< Osée 1 >

1 La parole de l'Eternel qui fut [adressée] à Osée fils de Béeri, au temps de Hozias, Jotham, Achaz et Ezéchias, Rois de Juda, et au temps de Jéroboam fils de Joas, Roi d'Israël.
Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Hosea ọmọ Beeri wá ní àkókò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah; àwọn ọba Juda àti ní àkókò ọba Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi ní Israẹli.
2 Au commencement que l'Eternel parla par Osée, l'Eternel dit à Osée: Va, prends-toi une femme débauchée, et [aie d'elle] des enfants illégitimes; car le pays ne fait que commettre adultère, [se détournant] de l'Eternel.
Nígbà tí Olúwa bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ̀rọ̀ láti ẹnu Hosea, Olúwa wí fún un pé, “Lọ, fẹ́ àgbèrè obìnrin kan fún ara rẹ, kí ó sì bí ọmọ àgbèrè fún ọ nípasẹ̀ àwọn ọkùnrin mìíràn, nítorí ilẹ̀ ti ṣẹ ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè púpọ̀ nípa yíyapa kúrò lọ́dọ̀ Olúwa.”
3 Il s'en alla donc, et prit Gomer, fille de Diblajim, laquelle conçut, et lui enfanta un fils.
Nígbà náà ni ó sì lọ, ó sì fẹ́ Gomeri ọmọbìnrin Diblaimu, ọmọbìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún un.
4 Et l'Eternel lui dit: Appelle son nom Jizréhel; car encore un peu de temps, et je visiterai le sang de Jizréhel sur la maison de Jéhu, et ferai cesser le règne de la maison d'Israël.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Hosea pé, “Pe orúkọ ọmọ náà ní Jesreeli, nítorí pé láìpẹ́ ni èmi yóò jẹ ìdílé Jehu ní ìyà fún ẹ̀jẹ̀ àwọn ènìyàn tó pa ní ìpakúpa ní Jesreeli, Èmi yóò sì mú ìjọba Israẹli wá sí òpin.
5 Et il arrivera qu'en ce jour-là je romprai l'arc d'Israël dans la vallée de Jizréhel.
Ní ọjọ́ náà ni Èmi yóò ṣẹ́ ọrun Israẹli ní àfonífojì Jesreeli.”
6 Elle conçut encore, et elle enfanta une fille, et [l'Eternel] lui dit: Appelle son nom Lo-ruhama; car je ne continuerai plus de faire miséricorde à la maison d'Israël, mais je les enlèverai entièrement.
Gomeri sì tún lóyún, ó sì bí ọmọbìnrin kan. Olúwa sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-ruhama, nítorí pé, Èmi kò ní ṣàánú fún ilé Israẹli mọ́, Èmi kò sì ní dáríjì wọ́n.
7 Mais je ferai miséricorde à la maison de Juda, et je les délivrerai par l'Eternel leur Dieu; et je ne les délivrerai point par l'arc, ni par l'épée, ni par des combats, ni par des chevaux, ni par des gens de cheval.
Síbẹ̀, èmi yóò ṣàánú fún ilé Juda, èmi ó gbà wọ́n—kì í ṣe nípa ọfà, idà tàbí ogun, ẹṣin tàbí kẹ̀kẹ́ ẹlẹ́ṣin bí kò ṣe nípa Olúwa Ọlọ́run wọn.”
8 Puis quand elle eut sevré Lo-ruhama, elle conçut, et enfanta un fils.
Lẹ́yìn ìgbà tí ó gba ọmú lẹ́nu Lo-ruhama, ó sì lóyún ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn. Nígbà náà ni
9 Et [l'Eternel] dit: Appelle son nom Lo-hammi; car vous n'êtes point mon peuple, et je ne serai point votre [Dieu].
Olúwa sì sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-Ammi, nítorí pé ẹ kì í ṣe ènìyàn mi, èmi náà kì í sì í ṣe Ọlọ́run yín.
10 Toutefois il arrivera que le nombre des enfants d'Israël sera comme le sable de la mer, qui ne se peut ni mesurer, ni compter; et il arrivera qu'au lieu où on leur aura dit: Vous êtes Lo-hammi, il leur sera dit: Vous êtes les enfants du Dieu vivant.
“Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli yóò pọ̀ bí i iyanrìn etí Òkun tí a kò le wọ́n, tí a kò sì le è kà, yóò sì ṣe. Ní ibi tí wọ́n ti sọ fún wọn pé. ‘Ẹ̀yin kì í ṣe ènìyàn mi,’ níbẹ̀ ni a ó ti máa pè wọ́n ní ‘Ọmọ Ọlọ́run alààyè.’
11 Aussi les enfants de Juda, et les enfants d'Israël seront assemblés, et ils s'établiront un Chef, et remonteront hors du pays; car la journée de Jizréhel aura été grande.
Àwọn ènìyàn Juda àti àwọn ènìyàn Israẹli yóò parapọ̀, wọn yóò sì yan olórí kan tí yóò jáde láti ilẹ̀ náà, nítorí pé ọjọ́ ńlá ni ọjọ́ Jesreeli yóò jẹ́.

< Osée 1 >