< 1 Chroniques 20 >

1 Or il arriva l'armée suivante, au temps que les Rois font leur sortie, que Joab conduisit le gros de l'armée, et ravagea le pays des enfants de Hammon; puis il alla assiéger Rabba, tandis que David demeurait à Jérusalem; et Joab battit Rabba, et la détruisit.
Ní àkókò àkọ́rọ̀ òjò, ni ìgbà tí àwọn ọba lọ sí ogun, Joabu ṣamọ̀nà àwọn ọ̀wọ́ ọmọ-ogun. Ó fi ilẹ̀ àwọn ará Ammoni ṣòfò. Ó lọ sí ọ̀dọ̀ Rabba. Ó sì fi ogun dúró tì í. Ṣùgbọ́n Dafidi dúró sí Jerusalẹmu Joabu kọlu Rabba, ó sì fi sílẹ̀ ní ìparun.
2 Et David prit la couronne de dessus la tête de leur Roi, et il trouva qu'elle pesait un talent d'or, et il y avait des pierres précieuses; et on la mit sur la tête de David, qui emmena un fort grand butin de la ville.
Dafidi mú adé kúrò lórí àwọn ọba wọn ìwọ̀n rẹ̀ dàbí i tálẹ́ǹtì wúrà, a sì tò ó jọ pẹ̀lú àwọn òkúta iyebíye. A sì gbé e ka orí Dafidi. Ó kó ọ̀pọ̀ ìkógun láti ìlú ńlá náà.
3 Il emmena aussi le peuple qui y était, et les scia avec des scies, et avec des herses de fer et de scies. David traita de la sorte toutes les villes des enfants de Hammon; puis il s'en retourna avec tout le peuple à Jérusalem.
Ó sì kó gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ibẹ̀ jáde, ó sì fi iṣẹ́ lé wọn lọ́wọ́ láti ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ayùn àti ìtulẹ̀ onírin àti àáké. Dafidi ṣe eléyìí sí gbogbo àwọn ará ìlú Ammoni. Nígbà náà, Dafidi àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ padà sí Jerusalẹmu.
4 Il arriva après cela que la guerre continua à Guézer contre les Philistins; [et] alors Sibbecaï le Husathite frappa Sippaï, qui était des enfants de Rapha, et ils furent abaissés.
Ní ẹ̀yìn èyí ni ogun bẹ́ sílẹ̀ ní Geseri pẹ̀lú àwọn ará Filistini, ní àkókò yìí ni Sibekai ará Huṣati pa Sipai, ọ̀kan lára àwọn ọmọ Refaimu, àti àwọn ará Filistini ni a ṣẹ́gun.
5 Il y eut encore une autre guerre contre les Philistins, dans laquelle Elhanan fils de Jahir frappa Lahmi, frère de Goliath Guittien, qui avait une hallebarde dont la hampe était comme l'ensuble d'un tisserand.
Nínú ogun mìíràn pẹ̀lú àwọn ará Filistini, Elhanani ọmọ Jairi pa Lahmi arákùnrin Goliati ará Gitti, ẹni ti ó ní ọ̀kọ̀ kan tí ó dàbí ọ̀pá ahunṣọ.
6 Il y eut encore une autre guerre à Gath, où se trouva un homme de grande stature, qui avait six doigts à chaque main, et [six orteils] à chaque pied, de sorte qu'il en avait en tout vingt-quatre; et il était aussi de la race de Rapha.
Síbẹ̀síbẹ̀ nínú ogun mìíràn, tí ó wáyé ní Gati, ọkùnrin títóbi kan wà tí ó ní ìka mẹ́fà ní ọwọ́ rẹ̀ pẹ̀lú ìka mẹ́fà ní ẹsẹ̀ rẹ̀ mẹ́rìnlélógún lápapọ̀. Òun pẹ̀lú wá láti Rafa.
7 Et il défia Israël; mais Jonathan, fils de Simha frère de David, le tua.
Nígbà tí ó fi Israẹli ṣẹ̀sín, Jonatani ọmọ Ṣimea, arákùnrin Dafidi sì pa á.
8 Ceux-là naquirent à Gath; ils étaient de la race de Rapha, et ils moururent par les mains de David, et par les mains de ses serviteurs.
Wọ̀nyí ni ìran ọmọ Rafa ní Gati, wọ́n sì ṣubú sí ọwọ́ Dafidi àti àwọn ọkùnrin rẹ̀.

< 1 Chroniques 20 >