< Job 22 >

1 Or Eliphaz le Thémanite reprenant dit:
Ìgbà náà ni Elifasi, ará Temani, dáhùn wí pé,
2 N'est-ce point le Seigneur qui distribue l'intelligence et le savoir?
“Ènìyàn lè è ṣe rere fún Ọlọ́run? Bí ọlọ́gbọ́n ti í ṣe rere fún ara rẹ̀?
3 Qu'importe au Seigneur que tu aies été irréprochable en tes œuvres? Qu'a- t-il besoin de l'innocence de tes voies?
Ohun ayọ̀ ha ni fún Olódùmarè pé olódodo ni ìwọ? Tàbí èrè kí ni fún un ti ìwọ mú ọ̀nà rẹ̀ pé?
4 Est-ce que tes arguments le convaincront? est-ce qu'il viendra à toi en jugement?
“Yóò ha bá ọ wí bí, nítorí ìbẹ̀rù Ọlọ́run rẹ? Yóò ha bá ọ lọ sínú ìdájọ́ bí?
5 Ta méchanceté n'est-elle pas immense? tes péchés ne sont-ils pas innombrables?
Ìwà búburú rẹ kò ha tóbi, àti ẹ̀ṣẹ̀ rẹ láìníye?
6 Tu as mal à propos exigé des gages de tes frères; tu as dépouillé de leurs vêtements des nus.
Nítòótọ́ ìwọ béèrè fún ààbò ni ọwọ́ arákùnrin rẹ láìnídìí, ìwọ sì tú oníhòhò ní aṣọ wọn.
7 Tu n'as point abreuvé d'eau ceux qui avaient soif; tu as refusé une bouchée à ceux qui avaient faim.
Ìwọ kò fi omi fún aláàárẹ̀ mu, ìwọ sì háwọ́ oúnjẹ fún ẹni tí ebi ń pa.
8 Tu as eu égard à la grandeur; tu as hébergé les puissants de la terre.
Bí ó ṣe ti alágbára nì, òun ni ó ní ilẹ̀, ọlọ́lá sì tẹ̀dó sínú rẹ̀.
9 Tu as renvoyé vides les veuves; tu as maltraité les orphelins.
Ìwọ ti rán àwọn opó padà lọ ní ọwọ́ òfo, apá àwọn ọmọ aláìní baba ti di ṣiṣẹ́.
10 Voilà pourquoi des filets t'enveloppent et tu as à soutenir une guerre imprévue.
Nítorí náà ni ìdẹ̀kùn ṣe yí ọ káàkiri, àti ìbẹ̀rù òjijì ń yọ ọ́ lẹ́nu.
11 Ta lumière s'est changée en ténèbres, et, tandis que tu étais couché, l'eau t'a submergé.
Èéṣe tí òkùnkùn fi pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ kò fi lè ríran. Èéṣe tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi sì bò ọ́ mọ́lẹ̀.
12 Celui qui réside au plus haut des cieux ne surveille-t-il plus? N'a-t-il pas toujours humilié les superbes?
“Ọlọ́run kò ha jẹ́ ẹni gíga ọ̀run? Sá wo orí àwọn ìràwọ̀ bí wọ́n ti ga tó!
13 Et tu avais dit: Que fait le Tout-Puissant? Est-ce qu'il peut juger au milieu des ténèbres?
Ìwọ sì wí pé, Ọlọ́run ti ṣe mọ̀? Òun ha lè ṣe ìdájọ́ láti inú òkùnkùn wá bí?
14 Une nuée le cache et nul ne le verra; et il parcourt le cercle du ciel.
Ǹjẹ́ àwọsánmọ̀ tí ó nípọn jẹ ìbora fún un, tí kò fi lè ríran; ó sì ń rìn nínú àyíká ọ̀run.
15 Ne seras-tu pas attentif à suivre le sentier éternel qu'ont foulé les justes?
Ǹjẹ́ ìwọ fẹ́ rin ipa ọ̀nà ìgbàanì tí àwọn ènìyàn búburú tí rìn?
16 Ceux qui s'en sont écartés ont été pris; ils appuient leurs fondations sur le courant d'un fleuve.
A ké wọn lulẹ̀ kúrò nínú ayé láìpé ọjọ́ wọn, ìpìlẹ̀ wọn ti da bí odò ṣíṣàn.
17 Des gens disent: Que nous fera le Seigneur? Quel mal le Tout-Puissant nous enverra-t-il?
Àwọn ẹni tí ó wí fún Ọlọ́run pé, ‘Lọ kúrò lọ́dọ̀ wa! Kí ni Olódùmarè yóò ṣe fún wọn?’
18 Et c'est Lui qui a comblé de biens leurs maisons; et la volonté des impies s'est détournée de Dieu.
Síbẹ̀ ó fi ohun rere kún ilé wọn! Ṣùgbọ́n ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí mi!
19 Les justes en les voyant ont ri; l'innocent les a raillés,
Àwọn olódodo rí ìparun wọn, wọ́n sì yọ̀, àwọn aláìlẹ́ṣẹ̀ sì fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà pé,
20 Jusqu'à ce que leur fortune se soit évanouie et que le feu ait dévoré leur restes.
‘Lóòtítọ́ àwọn ọ̀tá wa ni a ké kúrò, iná yóò sì jó oró wọn run.’
21 Tu t'es endurci: si tu persistes, les bons récolteront tes fruits.
“Fa ara rẹ súnmọ́ Ọlọ́run, ìwọ ó sì rí àlàáfíà; nípa èyí ni rere yóò wá bá ọ.
22 Recueille ce que te révélera sa bouche; fais entrer ses paroles en ton cœur.
Èmi bẹ̀ ọ́, gba òfin láti ẹnu rẹ̀ wá, kí o sì to ọ̀rọ̀ rẹ̀ sí àyà rẹ.
23 Si tu te convertis, si tu te fais humble devant le Seigneur, tu auras chassé l'iniquité de ta maison.
Bí ìwọ bá yípadà sọ́dọ̀ Olódùmarè, a sì gbé ọ ró. Bí ìwọ bá sì mú ẹ̀ṣẹ̀ jìnnà réré kúrò nínú àgọ́ rẹ,
24 Alors il changera les cailloux de tes champs en pierres précieuses comme celles du torrent d'Ophir.
tí ìwọ bá tẹ́ wúrà dáradára sílẹ̀, lórí erùpẹ̀ àti wúrà Ofiri lábẹ́ òkúta odò,
25 Le Tout-Puissant sera ton auxiliaire contre tes ennemis; il te rendra pur comme l'argent récemment fondu.
nígbà náà ní Olódùmarè yóò jẹ́ wúrà rẹ, àní yóò sì jẹ́ fàdákà fún ọ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
26 Enfin, après t'être exprimé franchement devant le Seigneur, tu seras pénétré de joie en regardant le ciel.
Lóòtítọ́ nígbà náà ní ìwọ ó ní inú dídùn nínú Olódùmarè, ìwọ ó sì gbé ojú rẹ sókè sọ́dọ̀ Ọlọ́run.
27 Dès que tu l'auras prié, il t'exaucera et il fera en sorte que tu puisses accomplir tes vœux.
Bí ìwọ bá gbàdúrà rẹ sọ́dọ̀ rẹ̀, yóò sì gbọ́ tìrẹ, ìwọ ó sì san ẹ̀jẹ́ rẹ.
28 Il te remettra dans les voies de la justice, et une vive lumière éclairera ton chemin.
Ìwọ ó sì gbìmọ̀ ohun kan pẹ̀lú, yóò sì fi ìdí múlẹ̀ fún ọ; ìmọ́lẹ̀ yóò sì mọ́ sípa ọ̀nà rẹ.
29 Parce que tu te seras humilié et que tu auras dit: l'homme s'était enorgueilli, mais il a baissé les yeux et il est sauvé.
Nígbà tí ipa ọ̀nà rẹ bá lọ sísàlẹ̀, nígbà náà ni ìwọ o wí pé, ‘Ìgbésókè ń bẹ!’ Ọlọ́run yóò sì gba onírẹ̀lẹ̀ là!
30 Dieu protégera l'innocent: qu'il soit sauvé, ô mon Dieu, par vos mains pures.
Yóò gba ẹni tí kì í ṣe aláìjẹ̀bi là, a ó sì gbà á nípa mímọ́ ọwọ́ rẹ̀.”

< Job 22 >