< Isaïe 14 >

1 Le moment arrive, et il ne tardera point, où le Seigneur aura pitié de Jacob, où Israël sera encore son élu; alors ils reposeront dans leur terre, et l'étranger viendra se joindre à eux, et s'unira à la maison de Jacob,
Olúwa yóò fi àánú hàn fún Jakọbu, yóò tún Israẹli yàn lẹ́ẹ̀kan sí i yóò sì fi ìdí wọn kalẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn tìkára wọn. Àwọn àjèjì yóò darapọ̀ mọ́ wọn, wọn yóò sì fọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú ilé e Jakọbu.
2 Et les Gentils se les adjoindront et ils les introduiront dans leur pays; et les enfants d'Israël auront leur héritage, et y multiplieront leurs serviteurs et leurs servantes; et ceux qui les avaient tenus captifs seront leurs captifs à leur tour, et ceux qui les avaient dominés seront dominés par eux.
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò gbà wọ́n wọn yóò sì mú wọn wá sí ààyè e wọn. Ilé Israẹli yóò gba àwọn orílẹ̀-èdè gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin ní ilẹ̀ Olúwa. Wọn yóò kó àwọn akónilẹ́rú wọn ní ìgbèkùn wọn yóò sì jẹ ọba lórí àwọn amúnisìn wọn.
3 Et voici ce qui arrivera en ce jour: le Seigneur apaisera ta douleur, et ton humiliation, et la dure servitude à laquelle ils t'avaient assujetti.
Ní ọjọ́ tí Olúwa yóò fi ìtura fún un yín kúrò nínú ìpọ́njú àti ìyà àti ìdè ìkà,
4 Et tu composeras cette lamentation sur le roi de Babylone: Comment est mort cet exacteur? Comment est mort ce maître impitoyable?
ẹ ó sì fi ọ̀rọ̀ àbùkù yìí kan ọba Babeli pé, báwo ni amúnisìn ṣe wá sí òpin! Báwo ni ìbínú rẹ̀ ṣe parí!
5 Le Seigneur a brisé le joug des impies, le joug des dominateurs.
Olúwa ti dá ọ̀pá ìkà náà, ọ̀pá àwọn aláṣẹ,
6 Il a frappé avec colère cette nation d'une plaie incurable, puis il l'a renversée dans sa colère et ne l'a point épargnée.
èyí tí ó ti lu àwọn ènìyàn bolẹ̀ pẹ̀lú ti kò dáwọ́ dúró, nínú ìrunú ni ó ṣẹ́gun àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú ìgbónára tí kò lópin.
7 Et toute la terre s'est reposée avec confiance et a poussé des cris de joie;
Gbogbo ilẹ̀ ni ó wà ní ìsinmi àti àlàáfíà, wọ́n bú sí orin.
8 Et les arbres du Liban se sont réjouis de ta chute; et le cèdre du Liban, depuis que tu es mort, dit: Celui qui nous abattait ne monte plus ici!
Pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn igi junifa àti àwọn igi kedari ti Lebanoni ń yọ̀ lórí rẹ wí pé, “Níwọ́n bí a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ báyìí, kò sí agégi tí yóò wá láti gé wa lulẹ̀.”
9 L'enfer en ses abîmes s'est troublé à ton approche; et ils se sont levés ensemble contre toi, tous les géants, jadis princes de la terre, qui faisaient descendre de leurs trônes tous les rois des nations. (Sheol h7585)
Ibojì tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni a ru sókè láti pàdé rẹ ní ìpadàbọ̀ rẹ̀ ó ru ẹ̀mí àwọn tí ó ti lọ sókè láti wá kí ọ gbogbo àwọn tí ó jẹ́ olórí ní ayé ó mú kí wọn dìde lórí ìtẹ́ wọn gbogbo àwọn tí ó jẹ ọba lórí àwọn orílẹ̀-èdè. (Sheol h7585)
10 Ils te parleront tous et te diront: Te voilà pris comme nous, et te voilà l'un des nôtres!
Gbogbo wọn yóò dáhùn, wọn yóò wí fún ọ wí pé, “Ìwọ pẹ̀lú ti di aláìlera, gẹ́gẹ́ bí àwa pẹ̀lú ìwọ náà ti dàbí wa.”
11 Ta gloire et ta longue prospérité sont descendues aux enfers; la pourriture est ta couche, les vers ta couverture. (Sheol h7585)
Gbogbo rẹ̀ ni ó di ìrẹ̀sílẹ̀ lọ sí ibojì, pẹ̀lú ariwo àwọn dùùrù rẹ, àwọn ìdin ni wọ́n fọ́nkálẹ̀ lábẹ́ rẹ àwọn ekòló sì ti bò ọ́ mọ́lẹ̀. (Sheol h7585)
12 Comment est tombée des cieux l'étoile du matin qui se levait dès l'aurore? Comment a été brisé contre terre celui qui commandait à toutes les nations?
Báwo ni ìwọ ṣe ṣubú lulẹ̀ láti ọ̀run wá, ìwọ ìràwọ̀ òwúrọ̀, ọmọ òwúrọ̀ náà! A ti sọ ọ́ sílẹ̀ sínú ayé, ìwọ tí o ti tẹ orí àwọn orílẹ̀-èdè ba rí!
13 Tu disais dans ton cœur: Je monterai au ciel; je placerai mon trône au- dessus des astres; je m'assoirai sur une haute montagne, sur ces hautes montagnes qui s'étendent vers l'aquilon.
Ìwọ sọ nínú ọkàn rẹ pé, “Èmi yóò gòkè lọ sí ọ̀run; èmi yóò gbé ìtẹ́ mi sókè ga ju àwọn ìràwọ̀ Ọlọ́run, Èmi yóò gúnwà ní orí òkè àpéjọ ní ṣóńṣó orí òkè mímọ́.
14 Je monterai au-dessus des nuages; je serai semblable au Très-Haut.
Èmi yóò gòkè lọ rékọjá àwọn àwọsánmọ̀; èmi yóò ṣe ara mi gẹ́gẹ́ bí Ọ̀gá-ògo.”
15 Et maintenant tu es descendu en enfer, et jusqu'aux fondements de la terre. (Sheol h7585)
Ṣùgbọ́n a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ wọ inú ibojì lọ lọ sí ìsàlẹ̀ ọ̀gbun. (Sheol h7585)
16 Ceux qui t'ont vu seront étonnés de ta chute, et ils diront: Voilà cet homme qui exaspérait la terre, qui ébranlait les rois;
Àwọn tí ó rí ọ yóò tẹjúmọ́ ọ, wọ́n ronú nípa àtubọ̀tán rẹ: “Ǹjẹ́ èyí ni ẹni tí ó mi ayé tìtì tí ó sì jẹ́ kí àwọn ilẹ̀ ọba wárìrì.
17 Qui avait fait de toute la terre une solitude, qui en détruisait les cités, et qui ne délivrait pas ceux qu'il avait faits captifs.
Ẹni tí ó sọ ayé di aginjù, tí ó sì pa ìlú ńlá ńlá rẹ̀ run tí kò dá àwọn òǹdè rẹ̀ sílẹ̀ láti padà sílé?”
18 Tous les rois des nations se sont endormis dans la mort, tous avec honneur et dans leurs palais.
Gbogbo àwọn ọba orílẹ̀-èdè ni a tẹ́ sílẹ̀ ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú ibojì tirẹ̀.
19 Mais toi, tu seras jeté dans les montagnes, comme un cadavre impur, avec une multitude de morts percés du glaive et descendus aux enfers. Comme un manteau souillé de sang ne peut être pur,
Ṣùgbọ́n a jù ọ́ síta kúrò nínú ibojì gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ka igi tí a kọ̀sílẹ̀, àwọn tí a pa ni ó bò ọ́ mọ́lẹ̀, àwọn tí idà ti gún, àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú òkúta inú ọ̀gbun. Gẹ́gẹ́ bí òkú ó di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ ní abẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀,
20 Ainsi tu seras impur; et parce que tu as désolé ma terre et tué mon peuple, toi, semence perverse, tu ne subsisteras pas longtemps!
a kò ní sin ọ́ pẹ̀lú wọn, nítorí pé o ti ba ilẹ̀ rẹ jẹ́ o sì ti pa àwọn ènìyàn rẹ. Ìran àwọn ìkà ni a kì yóò dárúkọ wọn mọ́.
21 Prépare tes enfants pour qu'on les égorge en punition du péché de leur père; qu'ils ne se relèvent pas, qu'ils n'héritent pas de leur royaume, qu'ils ne remplissent pas la terre du bruit de leurs batailles.
Tọ́jú ibìkan tí a ó ti pa àwọn ọmọkùnrin rẹ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wọn, wọn kò gbọdọ̀ dìde láti jogún ilẹ̀ kí wọ́n sì bo orí ilẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìlú u wọn.
22 Et je m'élèverai contre eux, dit le Seigneur des armées, et je détruirai leur nom, leurs restes et leur race. Voilà ce que dit le Seigneur.
“Èmi yóò dìde sókè sí wọn,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Èmi yóò ké orúkọ rẹ̀ kúrò ní Babeli àti àwọn tí ó sálà, àwọn ọmọ àti ìran rẹ̀,” ni Olúwa wí.
23 Et je ferai de là Babylonie un désert, une demeure pour les hérissons; et je la réduirai au néant; et j'en ferai pour la perdre un abîme de fange.
Èmi yóò yí i padà sí ibùgbé àwọn òwìwí àti sí irà; Èmi yóò fi ọwọ́ ìparun gbá a, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
24 Or voici ce que dit le Seigneur des armées: Comme j'ai dit, il sera fait; ce que j'ai résolu s'accomplira.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra, “Gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣètò, bẹ́ẹ̀ ni yóò rí, àti bí mo ti pinnu, bẹ́ẹ̀ ni yóò sì dúró.
25 Je détruirai les Assyriens sur ma terre et sur mes montagnes; et ils seront foulés aux pieds; et mon peuple sera délivré de leur joug, et leur gloire à eux sera enlevée de leurs épaules.
Èmi yóò run Asiria ní ilẹ̀ mi, ní àwọn orí òkè mi ni èmi yóò ti rún un mọ́lẹ̀. Àjàgà rẹ̀ ni a ó mú kúrò lọ́rùn àwọn ènìyàn mi, ẹrù u rẹ̀ ni ó mú kúrò ní èjìká wọn.”
26 Voilà le dessein que le Seigneur a décrété sur toute la terre, et voilà sa main levée sur toutes les nations.
Èyí ni ètò tí a pinnu rẹ̀ fún gbogbo ayé, èyí ni ọwọ́ tí a nà jáde káàkiri gbogbo orílẹ̀-èdè.
27 Et ce que le Dieu saint a décrété, qui pourra s'y opposer? Sa main levée, qui la détournera?
Nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti pète, ta ni yóò sì ká a lọ́wọ́ kò? Ọwọ́ọ rẹ ti nà jáde, ta ni ó sì le è fà á padà?
28 C'est l'année où mourut le roi Achaz que cette parole a été prédite:
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ yí wá ní ọdún tí ọba Ahasi kú.
29 Ne vous réjouissez pas, ô Philistins, de ce que le joug de celui qui vous frappait a été brisé; car d'une race de serpents sortira une famille d'aspics, et de cette famille sortiront des serpents ailés.
Má ṣe yọ̀, gbogbo ẹ̀yin Filistia, pé ọ̀pá tí ó lù ọ́ ti dá; láti ibi gbòǹgbò ejò náà ni paramọ́lẹ̀ yóò ti hù jáde, èso rẹ̀ yóò sì jẹ́ oró ejò tí í jóni.
30 Et les pauvres seront nourris par le Seigneur; les pauvres se reposeront en paix; tandis qu'il fera mourir de faim ta race, et détruira tes restes.
Ẹni tí ó kúṣẹ̀ẹ́ jù yóò ní pápá oko, àwọn aláìní yóò sì dùbúlẹ̀ láìléwu. Ṣùgbọ́n gbòǹgbò o rẹ̀ ni èmi ó fi ìyàn parun, yóò sì ké àwọn ẹni rẹ tí ó sálà kúrò.
31 Poussez des cris de douleur, portes des cités; que vos villes, ô Philistins, jettent des cris d'épouvante; car de l'aquilon vient un tourbillon de fumée, et nul ne peut y échapper.
Hu, ìwọ ẹnu-ọ̀nà! Kígbe, ìwọ ìlú! Yọ́ kúrò, gbogbo ẹ̀yin Filistia! Èéfín kurukuru kan ti àríwá wá, kò sì ṣí amóríbọ́ kan nínú ẹgbẹ́ wọn.
32 Et que répondront les rois des nations? Que le Seigneur a fondé Sion, et que, par lui, les humbles de son peuple seront sauvés.
Kí ni ìdáhùn tí a ó fún agbẹnusọ orílẹ̀-èdè náà? “Olúwa ti fi ìdí Sioni kalẹ̀, àti nínú rẹ̀ ni àwọn ènìyàn rẹ̀ tí a ti pọ́n ọn lójú yóò ti rí ààbò o wọn.”

< Isaïe 14 >