< Ézéchiel 2 >

1 Et il me fut dit: Fils d'homme, tiens-toi sur tes pieds, et je parlerai avec toi.
Ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, dìde dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ. Èmi yóò bá ọ sọ̀rọ̀.”
2 Alors l'Esprit entra dans moi, après qu'on m'eut parlé, et il me releva sur mes pieds, et j'ouïs celui qui me parlait,
Bí ó ṣe ń sọ̀rọ̀, ẹ̀mí sì wọ inú mi ó mú mi dúró lórí ẹsẹ̀ mi, mo sì ń gbọ́ tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀.
3 Qui me dit: fils d'homme; je t'envoie vers les enfants d'Israël, vers des nations rebelles qui se sont rebellées contre moi; eux et leurs pères ont péché contre moi jusques à ce propre jour.
Ó sọ pé, “Ọmọ ènìyàn, mo ń rán ọ sí àwọn ọmọ Israẹli, sí ọlọ̀tẹ̀ orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi; àwọn àti baba ńlá wọn ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi títí di òní olónìí.
4 Et ce sont des enfants effrontés, et d'un cœur obstiné, vers lesquels je t'envoie; c'est pourquoi tu leur diras que le Seigneur l'Eternel a ainsi parlé.
Àwọn ènìyàn tí mo ń rán ọ sí jẹ́ aláìgbọ́ràn àti ọlọ́kàn líle. Sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí.’
5 Et soit qu'ils écoutent, ou qu'ils n'en fassent rien; car ils sont une maison rebelle, ils sauront pourtant qu'il y aura eu un Prophète parmi eux.
Bí wọn fetísílẹ̀ tàbí wọn kò fetísílẹ̀ nítorí pé wọ́n ọlọ̀tẹ̀ ilé ni wọ́n—wọn yóò mọ̀ pé wòlíì kan wà láàrín wọn.
6 Mais toi, fils d'homme, ne les crains point, et ne crains point leurs paroles; quoique des gens revêches et [dont les langues sont perçantes] comme des épines soient avec toi, et que tu demeures parmi des scorpions; ne crains point leurs paroles, et ne t'effraie point à cause d'eux, quoiqu'ils soient une maison rebelle.
Àti ìwọ, ọmọ ènìyàn, má ṣe bẹ̀rù wọn tàbí ọ̀rọ̀ ẹnu wọn. Má ṣe bẹ̀rù, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òṣùṣú àti ẹ̀gún yí ọ ká, tí o sì ń gbé àárín àwọn àkéekèe. Má ṣe bẹ̀rù ohun tí wọ́n ń sọ tàbí bẹ̀rù wọn, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọlọ̀tẹ̀ ìdílé ni wọ́n.
7 Tu leur prononceras donc mes paroles, soit qu'ils écoutent, ou qu'ils n'en fassent rien; car ils ne sont que rébellion.
Ìwọ gbọdọ̀ sọ ọ̀rọ̀ mi fún wọn, bí wọ́n gbọ́ bí wọn kọ̀ láti gbọ́ torí pé ọlọ̀tẹ̀ ni wọ́n.
8 Mais toi, fils d'homme, écoute ce que je te dis, et ne sois point rebelle, comme cette maison rebelle; ouvre ta bouche, et mange ce que je te vais donner.
Ṣùgbọ́n ìwọ, ọmọ ènìyàn, gbọ́ ohun tí mo ń sọ fún ọ. Má ṣe ṣọ̀tẹ̀ bí i ti ìdílé ọlọ́tẹ̀; la ẹnu rẹ kí o sì jẹ ohun tí mo fún ọ.”
9 Alors je regardai, et voici, une main [fut] envoyée vers moi, et voici, elle avait un rouleau de livre.
Mo sì wò, mo sì rí ọwọ́ kan tí a nà sí mi. Ìwé kíká sì wà níbẹ̀,
10 Et elle l'ouvrit devant moi, et voici, il était écrit dedans et dehors, et des lamentations, des regrets, et des malédictions y étaient écrites.
ó sì tú ìwé náà fún mi. Ní ojú àti ẹ̀yìn ìwé náà ni a kọ ìpohùnréré ẹkún, ọ̀fọ̀ àti ègún sí.

< Ézéchiel 2 >