< Psaumes 24 >

1 Psaume de David, pour le premier jour de la semaine. La terre est au Seigneur, et tout ce qu'elle contient, le monde et ceux qui l'habitent.
Ti Dafidi. Saamu. Ti Olúwa ni ilẹ̀, àti ẹ̀kún rẹ̀, ayé àti àwọn tí ó tẹ̀dó sínú rẹ̀;
2 Il l'a fondée sur la mer, il l'a préparée sur les fleuves.
nítorí ó fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ lórí òkun ó sì gbé e kalẹ̀ lórí àwọn ìṣàn omi.
3 Qui montera sur la montagne du Seigneur? qui se tiendra dans son sanctuaire?
Ta ni yóò gun orí òkè Olúwa lọ? Ta ni yóò dúró ní ibi mímọ́ rẹ̀?
4 Celui dont les mains sont innocentes et dont le cœur est pur; qui n'a point reçu en vain son âme; qui n'a point trompé son prochain par de faux serments.
Ẹni tí ó ní ọwọ́ mímọ́ àti àyà funfun, ẹni tí kò gbé ọkàn rẹ̀ sókè sí asán tí kò sì búra èké.
5 Celui-là recevra la bénédiction du Seigneur, et la miséricorde de Dieu son Sauveur.
Òun ni yóò rí ìbùkún gbà láti ọ̀dọ̀ Olúwa, àti òdodo lọ́wọ́ Ọlọ́run ìgbàlà rẹ̀.
6 Telle est la génération de ceux qui le cherchent, qui cherchent la face du Dieu de Jacob. Interlude.
Èyí ni ìran àwọn tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, Ọlọ́run Jakọbu. (Sela)
7 Princes, levez vos portes; ouvrez-vous, portes éternelles, et le Roi de gloire entrera.
Ẹ gbé orí yín sókè, háà! Ẹ̀yin ọ̀nà; kí á sì gbe yín sókè, ẹyin ìlẹ̀kùn ayérayé! Kí ọba ògo le è wọlé.
8 Quel est donc le Roi de gloire? C'est le Seigneur fort et puissant, le Seigneur puissant au combat.
Ta ni ọba ògo náà? Olúwa tí ó lágbára tí ó sì le, Olúwa gan an, tí ó lágbára ní ogun.
9 Princes, levez vos portes; ouvrez-vous, portes éternelles, et le Roi de gloire entrera.
Gbé orí yín sókè, ẹyin ọ̀nà; kí a sì gbé e yín sókè, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn ayérayé, kí Ọba ògo le è wọlé wá.
10 Quel est donc ce Roi de gloire? C'est le Dieu des vertus, c'est lui qui est le Roi de gloire.
Ta ni Ọba ògo náà? Olúwa àwọn ọmọ-ogun Òun ni Ọba ògo náà. (Sela)

< Psaumes 24 >