< Malachie 2 >

1 Et maintenant voici un ordre pour vous, ô prêtres
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ̀yin àlùfáà, òfin yìí ní fún yín.
2 Si vous Me désobéissez, et si vous ne mettez pas en vos cœurs qu'il faut glorifier Mon Nom, dit le Seigneur tout-puissant, Je vous enverrai Ma malédiction; et votre bénédiction sera maudite, et Je la maudirai, et Je la rendrai vaine, et la Mienne ne sera pas en vous, parce que vous n'aurez point déposé Mes paroles en vos cœurs.
Bí ẹ̀yin kò bá ni gbọ́, bí ẹ̀yin kò bá ní fi í sí àyà láti fi ọ̀wọ̀ fún orúkọ mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí; èmi yóò sì ran ègún sí orí yín, èmi yóò sì fi ìbùkún yín ré. Nítòótọ́ mó ti fi ré ná, nítorí pé, ẹ̀yin kò fi sí ọkàn yín láti bu ọlá fún mi.
3 Voilà que Je vous prive de l'épaule de vos victimes, et Je répandrai sur votre face leur fiente, la fiente de vos fêtes, et Je vous prendrai en même temps à leur place.
“Nítorí tiyín èmí yóò ba àwọn ọmọ yín wí, èmi ó sì fi ìgbẹ́ rẹ́ yín lójú, àní àwọn ìgbẹ́ ọrẹ ọwọ́ yín wọ̀nyí, a ó sì kó yín lọ pẹ̀lú rẹ̀.
4 Et vous connaîtrez que c'est Moi qui vous ai envoyé ce commandement, que Mon alliance doit être avec les lévites, dit le Seigneur tout-puissant.
Ẹ̀yin ó sì mọ̀ pé, èmi ni ó ti rán òfin yìí sí yín, kí májẹ̀mú mi pẹ̀lú Lefi lè tẹ̀síwájú,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
5 Mon alliance était avec Lévi, une alliance de vie et de paix, et Je lui avais donné Ma crainte, de sorte qu'à Mon Nom il était frappé de crainte.
“Májẹ̀mú mi wà pẹ̀lú rẹ̀, májẹ̀mú ti ìyè àti àlàáfíà wà pẹ̀lú rẹ̀; mo sì fi wọn fún un, nítorí bíbẹ̀rù tí ó bẹ̀rù mi, tí ẹ̀rù orúkọ mi sì bà á.
6 La loi de vérité était en sa bouche, et nulle iniquité n'eût été trouvée sur ses lèvres; il marchait avec Moi, dirigeant sa voie en paix, et il a détourné du mal nombre d'hommes.
Òfin òtítọ́ wà ni ẹnu rẹ̀, a kò sì rí irọ́ ni ètè rẹ̀: ó ba mi rìn ní àlàáfíà àti ni ìdúró ṣinṣin, ó sì yí ọ̀pọ̀lọpọ̀ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀.
7 Les lèvres du prêtre doivent garder la doctrine; on cherchera la loi dans les paroles de sa bouche; car il est l'envoyé du Seigneur tout-puissant.
“Nítorí ètè àlùfáà ní òye láti máa pa ìmọ̀ mọ́, kí àwọn ènìyàn lè máa wá ìtọ́ni ni ẹnu rẹ̀: nítorí òun ni ìránṣẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
8 Mais vous vous êtes retirés de la voie, et vous avez détourné plusieurs de la loi, et vous avez profané l'alliance de Lévi, dit le Seigneur tout-puissant.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti yapa kúrò ní ọ̀nà náà; ẹ̀yin sì ti fi ìkọ́ni yín mú ọ̀pọ̀lọpọ̀ kọsẹ̀; ẹ̀yin ti ba májẹ̀mú tí mo da pẹ̀lú Lefi jẹ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
9 Aussi ai-Je fait de vous le mépris et le rebut de toutes les nations, parce que vous n'avez point gardé Mes voies, mais qu'en la loi vous avez fait acception des personnes.
“Nítorí náà ni èmi pẹ̀lú ṣe sọ yín di ẹ̀gàn, àti ẹni àìkàsí níwájú gbogbo ènìyàn, nítorí ẹ̀yin kò tẹ̀lé ọ̀nà mi, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ń ṣe ojúsàájú nínú òfin.”
10 N'avez-vous pas tous un seul Père? N'est-ce pas le Dieu unique qui vous a créés? Pourquoi donc chacun de vous a-t-il abandonné son frère en souillant l'alliance de vos ancêtres?
Baba kan náà kí gbogbo wa ha ní? Ọlọ́run kan náà kọ́ ni ó dá wa bí? Nítorí kín ni àwa ha ṣe sọ májẹ̀mú àwọn baba wa di aláìmọ nípa híhu ìwà àrékérekè olúkúlùkù sí arákùnrin rẹ̀?
11 Juda a failli, et l'abomination a été en Israël et en Jérusalem, parce que Juda a profané les choses saintes du Seigneur, où Dieu Se complaisait, et qu'il s'est attaché à des dieux étrangers.
Juda ti ń hùwà àrékérekè, a sì ti hùwà ìríra ní Israẹli àti ni Jerusalẹmu: nítorí Juda tí sọ ìwà mímọ́ Olúwa di aláìmọ́, èyí tí ó fẹ́, nípa gbígbé ọmọbìnrin ọlọ́run àjèjì ni ìyàwó.
12 Le Seigneur exterminera tout homme qui fera ainsi pour l'expulser des tentes de Jacob, et le séparer de ceux qui sacrifient au Seigneur tout- puissant.
Ní ti ẹni tí ó ṣe èyí, ẹni tí ó wù kí ó jẹ, kí Olúwa kí ó gé e kúrò nínú àgọ́ Jakọbu, bí ó tilẹ̀ mú ẹbọ ọrẹ wá fún Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
13 Et vous avez fait ce que Je déteste; vous avez couvert de larmes l'autel du Seigneur: vous vous êtes frappé la poitrine au milieu des cris et des gémissements. Est-il convenable que Je considère vos victimes, ou que J'agrée quelque chose de vos mains?
Èyí ni ohun mìíràn tí ẹ̀yin sì túnṣe. Ẹ̀yin fi omijé bo pẹpẹ Olúwa mọ́lẹ̀. Ẹ̀yin sọkún, ẹ̀yin sì ba ara jẹ́ nítorí tì Òun kò ka ọrẹ yín sí mọ́, tàbí kí ó fi inú dídùn gba nǹkan yìí lọ́wọ́ yín.
14 Et vous avez dit: Pour quel motif? C'est parce que le Seigneur a porté témoignage contre toi et la femme de ta jeunesse que tu as abandonnée: elle qui était ta compagne; elle qui était la femme de ton alliance.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wí pé, “Nítorí kín ní?” Nítorí Olúwa ti ṣe ẹlẹ́rìí láàrín ìwọ àti láàrín aya èwe rẹ, ẹni tí ìwọ ti ń hùwà ẹ̀tàn sí i: bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkejì rẹ ni òun jẹ́, àti aya májẹ̀mú rẹ.
15 Ne l'a-t-Il pas éternellement créée? n'est-elle pas Son esprit? Et tu as dit: Que demande Dieu, sinon des enfants issus de moi? Or garde cette parole en ton esprit: N'abandonne pas la femme de ta jeunesse.
Ọlọ́run kò ha ti ṣe wọ́n ní ọ̀kan? Ni ara àti ni ẹ̀mí tirẹ̀ ni. Èéṣe tí Ọlọ́run da yín lọ́kàn? Kí òun bá à lè wá irú-ọmọ bí ti Ọlọ́run. Nítorí náà, ẹ tọ́jú ẹ̀mí yín, ẹ má sì ṣe hùwà ẹ̀tàn sí aya èwe yín.
16 Mais si, l'ayant haïe, tu la répudies, dit le Seigneur Dieu d'Israël, l'impiété couvrira toutes tes pensées, dit le Seigneur tout-puissant; c'est pourquoi garde cette parole en ton esprit: N'abandonne pas la femme de ta jeunesse.
“Ọkùnrin tí ó bá kórìíra, tí ó sì kọ ìyàwó rẹ̀,” se ìwà ipá sí ẹni tí ó yẹ kí ó dá ààbò bò, ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Nítorí náà, ẹ ṣọ́ ẹ̀mí yín, kí ẹ má ṣe hùwà ẹ̀tàn.
17 Ô vous qui, par vos paroles, provoquez Dieu, et qui dites: En quoi L'avons-nous provoqué? C'est en disant: Quiconque fait le mal est bien vu du Seigneur; Il Se complaît en ceux-là; où donc est le Dieu de la justice?
Ẹ̀yin ti fi ọ̀rọ̀ yín dá Olúwa ní agara. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, “Nínú kín ni àwa fi dá a ní agara?” Nígbà tí ẹ̀yìn wí pé, “Gbogbo ẹni tí ó ṣe ibi, rere ni níwájú Olúwa, inú rẹ̀ sì dùn sí wọn,” tàbí “Níbo ni Ọlọ́run ìdájọ́ gbé wà?”

< Malachie 2 >