< Job 15 >

1 Alors Eliphas Témanite prit la parole, et dit:
Ìgbà náà ní Elifasi, ará Temani, dáhùn wí pé,
2 Un homme sage proférera-t-il dans ses réponses une science aussi légère que le vent, des opinions vaines; et remplira-t-il son ventre du vent d'Orient;
“Ọlọ́gbọ́n a máa sọ̀rọ̀ ìmọ̀ asán kí ó sì máa fi afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn kún ara rẹ̀ nínú?
3 Disputant avec des discours qui ne servent de rien, et avec des paroles dont on ne peut tirer aucun profit?
Òun lè máa fi àròyé sọ̀rọ̀ tí kò ní èrè, tàbí pẹ̀lú ọ̀rọ̀ nínú èyí tí kò lè fi ṣe rere?
4 Certainement tu abolis la crainte [de Dieu], et tu anéantis peu à peu la prière qu'on doit présenter au [Dieu] Fort.
Ṣùgbọ́n ìwọ ṣá ìbẹ̀rù tì, ìwọ sì dí iṣẹ́ ìsìn lọ́nà níwájú Ọlọ́run.
5 Car ta bouche fait connaître ton iniquité, et tu as choisi un langage trompeur.
Nítorí pé ẹnu ara rẹ̀ ni ó jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ìwọ sì yàn ahọ́n alárékérekè ni ààyò.
6 C'est ta bouche qui te condamne, et non pas moi; et tes lèvres témoignent contre toi.
Ẹnu ara rẹ̀ ni ó dá lẹ́bi, kì í ṣe èmi; àní ètè ara rẹ̀ ni ó jẹ́rìí gbè ọ́.
7 Es-tu le premier homme né? ou as-tu été formé avant les montagnes?
“Ìwọ ha í ṣe ọkùnrin tí a kọ́ bí? Tàbí a ha dá ọ ṣáájú àwọn òkè?
8 As-tu été instruit dans le conseil secret de Dieu, et renfermes-tu seul la sagesse?
Ìwọ gbúròó àṣírí Ọlọ́run rí? Tàbí ìwọ ha dá ọgbọ́n dúró sọ́dọ̀ ara rẹ?
9 Que sais-tu que nous ne sachions? quelle connaissance as-tu que nous n'ayons?
Kí ni ìwọ mọ̀ tí àwa kò mọ̀? Òye kí ní ó yé ọ tí kò sí nínú wa?
10 Il y a aussi parmi nous des hommes à cheveux blancs, et des gens d'une fort grande vieillesse, il y en a même de plus âgés que ton père.
Àwọn arúgbó àti ògbólógbòó ènìyàn wà pẹ̀lú wa, tí wọ́n dàgbà ju baba rẹ lọ.
11 Les consolations du [Dieu] Fort te semblent-elles trop petites? et as-tu quelque chose de caché par-devers toi?
Ìtùnú Ọlọ́run ha kéré lọ́dọ̀ rẹ? Ọ̀rọ̀ kan sì ṣe jẹ́jẹ́ jù lọ́dọ̀ rẹ?
12 Qu'est-ce qui t'ôte le cœur, et pourquoi clignes-tu les yeux?
Èéṣe ti ọkàn rẹ fi ń ti ọ kiri, kí ni ìwọ tẹjúmọ́ tóbẹ́ẹ̀.
13 Que tu pousses ton souffle contre le [Dieu] Fort, et que tu fasses sortir de ta bouche de tels discours?
Tí ìwọ fi yí ẹ̀mí rẹ padà lòdì sí Ọlọ́run, tí ó fi ń jẹ́ ki ọ̀rọ̀kọ́rọ̀ kí ó máa bọ́ ní ẹnu rẹ̀ bẹ́ẹ̀?
14 Qu'est-ce que de l'homme [mortel], qu'il soit pur, et de celui qui est né de femme, qu'il soit juste?
“Kí ni ènìyàn tí ó fi jẹ mímọ́, àti ẹni tí a tinú obìnrin bí tí yóò fi ṣe olódodo?
15 Voici, [le Dieu fort] ne s'assure point sur ses saints, et les cieux ne se trouvent point purs devant lui;
Kíyèsi i, bi Ọlọ́run ko ba gbẹ́kẹ̀lé àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀, àní àwọn ọ̀run kò mọ́ ní ojú rẹ̀,
16 Et combien plus l'homme, qui boit l'iniquité comme l'eau, est-il abominable et impur?
mélòó mélòó ni ènìyàn, ẹni ìríra àti eléèérí, tí ń mu ẹ̀ṣẹ̀ bi ẹní mu omi.
17 Je t'enseignerai, écoute-moi, et je te raconterai ce que j'ai vu;
“Èmi ó fihàn ọ́, gbọ́ ti èmi; èyí tí èmi sì rí, òun ni èmi ó sì sọ,
18 Savoir ce que les sages ont déclaré, et qu'ils n'ont point caché; ce qu'ils avaient [reçu] de leurs pères;
ohun tí àwọn ọlọ́gbọ́n ti pa ní ìtàn láti ọ̀dọ̀ àwọn baba wọn wá, ti wọ́n kò sì fi pamọ́.
19 Eux à qui seuls la terre a été donnée, et parmi lesquels l'étranger n'est point passé.
Àwọn tí a fi ilẹ̀ ayé fún nìkan, ti àlejò kan kò sì là wọ́n kọjá.
20 Le méchant est [comme] en travail d'enfant tous les jours de sa vie, et un [petit] nombre d'années est réservé à l'homme violent.
Ènìyàn búburú ń ṣe làálàá, pẹ̀lú ìrora, ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo, àti iye ọdún ní a dá sílẹ̀ fún aninilára.
21 Un cri de frayeur est dans ses oreilles; au milieu de la paix [il croit] que le destructeur se jette sur lui.
Ìró ìbẹ̀rù ń bẹ ní etí rẹ̀; nínú ìrora ni apanirun yóò dìde sí i.
22 Il ne croit point pouvoir sortir des ténèbres; et il est toujours regardé de l'épée.
Kò gbàgbọ́ pé òun ó jáde kúrò nínú òkùnkùn; a sì ṣà á sápá kan fún idà.
23 Il court après le pain, en [disant]: où y en a-t-il? il sait que le jour de ténèbres est tout prêt, et il le touche comme avec la main.
Ó ń wò káàkiri fún oúnjẹ wí pé, níbo ní ó wà? Ó mọ̀ pé ọjọ́ òkùnkùn súnmọ́ tòsí.
24 L'angoisse et l'adversité l'épouvantent, et chacune l'accable, comme un Roi équipé pour le combat.
Ìpọ́njú pẹ̀lú ìrora ọkàn yóò mú un bẹ̀rù, wọ́n ó sì ṣẹ́gun rẹ̀ bi ọba ti ìmúra ogun.
25 Parce qu'il a élevé sa main contre le [Dieu] Fort, et qu'il s'est roidi contre le Tout-puissant;
Nítorí pé ó ti nawọ́ rẹ̀ jáde lòdì sí Ọlọ́run, ó sì múra rẹ̀ le lòdì sí Olódùmarè,
26 Il lui sautera au collet, [et] sur l'épaisseur de ses gros boucliers.
ó súre, ó sì fi ẹ̀yìn gíga, àní fi ike-kókó àpáta rẹ̀ tí ó nípọn kọlù ú.
27 Parce que la graisse aura couvert son visage, et qu'elle aura fait des replis sur son ventre.
“Nítorí tí òun fi ọ̀rá rẹ̀ bo ara rẹ̀ lójú, o sì ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀.
28 Et qu'il aura habité dans les villes détruites, et dans des maisons où il ne demeurait plus personne, et qui étaient réduites en monceaux de pierres.
Òun sì gbé inú ahoro ìlú, àti nínú ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé mọ́, tí ó múra tán láti di àlàpà.
29 Mais il n'en sera pas plus riche, car ses biens ne subsisteront point, et leur entassement ne se répandra point sur la terre.
Òun kò lé di ọlọ́rọ̀, bẹ́ẹ̀ ohun ìní rẹ̀ kò lè dúró pẹ́; bẹ́ẹ̀ kò lè mú pípé rẹ̀ dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.
30 Il ne pourra point se tirer des ténèbres; la flamme séchera ses branches encore tendres; il s'en ira par le souffle de la bouche du [Tout-puissant].
Òun kì yóò jáde kúrò nínú òkùnkùn; ọ̀wọ́-iná ni yóò jó ẹ̀ka rẹ̀, àti nípasẹ̀ ẹ̀mí ẹnu Ọlọ́run ní a ó gba kúrò.
31 Qu'il ne s'assure [donc] point sur la vanité par laquelle il a été séduit, car son changement lui sera inutile.
Kí òun kí ó má ṣe gbẹ́kẹ̀lé asán, kí ó má sì ṣe tan ara rẹ̀ jẹ. Nítorí pé asán ní yóò jásí èrè rẹ̀.
32 Ce sera fait de lui avant son temps, ses branches ne reverdiront point.
A ó mú un ṣẹ ṣáájú pípé ọjọ́ rẹ̀, ẹ̀ka rẹ̀ kì yóò sì tutù.
33 On lui ravira son aigret comme à une vigne; et on [lui] fera tomber ses boutons comme à un olivier.
Yóò dàbí àjàrà tí a gbọn èso àìpọ́n rẹ̀ dànù, yóò sì rẹ̀ ìtànná rẹ̀ dànù bí i ti igi Olifi.
34 Car la bande des hypocrites sera désolée; le feu dévorera les tentes de [ceux qui reçoivent les] présents.
Nítorí pé ayọ̀ àwọn àgàbàgebè yóò túká, iná ní yóò sì jó àgọ́ àwọn tí ó fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀.
35 Ils conçoivent le travail, et ils enfantent le tourment, et machinent dans le cœur des fraudes.
Wọ́n lóyún ìwà ìkà, wọ́n sì bí ẹ̀ṣẹ̀, ikùn wọn sì pèsè ẹ̀tàn.”

< Job 15 >