< Job 22 >

1 Alors Eliphas Témanite prit la parole, et dit:
Ìgbà náà ni Elifasi, ará Temani, dáhùn wí pé,
2 L'homme apportera-t-il quelque profit au [Dieu] Fort? c'est plutôt à soi-même que l'homme sage apporte du profit.
“Ènìyàn lè è ṣe rere fún Ọlọ́run? Bí ọlọ́gbọ́n ti í ṣe rere fún ara rẹ̀?
3 Le Tout-puissant reçoit-il quelque plaisir, si tu es juste? ou quelque gain, si tu marches dans l'intégrité?
Ohun ayọ̀ ha ni fún Olódùmarè pé olódodo ni ìwọ? Tàbí èrè kí ni fún un ti ìwọ mú ọ̀nà rẹ̀ pé?
4 Te reprend-il, [et] entre-t-il avec toi en jugement pour la crainte qu'il ait de toi?
“Yóò ha bá ọ wí bí, nítorí ìbẹ̀rù Ọlọ́run rẹ? Yóò ha bá ọ lọ sínú ìdájọ́ bí?
5 Ta méchanceté n'est-elle pas grande? et tes injustices ne sont-elles pas sans fin?
Ìwà búburú rẹ kò ha tóbi, àti ẹ̀ṣẹ̀ rẹ láìníye?
6 Car tu as pris sans raison le gage de tes frères; tu as ôté la robe à ceux qui étaient nus.
Nítòótọ́ ìwọ béèrè fún ààbò ni ọwọ́ arákùnrin rẹ láìnídìí, ìwọ sì tú oníhòhò ní aṣọ wọn.
7 Tu n'as pas donné de l'eau à boire à celui qui était fatigué [du chemin]; tu as refusé ton pain à celui qui avait faim.
Ìwọ kò fi omi fún aláàárẹ̀ mu, ìwọ sì háwọ́ oúnjẹ fún ẹni tí ebi ń pa.
8 La terre était à l'homme puissant, et celui qui était respecté y habitait.
Bí ó ṣe ti alágbára nì, òun ni ó ní ilẹ̀, ọlọ́lá sì tẹ̀dó sínú rẹ̀.
9 Tu as envoyé les veuves vides, et les bras des orphelins ont été cassés.
Ìwọ ti rán àwọn opó padà lọ ní ọwọ́ òfo, apá àwọn ọmọ aláìní baba ti di ṣiṣẹ́.
10 C'est pour cela que les filets sont tendus autour de toi, et qu'une frayeur subite t'épouvante.
Nítorí náà ni ìdẹ̀kùn ṣe yí ọ káàkiri, àti ìbẹ̀rù òjijì ń yọ ọ́ lẹ́nu.
11 Et les ténèbres [sont autour de toi], tellement que tu ne vois point; et le débordement des eaux te couvre.
Èéṣe tí òkùnkùn fi pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ kò fi lè ríran. Èéṣe tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi sì bò ọ́ mọ́lẹ̀.
12 Dieu n'habite-t-il pas au plus haut des cieux? Regarde donc la hauteur des étoiles; [et] combien elles sont élevées.
“Ọlọ́run kò ha jẹ́ ẹni gíga ọ̀run? Sá wo orí àwọn ìràwọ̀ bí wọ́n ti ga tó!
13 Mais tu as dit: Qu'est-ce que le [Dieu] Fort connaît? Jugera-t-il au travers des nuées obscures?
Ìwọ sì wí pé, Ọlọ́run ti ṣe mọ̀? Òun ha lè ṣe ìdájọ́ láti inú òkùnkùn wá bí?
14 Les nuées nous cachent à ses yeux, et il ne voit rien, il se promène sur le tour des cieux.
Ǹjẹ́ àwọsánmọ̀ tí ó nípọn jẹ ìbora fún un, tí kò fi lè ríran; ó sì ń rìn nínú àyíká ọ̀run.
15 [Mais] n'as-tu pas pris garde au vieux chemin dans lequel les hommes injustes ont marché?
Ǹjẹ́ ìwọ fẹ́ rin ipa ọ̀nà ìgbàanì tí àwọn ènìyàn búburú tí rìn?
16 [Et n'as-tu pas pris garde] qu'ils ont été retranchés avant le temps; et que ce sur quoi ils se fondaient s'est écoulé comme un fleuve.
A ké wọn lulẹ̀ kúrò nínú ayé láìpé ọjọ́ wọn, ìpìlẹ̀ wọn ti da bí odò ṣíṣàn.
17 Ils disaient au [Dieu] Fort: Retire-toi de nous. Mais qu'est-ce que leur faisait le Tout-puissant?
Àwọn ẹni tí ó wí fún Ọlọ́run pé, ‘Lọ kúrò lọ́dọ̀ wa! Kí ni Olódùmarè yóò ṣe fún wọn?’
18 Il avait rempli leur maison de biens. Que le conseil des méchants soit [donc] loin de moi!
Síbẹ̀ ó fi ohun rere kún ilé wọn! Ṣùgbọ́n ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí mi!
19 Les justes le verront, et s'en réjouiront, et l'innocent se moquera d'eux.
Àwọn olódodo rí ìparun wọn, wọ́n sì yọ̀, àwọn aláìlẹ́ṣẹ̀ sì fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà pé,
20 Certainement notre état n'a point été aboli, mais le feu a dévoré leur excellence.
‘Lóòtítọ́ àwọn ọ̀tá wa ni a ké kúrò, iná yóò sì jó oró wọn run.’
21 Attache-toi à lui, je te prie, et demeure en repos, par ce moyen il t'arrivera du bien.
“Fa ara rẹ súnmọ́ Ọlọ́run, ìwọ ó sì rí àlàáfíà; nípa èyí ni rere yóò wá bá ọ.
22 Reçois, je te prie, la loi de sa bouche, et mets ses paroles en ton cœur.
Èmi bẹ̀ ọ́, gba òfin láti ẹnu rẹ̀ wá, kí o sì to ọ̀rọ̀ rẹ̀ sí àyà rẹ.
23 Si tu retournes au Tout-puissant, tu seras rétabli. Chasse l'iniquité loin de ta tente.
Bí ìwọ bá yípadà sọ́dọ̀ Olódùmarè, a sì gbé ọ ró. Bí ìwọ bá sì mú ẹ̀ṣẹ̀ jìnnà réré kúrò nínú àgọ́ rẹ,
24 Et tu mettras l'or sur la poussière, et l'or d'Ophir sur les rochers des torrents.
tí ìwọ bá tẹ́ wúrà dáradára sílẹ̀, lórí erùpẹ̀ àti wúrà Ofiri lábẹ́ òkúta odò,
25 Et le Tout-puissant sera ton or, et l'argent de tes forces.
nígbà náà ní Olódùmarè yóò jẹ́ wúrà rẹ, àní yóò sì jẹ́ fàdákà fún ọ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
26 Car alors tu trouveras tes délices dans le Tout-puissant, et tu élèveras ton visage vers Dieu.
Lóòtítọ́ nígbà náà ní ìwọ ó ní inú dídùn nínú Olódùmarè, ìwọ ó sì gbé ojú rẹ sókè sọ́dọ̀ Ọlọ́run.
27 Tu le fléchiras par tes prières, et il t'exaucera, et tu lui rendras tes vœux.
Bí ìwọ bá gbàdúrà rẹ sọ́dọ̀ rẹ̀, yóò sì gbọ́ tìrẹ, ìwọ ó sì san ẹ̀jẹ́ rẹ.
28 Si tu as quelque dessein, il te réussira, et la lumière resplendira sur tes voies.
Ìwọ ó sì gbìmọ̀ ohun kan pẹ̀lú, yóò sì fi ìdí múlẹ̀ fún ọ; ìmọ́lẹ̀ yóò sì mọ́ sípa ọ̀nà rẹ.
29 Quand on aura abaissé quelqu'un, et que tu auras dit: Qu'il soit élevé; alors [Dieu] délivrera celui qui tenait les yeux baissés.
Nígbà tí ipa ọ̀nà rẹ bá lọ sísàlẹ̀, nígbà náà ni ìwọ o wí pé, ‘Ìgbésókè ń bẹ!’ Ọlọ́run yóò sì gba onírẹ̀lẹ̀ là!
30 Il délivrera celui qui n'est pas innocent, et il sera délivré par la pureté de tes mains.
Yóò gba ẹni tí kì í ṣe aláìjẹ̀bi là, a ó sì gbà á nípa mímọ́ ọwọ́ rẹ̀.”

< Job 22 >