< Jérémie 16 >

1 Puis la parole de l'Eternel me fut adressée, en disant:
Bákan náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Tu ne prendras point de femme, et tu n'auras point de fils ni de filles en ce lieu-ci.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ìyàwó, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin níbí yìí.”
3 Car ainsi a dit l'Eternel touchant les fils et les filles qui naîtront en ce lieu-ci, et touchant leurs mères qui les auront enfantés, et touchant les pères qui les auront engendrés en ce pays;
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin tí wọ́n bá bí nílẹ̀ yìí, àti ìyá tí ó bí wọn àti baba wọn.
4 Ils mourront de maladies très douloureuses; ils ne seront point lamentés, ni ensevelis, mais ils seront sur le dessus de la terre comme du fumier, et ils seront consumés par l'épée et par la famine, et leurs corps morts seront pour viande aux oiseaux des cieux, et aux bêtes de la terre.
“Wọn yóò kú ikú ààrùn, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ fún wọn. Wọn ó dàbí ìdọ̀tí lórí ilẹ̀; wọn ó ṣègbé pẹ̀lú idà àti ìyàn. Òkú wọn yóò sì di oúnjẹ fún ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀.”
5 Même, ainsi a dit l'Eternel: n'entre point en aucune maison de deuil, et ne va point lamenter, ni te condouloir pour eux; car j'ai retiré de ce peuple, dit l'Eternel, ma paix, ma miséricorde, et mes compassions.
Nítorí báyìí ni Olúwa wí: “Má ṣe wọ ilé tí oúnjẹ ìsìnkú wà, má ṣe lọ síbẹ̀ láti káàánú tàbí ṣọ̀fọ̀, nítorí mo ti mú àlàáfíà, ìfẹ́ àti àánú mi kúrò lórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” ni Olúwa wí.
6 Et les grands et les petits mourront en ce pays; ils ne seront point ensevelis, et on ne les pleurera point, et personne ne se fera aucune incision, ni ne se rasera pour eux.
“Àti ẹni ńlá àti kékeré ni yóò ṣègbé ní ilẹ̀ yìí, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹni tí yóò fá irun orí wọn nítorí wọn.
7 On ne leur distribuera point de [pain] dans le deuil pour consoler quelqu'un d'eux au sujet d'un mort; et on ne leur donnera point à boire de la coupe de consolation pour leur père ou pour leur mère.
Kò sí ẹni tí yóò fi oúnjẹ tu àwọn tí í ṣọ̀fọ̀ nínú, kódà kì í ṣe fún baba tàbí fún ìyá, kì yóò sí ẹni tí yóò fi ohun mímu tù wọ́n nínú.
8 Aussi tu n'entreras point en aucune maison de festin afin de t'asseoir avec eux pour manger, ou pour boire.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ lọ sí ilé tí àjọyọ̀ wà, má ṣe jókòó jẹun tàbí mu ohun mímu.
9 Car ainsi a dit l'Eternel des armées, le Dieu d'Israël: voici, je m'en vais faire cesser de ce lieu-ci devant vos yeux et en vos jours, la voix de joie et la voix d'allégresse, la voix de l'époux et la voix de l'épouse.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli wí, Ní ojú yín ní ọjọ́ yín ni òpin yóò dé bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú, àti sí ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó ní ibí yìí.
10 Et il arrivera que quand tu auras prononcé à ce peuple toutes ces paroles-là, ils te diront: pourquoi l'Eternel a-t-il prononcé tout ce grand mal contre nous? et quelle est notre iniquité, et quel [est] notre péché que nous avons commis contre l'Eternel notre Dieu?
“Nígbà tí o bá sọ nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ènìyàn yìí, tí wọ́n bá sì bi ọ́ wí pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe mú búburú yìí bá wa? Kí ni àṣìṣe tí àwa ṣe? Kín ni ẹ̀ṣẹ̀ tí àwa ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa?’
11 Et tu leur diras: parce que vos pères m'ont abandonné, dit l'Eternel, et sont allés après d'autres dieux, et les ont servis, et se sont prosternés devant eux, et m'ont abandonné, et n'ont point gardé ma Loi,
Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ fún wọn wí pé, ‘Nítorí tí àwọn baba yín ti kọ̀ mí sílẹ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí wọ́n sì tẹ̀lé àwọn òrìṣà mìíràn tí wọ́n ń bọ, tí wọ́n ń sìn, wọ́n kọ̀ mí sílẹ̀ wọn kò sì tẹ̀lé òfin mi mọ́.
12 Et que vous avez encore fait pis que vos pères; car voici, chacun de vous marche après la dureté de son cœur mauvais, afin de ne m'écouter point;
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti ṣe búburú ju ti àwọn baba yín lọ. Wò ó bí gbogbo yín ṣe ń rìn, olúkúlùkù yín nínú agídí ọkàn búburú rẹ̀, dípò kí ẹ fi gbọ́ tèmi.
13 A cause de cela je vous transporterai de ce pays en un pays que vous n'avez point connu, ni vous ni vos pères; et là vous serez asservis jour et nuit à d'autres dieux, parce que je ne vous aurai point fait de grâce.
Èmi yóò gbé yin kúrò ní ilẹ̀ yìí lọ sí ilẹ̀ tí baba yín tàbí ẹ̀yin kò mọ̀ rí, níbẹ̀ ni ẹ̀yin yóò ti máa sìn ọlọ́run kéékèèké ní ọ̀sán àti òru nítorí èmi kì yóò fi ojúrere wò yín.’
14 Néanmoins voici, les jours viennent, dit l'Eternel, qu'on ne dira plus: l'Eternel [est] vivant qui a fait remonter les enfants d'Israël du pays d'Egypte;
“Nítorí náà, ọjọ́ náà ń bọ̀ wá,” ni Olúwa wí, “tí àwọn ènìyàn kò ní sọ pé, ‘Dájúdájú Olúwa wà láààyè Olúwa ń bẹ, Ẹni tí ó mú Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti.’
15 Mais, l'Eternel est vivant qui a fait remonter les enfants d'Israël du pays de l'Aquilon, et de tous les pays auxquels il les avait chassés; après que je les aurai ramenés dans leur pays, lequel j'ai donné à leurs pères.
Ṣùgbọ́n wọn yóò sọ wí pé, ‘Bí Olúwa ṣe wà nítòótọ́ tí ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ àríwá àti ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó ti lé wọn.’ Bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò dá wọn padà sí ilẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá wọn.
16 Voici, je m'en vais mander à plusieurs Pêcheurs, dit l'Eternel, et ils les pêcheront; et ensuite je m'en vais mander à plusieurs Veneurs, qui les chasseront par toutes les montagnes, et par tous les coteaux, et par tous les trous des rochers.
“Ṣùgbọ́n báyìí, Èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn apẹja púpọ̀,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì dẹ wọ́n lẹ́yìn èyí yìí èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn ọdẹ púpọ̀, wọn yóò dẹ wọ́n lórí gbogbo òkè ńlá àti òkè gíga, àti ní gbogbo pálapàla àpáta.
17 Car mes yeux sont sur tout leur train, lequel n'est point caché devant moi; ni leur iniquité n'est point celée devant mes yeux.
Ojú mi wà ní gbogbo ọ̀nà wọn, wọn kò pamọ́ fún mi bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀ṣẹ̀ wọn kò fi ara sin lójú mi.
18 Mais premièrement je leur rendrai le double de leur iniquité et de leur péché, à cause qu'ils ont souillé mon pays par leurs victimes abominables, et qu'ils ont rempli mon héritage de leurs abominations.
Èmi yóò san ẹ̀san ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn fún wọn ní ìlọ́po méjì, nítorí wọ́n ti ba ilẹ̀ mi jẹ́ pẹ̀lú àwọn ère wọn aláìlẹ́mìí, wọ́n sì fi òkú àti ohun ẹ̀gbin àti ìríra wọn kún ilẹ̀ ìní mi.”
19 Eternel, qui es ma force et ma puissance, et mon refuge au jour de la détresse, les nations viendront à toi des bouts de la terre, et diront: certes nos pères ont hérité le mensonge et la vanité, et les choses auxquelles il n'y a point de profit.
Olúwa, alágbára àti okun mi, ẹni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú, àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá láti òpin ayé wí pé, “Àwọn baba ńlá wa kò ní ohun kan bí kò ṣe ẹ̀gbin òrìṣà, ìríra tí kò dára fún wọn nínú rẹ̀.
20 L'homme se fera-t-il bien des dieux? qui toutefois ne sont point dieux.
Ṣé àwọn ènìyàn lè dá Ọlọ́run fún ara wọn bí? Bẹ́ẹ̀ ni, ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí kì í ṣe Ọlọ́run.”
21 C'est pourquoi, voici, je vais leur faire connaître à cette fois, je vais leur faire connaître ma main et ma force, et ils sauront que mon Nom est l'Eternel.
“Nítorí náà, Èmi yóò kọ́ wọn ní àkókò yìí, Èmi yóò kọ́ wọn pẹ̀lú agbára àti títóbi mi. Nígbà náà ni wọn ó mọ pé orúkọ mi ní Olúwa.

< Jérémie 16 >