< Ézéchiel 25 >

1 Et la parole du Seigneur me vint, disant:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Fils de l'homme, tourne ta face contre les fils d'Ammon, et prophétise contre eux.
“Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí àwọn ará Ammoni kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí wọn.
3 Et dis aux fils d'Ammon: Écoutez la parole du Seigneur; ainsi parle le Seigneur: En punition de ce que vous vous êtes réjouis contre mes choses saintes, parce qu'elles ont été profanées, et contre Israël, parce qu'il a été détruit, et contre la maison de Juda, parce qu'elle a été emmenée en captivité;
Sì wí fún àwọn ará Ammoni pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè tí ó wí pé. Nítorí tí ìwọ wí pé, “Á hà!” Sí ibi mímọ́ mi nígbà tí ó di àìlọ́wọ̀ àti sí orí ilẹ̀ Israẹli nígbà tí ó di ahoro; àti sí ilẹ̀ Juda, nígbà tí wọ́n lọ sí ìgbèkùn,
4 En punition de cela, je vous livre en héritage aux fils de Cédem, et ils séjourneront chez toi, avec leurs bagages, et ils y dresseront leurs tentes; ils mangeront tes fruits et ils boiront ton lait.
kíyèsi i, nítorí náà ni èmi yóò fi fi ọ lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn lọ́wọ́ ni ohun ìní. Wọn yóò sì gbé ààfin wọn kalẹ̀ nínú rẹ, wọn yóò sì gbé ibùgbé wọn nínú rẹ, wọn yóò jẹ èso rẹ, wọn yóò sì mu wàrà rẹ.
5 Et je ferai de la ville d'Ammon un pâturage pour leurs chameaux, et des fils d'Ammon un pâturage pour leurs brebis, et vous saurez que je suis le Seigneur.
Èmi yóò sì sọ Rabba di ibùjẹ, fún àwọn ìbákasẹ àti àwọn ọmọ Ammoni di ibùsùn fún agbo ẹran. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
6 Car voici ce que dit le Seigneur: En punition de ce que tu as battu des mains et frappé du pied, et de ce que tu t'es réjoui en ton âme contre la terre d'Israël,
Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí pé ìwọ pàtẹ́wọ́, ìwọ sì jan ẹsẹ̀ mọ́lẹ̀, tí ìwọ ń yọ̀ pẹ̀lú gbogbo àrankàn rẹ sí ilẹ̀ Israẹli
7 En punition de cela, j'étendrai sur toi ma main, et je te livrerai en proie aux nations, et je te détruirai parmi les peuples, et je t'anéantirai, et tu sauras que je suis le Seigneur.
nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mi lé ọ, èmi yóò sì fi ọ fún àwọn aláìkọlà fún ìkógun. Èmi yóò sì gé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì jẹ́ kí o parun kúrò ni ilẹ̀ gbogbo. Èmi yóò sì pa ọ́ run, ìwọ yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
8 Voici ce que dit le Seigneur: En punition de ce que Moab a dit: La maison d'Israël n'est-elle point maintenant comme toutes les nations?
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí pé Moabu àti Seiri sọ wí pé, “Wò ó, ilé Juda ti dàbí gbogbo àwọn kèfèrí,”
9 En punition de cela, voilà que je vais briser l'épaule de Moab, loin de ses villes frontières, sa terre choisie, la maison de Béthasimuth, située sur la fontaine de la ville maritime.
nítorí náà, Èmi yóò ṣí Moabu sílẹ̀ láti àwọn ìlú gbogbo tí ó wà ní ààlà rẹ̀, ògo ilẹ̀ náà, Beti-Jeṣimoti, Baali-Meoni àti Kiriataimu.
10 J'ai envoyé les fils de Cédem contre les fils d'Ammon, pour qu'ils en fassent leur héritage, et qu'il ne reste plus de souvenir des fils d'Ammon:
Èmi yóò fi Moabu pẹ̀lú àwọn ará Ammoni lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn ní ìní, kí a má bà á lè rántí àwọn ará Ammoni láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
11 Et je tirerai aussi vengeance de Moab, et ils sauront que je suis le Seigneur.
Èmi yóò sì mú ìdájọ́ sẹ sí Moabu lára, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
12 Voici ce que dit le Seigneur: En punition de ce qu'a fait l'Idumée, qui, en châtiant la maison de Juda, s'est souvenue de sa propre haine, et s'est elle-même vengée;
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí pé Edomu gbẹ̀san lára ilé Juda, ó sì jẹ̀bi gidigidi nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀,
13 À cause de cela, voici ce que dit le Seigneur: J'étendrai aussi la main sur l'Idumée, et j'y exterminerai les hommes et le bétail, et j'en ferai un désert; et ceux de Théman que l'on poursuivra tomberont sous le glaive.
nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé: Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Edomu èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn àti àwọn ẹranko rẹ̀. Èmi yóò fi ṣófo láti Temani dé Dedani yóò ti ipa idà ṣubú.
14 Et je punirai l'Idumée par les mains de mon peuple d'Israël, et ils traiteront l'Idumée selon ma colère et ma fureur, et ils connaîtront ma vengeance, dit le Seigneur.
Èmi yóò gbẹ̀san lára Edomu láti ọwọ́ àwọn ènìyàn mi Israẹli, wọn sì ṣe sí Edomu gẹ́gẹ́ bí ìbínú àti ìrunú mi, wọn yóò mọ̀ ìgbẹ̀san mi ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
15 À cause de cela, voici ce que dit le Seigneur: En punition de ce que les Philistins, en châtiant mon peuple, ont fait revivre leur propre vengeance, et se sont enorgueillis en leur âme de les faire périr jusqu'au dernier;
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí tí àwọn ará Filistini hùwà ẹ̀san tí wọ́n sì gbẹ̀san pẹ̀lú odì ní ọkàn wọn, àti pẹ̀lú ìkórìíra gbangba àtijọ́ ní wíwá ọ̀nà láti pa Juda run,
16 À cause de cela, ainsi dit le Seigneur: Voilà que j'étendrai ma main sur les étrangers, et j'exterminerai les Crétois, et je détruirai le reste des habitants de la côte.
nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé, “Èmi ti ṣetán láti na ọwọ́ mi jáde sí àwọn ará Filistini, èmi yóò sì ké àwọn ará Kereti kúrò, èmi yóò sì pa àwọn tí ó kù ní etí kún run.
17 Et je les frapperai de mes grandes vengeances, et ils sauront que je suis le Seigneur, quand ma vengeance tombera sur eux.
Èmi yóò sì gbẹ̀san ńlá lára wọn nípa ìbáwí gbígbóná; wọn yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi ni Olúwa. Nígbà tí èmi yóò gba ẹ̀san lára wọn.”’”

< Ézéchiel 25 >