< Jérémie 28 >

1 Il arriva aussi en cette même année, au commencement du règne de Sédécias Roi de Juda, [savoir] en la quatrième année, au cinquième mois, que Hanania fils de Hazur Prophète, qui était de Gabaon, me parla dans la maison de l'Eternel, en la présence des Sacrificateurs et de tout le peuple, en disant:
Ní oṣù karùn-ún ní ọdún kan náà, ọdún kẹrin ní ìbẹ̀rẹ̀ ìṣèjọba Sedekiah ọba Juda, wòlíì Hananiah ọmọ Assuri, tí ó wá láti Gibeoni, sọ fún mi ní ilé Olúwa tí ó wà ní iwájú àwọn àlùfáà àti gbogbo ènìyàn:
2 Ainsi a dit l'Eternel des armées, le Dieu d'Israël: j'ai rompu le joug du Roi de Babylone.
“Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Èmi yóò mú àjàgà ọba Babeli rọrùn.
3 Dans deux ans accomplis je ferai rapporter en ce lieu-ci tous les vaisseaux de la maison de l'Eternel, que Nébucadnetsar Roi de Babylone a emportés de ce lieu, et transportés à Babylone.
Láàrín ọdún méjì, Èmi yóò mú gbogbo ohun èlò tí ọba Nebukadnessari; ọba Babeli kó kúrò ní ilé Olúwa tí ó sì kó lọ sí Babeli padà wá.
4 Et je ferai revenir en ce lieu-ci, dit l'Eternel, Jéchonias fils de Jéhojakim Roi de Juda, et tous ceux qui ont été transportés de Juda en Babylone; car je romprai le joug du Roi de Babylone.
Èmi á tún mú ààyè Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda padà, àti gbogbo àwọn tí ń ṣe àtìpó láti Juda ní Babeli,’ èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa pé, ‘àjàgà yín láti ọwọ́ ọba Babeli yóò rọrùn.’”
5 Alors Jérémie le Prophète parla à Hanania le Prophète, en la présence des Sacrificateurs, et en la présence de tout le peuple qui assistaient dans la maison de l'Eternel.
Wòlíì Jeremiah wí fún wòlíì Hananiah ní iwájú ọmọ àlùfáà àti àwọn ènìyàn tí wọ́n dúró ní ilé Olúwa.
6 Et Jérémie le Prophète dit: ainsi soit-il; qu'ainsi fasse l'Eternel; que l'Eternel mette en effet tes paroles que tu as prophétisées, afin qu'il fasse revenir de Babylone en ce lieu-ci les vaisseaux de la maison de l'Eternel, et tous ceux qui ont été transportés à Babylone.
Jeremiah wòlíì wí pé, “Àmín! Kí Olúwa kí ó ṣe bẹ́ẹ̀! Kí Olúwa kí ó mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ tí ìwọ sọ àsọtẹ́lẹ̀ ṣẹ, láti mú ohun èlò ilé Olúwa àti gbogbo àwọn ìgbèkùn láti ilẹ̀ Babeli padà wá sí ibí yìí.
7 Toutefois écoute maintenant cette parole que je prononce, toi et tout le peuple l'entendant.
Nísinsin yìí, ìwọ gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí tí mo sọ sí etí rẹ àti sí etí gbogbo ènìyàn.
8 Les Prophètes qui ont été avant moi et avant toi dès longtemps, ont prophétisé contre plusieurs pays, et contre de grands Royaumes, la guerre, et l'affliction, et la mortalité.
Ní ìbẹ̀rẹ̀ àwọn wòlíì tí ó ṣáájú rẹ àti èmi ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ogun, ibi àti àjàkálẹ̀ sí ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè.
9 Le Prophète qui aura prophétisé la paix, quand la parole de ce Prophète sera accomplie, ce Prophète-là sera reconnu pour avoir été véritablement envoyé par l'Eternel.
Ṣùgbọ́n, àwọn wòlíì tí ó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ àlàáfíà ni a mọ̀ gẹ́gẹ́ bí wòlíì olóòtítọ́ tí Olúwa rán, tí àsọtẹ́lẹ̀ rẹ bá wá sí ìmúṣẹ.”
10 Alors Hanania le Prophète prit le joug de dessus le cou de Jérémie le Prophète, et le rompit.
Wòlíì Hananiah gbé àjàgà ọrùn wòlíì Jeremiah kúrò, ó sì fọ́ ọ.
11 Puis Hanania parla en la présence de tout le peuple, en disant: ainsi a dit l'Eternel: entre ci et deux ans accomplis, je romprai ainsi le joug de Nébucadnetsar Roi de Babylone de dessus le cou de toutes les nations. Et Jérémie le Prophète s'en alla son chemin.
Hananiah sọ níwájú gbogbo ènìyàn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Bákan náà ni Èmi yóò fọ́ àjàgà ọrùn Nebukadnessari, ọba Babeli láàrín ọdún méjì.’” Wòlíì Jeremiah sì bá ọ̀nà tirẹ̀ lọ.
12 Mais la parole de l'Eternel fut adressée à Jérémie, après que Hanania le Prophète eut rompu le joug de dessus le cou de Jérémie le Prophète, en disant:
Láìpẹ́ ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wòlíì wá lẹ́yìn ìgbà tí wòlíì Hananiah ti gbé àjàgà kúrò ní ọrùn wòlíì Jeremiah wí pé:
13 Va, et parle à Hanania, en disant: ainsi a dit l'Eternel: tu as rompu les jougs qui étaient de bois, mais au lieu de ceux-là, fais-en qui soient de fer.
“Lọ sọ fún Hananiah, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ìwọ ti wó àjàgà onígi, ṣùgbọ́n ní ààyè wọn, wà á bá àjàgà onírin.
14 Car ainsi a dit l'Eternel des armées, le Dieu d'Israël: j'ai mis un joug de fer sur le cou de toutes ces nations, afin qu'elles soient asservies à Nébucadnetsar Roi de Babylone, car elles lui seront asservies, et je lui ai aussi donné les bêtes des champs.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Èmi yóò fi àjàgà onírin sí ọrùn gbogbo orílẹ̀-èdè láti lè máa sin Nebukadnessari ọba Babeli, àti pé gbogbo yín ni ẹ̀ ó máa sìn ín. Èmi yóò tún fún un ní àṣẹ lórí àwọn ẹranko búburú.’”
15 Puis Jérémie le Prophète dit à Hanania le prophète: écoute maintenant, ô Hanania! l'Eternel ne t'a point envoyé, mais tu as fait que ce peuple s'est confié au mensonge.
Wòlíì Jeremiah sọ fún wòlíì Hananiah pé, “Gbọ́ ọ, Hananiah! Olúwa kò rán ọ, síbẹ̀, ìwọ jẹ́ kí orílẹ̀-èdè yìí gba irọ́ gbọ́.
16 C'est pourquoi ainsi a dit l'Eternel, voici, je te chasserai de dessus la terre, [et] tu mourras cette année; car tu as parlé de révolte contre l'Eternel.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Mo ṣetán láti mú ọ kúrò nínú ayé, ní ọdún yìí ni ìwọ yóò kú nítorí o ti wàásù ọ̀tẹ̀ sí Olúwa.’”
17 Et Hanania le prophète mourut cette année-là au septième mois.
Ní oṣù keje ọdún yìí ni Hananiah wòlíì kú.

< Jérémie 28 >