< Jérémie 2 >

1 Et la parole de l'Eternel me fut [adressée], en disant:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé:
2 Va, et crie, ceux de Jérusalem l'entendant, et dis: Ainsi a dit l'Eternel: il me souvient [pour l'amour] de toi de la compassion que j'ai eue pour toi en ta jeunesse, et de l'amour de tes épousailles, quand tu venais après moi dans le désert, en un pays qu'on ne sème point.
“Lọ kí o sì kéde sí etí Jerusalẹmu pé: “Báyìí ni Olúwa wí, “‘Èmi rántí ìṣeun ìgbà èwe rẹ, ìfẹ́ ìgbéyàwó rẹ àti nígbà tí ìwọ tẹ̀lé mi nínú ijù, nínú ìyàngbẹ ilẹ̀.
3 Israël était une chose sainte à l'Eternel, c'étaient les prémices de son revenu; tous ceux qui le dévoraient étaient [trouvés] coupables, il leur en arrivait du mal, dit l'Eternel.
Israẹli jẹ́ mímọ́ sí Olúwa, àkọ́kọ́ èso ìkórè rẹ̀, gbogbo ẹnikẹ́ni tí ó jẹ run ni a ó dá lẹ́bi, ibi yóò sì wá sí orí wọn,’” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.
4 Ecoutez la parole de l'Eternel, maison de Jacob, et vous toutes les familles de la maison d'Israël:
Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ìdílé Jakọbu àti gbogbo ẹ̀yin ará ilé Israẹli.
5 Ainsi a dit l'Eternel: quelle injustice ont trouvée vos pères en moi, qu'ils se soient éloignés de moi, qu'ils aient marché après la vanité, et qu'ils soient devenus vains?
Báyìí ni Olúwa wí: “Irú àìṣedéédéé wo ni baba yín rí lọ́wọ́ mi, tí wọ́n fi jìnnà sí mi? Wọ́n tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán, àwọn fúnra wọn sì di asán.
6 Et ils n'ont point dit: où est l'Eternel qui nous a fait remonter du pays d'Egypte, qui nous a conduits par un désert, par un pays de landes et montagneux, par un pays aride et d'ombre de mort, par un pays où aucun homme n'avait passé, et où personne n'avait habité?
Wọn kò béèrè, ‘Níbo ni Olúwa wà, tí ó mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, tí ó mú wa la aginjù já, tí ó mú wa la àárín pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti ihò, ìyàngbẹ ilẹ̀ àti òkùnkùn biribiri, ilẹ̀ ibi tí ẹnikẹ́ni kò là kọjá, tí ẹnikẹ́ni kò sì tẹ̀dó sí?’
7 Car je vous ai fait entrer dans un pays de Carmel, afin que vous mangeassiez ses fruits, et de ses biens; mais sitôt que vous [y] êtes entrés, vous avez souillé mon pays, et avez rendu abominable mon héritage.
Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ ọlọ́ràá láti máa jẹ èso ibẹ̀ àti ọrọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin wọ inú rẹ̀, ẹ sì bà á jẹ́, ẹ sì sọ ogún mi di ohun ìríra.
8 Les Sacrificateurs n'ont point dit: où est l'Eternel? Et ceux qui expliquaient la Loi, ne m'ont point connu; et les pasteurs ont prévariqué contre moi, et les prophètes ont prophétisé de par Bahal, et ont marché après des choses qui ne profitent de rien.
Àwọn àlùfáà kò béèrè wí pé, ‘Níbo ni Olúwa wà?’ Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú òfin kò si mọ̀ mí, àwọn olùṣọ́ sì ṣẹ̀ sí mi. Àwọn wòlíì sì ń sọtẹ́lẹ̀ nípa òrìṣà Baali, wọ́n sì ń tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán.
9 Pour cette cause encore je plaiderai avec vous, dit l'Eternel, et je plaiderai avec les enfants de vos enfants.
“Nítorí náà, mo fi ẹ̀sùn kàn yín lẹ́ẹ̀kan sí i,” ni Olúwa wí. “Èmi ó sì fi ẹ̀sùn kan àwọn ọmọ ọwọ́ rẹ.
10 Car passez par les Îles de Kittim, et voyez; envoyez en Kédar, et considérez bien, et regardez s'il y a eu rien de tel.
Rékọjá lọ sí erékùṣù àwọn ara Kittimu, kí ẹ sì wò ó, ránṣẹ́ lọ sí ìlú Kedari, kí ẹ sì kíyèsi gidigidi; kí ẹ wò bí irú nǹkan báyìí bá ń bẹ níbẹ̀?
11 Y a-t-il aucune nation qui ait changé de dieux, lesquels toutefois ne [sont] pas dieux? Mais mon peuple a changé sa gloire en ce qui ne profite de rien.
Orílẹ̀-èdè kan ha á pa ọlọ́run rẹ̀ dà? (Síbẹ̀, wọ́n kì í ṣe iṣẹ́ ọlọ́run.) Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi ti pààrọ̀ Ọlọ́run ògo wọn fún àwọn ère tí kò níyì.
12 Cieux soyez étonnés de ceci; ayez-[en] de l'horreur, et soyez extrêmement asséchés, dit l'Eternel.
Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì kí ẹ sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù ńlá,” ni Olúwa wí.
13 Car mon peuple a fait deux maux; ils m'ont abandonné, moi [qui suis] la source des eaux vives, pour se creuser des citernes, des citernes crevassées qui ne peuvent point contenir d'eau.
“Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì, wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, Èmi orísun omi ìyè, wọ́n sì ti ṣe àmù, àmù fífọ́ tí kò lè gba omi dúró.
14 Israël est-il un esclave, ou un esclave né dans la maison? pourquoi donc a-t-il été mis au pillage?
Israẹli ha á jẹ́ ọmọ ọ̀dọ̀ ẹrú nípa ìbí? Kí ló ha a dé tí ó fi di ìkógun?
15 Les lionceaux ont rugi, et ont jeté leur cri sur lui; et on a mis leur pays en désolation, ses villes ont été brûlées, de sorte qu'il n'y a personne qui y habite.
Àwọn kìnnìún ké ramúramù; wọ́n sì ń bú mọ́ wọn. Wọ́n ti fi ilẹ̀ rẹ̀ ṣòfò; ìlú rẹ̀ ti di jíjóná, ó sì ti di ìkọ̀sílẹ̀.
16 Même les enfants de Noph, et de Taphnés te casseront le sommet de la tête.
Bákan náà, àwọn ọkùnrin Memfisi àti Tafanesi wọ́n ti fa adé orí rẹ yọ.
17 Ne t'es-tu pas fait cela parce que tu as abandonné l'Eternel ton Dieu, dans le temps qu'il te menait par le chemin?
Ẹ̀yin kò ha a ti fa èyí sórí ara yín nípa kíkọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀ nígbà tí ó tọ́ ọ lójú ọ̀nà?
18 Et maintenant, qu'as-tu affaire d'aller en Egypte pour y boire de l'eau de Sihor? et qu'as-tu affaire d'aller en Assyrie, pour y boire de l'eau du fleuve?
Kí ló dé tí o ṣe wá lọ Ejibiti láti lọ mu omi ní Ṣihori? Kí ló dé tí o sì fi lọ sí Asiria láti lọ mú omi ni odò Eufurate náà?
19 Ta malice te châtiera, et tes débauches te réprimanderont, afin que tu saches et que tu voies que c'est une chose mauvaise et amère, que tu aies abandonné l'Eternel ton Dieu, et que tu ne sois point rempli de ma frayeur, dit le Seigneur l'Eternel des armées.
Iṣẹ́ búburú yín yóò fìyà jẹ yín ìpadàsẹ́yìn rẹ yóò sì bá ọ wí mọ̀ kí o sì rí i wí pé ibi àti ohun búburú yóò sì jẹ́ tìrẹ nígbà tí o ti kọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀, ẹ kò sì ní ìbẹ̀rù fún mi,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
20 Parce que depuis longtemps j'ai brisé ton joug, et rompu tes liens, tu as dit: je ne serai plus dans la servitude; c'est pourquoi tu as erré en te prostituant sur toute haute colline, et sous tout arbre vert.
“Nígbà àtijọ́, o ti fọ́ àjàgà rẹ sọnù, ìwọ sì já ìdè rẹ; ìwọ wí pé, ‘Èmi kì yóò sìn ọ́!’ Lóòtítọ́, lórí gbogbo òkè gíga ni àti lábẹ́ igi tí ó tànkálẹ̀ ni ìwọ dùbúlẹ̀ sí gẹ́gẹ́ bí panṣágà.
21 Or je t'avais moi-même plantée [comme] une vigne exquise, de laquelle tout le plant était franc; comment donc t'es-tu changée en sarments d'une vigne abâtardie?
Èmi ti gbìn ọ́ gẹ́gẹ́ bí àjàrà ọ̀tọ̀, gẹ́gẹ́ bí ìṣúra ọlọ́lá. Báwo wá ni ìwọ ṣe yípadà sí mi di àjàrà búburú àti aláìmọ́?
22 Quand tu te laverais avec du nitre, et que tu prendrais beaucoup de savon, ton iniquité [demeurerait] encore marquée devant moi, dit le Seigneur l'Eternel.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o wẹ ara rẹ pẹ̀lú sódà tí o sì lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọṣẹ síbẹ̀síbẹ̀ èérí ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ níwájú,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
23 Comment dis-tu: je ne me suis point souillée, je ne suis point allée après les Bahalins? Regarde ton train dans la vallée, reconnais ce que tu as fait, dromadaire légère, qui ne tiens point de route certaine.
“Báwo ni ìwọ ṣe wí pé, ‘Èmi kò ṣe aláìmọ́, Èmi kò sá à tẹ̀lé àwọn Baali’? Wo bí o ṣe hùwà ní àfonífojì; wo ohun tí o ṣe. Ìwọ jẹ́ abo ìbákasẹ tí ń sá síyìn-ín sọ́hùn-ún.
24 Anesse sauvage, accoutumée au désert, humant le vent à son plaisir; et qui est-ce qui lui pourrait faire rebrousser sa course? nul de ceux qui la cherchent ne se lassera après elle, on la trouvera en son mois.
Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń gbé aginjù tí ń fa ẹ̀fúùfù ìfẹ́ sí i mu rẹ, ta ni ó le è mú dúró ní àkókò rẹ̀? Kí gbogbo àwọn akọ ẹran tí o wá a kiri kì ó má ṣe dá ara wọn lágara, nítorí wọn yóò rí ní àkókò oṣù rẹ̀.
25 Retiens ton pied, que tu ne marches déchaussée, et ton gosier, que tu ne sois altérée. Mais tu as dit: c'en est fait. Non; car j'aime les étrangers, et j'irai après eux.
Dá ẹsẹ̀ dúró láìwọ bàtà, àti ọ̀fun rẹ nínú òǹgbẹ. Ṣùgbọ́n ìwọ wí pé, ‘Asán ni! Èmi fẹ́ràn àwọn ọlọ́run àjèjì, àwọn ni èmi yóò tọ̀ lẹ́yìn.’
26 Comme le larron est confus, quand il est surpris, ainsi sont confus ceux de la maison d'Israël, eux, leurs Rois, les principaux d'entre eux, leurs Sacrificateurs, et leurs Prophètes;
“Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń dójútì olè nígbà tí a bá mú u, bẹ́ẹ̀ náà ni ojú yóò ti ilé Israẹli— àwọn ọba àti àwọn ìjòyè wọn, àwọn àlùfáà àti wòlíì wọn pẹ̀lú.
27 Qui disent au bois: tu es mon père; et à la pierre: tu m'as engendré. Car ils m'ont tourné le dos, et non pas la face; puis ils disent dans le temps de leur calamité: lève-toi, et nous délivre.
Wọ́n sọ fún igi pé, ‘Ìwọ ni baba mi,’ àti sí òkúta wí pé, ‘Ìwọ ni ó bí mi,’ wọ́n ti kọ ẹ̀yìn wọn sí mi, wọn kò kọ ojú sí mi síbẹ̀ nígbà tí wọ́n bá wà nínú ìṣòro, wọn yóò wí pé, ‘Wá kí o sì gbà wá!’
28 Et où sont tes dieux que tu t'es faits? qu'ils se lèvent pour voir s'ils te délivreront au temps de la calamité; car, ô Juda! tu as eu autant de dieux que de villes.
Níbo wá ni àwọn ọlọ́run tí ẹ ṣe fúnra yín ha a wà? Jẹ́ kí wọ́n wá kí wọ́n sì gbà yín nígbà tí ẹ bá wà nínú ìṣòro! Nítorí pé ẹ̀yin ní àwọn ọlọ́run púpọ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ṣe ni àwọn ìlú, ìwọ Juda.
29 Pourquoi plaideriez-vous contre moi? vous avez tous péché contre moi, dit l'Eternel.
“Kí ló dé tí o ṣe wá ń fi ẹ̀sùn kàn mí? Gbogbo yín ni ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi,” ni Olúwa wí.
30 J'ai frappé en vain vos enfants, ils n'ont point reçu d'instruction; votre épée a dévoré vos Prophètes, comme un lion qui ravage [tout].
“Nínú asán mo fìyà jẹ àwọn ènìyàn yín, wọn kò sì gba ìbáwí. Idà yín ti pa àwọn wòlíì yín run, gẹ́gẹ́ bí kìnnìún tí ń bú ramúramù.
31 Ô race! considérez vous-mêmes la parole de l'Eternel, [qui dit]: Ai-je été un désert à Israël? ai-je été une terre toute ténébreuse? Pourquoi mon peuple a-t-il dit: nous sommes les maîtres; nous ne viendrons plus à toi?
“Ẹ̀yin ìran yìí, ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ Olúwa: “Mo ha ti di aginjù sí Israẹli tàbí mo jẹ ilẹ̀ olókùnkùn biribiri? Èéṣe tí àwọn ènìyàn mi ṣe wí pé, ‘A ní àǹfààní láti máa rìn kiri; àwa kì yóò tọ̀ ọ́ wá mọ́?’
32 La vierge oubliera-t-elle son ornement? l'épouse ses atours? mais mon peuple m'a oublié durant des jours sans nombre.
Wúńdíá ha le gbàgbé ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, tàbí ìyàwó ohun ọ̀ṣọ́ ìgbéyàwó rẹ̀? Síbẹ̀, àwọn ènìyàn mi ti gbàgbé mi ní ọjọ́ àìníye.
33 Pourquoi rends-tu ainsi affectée ta contenance pour chercher des amoureux, en sorte que tu as même enseigné tes manières de faire aux femmes de mauvaise vie?
Ìwọ ti jẹ́ ọlọ́gbọ́n tó nípa ọ̀rọ̀ ìfẹ́! Àwọn obìnrin búburú yóò kẹ́kọ̀ọ́ nípa ọ̀nà rẹ.
34 Même dans les pans de ta robe a été trouvé le sang des âmes des pauvres innocents, que tu n'avais point surpris en fracture, mais il y a été trouvé pour toutes ces choses-là.
Lórí aṣọ rẹ ni wọ́n bá ẹ̀jẹ̀ àwọn tálákà aláìṣẹ̀, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò ká wọn mọ́ níbi tí wọ́n ti ń rùn wọlé. Síbẹ̀ nínú gbogbo èyí
35 Et tu dis: je suis innocente; quoi qu'il en soit, sa colère s'est détournée de moi. Voici, je m'en vais contester contre toi, sur ce que tu as dit: je n'ai point péché.
ìwọ sọ wí pé, ‘Èmi jẹ́ aláìṣẹ̀; kò sì bínú sí mi.’ Èmi yóò mú ìdájọ́ mi wá sórí rẹ nítorí pé ìwọ wí pé, ‘Èmi kò dẹ́ṣẹ̀.’
36 Pourquoi te donnes-tu tant de mouvement, changeant de chemin? tu seras aussi confuse d'Egypte, que tu as été confuse d'Assyrie.
Èéṣe tí ìwọ fi ń lọ káàkiri láti yí ọ̀nà rẹ padà? Ejibiti yóò dójútì ọ́ gẹ́gẹ́ bí i ti Asiria.
37 Tu sortiras même d'ici, ayant tes mains sur ta tête, parce que l'Eternel a rejeté les fondements de ta confiance, et tu n'auras aucune prospérité par eux.
Ìwọ yóò sì fi ibẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú kíkáwọ́ rẹ lé orí rẹ, nítorí pé Olúwa ti kọ̀ àwọn tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé sílẹ̀, kì yóò sí ìrànlọ́wọ́ kankan fún ọ láti ọ̀dọ̀ wọn.

< Jérémie 2 >