< Amos 2 >

1 Ainsi a dit l'Eternel: à cause de trois crimes de Moab, même à cause de quatre, je ne rappellerai point cela; [mais je le ferai] parce qu'il a brûlé les os du Roi d'Edom, jusqu'à les calciner.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Moabu, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà, nítorí ó ti sun ún, di eérú, egungun ọba Edomu,
2 Et j'enverrai le feu en Moab, et il dévorera les palais de Kérijoth; et Moab mourra dans le tumulte, dans l'alarme, et au bruit du cor.
Èmi yóò rán iná sí orí Moabu èyí tí yóò jó àwọn ààfin Kerioti run. Moabu yóò sì kú pẹ̀lú ariwo pẹ̀lú igbe àti pẹ̀lú ìró ìpè.
3 Et j'exterminerai les Gouverneurs du milieu de son pays; et je tuerai ensemble avec lui tous les principaux du pays, a dit l'Eternel.
Èmi yóò ké onídàájọ́ rẹ̀ kúrò, Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn ọmọ-aládé rẹ́ nínú rẹ̀,” ni Olúwa wí.
4 Ainsi a dit l'Eternel: à cause de trois crimes de Juda, même à cause de quatre, je ne rappellerai point cela; [mais je le ferai] parce qu'ils ont rejeté la Loi de l'Eternel, et n'ont point gardé ses statuts; mais leurs mensonges, lesquels leurs pères avaient suivis, les ont fait égarer.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Juda, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀, wọn kò sì pa àwọn ìlànà rẹ̀ mọ́. Nítorí àwọn òrìṣà ti sì wọ́n lọ́nà, òrìṣà tí àwọn Baba ńlá wọn ń tẹ̀lé,
5 Et j'enverrai le feu en Juda, et il dévorera les palais de Jérusalem.
Èmi yóò rán iná sí orí Juda èyí tí yóò jó àwọn ààfin Jerusalẹmu run.”
6 Ainsi a dit l'Eternel: à cause de trois crimes d'Israël, même à cause de quatre, je ne rappellerai point cela; [mais je le ferai] parce qu'ils ont vendu le juste pour de l'argent, et le pauvre pour une paire de souliers;
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Israẹli àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Wọ́n ta olódodo fún fàdákà àti aláìní fún bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì.
7 Soupirant après la poussière de la terre pour la jeter sur la tête des chétifs; et ils pervertissent la voie des débonnaires; et le fils et le père s'en vont à une même jeune fille, pour profaner le Nom de ma sainteté.
Wọ́n fi ẹsẹ̀ tẹ orí àwọn tálákà mọ́lẹ̀, bí wọ́n ti ń tẹ erùpẹ̀ ilẹ̀ tí wọ́n ko sì ṣe òtítọ́ si àwọn tí a ni lára. Baba àti ọmọ ń wọlé tọ wúńdíá kan náà, láti ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́.
8 Et se couchent près de tout autel, sur les vêtements qu'ils ont pris en gage, et boivent dans la maison de leurs dieux le vin des condamnés.
Wọ́n dùbúlẹ̀ lẹ́bàá a pẹpẹ, lórí aṣọ tí wọ́n fi jẹ́ ẹ̀jẹ́ ní ilé òrìṣà wọn wọ́n sì mu ọtí tí wọ́n san fún ìtánràn.
9 J'ai pourtant détruit devant eux l'Amorrhéen, dont la hauteur était comme la hauteur des cèdres, et qui était fort comme les chênes; et j'ai ruiné son fruit par-dessus, et ses racines par-dessous.
“Mo pa àwọn ará Amori run níwájú wọn gíga ẹni tí ó dàbí igi kedari. Òun sì le koko bí igi óákù mo pa èso rẹ̀ run láti òkè wá àti egbò rẹ̀ láti ìsàlẹ̀ wá.
10 Je vous ai aussi tirés du pays d'Egypte, et je vous ai conduits par le désert durant quarante ans, afin que vous possédassiez le pays de l'Amorrhéen.
Èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá, mo sì sìn yín la aginjù já ní ogójì ọdún láti fi ilẹ̀ àwọn ará Amori fún un yín.
11 Davantage, j'ai suscité quelques-uns d'entre vos fils pour être Prophètes, et quelques-uns d'entre vos jeunes gens pour être Nazariens; n'est-il pas ainsi, enfants d'Israël; dit l'Eternel?
“Èmi sì tún gbé àwọn wòlíì dìde láàrín àwọn ọmọ yín àti láàrín àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín láti jẹ Nasiri èyí kò ha jẹ́ òtítọ́ bí ará Israẹli?” ni Olúwa wí.
12 Mais vous avez fait boire du vin aux Nazariens, et vous avez commandé aux Prophètes, et leur avez dit: Ne prophétisez plus.
“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin fún àwọn Nasiri ní ọtí mu e sì pàṣẹ fún àwọn wòlíì kí wọ́n má ṣe sọtẹ́lẹ̀.
13 Voici, je m'en vais fouler le lieu où vous habitez, comme un chariot plein de gerbes foule [tout par où il passe].
“Ní báyìí, èmi yóò tẹ̀ yín mọ́lẹ̀ bí kẹ̀kẹ́ tí ó kún fún ìtí ti í tẹ̀.
14 Tellement que l'homme léger ne pourra point fuir, et le fort ne pourra pas faire usage de sa vigueur, et le vaillant ne sauvera point sa vie.
Ẹni tí ó yára bí àṣá kò ní rí ọ̀nà àbáyọ alágbára kò ní le è dúró lé agbára rẹ̀ jagunjagun kì yóò le gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là.
15 Et celui qui manie l'arc, ne pourra point demeurer ferme; et celui qui est léger à la course n'échappera point; et l'homme de cheval ne sauvera point sa vie.
Tafàtafà kì yóò dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó gún ẹṣin kì yóò gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là.
16 Et le plus courageux entre les [hommes] forts s'enfuira tout nu en ce jour-là, dit l'Eternel.
Àní jagunjagun tí ó gbóyà jùlọ yóò sálọ ní ìhòhò ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí.

< Amos 2 >