< 2 Chroniques 19 >

1 Et Josaphat Roi de Juda revint sain et sauf dans sa maison à Jérusalem.
Nígbà tí Jehoṣafati ọba Juda padà ní àlàáfíà sí ilé rẹ̀ ní Jerusalẹmu,
2 Et Jéhu fils d'Hanani le Voyant sortit au devant du Roi Josaphat, et lui dit: As-tu donc donné du secours au méchant, et aimes-tu ceux qui haïssent l'Eternel? à cause de cela l'indignation est sur toi de par l'Eternel.
Jehu aríran, ọmọ Hanani jáde lọ láti lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí fún ọba pé, “Ṣé ìwọ yóò máa ran ènìyàn búburú lọ́wọ́, kí o sì fẹ́ràn àwọn tí ó kórìíra Olúwa? Nítorí èyí, ìbínú Olúwa wà lórí wa.
3 Mais il s'est trouvé de bonnes choses en toi; puisque tu as ôté du pays les bocages, et que tu as disposé ton cœur pour rechercher Dieu.
Bí ó ti wù kí ó rí, ohun rere wà nínú rẹ, nítorí tí ìwọ ti mú àwọn ilé àwọn ère òrìṣà Aṣerah kúrò, tí o sì múra ọkàn rẹ láti wá Ọlọ́run.”
4 Depuis cela Josaphat se tint à Jérusalem; toutefois il fit encore la revue du peuple, depuis Béersébah jusqu'à la montagne d'Ephraïm; et il les ramena à l'Eternel le Dieu de leurs pères.
Jehoṣafati sì ń gbé ní Jerusalẹmu ó sì jáde lọ padà láàrín àwọn ènìyàn láti Beerṣeba dé òkè ìlú Efraimu, ó sì mú wọn padà sọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run baba wọn.
5 Et il établit des Juges au pays, par toutes les villes fortes de Juda, de ville en ville.
Ó sì yan àwọn onídàájọ́ sí ilẹ̀ náà, ní olúkúlùkù ìlú olódi Juda.
6 Et il dit aux Juges: Regardez ce que vous ferez, car vous n'exercez pas la justice de la part d'un homme, mais de la part de l'Eternel, qui est au milieu de vous en jugement.
Ó sì wí fun wọ́n pé, “Ẹ kíyèsi ohun tí ẹ̀yin ń ṣe, nítorí ìwọ kò ṣe ìdájọ́ fun ènìyàn ṣùgbọ́n fún Olúwa, ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ ní ìdájọ́.
7 Maintenant donc que la frayeur de l'Eternel soit sur vous; prenez garde à ceci, [et] faites-le, car il n'y a point d'iniquité en l'Eternel notre Dieu, ni d'acception de personnes, ni de réception de présents.
Nísinsin yìí jẹ́ kí ìbẹ̀rù Olúwa kí ó wá sí ọkàn rẹ̀. Ṣe ìdájọ́ pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́, nítorí pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run kò sí àìṣedéédéé tàbí ojúsàájú tàbí gbígba àbẹ̀tẹ́lẹ̀.”
8 Josaphat aussi établit à Jérusalem quelques-uns des Lévites, et des Sacrificateurs, et des Chefs des pères d'Israël, pour le jugement de l'Eternel, et pour les procès; car on revenait à Jérusalem.
Ní Jerusalẹmu pẹ̀lú, Jehoṣafati yan díẹ̀ lára àwọn Lefi, àwọn àlùfáà àti àwọn olórí ìdílé Israẹli si pípa òfin Olúwa mọ́ àti láti ṣe ìdájọ́. Wọn sì ń gbé ní Jerusalẹmu.
9 Et il leur commanda, en disant: Vous agirez ainsi en la crainte de l'Eternel, avec fidélité, et avec intégrité de cœur.
Ó sì kìlọ̀ fún wọn wí pé. “Ìwọ gbọdọ̀ sìn pẹ̀lú òtítọ́ àti pẹ̀lú ọkàn pípé ní ìbẹ̀rù Olúwa.
10 Et quant à tous les différends qui viendront devant vous de la part de vos frères qui habitent dans leurs villes, lorsqu'il faudra juger entre meurtre et meurtre, entre loi et commandement, entre statuts et ordonnances, vous les en instruirez, afin qu'ils ne se trouvent point coupables envers l'Eternel; et que son indignation ne soit point sur vous et sur vos frères; vous agirez donc ainsi, et vous ne serez point trouvés coupables.
Ní gbogbo ẹjọ́ tí ó bá wà níwájú rẹ láti ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin yín tí ń gbé ìlú wọn bóyá ẹ̀jẹ̀ tí ń sàn tàbí ìyókù òfin pẹ̀lú, pa á láṣẹ ìlànà àti ẹ̀tọ́, ìwọ gbọdọ̀ kìlọ̀ fún wọn láti má ṣe dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ìbínú yóò sì wá sórí yín, àti sórí àwọn arákùnrin. Ṣe èyí, ìwọ kì yóò sì jẹ̀bi.
11 Et voici, Amaria le principal Sacrificateur sera au dessus de vous dans toutes les affaires de l'Eternel; et Zébadia fils d'Ismaël sera le conducteur de la maison de Juda, dans toutes les affaires du Roi; et les prévôts Lévites sont devant vous. Fortifiez-vous, et faites ainsi, et l'Eternel sera avec les gens de bien.
“Amariah àlùfáà ni yóò jẹ́ olórí yín nínú gbogbo ọ̀ràn tí ó jẹ́ ti Olúwa, àti Sebadiah ọmọ Iṣmaeli alákòóso ìdílé Juda, ní yóò jẹ́ olórí ní gbogbo ọ̀rọ̀ tí ọba, àti àwọn ará Lefi pẹ̀lú yin yóò sìn gẹ́gẹ́ bí ìjòyè níwájú yín. Ẹ ṣe é pẹ̀lú ìmọ́kànle, Olúwa yóò sì wà pẹ̀lú àwọn tó bá ń ṣe rere.”

< 2 Chroniques 19 >