< Ézéchiel 6 >

1 La parole de l'Eternel me fut encore [adressée], en disant:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé,
2 Fils d'homme, tourne ta face contre les montagnes d'Israël, et prophétise contre elles;
“Ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn òkè Israẹli; kí o sì sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí wọn
3 Et dis: montagnes d'Israël, écoutez la parole du Seigneur l'Eternel. Ainsi a dit le Seigneur l'Eternel aux montagnes et aux coteaux, aux cours des rivières, et aux vallées: me voici, je m'en vais faire venir l'épée sur vous, et je détruirai vos hauts lieux.
wí pé, ‘Ẹ̀yin òkè Israẹli, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè. Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí ẹ̀yin òkè ńlá àti àwọn òkè kéékèèké, sí àwọn odò ṣíṣàn àti sí àfonífojì, èmi yóò mú idà wa sórí yín, èmí yóò sì pa ibi gíga yín run.
4 Et vos autels seront désolés, et les tabernacles de vos idoles seront brisés, et j'abattrai les blessés à mort d'entre vous, devant vos dieux de fiente.
Èmi yóò wó pẹpẹ yín lulẹ̀, èmi yóò sì fọ́ pẹpẹ tùràrí yín túútúú; èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn yín síwájú àwọn òrìṣà wọn.
5 Car je mettrai les cadavres des enfants d'Israël devant leurs dieux de fiente, et je disperserai vos os autour de vos autels.
Èmi yóò tẹ́ òkú àwọn ará Israẹli síwájú òrìṣà wọn, èmi yóò sì fọ́n egungun wọn yí pẹpẹ wọn ká.
6 Les villes seront désertes en toutes vos demeures, et les hauts lieux seront désolés, tellement que vos autels seront déserts et désolés, et vos dieux de fiente seront brisés, et ne seront plus; les tabernacles [de vos idoles] seront mis en pièces, et vos ouvrages seront abolis.
Gbogbo ibi tí ẹ ń gbé àti àwọn ibi gíga yín ni yóò di píparun, gbogbo pẹpẹ yín ni yóò di ahoro, àwọn òrìṣà yín yóò di fífọ́ túútúú, àwọn pẹpẹ tùràrí yín ni a ó gé lulẹ̀, gbogbo iṣẹ́ yín yóò parẹ́.
7 Et les blessés à mort tomberont parmi vous; et vous saurez que je [suis] l'Eternel.
Àwọn ènìyàn yín yóò ṣubú láàrín yín, ẹ ó sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
8 Mais j'en laisserai d'entre vous quelques-uns de reste, afin que vous ayez quelques réchappés de l'épée entre les nations, quand vous serez dispersés parmi les pays.
“‘Ṣùgbọ́n èmi yóò dá àwọn kan sí nítorí pé díẹ̀ nínú yín ni yóò bọ́ lọ́wọ́ idà, nígbà tí a bá fọ́n yín ká sí gbogbo ilẹ̀ àti orílẹ̀-èdè.
9 Et vos réchappés se souviendront de moi entre les nations parmi lesquelles ils seront captifs, parce que je me serai tourmenté à cause de leur cœur adonné à la fornication, qui s'est détourné de moi, et [à cause] de leurs yeux qui se livrent à la fornication après leurs dieux de fiente; et ils se déplairont en eux-mêmes au sujet des maux qu'ils auront faits dans toutes leurs abominations.
Àwọn ti ó bọ́ nínú yin yóò sì rántí mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè níbi tí wọn yóò dìwọ́n ní ìgbèkùn lọ, nítorí wọ́n yóò máa rántí mi bí wọ́n ti bà mí lọ́kàn jẹ́ nípa àgbèrè wọn, tí ó yà wọ́n kúrò lọ́dọ̀ mi àti nípa ojú wọn tí ó ṣàfẹ́rí àwọn òrìṣà. Wọn yóò sì ṣú ara wọn nítorí ìwà ibi tí wọ́n ti hù nípa gbogbo ìríra wọn.
10 Et ils sauront que je suis l'Eternel, [qui] n'aurai point parlé en vain de leur faire ce mal-ci.
Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa; àti pé kì í ṣe lásán ni mo ń lérí pé èmi yóò mú ìdààmú bá wọn.
11 Ainsi a dit le Seigneur l'Eternel: frappe de ta main et bats de ton pied, et dis: hélas! à cause de toutes les abominations des maux de la maison d'Israël; car ils tomberont par l'épée, par la famine, et par la mortalité.
“‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, Pàtẹ́wọ́ kí o tún fẹsẹ̀ janlẹ̀, kí o wá kígbe síta pé, “Ó ṣe!” Ilé Israẹli yóò ṣubú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn nítorí gbogbo ìwà ìríra búburú tí wọ́n hù. Wọn yóò ṣubú nípa idà àti ìyàn.
12 Celui qui sera loin mourra par la mortalité, et celui qui sera près tombera par l'épée; et celui qui sera demeuré de reste, et qui sera assiégé, mourra par la famine; ainsi je consommerai ma fureur sur eux.
Ẹni tó wà lókèèrè yóò kú pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, àti ẹni tó wà nítòsí yóò ṣubú pẹ̀lú idà, ìyàn ni yóò pa ẹni tó bá ṣẹ́kù sílẹ̀. Báyìí ni èmi yóò ṣe mú ìbínú gbígbóná mi wá sórí wọn.
13 Et vous saurez que je suis l'Eternel, quand les blessés à mort d'entre eux seront parmi leurs dieux de fiente, autour de leurs autels, sur tout coteau haut élevé, sur tous les sommets des montagnes, sous tout arbre vert, et sous tout chêne branchu, qui est le lieu auquel ils ont fait des parfums de bonne odeur à tous leurs dieux de fiente.
Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí òkú àwọn ènìyàn wọn bá wà níbẹ̀ láàrín òrìṣà wọn yí pẹpẹ wọn ká, lórí àwọn òkè gíga gbogbo, àti lórí góńgó òkè àti lábẹ́ igi tútù àti lábẹ́ igi óákù, níbi tí wọ́n ti ń fi tùràrí olóòórùn dídùn rú ẹbọ sí gbogbo òrìṣà wọn.
14 J'étendrai donc ma main sur eux, et je rendrai leur pays désolé et désert dans toutes leurs demeures, plus que le désert qui est vers Dibla; et ils sauront que je suis l'Eternel.
Èmi yóò na ọwọ́ mi jáde sí wọn láti mú kí ilẹ̀ náà ṣòfò, kí ó sì dahoro dé aṣálẹ̀ ìhà Dibila—ní gbogbo ibùgbé wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”

< Ézéchiel 6 >