< Psaumes 56 >

1 Jusqu'à la Fin, pour le peuple, quand il fut éloigné des saints lieux, inscription de David, lorsque les Philistins l'eurent maîtrisé dans Geth. Aie pitié de moi, ô Dieu, car l'homme m'a foulé aux pieds; tout le jour, il a bataillé contre moi, et il m'a accablé.
Fún adarí orin. Ti ohùn “Àdàbà lórí Óákù òkè réré.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí àwọn ará Filistini ka mọ́ ní Gati. Ṣàánú fún mi, Ọlọ́run, nítorí àwọn ènìyàn ń fi ìgbónára lépa mi; ní gbogbo ọjọ́ ni wọn ń kọjú ìjà sí mi, wọn ń ni mi lára.
2 Mes ennemis m'ont foulé aux pieds tout le jour, à partir de l'aurore; ils étaient nombreux à me combattre.
Àwọn ọ̀tá mi ń lé mi ní gbogbo ọjọ́, àwọn ènìyàn ń kọjú ìjà sí mi nínú ìgbéraga wọn.
3 Mais ils sentiront la crainte, et moi j'espérerai en toi.
Nígbà tí ẹ̀rù bà ń bà mí, èmi o gbẹ́kẹ̀lé ọ.
4 En Dieu je louerai mes paroles; tout le jour j'ai espéré en Dieu; je ne craindrai rien de ce que la chair fera contre moi.
Nínú Ọlọ́run èmi yóò máa yìn ọ̀rọ̀ rẹ, nínú Ọlọ́run ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi; ẹ̀rù kì yóò bà mí kí ni ẹran-ara lè ṣe sí mi?
5 Tout le long du jour ils ont eu en mépris mes discours; toutes leurs pensées tendaient à me nuire.
Wọn ń yí ọ̀rọ̀ mí ní gbogbo ọjọ́, wọn ń gbèrò nígbà gbogbo láti ṣe mí níbi.
6 Ils s'établiront auprès de moi, s'embusqueront et guetteront mes pieds, comme ils ont cherché la perte de mon âme.
Wọn kó ara wọn jọ, wọ́n ba. Wọ́n ń ṣọ́ ìgbésẹ̀ mi wọn ń làkàkà láti gba ẹ̀mí mi.
7 Tu ne les sauveras pas; tu briseras les peuples en ta colère, ô mon Dieu.
San ẹ̀san iṣẹ́ búburú wọ́n fún wọn; ní ìbínú rẹ, Ọlọ́run, wọ́ àwọn ènìyàn náà bọ́ sílẹ̀.
8 Je t'ai dévoilé ma vie; tu as mis devant toi mes larmes, selon ta promesse.
Kọ ẹkún mi sílẹ̀; kó omijé mi sí ìgò rẹ, wọ́n kò ha sí nínú ìkọ̀sílẹ̀ rẹ bí?
9 Mes ennemis tourneront le dos, quel que soit le jour où je t'invoque; voilà comment je reconnais que tu es mon Dieu.
Nígbà náà ni àwọn ọ̀tá mi yóò pẹ̀yìndà nígbà tí mo bá pè fún ìrànlọ́wọ́ nípa èyí ni mo mọ̀ pé Ọlọ́run ń bẹ fún mi.
10 En Dieu je louerai la parole; en Dieu je louerai les discours.
Nínú Ọlọ́run, ẹni tí mo yìn ọ̀rọ̀ rẹ̀ nínú Olúwa, ẹni tí mo yin ọ̀rọ̀ rẹ̀,
11 J'ai espéré en Dieu, je ne craindrai rien de ce que l'homme fera contre moi.
nínú Ọlọ́run ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi: ẹ̀rù kì yóò bà mí. Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?
12 En moi sont les vœux de louange que je te rendrai, ô Dieu.
Mo jẹ́ ẹ̀jẹ́ lábẹ́ rẹ Ọlọ́run: èmi o mú ìyìn mi wá fún ọ.
13 Car tu as délivré mon âme de la mort et mes pieds de la chute, afin que je sois agréable aux yeux de Dieu dans la lumière des vivants.
Nítorí ìwọ tí gbà mí lọ́wọ́ ikú àti ẹsẹ̀ mi lọ́wọ́ ìṣubú, kí èmí lè máa rìn níwájú Ọlọ́run ní ìmọ́lẹ̀ àwọn alààyè.

< Psaumes 56 >