< Juges 15 >

1 Après cela, au temps de la moisson du froment, Samson partit avec un chevreau pour visiter sa femme, et il dit: Je veux entrer auprès de ma femme dans la chambre nuptiale; mais son beau-père ne lui permit pas d'entrer.
Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, ní àkókò ìkórè alikama, Samsoni mú ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan láti bẹ ìyàwó rẹ̀ wò. Ó ní, “Èmi yóò wọ yàrá ìyàwó mi lọ.” Ṣùgbọ́n baba rẹ̀ kò gbà á láààyè láti wọlé.
2 Il le retint, disant: J'ai pensé que tu la haïssais, et je l'ai donnée à l'un de tes amis; n'a-t-elle pas une sœur plus belle et plus jeune? Qu'elle soit ta femme, au lieu de la première.
Baba ìyàwó dá a lóhùn pé, “Ó dá mi lójú pé o kórìíra rẹ̀, torí náà mo ti fi fún ọ̀rẹ́ rẹ, ṣe bí àbúrò rẹ̀ obìnrin kò ha lẹ́wà jùlọ? Fẹ́ ẹ dípò rẹ̀.”
3 Et Samson leur dit: Je suis irrépréhensible cette fois; je suis innocent, cette fois encore, à l'égard des Philistins, en leur faisant du mal.
Samsoni dáhùn pé, “Ní àkókò yìí tí mo bá ṣe àwọn Filistini ní ibi èmi yóò jẹ́ aláìjẹ̀bi.”
4 Et Samson s'en étant allé, prit trois cents renards et trois cents torches; il accoupla les renards côte à côte, et il attacha une torche entre deux queues;
Samsoni sì jáde lọ, ó mú ọ̀ọ́dúnrún kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ ó so ìrù wọn mọ́ ara wọn ní méjì méjì. Ó mú ètùfù iná, ó so ó mọ́ àwọn ìrù tí ó so pọ̀.
5 Puis, il alluma les torches, et il lança les renards au milieu des blés des Philistins; les blés furent détruits depuis le sol jusqu'à l'épi, et la flamme atteignit les vignes et les oliviers.
Ó fi iná ran àwọn ètùfù tí ó so náà, ó sì jọ̀wọ́ wọn lọ́wọ́ lọ sínú àwọn oko ọkà àwọn Filistini. Ó jó àwọn pòpóòrò ọkà tí ó dúró àti àwọn tí a dì ní ìtí, ìtí, pẹ̀lú àwọn ọgbà àjàrà àti olifi.
6 Les Philistins dirent: Qui a fait cela? Et on leur répondit: C'est Samson, l'époux de Thamni, parce que le père de celle-ci lui a pris sa femme et l'a donnée à l'un de ses amis. Et les Philistins partirent, et ils la livrèrent aux flammes, elle et la maison de son père.
Nígbà tí àwọn Filistini béèrè pé, “Ta ni ó ṣe èyí?” Wọ́n dá wọn lóhùn pé, “Samsoni ará Timna ni, nítorí a gba ìyàwó rẹ̀ fún ọ̀rẹ́ rẹ̀.” Nítorí náà àwọn Filistini lọ wọ́n sì sun obìnrin náà àti baba rẹ̀.
7 Et Samson dit: Puisque vous l'avez traitée de la sorte, certes, j'en tirerai vengeance sur vous, jusqu'à ce qu'il me plaise de cesser.
Samsoni sọ fún un pé, “Nítorí pé ẹ̀yin ṣe èyí, èmi ó gbẹ̀san lára yín, lẹ́yìn náà èmi yóò sì dẹ́kun.”
8 Et il les frappa en les bouleversant; ce fut une plaie très-grande; ensuite, il alla s'établir dans le souterrain de la roche d'Etam.
Ó kọlù wọ́n pẹ̀lú ìbínú àti agbára ńlá, ó sì pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú wọn. Lẹ́yìn náà ni ó lọ, ó sì dúró nínú ihò àpáta kan nínú àpáta Etamu.
9 Les Philistins, s'étant mis en campagne, campèrent en Juda, et ils essuyèrent un échec au lieu dit la Mâchoire.
Àwọn ará Filistini sì dìde ogun sí Juda, wọ́n ti tan ara wọn ká sí agbègbè Lehi.
10 Et Juda leur dit: Pourquoi avez-vous marché contre nous? Ils répondirent: Nous sommes venus pour exterminer Samson et le traiter comme il nous a traités.
Àwọn ọkùnrin Juda sì béèrè pé, “Èéṣe tí ẹ fi wá gbóguntì wá?” Ìdáhùn wọn ni pé, “A wá láti mú Samsoni ní ìgbèkùn, kí a ṣe sí i bí òun ti ṣe sí wa.”
11 Trois mille hommes de Juda descendirent alors a la caverne de la roche d'Etam, et ils dirent à Samson: Ne sais-tu pas que les Philistins nous dominent? Pourquoi donc nous as-tu amené cette affaire? Et Samson leur dit: Je les ai traités comme ils m'avaient traité.
Nígbà náà ni ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkùnrin láti Juda sọ̀kalẹ̀ lọ sí ihò àpáta nínú àpáta Etamu, wọ́n sì sọ fún Samsoni pé, “Kò ti yé ọ pé àwọn Filistini ní ń ṣe alákòóso lórí wa? Kí ni o ṣe sí wa?” Òun sì dáhùn pé, “Ohun tí wọ́n ṣe sí mi ni èmi náà ṣe sí wọn.”
12 Et ils lui dirent: Nous sommes descendus pour te lier et te remettre en leurs mains. Et Samson leur dit: Jurez que vous-mêmes, vous n'êtes point venus contre moi?
Wọ́n wí pé, “Àwa wá láti dè ọ́, kí a sì fi ọ́ lé àwọn Filistini lọ́wọ́.” Samsoni wí pé, “Ẹ búra fún mi pé, ẹ̀yin kì yóò fúnra yín pa mí.”
13 Ils lui répondirent: Nullement, mais nous allons te charger de liens pour te livrer à eux, et nous ne te tuerons pas. Ils le lièrent donc avec deux cordes neuves, et ils l'enlevèrent de cette roche.
“Àwa gbà,” ni ìdáhùn wọn. “Àwa yóò kàn dè ọ́, àwa yóò sì fi ọ́ lé wọn lọ́wọ́, àwa kì yóò pa ọ́.” Wọ́n sì dé pẹ̀lú okùn tuntun méjì, wọ́n sì mú u jáde wá láti ihò àpáta náà.
14 De là, ils allèrent jusqu'au lieu dit la Mâchoire, et les Philistins jetèrent de grands cris, et ils accoururent à sa rencontre. Aussitôt, l'Esprit du Seigneur s'élança sur lui, et les cordes qui lui retenaient les bras furent pour lui comme de l'étoupe brûlée, les liens de ses mains se rompirent.
Bí ó ti súnmọ́ Lehi, àwọn Filistini ń pariwo bí wọ́n ṣe ń tò bọ̀. Ẹ̀mí Olúwa bà lé e pẹ̀lú agbára. Àwọn okùn ọwọ́ rẹ̀ dàbí òwú tí ó jóná, ìdè ọwọ́ rẹ̀ já kúrò ní ọwọ́ rẹ̀.
15 Et il trouva à terre une mâchoire d'âne, et il étendit la main, et il la ramassa, et, avec cette mâchoire, il tua mille hommes.
Nígbà tí ó rí egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tuntun kan, ó mú un, ó sì fi pa ẹgbẹ̀rún ọkùnrin.
16 Et Samson dit: Avec une mâchoire d'âne, je les ai détruits, et je les ai détruits; avec une mâchoire d'âne, j'ai tué mille hommes.
Samsoni sì wí pé, “Pẹ̀lú egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan, mo sọ wọ́n di òkìtì kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Pẹ̀lú egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan, mo ti pa ẹgbẹ̀rún ọkùnrin.”
17 Lorsqu'il eut cessé de parler et qu'il eut jeté la mâchoire, il appela ce lieu l'Elévation de la Mâchoire.
Nígbà tí ó dákẹ́ ọ̀rọ̀ í sọ, ó ju egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ náà nù, wọ́n sì pe ibẹ̀ ní Ramati-Lehi (ìtumọ̀ rẹ̀ jẹ́ egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ pa).
18 Il avait bien soif et il pleura devant le Seigneur, et il dit: Il vous a plu d'opérer cette grande délivrance par la main de votre serviteur; vais-je maintenant mourir de soif et retomber entre les mains des incirconcis?
Nítorí tí òǹgbẹ gbẹ ẹ́ gidigidi, ó ké pe Olúwa, wí pé, “Ìwọ ti fún ìránṣẹ́ ní ìṣẹ́gun tí ó tóbi yìí. Ṣé èmi yóò ha kú pẹ̀lú òǹgbẹ, kí èmi sì ṣubú sí ọwọ́ àwọn aláìkọlà ènìyàn?”
19 Et le Seigneur ouvrit le creux de la mâchoire, et de l'eau en jaillit, et Samson but, et il ranima ses esprits, et il revint à la vie. A cause de cela, on donna à cette source le nom de Fontaine de l'Invocation, et encore de nos jours elle existe au lieu dit la Mâchoire.
Nígbà náà ni Ọlọ́run la kòtò ìsun omi tí ó wà ní Lehi, omi sì tú jáde láti inú rẹ̀. Nígbà tí Samsoni mú mi tan, agbára rẹ̀ sì padà, ọkàn sì sọjí, fún ìdí èyí wọ́n pe ìsun omi náà ni. Ẹni Hakkore (orísun ẹni tí ó pe Ọlọ́run) èyí tí ó sì wà ní Lehi di òní.
20 Or, Samson jugea vingt ans Israël aux jours des Philistins.
Samsoni ṣe ìdájọ́ Israẹli fún ogún ọdún ní àkókò àwọn ará Filistini.

< Juges 15 >