< 2 Rois 17 >

1 La douzième année d'Achaz Roi de Juda, Hosée fils d'Ela [commença] à régner à Samarie sur Israël, [et il régna] neuf ans.
Ní ọdún kejìlá ọba Ahasi ará Juda, Hosea ọmọ Ela jẹ ọba Israẹli ní Samaria, ó sì jẹ fún ọdún mẹ́sàn-án.
2 Et il fit ce qui déplaît à l'Eternel, non pas toutefois comme les Rois d'Israël qui avaient été avant lui.
Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe bí i ti ọba Israẹli ẹni tí ó ti wà ṣáájú rẹ̀.
3 Salmanéser Roi des Assyriens monta contre lui, et Hosée lui fut asservi, et il lui envoyait des présents.
Ṣalamaneseri ọba Asiria wá sókè láti mú Hosea, ẹni tí ó ti jẹ fún Ṣalamaneseri ó sì ti san owó òde fún un.
4 Mais le Roi des Assyriens découvrit une conspiration en Hosée; car Hosée avait envoyé des messagers vers So, Roi d'Egypte, et il n'envoyait plus de présents tous les ans au Roi d'Assyrie; c'est pourquoi le Roi des Assyriens l'enferma, et le mit en prison.
Ṣùgbọ́n ọba Asiria rí i wí pé Hosea jẹ́ ọlọ́tẹ̀, nítorí ó ti rán oníṣẹ́ sọ́dọ̀ ọba Ejibiti, kò sì san owó òde mọ́ fún ọba Asiria, gẹ́gẹ́ bí o ti máa ń ṣe ní ọdọọdún. Nígbà náà ọba Asiria fi agbára mú ún, ó sì fi sínú túbú.
5 Le Roi des Assyriens monta par tout le pays, et monta à Samarie, et l'assiégea pendant trois ans.
Ọba Asiria gòkè wá sí gbogbo ibi ilé náà, ó sì lọ sí Samaria, ó sì dúró tí ì fún ọdún mẹ́ta.
6 La neuvième année d'Hosée, le Roi des Assyriens prit Samarie, et transporta les Israëlites en Assyrie, et les fit habiter à Chalach, et sur Chabor fleuve de Gozan, et dans les villes des Mèdes.
Ní ọdún kẹsànán ti Hosea, ọba Asiria mú Samaria ó sì kó Israẹli lọ sí Asiria. Ó sì fi wọ́n sílẹ̀ ní Hala, ní Gosani ní etí odò Habori àti ní ìlú àwọn ará Media.
7 Car il était arrivé que les enfants d'Israël avaient péché contre l'Eternel leur Dieu qui les avait fait monter hors du pays d'Egypte, de dessous la main de Pharaon Roi d'Egypte, et avaient révéré d'autres dieux.
Gbogbo eléyìí ṣẹlẹ̀ nítorí àwọn ọmọ Israẹli ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó mú wọn jáde ní Ejibiti lábẹ́ agbára Farao ọba Ejibiti. Wọ́n sin ọlọ́run mìíràn,
8 Et ils avaient suivi le train des nations que l'Eternel avait chassées de devant les enfants d'Israël, et le train des Rois d'Israël qu'ils avaient établis.
wọn si tẹ̀lé ìwà orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti gbá kúrò níwájú wọn gẹ́gẹ́ bí ìwà ti ọba Israẹli tí ó ti paláṣẹ.
9 Et les enfants d'Israël avaient fait couvertement des choses qui n'étaient point droites devant l'Eternel leur Dieu; et s'étaient bâti des hauts lieux par toutes leurs villes, depuis la tour des gardes jusqu'aux villes fortes.
Àwọn ọmọ Israẹli ṣe ohun ìríra sí Olúwa Ọlọ́run wọn kọ́ láti ilé ìṣọ́ sí ìlú tí a dáàbò bò, wọ́n kọ́ ilé gíga fún ara wọn ní gbogbo ìlú wọn.
10 Ils s'étaient dressé des statues, et [planté] des bocages, sur toutes les hautes collines et sous tout arbre verdoyant.
Wọ́n sì gbé àwọn òkúta tí a yà sọ́tọ̀ sókè àti ère òrìṣà Aṣerah lórí gbogbo igi tútù.
11 Ils avaient fait là des encensements dans tous les hauts lieux, à l'imitation des nations que l'Eternel avait chassées de devant eux; et ils avaient fait des choses méchantes pour irriter l'Eternel.
Ní gbogbo ibi gíga, wọ́n sun tùràrí gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti lé jáde níwájú wọn. Wọ́n ṣe ohun búburú tí ó rú ìbínú Olúwa sókè.
12 Et ils avaient servi les dieux de fiente, au sujet desquels l'Eternel leur avait dit: Vous ne ferez point cela.
Wọ́n sìn òrìṣà, èyí tí Olúwa ti sọ pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe èyí.”
13 Et l'Eternel avait sommé Israël et Juda par le moyen de tous les Prophètes, ayant toute sorte de vision, en disant: Détournez-vous de toutes vos méchantes voies; retournez, et gardez mes commandements, et mes statuts, selon toute la Loi que j'ai commandée à vos pères, et que je vous ai envoyée par mes serviteurs les Prophètes.
Olúwa kìlọ̀ fún Israẹli àti Juda nípa gbogbo àwọn wòlíì wọn àti aríran: “Ẹ yípadà kúrò ní ọ̀nà búburú yín. Kí ẹ ṣe òfin mi àti ìlànà mi, ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo òfin tí Èmi paláṣẹ fún àwọn baba yín láti tẹ̀lé àti èyí tí mo rán sí i yín nípa ìránṣẹ́ àwọn wòlíì mi.”
14 Mais ils n'avaient point écouté, et ils avaient roidi leur cou, comme leurs pères [avaient roidi] leur cou, lesquels n'avaient point cru à l'Eternel leur Dieu.
Ṣùgbọ́n wọn kò ní gbọ́, wọ́n sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ọlọ́rùn líle gẹ́gẹ́ bí i ti baba wọn, ẹni tí kò gbà Olúwa Ọlọ́run wọn gbọ́.
15 Et ils avaient dédaigné ses statuts, et son alliance, qu'il avait traitée avec leurs pères, et ses témoignages, par lesquels il les avait sommés, et avaient marché après la vanité, et étaient devenus vains, et avaient suivi les nations qui étaient autour d'eux, touchant lesquelles l'Eternel avait commandé qu'ils ne fissent point comme elles.
Wọ́n kọ̀ ìlànà rẹ̀ àti májẹ̀mú tí ó ti ṣe pẹ̀lú baba wọn àti ìkìlọ̀ tí ó ti fi fún wọn. Wọ́n tẹ̀lé òrìṣà aláìníláárí, àwọn fún rara wọn sì jẹ́ aláìníláárí. Wọ́n tẹ̀lé orílẹ̀-èdè tí ó yí wọn ká bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti kìlọ̀ fún wọn pé, “Má ṣe ṣe gẹ́gẹ́ bí wọn tí ń ṣe,” wọ́n sì ṣe ohun tí Olúwa ti kà léèwọ̀ fún wọn láti ṣe.
16 Et ayant abandonné tous les commandements de l'Eternel leur Dieu, ils s'étaient fait des simulacres de fonte, [c'est-à-dire] deux veaux, et avaient planté des bocages, et s'étaient prosternés devant toute l'armée des cieux, et avaient servi Bahal.
Wọ́n kọ̀ gbogbo òfin Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, wọ́n sì ṣe òrìṣà méjì fún ara wọn, wọ́n sì gbẹ́ ẹ ọ̀kan ní ère ẹgbọrọ màlúù, àti ọ̀kan ní ère òrìṣà Aṣerah. Wọ́n sì tẹrí wọn ba sí gbogbo ogun ọ̀run, wọ́n sì sin Baali.
17 Ils avaient fait aussi passer leurs fils, et leurs filles par le feu, et s'étaient adonnés aux divinations, et aux enchantements, et s'étaient vendus pour faire ce qui déplaît à l'Eternel afin de l'irriter.
Wọ́n sì fi àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn rú ẹbọ nínú iná. Wọ́n sì ń fọ àfọ̀ṣẹ, wọ́n sì ń ṣe àlúpàyídà wọ́n sì ta ara wọn láti ṣe ohun búburú níwájú Olúwa, wọ́n sì mú un bínú.
18 C'est pourquoi l'Eternel fut fort irrité contre Israël, et il les rejeta, en sorte qu'il n'y eut que la seule Tribu de Juda, qui restât.
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì bínú gidigidi pẹ̀lú Israẹli ó sì mú wọn kúrò níwájú rẹ̀. Ẹ̀yà Juda nìkan ṣoṣo ni ó kù,
19 Et même Juda ne garda point les commandements de l'Eternel son Dieu, mais ils marchèrent dans les ordonnances qu'Israël avait établies.
àti pẹ̀lú, Juda kò pa òfin Olúwa Ọlọ́run wọn mọ́. Wọ́n tẹ̀lé ìhùwàsí àwọn Israẹli tí wọ́n ṣe.
20 C'est pourquoi l'Eternel rejeta toute la race d'Israël, car il les affligea, et les livra entre les mains de ceux qui les pillaient, jusqu'à ce qu'il les eût rejetés de devant sa face.
Nítorí náà Olúwa kọ gbogbo àwọn ènìyàn Israẹli; ó sì jẹ wọ́n ní yà. Ó sì fi wọ́n lé ọwọ́ àwọn olè títí tí ó fi ta wọ́n nù kúrò níwájú rẹ̀.
21 Parce qu'Israël s'était retranché de la maison de David, et avait établi Roi Jéroboam fils de Nébat, car Jéroboam avait débauché Israël, afin qu'il ne suivît plus l'Eternel, et leur avait fait commettre un grand péché.
Nígbà tí ó ta Israẹli kúrò láti ìdílé Dafidi, wọ́n sì mú Jeroboamu ọmọ Nebati jẹ ọba wọn. Jeroboamu sì mú kí àwọn ọmọ Israẹli yípadà kúrò ní títẹ̀lé Olúwa, ó sí mú kí wọn dẹ́ṣẹ̀ ńlá.
22 C'est pourquoi les enfants d'Israël marchèrent dans tous les péchés que Jéroboam avait faits, et ils ne s'en sont point retirés.
Àwọn ọmọ Israẹli forítì í nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu kò sì yí padà kúrò lọ́dọ̀ wọn,
23 Jusqu'à ce que l'Eternel les a rejetés de devant soi, selon qu'il en avait parlé par le moyen de tous ses serviteurs les Prophètes; et Israël a été transporté de dessus la terre en Assyrie, jusqu'à ce jour.
títí tí Olúwa fi mú wọn kúrò níwájú rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ó ti paláṣẹ láti ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ wòlíì. Bẹ́ẹ̀ ni a kó gbogbo ènìyàn Israẹli kúrò ní ilẹ̀ wọn lọ sí ìgbèkùn ni Asiria, títí di òní yìí.
24 Et le Roi des Assyriens fit venir des gens de Babel, et de Cuth, et de Hava, et de Hamath, et de Sépharvajim, et les fit habiter dans les villes de Samarie, en la place des enfants d'Israël; et ils possédèrent la Samarie, et ils habitèrent dans ses villes.
Ọba Asiria mú àwọn ènìyàn láti Babeli, Kuta, Afa, Hamati àti Sefarfaimi, wọ́n sì fi wọ́n sínú ìlú Samaria láti rọ́pò àwọn ọmọ Israẹli. Wọ́n sì ń gbé ní ìlú náà.
25 Or il arriva qu'au commencement qu'ils habitèrent là, ils ne révérèrent point l'Eternel, et l'Eternel envoya contr'eux des lions, qui les tuaient.
Nígbà tí wọ́n gbé bẹ̀ ní àkọ́kọ́, wọn kò sì bẹ̀rù Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni ó rán kìnnìún sí àárín wọn. Wọ́n sì pa nínú wọn.
26 Et on dit au Roi des Assyriens: Les nations que tu as transportées et fait habiter dans les villes de Samarie, ne savent pas la manière de servir le Dieu du pays; c'est pourquoi il a envoyé contr'eux des lions, et voilà, [ces lions] les tuent, parce qu'ils ne savent pas la manière de servir le Dieu du pays.
Wọ́n sì sọ fún ọba Asiria pé, “Àwọn ènìyàn tí ìwọ lé kúrò tí o sì fi sínú ìlú Samaria kò mọ ohun tí ọlọ́run ìlú náà béèrè. Ó sì ti rán kìnnìún sí àárín wọn, tí ó sì ń pa wọ́n run, nítorí ènìyàn wọn kò mọ ohun tí ó béèrè.”
27 Alors le Roi des Assyriens commanda, en disant: Faites aller là quelqu'un des Sacrificateurs que vous en avez transportés; qu'on aille donc, et qu'on demeure là, et qu'on enseigne la manière de servir le Dieu du pays.
Nígbà náà ọba Asiria pàṣẹ yìí wí pé, “Mú ọ̀kan lára àwọn àlùfáà tí ó mú láti Samaria lọ padà gbé níbẹ̀ kí ó sì kọ́ àwọn ènìyàn ní, ohun tí ọlọ́run ilẹ̀ náà béèrè.”
28 Ainsi un des Sacrificateurs qu'on avait transportés de Samarie, vint et habita à Béthel, et il leur enseignait comment ils devaient révérer l'Eternel.
Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kan lára àwọn àlùfáà tí ó ti kúrò ní Samaria wá gbé ní Beteli ó sì kọ́ wọn bí a ti ń sin Olúwa.
29 Mais chaque nation fit ses dieux, et ils les mirent dans les maisons des hauts lieux que les Samaritains avaient faits; chaque nation les mit dans ses villes où ils habitaient.
Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, olúkúlùkù orílẹ̀-èdè ṣe òrìṣà tirẹ̀ ní gbogbo ìlú níbi tí wọ́n gbé wà, wọ́n sì gbé wọn nínú ilé òrìṣà àti àwọn ènìyàn Samaria ó sì ṣe wọ́n sí ibi gíga wọ̀n-ọn-nì.
30 Car les gens de Babel firent Succoth-benoth; et les gens de Cuth firent Nergal; et les gens de Hamath firent Asima.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin láti Babeli ṣe àgọ́ àwọn wúńdíá, àwọn ènìyàn Kuti ṣe òrìṣà Nergali, àti àwọn ènìyàn Hamati ṣe ti Aṣima;
31 Et les Haviens firent Nibchaz et Tartac; mais ceux de Sépharvajim brûlaient leurs enfants au feu à Adrammélec et Hanammélec, les dieux de Sépharvajim.
àti àwọn ará Afa ṣe Nibhasi àti Tartaki, àti àwọn ará Sefarfaimi sun àwọn ọmọ wọn níná gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí Adrameleki àti Anameleki, àwọn òrìṣà Sefarfaimi.
32 Toutefois ils révéraient l'Eternel, et ils établirent pour Sacrificateurs des hauts lieux des derniers d'entr'eux, qui leur faisaient [le service] dans les maisons des hauts lieux.
Wọ́n sin Olúwa, ṣùgbọ́n wọ́n sì tún yan gbogbo ẹgbẹ́ tí ènìyàn wọn láti ṣe iṣẹ́ oyè fún wọn gẹ́gẹ́ bí àlùfáà ní ibi gíga.
33 [Ainsi] ils révéraient l'Eternel, et en même temps ils servaient leurs dieux à la manière des nations qu'on avait transportées hors de là.
Wọ́n sin Olúwa ṣùgbọ́n wọ́n sin òrìṣà wọn ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú àṣà orílẹ̀-èdè wọn láti ibi tí wọ́n ti gbé wọn wá.
34 Et jusqu'à ce jour ils font selon leurs premières coutumes; ils ne révèrent point l'Eternel, et néanmoins ils ne font ni selon leurs statuts et selon leurs ordonnances, ni selon la Loi [et] le commandement que l'Eternel Dieu donna aux enfants de Jacob, lequel il nomma Israël.
Láti ìgbà náà wá àwọn àlùfáà wọn ṣe bí ti àtẹ̀yìnwá. Wọn kò sin Olúwa tàbí kí wọ́n fi ara mọ́ ìlànà àti àṣẹ àti òfin tí Olúwa fi fún ìránṣẹ́ Jakọbu, tí wọ́n pe orúkọ rẹ̀ ní Israẹli.
35 Avec lesquels l'Eternel avait traité alliance, et auxquels il avait commandé, en disant: Vous ne révérerez point d'autres dieux, et ne vous prosternerez point devant eux; vous ne les servirez point, et vous ne leur sacrifierez point.
Nígbà tí Olúwa ṣe májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ó pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ má ṣe sin òrìṣà mìíràn tàbí tẹríba fún wọn, sìn wọ́n tàbí kí ẹ rú ẹbọ sí wọn.
36 Mais vous révérerez l'Eternel qui vous a fait monter hors du pays d'Egypte par une grande force, et avec un bras étendu; et vous vous prosternerez devant lui, et vous lui sacrifierez.
Ṣùgbọ́n Olúwa, ẹni tí ó mú yín gòkè jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú agbára ńlá àti nínà apá, òun ni ẹni náà tí ó yẹ kí ẹ sìn. Òun ni ẹni tí ó yẹ kí ẹ tẹríba fún àti sí òun ni kí ẹ rú ẹbọ fún.
37 Vous prendrez garde à faire toujours les statuts, les ordonnances, la Loi, et les commandements qu'il vous a écrits; et vous ne révérerez point d'autres dieux.
Ó yẹ kí ẹ̀yin kí ó máa kíyèsi ara yín gidigidi láti pa ìlànà àti àṣẹ, àti òfin tí ó kọ fún un yín mọ́. Ẹ má ṣe sin ọlọ́run mìíràn.
38 Vous n'oublierez donc point l'alliance que j'ai traitée avec vous, et vous ne révérerez point d'autres dieux;
Ẹ má ṣe gbàgbé májẹ̀mú tí mo ti ṣe pẹ̀lú yín mọ́ àti kí ẹ má sin ọlọ́run mìíràn.
39 Mais vous révérerez l'Eternel votre Dieu, et il vous délivrera de la main de tous vos ennemis.
Kúkú sin Olúwa Ọlọ́run rẹ; Òun ni ẹni náà tí yóò gbà yín kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá a yín.”
40 Mais ils n'écoutèrent point, et ils firent selon leurs premières coutumes.
Wọn kò ní gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni, wọ́n sì ń ṣe iṣẹ́ wọ́n ti àtijọ́.
41 Ainsi ces nations-là révéraient l'Eternel, et servaient en même temps leurs images; et leurs enfants, et les enfants de leurs enfants font jusqu'à ce jour comme leurs pères ont fait.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn wọn sin Olúwa, wọ́n sì ń sin òrìṣà wọn. Títí di ọjọ́ òní ọmọ wọn àti àwọn ọmọ ọmọ wọn sì ń ṣe bí àwọn baba wọn ti ń ṣe.

< 2 Rois 17 >