< Esdras 8 >

1 Or ce sont ici les Chefs des pères, avec le dénombrement qui fut fait selon les généalogies, de ceux qui montèrent avec moi de Babylone, pendant le règne du Roi Artaxerxes;
Wọ̀nyí ni àwọn olórí ìdílé àti àwọn tí ó fi orúkọ sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn tì wọn gòkè pẹ̀lú mi láti Babeli ní àkókò ìjọba Artasasta ọba:
2 Des enfants de Phinées, Guersom; des enfants d'Ithamar, Daniel; des enfants de David, Hattus;
nínú àwọn ọmọ Finehasi: Gerṣomu; nínú àwọn ọmọ Itamari: Daniẹli; nínú àwọn ọmọ Dafidi: Hattusi,
3 Des enfants de Sécania, qui était des enfants de Parhos, Zacharie, et avec lui, en faisant le dénombrement par leur généalogie selon les mâles, cent cinquante hommes.
nínú àwọn ọmọ Ṣekaniah; nínú àwọn ọmọ Paroṣi: Sekariah, àti pé àádọ́jọ ọkùnrin fi orúkọ sílẹ̀ pẹ̀lú rẹ;
4 Des enfants de Péhath-Moab, Eliehohénaï fils de Zérahia, et avec lui deux cents hommes;
nínú àwọn ọmọ Pahati-Moabu: Elihoenai ọmọ Serahiah àti àwọn igba ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
5 Des enfants de Sécania, le fils de Jahaziël, et avec lui trois cents hommes;
nínú àwọn ọmọ Sattu: Ṣekaniah ọmọ Jahasieli àti àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
6 Des enfants de Hadin, Hébed fils de Jonathan, et avec lui cinquante hommes;
nínú àwọn ọmọ Adini: Ebedi ọmọ Jonatani, àti àádọ́ta ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
7 Des enfants de Hélam, Esaïe, fils de Hathalia, et avec lui soixante-dix hommes;
nínú àwọn ọmọ Elamu: Jeṣaiah ọmọ Ataliah àwọn àádọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
8 Des enfants de Sépharia, Zébadia fils de Micaël, et avec lui quatre-vingts hommes;
nínú àwọn ọmọ Ṣefatia: Sebadiah ọmọ Mikaeli, àti ọgọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
9 Des enfants de Joab, Habadia fils de Jéhiël, et avec lui deux cent dix-huit hommes;
nínú àwọn ọmọ Joabu: Obadiah ọmọ Jehieli àti ogún ó lé nígba ó dín méjì ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
10 Des enfants de Sélomith, le fils de Josiphia, et avec lui cent soixante hommes;
nínú àwọn ọmọ Bani: Ṣelomiti ọmọ Josafiah, àti ọgọ́jọ ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
11 Des enfants de Bébaï, Zacharie fils de Bébaï, et avec lui vingt-huit hommes;
nínú àwọn ọmọ Bebai: Sekariah ọmọ Bebai àti ọkùnrin méjìdínlọ́gbọ̀n pẹ̀lú rẹ̀;
12 Des enfants de Hazgad, Johanan, fils de Katan, et avec lui cent et dix hommes;
nínú àwọn ọmọ Asgadi: Johanani ọmọ Hakatani, àti àádọ́fà ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
13 Des enfants d'Adonicam, les derniers, desquels les noms sont Eliphelet, Jéhiël, et Sémahia, et avec eux soixante hommes.
nínú àwọn ọmọ Adonikami: àwọn ti ó gbẹ̀yìn, tì orúkọ wọn ń jẹ́ Elifaleti, Jeieli àti Ṣemaiah, àti ọgọ́ta ọkùnrin pẹ̀lú wọn;
14 Des enfants de Bigvaï, Huthaï, Zabbud, et avec eux soixante-dix hommes.
nínú àwọn ọmọ Bigfai: Uttai àti Sakkuri, àti àádọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú wọn.
15 Et je les assemblai près de la rivière, qui se rend à Ahava, et nous y demeurâmes trois jours. Puis je pris garde au peuple et aux Sacrificateurs, et je n'y trouvai aucun des enfants de Lévi.
Èmi kó wọn jọ pọ̀ si etí odò ti ń sàn lọ sí Ahafa, a pàgọ́ síbẹ̀ fún odidi ọjọ́ mẹ́ta, nígbà ti mo wo àárín àwọn ènìyàn àti àárín àwọn àlùfáà, ń kò rí ọmọ Lefi kankan níbẹ̀.
16 Et ainsi j'envoyai d'entre les principaux Elihéser, Ariel, Sémahia, Elnathan, Jarib, Elnathan, Nathan, Zacharie, et Mésullam, avec Jojarib et Elnathan, docteurs.
Nígbà náà ni mo pe Elieseri, Arieli, Ṣemaiah, Elnatani, Jaribi, Elnatani, Natani, Sekariah, àti Meṣullamu, tí wọ́n jẹ́ olórí, àti Joiaribu àti Elnatani tí wọ́n jẹ́ onímọ̀ ìjìnlẹ̀,
17 Et je leur donnai des ordres pour Iddo, principal chef, [qui demeurait] dans le lieu de Casiphia; et je mis en leur bouche les paroles qu'ils devaient dire à Iddo, [et] à son frère, Néthiniens, dans le lieu de Casiphia, afin qu'ils nous fissent venir des ministres pour la maison de notre Dieu.
mo sì rán wọn tí àwọn ti àṣẹ sí ọ̀dọ̀ Iddo, tí ó jẹ́ olórí ní ibi ti a ń pè ni Kasifia, mo sì sọ fún wọn ohun tí wọn yóò wí fun Iddo àti àwọn Lefi arákùnrin rẹ̀, tí wọ́n jẹ́ òṣìṣẹ́ tẹmpili ní Kasifia pé, kí wọn mú àwọn ìránṣẹ́ wá sí ọ̀dọ̀ wa fún ilé Ọlọ́run wa.
18 Et ils nous amenèrent, selon que la main de notre Dieu était bonne sur nous, un homme intelligent, d'entre les enfants de Mahli, fils de Lévi, fils d'Israël; [savoir] Sérébia, avec ses fils et ses frères, [qui furent] dix-huit hommes.
Nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run wa wà lára wa, wọ́n sì mú Ṣerebiah wá fún wa, ẹni tí ó kún ojú òsùwọ̀n láti ìran Mahili, ọmọ Lefi, ọmọ Israẹli, àti àwọn ọmọ Ṣerebiah àti àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n jẹ́ ọkùnrin méjìdínlógún.
19 Et Hasabia, et avec lui Esaïe, d'entre les enfants de Mérari, ses frères, et leurs enfants, vingt hommes.
Àti Haṣabiah, pẹ̀lú Jeṣaiah láti ìran Merari, pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn ọmọ wọ́n jẹ́ ogún ọkùnrin.
20 Et des Néthiniens, que David et les principaux du peuple avaient assignés pour le service des Lévites, deux cent et vingt Néthiniens, qui furent tous nommés par leurs noms.
Wọ́n sì tún mú ogún lé nígba àwọn òṣìṣẹ́ tẹmpili wá—àwọn ènìyàn tí Dafidi àti àwọn ìjòyè rẹ̀ gbé kalẹ̀ láti ran àwọn ọmọ Lefi lọ́wọ́. Gbogbo wọn ni a ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ wọn.
21 Et je publiai là le jeûne auprès de la rivière d'Ahava, afin de nous humilier devant notre Dieu, le priant de nous donner un heureux voyage pour nous, et pour nos familles, et pour tous nos biens.
Níbẹ̀, ní ẹ̀bá odò Ahafa, mo kéde àwẹ̀, kí a ba à le rẹ ara wa sílẹ̀ níwájú Ọlọ́run, kí a sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ fún ìrìnàjò àìléwu fún wa àti àwọn ọmọ wa àti fún gbogbo ohun ìní wa.
22 Car j'eus honte de demander au Roi des forces et des gens de cheval pour nous défendre des ennemis par le chemin; à cause que nous avions dit au Roi en termes exprès: La main de notre Dieu est favorable à tous ceux qui l'invoquent; mais sa force et sa colère est contre ceux qui l'abandonnent.
Mo tijú láti béèrè lọ́wọ́ ọba fún àwọn jagunjagun orí ilẹ̀, àti ti orí ẹṣin láti dáàbò bò wá kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá ní ọ̀nà wa, nítorí àti sọ fún ọba pé, “Ọwọ́ àánú Ọlọ́run wà ní ara gbogbo ẹni tí ó gbé ojú sókè sí i, ṣùgbọ́n ìbínú ńlá rẹ wà lórí ẹni tó kọ̀ ọ́ sílẹ̀.”
23 Nous jeûnâmes donc, et nous implorâmes [le secours] de notre Dieu à cause de cela; et il fut fléchi par nos prières.
Bẹ́ẹ̀ ni a sì gbààwẹ̀, a sì bẹ̀bẹ̀ fún èyí lọ́dọ̀ Ọlọ́run wa, òun sì gbọ́ àdúrà wa.
24 Alors je séparai douze des principaux des Sacrificateurs; avec Sérébia, Hasabia, et avec eux dix de leurs frères.
Nígbà náà ni mo ya àwọn àlùfáà tó jẹ́ aṣáájú méjìlá sọ́tọ̀, pẹ̀lú Ṣerebiah, Haṣabiah àti mẹ́wàá lára àwọn arákùnrin wọn,
25 Et je leur pesai l'argent et l'or et les ustensiles, qui étaient l'offrande que le Roi, ses conseillers, ses gentilshommes, et tous ceux d'Israël qui s'[y] étaient trouvés, avaient faite à la maison de notre Dieu.
mo sì fi òsùwọ̀n wọn ọrẹ fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò tí ọba, àti ti àwọn ìgbìmọ̀, àti ti àwọn ìjòyè, àti ti gbogbo ọmọ Israẹli tí ó wà níbẹ̀, tí wọ́n gbe sílẹ̀ fún ilé Ọlọ́run wa.
26 Je leur pesai donc, et je leur délivrai six cent cinquante talents d'argent, et des plats d'argent [pesant] cent talents, et cent talents d'or.
Mo fi òsùwọ̀n wọn ẹgbẹ̀ta lé láàádọ́ta tálẹ́ǹtì fàdákà, àti ohun èlò fàdákà tí ó wọn ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì, ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì wúrà,
27 Et vingt plats d'or [montant] à mille drachmes, et deux ustensiles de cuivre resplendissant et fin, aussi précieux que s'ils eussent été d'or.
ogún ago wúrà tí iye rẹ̀ tó ẹgbẹ̀rún dariki, àti ohun èlò idẹ dáradára méjì ti ó ni iye lórí bí i wúrà.
28 Et je leur dis: Vous êtes sanctifiés à l'Eternel; et les ustensiles sont sanctifiés; et cet argent et cet or est une offrande volontaire faite à l'Eternel le Dieu de vos pères.
Mo wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin àti àwọn ohun èlò wọ̀nyí ni a ti yà sí mímọ́ fún Olúwa. Fàdákà àti wúrà sì jẹ́ ọrẹ àtinúwá sí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín.
29 Ayez-y l'œil et gardez-les, jusqu'à ce que vous les pesiez en la présence des principaux des Sacrificateurs et des Lévites, et devant les principaux des pères d'Israël à Jérusalem, dans les chambres de la maison de l'Eternel.
Ẹ máa tọ́jú wọn dáradára títí ẹ̀yin yóò fi fi òsùwọ̀n wọ̀n wọ́n jáde kúrò ni ilé Olúwa ni Jerusalẹmu ní iwájú àwọn aṣáájú, àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, àti ní iwájú olórí ìdílé gbogbo ni Israẹli.”
30 Les Sacrificateurs donc et les Lévites reçurent le poids de l'argent, et de l'or, et des ustensiles, pour les apporter à Jérusalem, dans la maison de notre Dieu.
Nígbà náà ni àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi gba fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò mímọ́ tí a ti wọ̀n jáde fún kíkó lọ sí ilé Ọlọ́run wa ní Jerusalẹmu.
31 Et nous partîmes de la rivière d'Ahava le douzième jour du premier mois, pour aller à Jérusalem; et la main de notre Dieu fut sur nous; et il nous délivra de la main des ennemis, et de [leurs] embûches sur le chemin.
Ní ọjọ́ kejìlá oṣù kìn-ín-ní ni a gbéra kúrò ní ẹ̀bá odò Ahafa láti lọ sí Jerusalẹmu. Ọwọ́ Ọlọ́run wa wà lára wa, ó sì dáàbò bò wá kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá àti àwọn adigunjalè ní ọ̀nà wa.
32 Puis nous arrivâmes à Jérusalem, et nous étant reposés trois jours,
Bẹ́ẹ̀ ni a gúnlẹ̀ sí Jerusalẹmu, níbi tí a ti sinmi fún ọjọ́ mẹ́ta.
33 Au quatrième jour nous pesâmes l'argent et l'or, et les ustensiles dans la maison de notre Dieu, et nous les délivrâmes à Mérémoth, fils d'Urija Sacrificateur, avec lequel [était] Eléazar fils de Phinées; et avec eux Jozabad fils de Jésuah, et Nohadia, fils de Binuï, Lévites.
Ní ọjọ́ kẹrin, a wọn ohun èlò fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò mímọ lé àlùfáà Meremoti ọmọ Uriah lọ́wọ́, láti inú ilé Ọlọ́run wa, Eleasari ọmọ Finehasi wà pẹ̀lú rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Lefi; Josabadi ọmọ Jeṣua àti Noadiah ọmọ Binnui wà níbẹ̀ pẹ̀lú.
34 Selon le nombre et le poids de toutes ces choses, et tout le poids en fut mis alors par écrit.
Gbogbo nǹkan ni a kà, tí a sì wọ̀n, gbogbo iye ìwọ̀n ni a sì ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ sínú ìwé ní ìgbà náà.
35 Et ceux qui avaient été transportés, [et] qui étaient retournés de la captivité, offrirent pour tout Israël, en holocauste au Dieu d'Israël, douze veaux, quatre-vingt-seize béliers, soixante-dix-sept agneaux, [et] douze boucs pour le péché; le tout en holocauste à l'Eternel.
Nígbà náà ni àwọn ìgbèkùn tí ó ti padà láti ilẹ̀ àjèjì rú ẹbọ sísun sí Ọlọ́run Israẹli: akọ màlúù méjìlá fún gbogbo Israẹli, àgbò mẹ́rìndínlọ́gọ́rùn-ún, ọ̀dọ́-àgùntàn mẹ́tàdínlọ́gọ́rin, àti òbúkọ méjìlá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀. Gbogbo èyí jẹ́ ẹbọ sísun sí Olúwa.
36 Et ils remirent les ordonnances du Roi entre les mains des Satrapes du Roi et des Gouverneurs qui étaient au deçà du fleuve, lesquels favorisèrent le peuple, et la maison de Dieu.
Wọ́n sì jíṣẹ́ àṣẹ ọba fún àwọn ìjòyè àti àwọn baálẹ̀ agbègbè Eufurate, wọ́n sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún àwọn ènìyàn àti ilé Ọlọ́run.

< Esdras 8 >