< Osée 8 >

1 Ils seront frappés au sein d'un coup rapide contre terre, ou comme l'aigle s'abattant sur la maison du Seigneur, parce qu'ils ont transgressé Mon alliance et péché contre Ma loi.
“Fi ìpè sí ẹnu rẹ! Ẹyẹ idì wà lórí ilé Olúwa nítorí pé àwọn ènìyàn ti dalẹ̀ májẹ̀mú, wọ́n sì ti ṣọ̀tẹ̀ sí òfin mi.
2 Et ils crieront vers Moi, en disant: Ô Dieu, nous Te reconnaissons!
Israẹli kígbe pè mí, ‘Ọlọ́run wa, àwa mọ̀ ọ́n!’
3 Israël a pris en haine le bien; ils M'ont poursuivi comme un ennemi.
Ṣùgbọ́n Israẹli ti kọ ohun tí ó dára sílẹ̀ ọ̀tá yóò sì máa lépa rẹ̀.
4 Ils ont fait pour eux, et non pour Moi, des rois qui ont régné, sans Me les faire connaître; avec leur argent et leur or, ils se sont fabriqué des idoles, et c'est pour cela qu'ils ont été exterminés.
Wọ́n fi àwọn ọba jẹ ṣùgbọ́n, kì í ṣe nípasẹ̀ mi wọ́n yan ọmọ-aládé láì si ìmọ̀ mi níbẹ̀. Wọ́n fi fàdákà àti wúrà ṣe ère fún ara wọn, si ìparun ara wọn.
5 Répudie ton veau, Samarie; Ma colère est exaspérée contre eux: jusques à quand sera-t-il impossible qu'ils soient purifiés
Ju ère ẹgbọrọ màlúù rẹ, ìwọ Samaria! Ìbínú mi ń ru sí wọn: yóò ti pẹ́ tó kí wọ́n tó dé ipò àìmọ̀kan?
6 en Israël? C'est un artisan qui l'a fait; il n'est point Dieu; c'est pourquoi ton veau t'a égaré, Samarie.
Israẹli ni wọ́n ti wá! Ère yìí agbẹ́gilére ló ṣe é, àní ère ẹgbọrọ màlúù Samaria, ni a ó fọ́ túútúú.
7 Ils ont semé du grain éventé, et leur destruction en fera la récolte. Ils n'ont pas une gerbe dont on puisse faire de la farine, et s'il y en a, les étrangers la mangeront.
“Wọ́n gbin afẹ́fẹ́ wọ́n sì ká ìjì. Igi ọkà kò lórí, kò sì ní mú oúnjẹ wá. Bí ó bá tilẹ̀ ní ọkà àwọn àjèjì ni yóò jẹ.
8 Israël a été dévoré; il est maintenant parmi les nations comme un vase inutile,
A ti gbé Israẹli mì, báyìí, ó sì ti wà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè bí ohun èlò tí kò wúlò.
9 parce qu'ils sont allés aux Assyriens. Éphraïm a refleuri contre lui-même; ils ont aimé les présents.
Nítorí pé wọ́n ti gòkè lọ sí Asiria gẹ́gẹ́ bí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tó ń rìn kiri. Efraimu ti ta ara rẹ̀ fún àwọn olólùfẹ́ rẹ̀.
10 Et c'est pourquoi ils seront livrés aux gentils; alors Je les recevrai, et ils cesseront en peu de temps d'oindre des rois et des princes.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ti ta ara wọn sí àárín Orílẹ̀-èdè, Èmi ó ṣà wọ́n jọ nísinsin yìí. Wọn ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣòfò dànù lọ́wọ́ ìnilára ọba alágbára.
11 Car Éphraïm avait multiplié les autels; mais ceux qu'il a aimés étaient des autels de péché.
“Nítorí Efraimu ti kọ́ pẹpẹ púpọ̀ fún ìrúbọ ẹ̀ṣẹ̀ gbogbo rẹ̀ ti di pẹpẹ ìdẹ́ṣẹ̀ fún un
12 J'avais écrit pour lui une multitude de préceptes; mais ces lois ont été réputés par lui comme étrangères, même les autels qu'il aime.
Mo kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun tí ó jẹ́ òfin mi fún wọn, ṣùgbọ́n wọn kà á sí ohun àjèjì.
13 Aussi quand ils immoleront une victime et en mangeront les chairs, le Seigneur ne les agréera pas. Alors Il Se souviendra de leur iniquité, et tirera vengeance de leurs crimes. Ils seront retournés en Égypte, et ils mangeront des viandes impures chez les Assyriens.
Wọ́n ń rú ẹbọ tí wọ́n yàn fún mi, wọ́n sì ń jẹ ẹran ibẹ̀, ṣùgbọ́n inú Olúwa kò dùn sí wọn. Báyìí yóò rántí ìwà búburú wọn yóò sì jẹ wọ́n ní yà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Wọn yóò padà sí Ejibiti.
14 Tel Israël aussi a oublié son Créateur, et ils ont planté des bois sacrés, et Juda a multiplié les villes fortifiées; mais sur ces villes J'enverrai la flamme, et elles seront dévorées jusqu'aux fondations.
Nítorí Israẹli ti gbàgbé ẹlẹ́dàá rẹ̀ Ó sì ń kọ́ ààfin púpọ̀ Juda ti kọ́ ìlú olódi púpọ̀ ṣùgbọ́n èmi ó rán iná kan sí orí àwọn ìlú rẹ̀ èyí tí yóò jẹ ibi agbára rẹ̀ run.”

< Osée 8 >