< 1 Chroniques 12 >

1 Or ce sont ici ceux qui allèrent trouver David à Tsiklag, lorsqu'il y était encore enfermé à cause de Saül fils de Kis, et qui étaient des plus vaillants, pour donner du secours dans la guerre,
Àwọn wọ̀nyí ni ọkùnrin tí ó wá sí ọ̀dọ̀ Dafidi ní Siklagi, nígbà tí ó sá kúrò níwájú Saulu ọmọ Kiṣi (wọ́n wà lára àwọn jagunjagun ẹni tí ó ràn án lọ́wọ́ láti ibi ìjà.
2 Equipés d'arcs, se servant de la main droite et de la gauche à jeter des pierres, et à tirer des flèches avec l'arc. D'entre les parents de Saül, qui étaient de Benjamin,
Wọ́n sì mú wọn pẹ̀lú ìtẹríba wọ́n sì lágbára láti ta ọfà tàbí láti ta kànnàkànnà òkúta ní ọwọ́ òsì tàbí ní ọwọ́ ọ̀tún, wọ́n sì jẹ́ ìbátan ọkùnrin Saulu láti ẹ̀yà Benjamini):
3 Ahihézer le Chef, et Joas, enfants de Sémaha, qui était de Guibha, et Jéziël, et Pelet enfants de Hazmaveth, et Beraca, et Jéhu Hanathothite,
Ahieseri olórí wọn àti Joaṣi àwọn ọmọ Ṣemaah ará Gibeah: Jeṣieli àti Peleti ọmọ Asmafeti, Beraka, Jehu ará Anatoti.
4 Et Jismahja Gabaonite, vaillant entre les trente, et même plus que les trente, et Jérémie, Jahaziël, Johanan, et Jozabad Guédérothite,
Àti Iṣmaiah ará Gibeoni, ọkùnrin alágbára kan lára àwọn ọgbọ̀n ẹni tí ó jẹ́ olórí nínú àwọn ọgbọ̀n; Jeremiah, Jahasieli, Johanani, Josabadi ará Gedera,
5 Elhuzaï, Jérimoth, Béhalia, Sémaria, et Séphatia Haruphien,
Elusai, Jerimoti, Bealiah, Ṣemariah àti Ṣefatia ará Harufiti;
6 Elkana, Jisija, Hazaréël, Johézer et Jasobham Corites,
Elkana, Iṣiah, Asareeli, Joeseri àti Jaṣobeamu ará Kora;
7 Et Johéla et Zébadia, enfants de Jéroham de Guédor.
àti Joẹla, àti Sebadiah àwọn ọmọ Jerohamu láti Gedori.
8 Quelques-uns aussi des Gadites se retirèrent vers David, dans la forteresse au désert, hommes forts et vaillants, experts à la guerre, [et] maniant le bouclier et la lance. Leurs visages étaient [comme] des faces de lion, et ils semblaient des daims sur les montagnes, tant ils couraient légèrement.
Díẹ̀ lára àwọn ará Gadi yà sọ́dọ̀ Dafidi ní ibi gíga ní aginjù. Wọ́n sì jẹ́ onígboyà ológun tí ó múra fún ogun tí ó sì lágbára láti di asà àti ẹṣin mú. Ojú wọn sì dàbí ojú kìnnìún, wọ́n sì yára bí àgbọ̀nrín lórí àwọn òkè.
9 Hézer le premier, Hobadia le second, Eliab le troisième,
Eseri sì jẹ́ ìjòyè, Obadiah sì jẹ́ igbákejì akọgun, Eliabu ẹlẹ́ẹ̀kẹta,
10 Mismanna le quatrième, Jérémie le cinquième,
Miṣimana ẹlẹ́ẹ̀kẹrin, Jeremiah ẹlẹ́ẹ̀karùnún
11 Hattaï le sixième; Eliël le septième,
Attai ẹlẹ́ẹ̀kẹfà, Elieli èkeje,
12 Johanan le huitième, Elzabad le neuvième,
Johanani ẹlẹ́ẹ̀kẹjọ Elsabadi ẹlẹ́ẹ̀kẹsàn-án
13 Jérémie le dixième, Macbannaï le onzième.
Jeremiah ẹlẹ́ẹ̀kẹwàá àti Makbannai ẹlẹ́ẹ̀kọkànlá.
14 Ceux-là d'entre les enfants de Gad furent Capitaines de l'armée; le moindre avait la charge de cent hommes, et le plus distingué, de mille.
Àwọn ará Gadi wọ́n sì jẹ́ olórí ogun; ẹni tí ó kéré jù sì jẹ́ àpapọ̀ ọgọ́rùn-ún, àti fún ẹni tí ó pọ̀jù fún ẹgbẹ̀rún.
15 Ce sont ceux qui passèrent le Jourdain au premier mois, au temps qu'il a accoutumé de se déborder sur tous ses rivages; et ils chassèrent ceux qui demeuraient dans les vallées, vers l'Orient et l'Occident.
Àwọn ni ẹni tí ó rékọjá Jordani ní oṣù àkọ́kọ́ nígbà tí ó kún bo gbogbo bèbè rẹ̀, wọ́n sì lé gbogbo àwọn tí ó ń gbé nínú àfonífojì, lọ sí ìlà-oòrùn àti níhà ìwọ̀-oòrùn.
16 Il vint aussi des enfants de Benjamin et de Juda vers David à la forteresse.
Ìyókù ará Benjamini àti àwọn díẹ̀ ọkùnrin láti Juda lọ sí ọ̀dọ̀ Dafidi ní ibi gíga.
17 Et David sortit au devant d'eux et prenant la parole, il leur dit: Si vous êtes venus en paix vers moi pour m'aider, mon cœur vous sera uni; mais si c'est pour me trahir, [et me livrer] à mes ennemis, quoique je ne sois coupable d'aucune violence, que le Dieu de nos pères le voie, et qu'il en fasse la punition.
Dafidi sì lọ láti lọ pàdé wọn ó sì wí fún wọn pé, “Tí ẹ bá wá sọ́dọ̀ mi lálàáfíà, láti ràn mí lọ́wọ́ mo ṣetán láti mú un yín wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú mi ṣùgbọ́n tí ẹ bá wá láti dá mi sí fún àwọn ọ̀tá mi nígbà tí ọwọ́ mi bá mọ́ kúrò nínú ìwà agbára, kí Ọlọ́run àwọn baba wa kí ó sì ri kí ó sì ṣe ìdájọ́.”
18 Et l'esprit revêtit Hamasaï un des principaux Capitaines, [qui dit]: Que la paix soit avec toi, ô David! qu'elle soit avec toi, fils d'Isaï! que la paix soit à ceux qui t'aident, puisque ton Dieu t'aide! Et David les reçut, et les établit entre les Capitaines de ses troupes.
Nígbà náà Ẹ̀mí Mímọ́ wa sórí Amasai ìjòyè àwọn ọgbọ̀n, ó sì wí pé, “Tìrẹ ni àwa ń ṣe, ìwọ Dafidi! Àwa pẹ̀lú rẹ, ìwọ ọmọ Jese! Àlàáfíà, àlàáfíà fún ọ, àti àlàáfíà fún àwọn tí ó ràn ó lọ́wọ́, nítorí Ọlọ́run rẹ̀ yóò ràn ọ́ lọ́wọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì gbà wọ́n ó sì mú wọn jẹ olórí ẹgbẹ́ ogun.
19 Il y en eut aussi de ceux de Manassé qui s'allèrent rendre à David, quand il vint avec les Philistins pour combattre contre Saül; mais ils ne leur donnèrent point de secours, parce que les Gouverneurs des Philistins, après en avoir délibéré entr'eux, le renvoyèrent, en disant: Il se tournera vers son Seigneur Saül, au péril de nos têtes.
Díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin Manase sì yà sí ọ̀dọ̀ Dafidi nígbà tí ó lọ pẹ̀lú àwọn ará Filistini láti bá Saulu jà. (Òun àti àwọn ọkùnrin rẹ̀ wọn kò sì ran ará Filistini lọ́wọ́ nítorí, lẹ́yìn tiwọn sọ̀rọ̀ papọ̀, àwọn olórí wọn rán wọn jáde, wọ́n sì wí pé, “Yóò jẹ́ ìparun fún wa tí ó bá padà tọ ọ̀gá rẹ̀ Saulu lọ.”)
20 Quand donc il retournait à Tsiklag, Hadna, Jozabad, Jédihaël, Micaël, Jozabad, Elihu, et Tsillethaï, Chefs des milliers qui étaient en Manassé, se tournèrent vers lui.
Nígbà tí Dafidi lọ sí Siklagi, àwọn wọ̀nyí ni ọkùnrin ti Manase ẹni tí ó sì yà sọ́dọ̀ rẹ̀. Adina, Josabadi, Jediaeli, Mikaeli, Josabadi, Elihu àti Siletai, àwọn olórí ìrẹ́pọ̀ ti ẹgbẹẹgbẹ̀rún ní Manase.
21 Et ils aidèrent David contre la troupe des Hamalécites, car ils étaient tous forts et vaillants, et ils furent faits Capitaines dans l'armée.
Wọ́n sì ran Dafidi lọ́wọ́ lórí ẹgbẹ́ ogun náà, nítorí gbogbo wọn ni akọni ènìyàn àwọn sì tún ni olórí nínú àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
22 Et même à toute heure il venait des gens vers David pour l'aider, de sorte qu'il eut une grande armée, comme une armée de Dieu.
Ọjọ́ dé ọjọ́ ni àwọn ọkùnrin wá láti ran Dafidi lọ́wọ́, títí tí ó fi ní àwọn ológun ńlá, bí ogun Ọlọ́run.
23 Or ce sont ici les dénombrements des hommes équipés pour la guerre, qui vinrent vers David à Hébron, afin de faire tomber sur lui le Royaume de Saül, suivant le commandement de l'Eternel.
Àwọn wọ̀nyí sì ni iye ọkùnrin tí ó ti di ìhámọ́ra fún ogun àwọn ẹni tí ó wá sọ́dọ̀ Dafidi ní Hebroni láti yí ìjọba Dafidi padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.
24 Des enfants de Juda, qui portaient le bouclier et la javeline, six mille huit cents, équipés pour la guerre.
Ọkùnrin Juda, tí o ń gbé asà àti ọ̀kọ̀, ẹgbàáta lé lẹ́gbẹ̀rin tí ó ti di ìhámọ́ra fún ogun.
25 Des enfants de Siméon, forts et vaillants pour la guerre, sept mille et cent.
Àwọn ọkùnrin Simeoni, akọni tó mú fún ogun sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ó lé ọgọ́rùn-ún;
26 Des enfants de Lévi, quatre mille six cents.
àwọn ọkùnrin Lefi ẹgbàajì ó le ẹgbẹ̀ta,
27 Et Jéhojadah, conducteur de ceux d'Aaron et avec lui trois mille sept cents.
pẹ̀lú Jehoiada, olórí ìdílé Aaroni pẹ̀lú ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ènìyàn,
28 Et Tsadoc, jeune homme fort et vaillant, et vingt et deux des principaux de la maison de son père.
àti Sadoku akọni ọ̀dọ́mọkùnrin, pẹ̀lú àwọn méjìlélógún ìjòyè láti ọ̀dọ̀ àwọn ìdílé rẹ̀;
29 Des enfants de Benjamin, parents de Saül, trois mille; car jusqu'alors la plus grande partie d'entr'eux avait tâché de soutenir la maison de Saül.
àwọn arákùnrin Benjamini ìbátan ọkùnrin Saulu ẹgbẹ̀rún mẹ́ta, ọ̀pọ̀ nínú àwọn ẹni tí ó si kù ní olóòtítọ́ sí ilé Saulu títí di ìgbà náà;
30 Des enfants d'Ephraïm vingt mille huit cents, forts et vaillants, [et] hommes de réputation dans la maison de leurs pères.
àwọn arákùnrin Efraimu, ògbójú akọni, ènìyàn Ọlọ́run ni wọ́n nílé baba wọn ogún ẹgbẹ̀rún ó le ẹgbẹ̀rin;
31 De la demi-Tribu de Manassé dix-huit mille, qui furent nommés par leur nom pour aller établir David Roi.
àwọn ọkùnrin nínú ààbọ̀ ẹ̀yà Manase, tí a yàn nípa orúkọ láti wá àti láti yan Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba, ẹgbàá mẹ́sàn.
32 Des enfants d'Issacar, fort intelligents dans la connaissance des temps, pour savoir ce que devait faire Israël, deux cents de leurs Chefs, et tous leurs frères se conduisaient par leur avis.
Àti ní ti àwọn ọmọ Isakari, àwọn ẹni tí ó ní òye àkókò, láti mọ ohun tí Israẹli ìbá máa ṣe; olórí wọn jẹ́ ìgbà; àti gbogbo àwọn ìbátan wọn ń bẹ ní ìkáwọ́ wọn.
33 De Zabulon, cinquante mille combattants, rangés en bataille avec toutes sortes d'armes, et gardant leur rang d'un cœur assuré.
Àwọn ọkùnrin Sebuluni, àti àwọn jagunjagun tí ó ti nípa ogun múra fún ogun pẹ̀lú oríṣìíríṣìí ohun èlò ìjà, láti ran Dafidi lọ́wọ́ pẹ̀lú àwọn tí kò fi iyèméjì ṣe ìjólóòótọ́ wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n.
34 De Nephthali, mille capitaines, et avec eux trente-sept mille, portant le bouclier et la hallebarde.
Àwọn ọkùnrin Naftali, ẹgbẹ̀rún ìjòyè àpapọ̀ pẹ̀lú ẹgbàá méjìdínlógún. Ọkùnrin tí wọ́n gbé asà àti ọ̀kọ̀ wọn.
35 Des Danites, vingt-huit mille six cents, rangés en bataille.
Àwọn ọkùnrin Dani, tí wọ́n ṣetán fún ogun ẹgbàá mẹ́tàlá.
36 D'Aser, quarante mille combattants, et gardant leur rang en bataille.
Àwọn ọkùnrin Aṣeri, àwọn tí ó ti ní ìmọ̀ ogun múra fún ogun ọ̀kẹ́ méjì.
37 De ceux de delà le Jourdain, [savoir] des Rubénites, des Gadites, et de la demi-Tribu de Manassé, six-vingt mille, avec tous les instruments de guerre pour combattre.
Láti ìlà-oòrùn Jordani, ọkùnrin Reubeni, Gadi, àti ìdajì ẹ̀yà Manase, dìmọ́ra pẹ̀lú gbogbo onírúurú ohun èlò ìjà ọ̀kẹ́ mẹ́fà.
38 Tous ceux-ci, gens de guerre, rangés en bataille, vinrent tous de bon cœur à Hébron, pour établir David Roi sur tout Israël; et tout le reste d'Israël était aussi d'un même sentiment pour établir David Roi.
Gbogbo èyí ni àwọn ọkùnrin ológun tí ó fi ara wọn fún ogun láti ṣe iṣẹ́ fún nínú ẹgbẹ́. Wọ́n wá sí Hebroni tí ó kún fún ìpinnu láti fi Dafidi jẹ́ ọba lórí gbogbo Israẹli. Gbogbo àwọn ìyókù lára àwọn ọmọ Israẹli sì jẹ́ onínú kan láti fi Dafidi jẹ ọba.
39 Et ils furent là avec David, mangeant et buvant pendant trois jours; car leurs frères leur avaient préparé des vivres.
Àwọn ọkùnrin náà lo ọjọ́ mẹ́ta níbẹ̀ pẹ̀lú Dafidi, wọ́n jẹ, wọ́n sì ń mu, nítorí ìdílé wọn ti pèsè oúnjẹ fún wọn.
40 Et même ceux qui étaient les plus proches d'eux jusqu'à Issacar, et Zabulon, et Nephthali, apportaient du pain sur des ânes et sur des chameaux, sur des mulets, et sur des bœufs, de la farine, des figues sèches, des raisins secs, du vin, [et] de l'huile, [et ils amenaient] des bœufs, et des brebis en abondance; car il y avait joie en Israël.
Àwọn aládùúgbò láti ọ̀nà jíjìn gẹ́gẹ́ bí Isakari, Sebuluni àti Naftali gbé oúnjẹ wá lórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, lórí ràkunmí, àti lórí ìbáaka àti lórí màlúù, àní oúnjẹ ti ìyẹ̀fun, èso àjàrà gbígbẹ, èso ọ̀pọ̀tọ́, àkàrà dídùn, ọtí wáìnì, òróró, màlúù àti àgùntàn, nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ayọ̀ wà ní Israẹli.

< 1 Chroniques 12 >