fort a mis mon droit à l'écart.
“Nítorí pé Jobu wí pé, ‘Aláìlẹ́ṣẹ̀ ni èmi; Ọlọ́run sì ti gba ìdájọ́ mi lọ.
6 Mentirais-je à mon droit? ma flèche est mortelle, sans que j'aie commis de crime.
Èmi ha purọ́ sí ẹ̀tọ́ mi bí, bí mo tilẹ̀ jẹ́ aláìjẹ̀bi, ọfà rẹ̀ kò ní àwòtán ọgbẹ́.’
7 [Mais] où y a-t-il un homme comme Job qui avale la moquerie comme de l'eau?
Ọkùnrin wo ni ó dàbí Jobu, tí ń mu ẹ̀gàn bí ẹní mú omi?
8 Qui marche en la compagnie des ouvriers d'iniquité, et qui fréquente les méchants?
Tí ń bá àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kẹ́gbẹ́ tí ó sì ń bá àwọn ènìyàn búburú rìn.
9 Car [Job] a dit, il ne sert de rien à l'homme de se plaire avec Dieu.
Nítorí ó sá ti wí pé, ‘Èrè kan kò sí fún ènìyàn, tí yóò fi máa ṣe inú dídùn sí Ọlọ́run.’
10 C'est pourquoi vous qui avez de l'intelligence écoutez-moi. A Dieu ne plaise qu'il y ait de la méchanceté dans le [Dieu] Fort, et de l'injustice dans le Tout-puissant!
“Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ fetísílẹ̀ sí mi, ẹ fi etí sí mi ẹ̀yin ènìyàn amòye: Ó di èèwọ̀ fún Ọlọ́run ti ìbá fi hùwà búburú, àti fún Olódùmarè, tí yóò fi ṣe àìṣedéédéé!
11 Car il rendra à l'homme selon son œuvre, et il fera trouver à chacun selon sa voie.
Nítorí pé ó ń sán fún ènìyàn fún gẹ́gẹ́ bi ohun tí a bá ṣe, yóò sì mú olúkúlùkù kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ipa ọ̀nà rẹ̀.
12 Certainement, le [Dieu] Fort ne déclare point méchant [l'homme de bien], et le Tout-puissant ne renverse point le droit.
Nítòótọ́ Ọlọ́run kì yóò hùwàkiwà; bẹ́ẹ̀ ni Olódùmarè kì yóò yí ìdájọ́ po.
13 Qui est-ce qui lui a donné la terre en charge? ou qui est-ce qui a placé la terre habitable toute entière?
Ta ni ó fi ìtọ́jú ayé lé e lọ́wọ́, tàbí ta ni ó fi gbogbo ayé lé e lọ́wọ́?
14 Si [Dieu] prenait garde à lui de près, il retirerait à soi son esprit et son souffle.
Bí ó bá gbé ayé rẹ̀ lé kìkì ara rẹ̀ tí ó sì gba ọkàn rẹ̀ àti ẹ̀mí rẹ̀ sọ́dọ̀ ara rẹ̀,
15 Toute chair expirerait ensemble, et l'homme retournerait dans la poudre.
gbogbo ènìyàn ni yóò parun pọ̀, ènìyàn a sì tún padà di erùpẹ̀.
16 Si donc tu as de l'intelligence, écoute ceci, prête l'oreille à ce que tu entendras de moi.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, bí ìwọ bá ní òye, gbọ́ èyí; fetísí ohùn ẹnu mi.
17 Comment celui qui n'aimerait pas à faire justice, jugerait-il le monde? et condamneras-tu comme méchant celui qui est souverainement juste?
Ẹni tí ó kórìíra òtítọ́ ha le ṣe olórí bí? Ìwọ ó ha sì dá olóòótọ́ àti ẹni ńlá lẹ́bi?
18 Dira-t-on à un Roi, qu'il est un scélérat? et aux Princes, qu'ils sont des méchants?
O ha tọ́ láti wí fún ọba pé, ‘Ènìyàn búburú ní ìwọ,’ tàbí fún àwọn ọmọ-aládé pé, ‘Ìkà ni ẹ̀yin,’
19 [Combien moins le dira-t-on à celui] qui n'a point d'égard à la personne des grands, et [qui] ne connaît point les riches pour les préférer aux pauvres, parce qu'ils sont tous l'ouvrage de ses mains.
mélòó mélòó fún ẹni tí kì í ṣe ojúsàájú àwọn ọmọ-aládé tàbí tí kò kà ọlọ́rọ̀ sí ju tálákà lọ, nítorí pé iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni gbogbo wọn í ṣe?
20 Ils mourront en un moment, et à minuit tout un peuple sera rempli de frayeur et passera; et le fort sera emporté sans qu'aucune main le frappe.
Ní ìṣẹ́jú kan ni wọn ó kú, àwọn ènìyàn á sì di yíyọ́ lẹ́nu láàrín ọ̀gànjọ́, wọn a sì kọjá lọ; a sì mú àwọn alágbára kúrò láìsí ọwọ́ ènìyàn níbẹ̀.
21 Car ses yeux sont sur les voies de chacun, et il regarde tous leurs pas.
“Nítorí pé ojú rẹ̀ ń bẹ ní ipa ọ̀nà ènìyàn, òun sì rí ìrìn rẹ̀ gbogbo.
22 Il n'y a ni ténèbres ni ombre de mort, où se puissent cacher les ouvriers d'iniquité.
Kò sí ibi òkùnkùn, tàbí òjìji ikú, níbi tí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ yóò gbé sá pamọ́ sí.
23 Mais il n'impute rien à l'homme contre la justice, lorsque l'homme vient à plaider avec le [Dieu] Fort.
Nítorí pé òun kò pẹ́ àti kíyèsi ẹnìkan, kí òun kí ó sì mú lọ sínú ìdájọ́ níwájú Ọlọ́run.
24 Il brise, par des voies incompréhensibles, les hommes puissants, et il en établit d'autres en leur place.
Òun ó sì fọ́ àwọn alágbára túútúú láìní ìwádìí, a sì fi ẹlòmíràn dípò wọn,
25 Parce qu'il connaît leurs œuvres, il [les] renverse la nuit, et sont brisés.
nítorí pé ó mọ iṣẹ́ wọn, ó sì yí wọn po ní òru, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n di ìtẹ̀mọ́lẹ̀.
26 Parce qu'ils sont méchants, il les froisse à la vue de tout le monde.
Ó kọlù wọ́n nítorí ìwà búburú wọn níbi tí àwọn ẹlòmíràn ti lè rí i,
27 A cause qu'ils se sont ainsi détournés de lui, et qu'ils n'ont considéré aucune de ses voies;
nítorí pé wọ́n padà pẹ̀yìndà sí i, wọn kò sì fiyèsí ipa ọ̀nà rẹ̀ gbogbo,
28 En sorte qu'ils ont fait monter le cri du pauvre jusqu'à lui, et qu'il a entendu la clameur des affligés.
kí wọn kí ó sì mú igbe ẹkún àwọn tálákà lọ dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, òun sì gbọ́ igbe ẹkún aláìní.
29 Que s'il donne du repos, qui est-ce qui causera du trouble? S'il cache sa face à quelqu'un, qui est-ce qui le regardera, soit qu'il s'agisse de toute une nation, ou qu'il ne s'agisse que d'un seul homme?
Ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá dákẹ́ síbẹ̀, ta ni yóò dá lẹ́bi? Nígbà tí ó bá pa ojú rẹ̀ mọ́, ta ni yóò lè rí i? Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe si orílẹ̀-èdè tàbí sí ènìyàn kan ṣoṣo;
30 Afin que l'hypocrite ne règne point, de peur qu'il ne soit un filet pour le peuple.
kí aláìwà bi Ọlọ́run kí ó má bá à jẹ ọba kí wọn kí ó má di ìdẹwò fún ènìyàn.
31 Certes, tu devrais avoir dit au [Dieu] Fort: J'ai souffert; mais je ne pécherai plus;
“Nítorí pé ẹnìkan ha lè wí fún Ọlọ́run pé, èmi jẹ̀bi, èmi kò sì ní ṣẹ̀ mọ́?
32 Et toi, [Seigneur!] enseigne-moi ce qui est au delà de ce que je vois; et si j'ai mal fait, je ne continuerai plus.
Èyí tí èmi kò rí ìwọ fi kọ́ mi bi mo bá sì dẹ́ṣẹ̀ èmi kì yóò ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́.
33 [Mais Dieu] ne te le rendra-t-il pas, puisque tu as rejeté son châtiment, quand tu as fait le choix que tu as fait? Pour moi, je ne [saurais que dire à cela]; mais toi, si tu as quelque chose à répondre, parle.
Ǹjẹ́ bí ti inú rẹ̀ ni ki òun ó san ẹ̀ṣẹ̀ padà? Ǹjẹ́ òun yóò san án padà bí ìwọ bá kọ̀ ọ́ láti jẹ́wọ́, ìwọ gbọdọ̀ yan, kì í ṣe èmi. Nítorí náà sọ ohun tí o mọ̀, pẹ̀lúpẹ̀lú ohun tí ìwọ mọ̀, sọ ọ́!
34 Les gens de bon sens diront avec moi, et tout homme sage en conviendra,
“Àwọn ènìyàn amòye yóò wí fún mi, àti pẹ̀lúpẹ̀lú ẹnikẹ́ni tí í ṣe ọlọ́gbọ́n tí ó sì gbọ́ mi pé,
35 Que Job n'a pas parlé avec connaissance, et que ses paroles non point été avec intelligence.
‘Jobu ti fi àìmọ̀ sọ̀rọ̀, ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì ṣe aláìgbọ́n.’
36 Ha! mon père, que Job soit éprouvé jusqu'à ce qu'il soit vaincu, puisqu'il a répondu comme les impies.
Ìfẹ́ mi ni kí a dán Jobu wò dé òpin, nítorí ìdáhùn rẹ̀ dàbí i ti ènìyàn búburú.
37 Car [autrement] il ajoutera péché sur péché, il battra des mains entre nous, et parlera de plus en plus contre le [Dieu] Fort.
Nítorí pe ó fi ìṣọ̀tẹ̀ kún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀; ó pàtẹ́wọ́ ní àárín wa, ó sì sọ ọ̀rọ̀ odi púpọ̀ sí Ọlọ́run.”

< Job 34 >