< Ézéchiel 16 >

1 Et la parole du Seigneur me vint, disant:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Fils de l'homme, fais connaître à Jérusalem ses iniquités;
“Ọmọ ènìyàn, mú kí Jerusalẹmu mọ gbogbo ìwà ìríra rẹ̀.
3 Et dis: Ainsi parle le Seigneur à Jérusalem: Ta racine et ton origine sortent de la terre de Chanaan; ton père était Amorrhéen, et ta mère une fille des Héthéens.
Sọ pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí Jerusalẹmu, ìran rẹ àti ilẹ̀ ìbí rẹ wà ní ilẹ̀ Kenaani; ará Amori ni baba rẹ̀, ìyá rẹ̀ sì jẹ́ ará Hiti.
4 Quant à ta naissance, le jour où tu as été enfantée, tu n'as point lié tes mamelles; tu n'as point été lavée dans l'eau; tu n'as point été salée avec du sel; tu n'as pas été enveloppée de langes.
Ní ọjọ́ tí a bí ọ, a kò gé okùn ìwọ́ rẹ, bẹ́ẹ̀ ni a kò sì fi omi wẹ̀ ọ́ láti mú kí o mọ́, a kò fi iyọ̀ pa ọ́ lára rárá, bẹ́ẹ̀ ni a kò fi aṣọ wé ọ.
5 Et mon œil ne s'est point apitoyé sur toi, et je ne t'ai fait aucune de ces choses, et je n'ai rien senti en ta faveur. Et tu as été jetée sur la terre d'un champ, dans la dépravation de ton âme, le jour où tu as été enfantée.
Kò sí ẹni tó ṣàánú tàbí kẹ́dùn rẹ dé bi à ti ṣe nǹkan kan nínú ìwọ̀nyí fún ọ, ṣùgbọ́n lọ́jọ́ ìbí rẹ, ìta la jù ọ́ sí torí wọ́n kórìíra rẹ.
6 Et j'ai passé près de toi, et je t'ai vue souillée de ton sang, et je t'ai dit: Que ta vie vienne de ton sang;
“‘Nígbà tí mo sì kọjá tí mo rí ọ tó ń jàgùdù nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ, mo sọ fún ọ pé, “Yè!” Nítòótọ́, nígbà tí ìwọ wà nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ pé, “Yè.”
7 Multiplie-toi! Et je t'ai faite comme l'herbe qui pousse dans les champs; et tu as crû, et tu as grandi, et tu es entrée dans les villes des villes. Et tes mamelles se sont gonflées, et tu es devenue nubile, et tu étais nue et confuse.
Mo mú ọ dàgbà bí ohun ọ̀gbìn inú oko. O ga sókè, o sì dàgbà, o wá di arẹwà jùlọ, ọmú rẹ yọ, irun rẹ gùn, ìwọ tí o wà ní ìhòhò láìfi nǹkan kan bora.
8 Et j'ai passé près de toi, et je t'ai vue, et voilà que c'était ton temps, le temps où l'on dénoue les ceintures des vierges. Et j'ai étendu sur toi mes ailes, et j'ai caché ta nudité, et je t'ai fait des promesses, et j'ai fait alliance avec toi, dit le Seigneur. Et tu as été à moi.
“‘Nígbà tí mo tún kọjá, tí mo rí ọ, mo rí i pé àsìkò àti nífẹ̀ẹ́ rẹ ti tó, mo fi ìṣẹ́tí aṣọ mi bo ìhòhò rẹ. Mo búra fún ọ, èmi sì bá ọ dá májẹ̀mú ìwọ sì di tèmi, ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 Et je t'ai lavée dans l'eau, et j'ai enlevé le sang qui te souillait, et je t'ai parfumée d'huile.
“‘Nígbà náà ni mo fi omi wẹ ẹ̀jẹ̀ kúrò ní ara rẹ, mo fi ìpara pa ọ́ lára.
10 Et je t'ai vêtue de robes brodées, et je t'ai chaussée d'hyacinthe, et je t'ai ceinte de fin lin, et je t'ai enveloppée des tissus les plus délicats.
Mo fi aṣọ oníṣẹ́-ọnà sí ọ lára láti wọ̀ ọ́, mo wọ bàtà aláwọ fún ọ. Mo fi aṣọ funfun gbòò àti aṣọ olówó iyebíye ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́.
11 Et je t'ai parée de joyaux; je t'ai mis des bracelets et un collier.
Mo fi ohun ọ̀ṣọ́ ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́, mo fi ẹ̀gbà ọwọ́ sí ọ ní ọwọ́, mo fi ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn sí ọ ní ọrùn,
12 Et je t'ai donné un anneau pour tes narines, et je t'ai mis des boucles d'oreilles, et j'ai posé sur ta tête une couronne de gloire.
mo sì tún fi òrùka sí ọ ní imú, mo fi yẹtí sí ọ ní etí, mo sì fi adé tó rẹwà dé ọ ní orí.
13 Et tu as été ornée d'or et d'argent, et tes voiles étaient de fin lin, et ils étaient délicatement tissus, et ils étaient brodés. Et tu te nourrissais de fleur de farine, de miel et d'huile, et tu es devenue merveilleusement belle.
Báyìí ni mo ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú wúrà àti fàdákà; tí aṣọ rẹ jẹ́ funfun gbòò, aṣọ olówó iyebíye àti aṣọ tí a ṣiṣẹ́ ọnà sí. Ìyẹ̀fun kíkúnná, oyin àti òróró ni oúnjẹ rẹ. Ó di arẹwà títí ó fi dé ipò ayaba.
14 Et ta renommée s'est répandue parmi les nations, à cause de ta beauté; car elle était accomplie par la convenance, par le charme que j'avais mis en toi, dit le Seigneur.
Òkìkí rẹ sì kàn káàkiri orílẹ̀-èdè nítorí ẹwà rẹ, nítorí dídán tí mo fi ṣe ẹwà rẹ ní àṣepé, ni Olúwa Olódùmarè wí.
15 Mais tu t'es confiée en ta beauté, tu t'es prostituée au milieu de ta gloire; et tu t'es livrée à la fornication avec tous les passants.
“‘Ṣùgbọ́n, ìwọ gbẹ́kẹ̀lé ẹwà rẹ, ìwọ sì di alágbèrè nítorí òkìkí rẹ. Ìwọ sì fọ́n ojúrere rẹ káàkiri sí orí ẹni yówù tó ń kọjá lọ, ẹwà rẹ sì di tìrẹ.
16 Et tu as pris tes vêtements; et tu en as fabriqué des idoles; et tu t'es prostituée sur elles, et tu ne peux aller plus loin, et nul ne le pourra.
Ìwọ mú lára àwọn aṣọ rẹ, láti rán aṣọ aláràbarà fún ibi gíga òrìṣà tí ìwọ ti ń ṣe àgbèrè. Èyí kò yẹ kí ó rí bẹ́ẹ̀, tàbí kó tilẹ̀ ṣẹlẹ̀ rárá.
17 Et tu as pris tes parures de gloire, faites de mon argent et de mon or, et tu en as fabriqué pour toi des images d'hommes auxquelles tu t'es prostituée.
Ìwọ tún mú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ dáradára tí mo fi wúrà àti fàdákà ṣe fún ọ láti fi yá ère ọkùnrin tí ó ń bá ọ ṣe àgbèrè papọ̀.
18 Et tu as pris tes robes brodées, et tu les en as revêtues; et tu leur as fait offrande de mon huile et de mes parfums,
Ìwọ sì wọ aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́ rẹ fún wọn, o sì tún gbé òróró àti tùràrí mi sílẹ̀ níwájú wọn.
19 Et de mes pains que je t'avais donnés (car je te nourrissais de fleur de farine, d'huile et de miel); et tu les as posés devant ces idoles en odeur de suavité. Et voici ce qui est advenu, dit le Seigneur.
Ìwọ tún gbé oúnjẹ tí mo fún ọ—ìyẹ̀fun dáradára, òróró àti oyin—fún wọn gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun olóòórùn dídùn; ohun tó ṣẹlẹ̀ nìyìí, ni Olúwa Olódùmarè wí.
20 Tu as pris tes fils et tes filles que tu avais engendrés, et tu les leur as sacrifiés, pour qu'ils soient consumés par le feu. Et comme si c'était peu de t'être ainsi prostituée,
“‘Àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin tí o bí fún mi lo ti fi rú ẹbọ bí oúnjẹ fún àwọn òrìṣà. Ṣé ìwà àgbèrè rẹ kò ha tó bí?
21 Tu as égorgé tes enfants pour les livrer à tes idoles, comme des victimes expiatoires.
Tí ìwọ ti pa àwọn ọmọ mí, ìwọ sì fà wọ́n fún ère gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun.
22 Mais ceci dépasse toute ton infamie: tu ne t'es point souvenue de ta jeunesse, quand tu étais nue et confuse, et que tu vivais souillée dans ton sang.
Nínú gbogbo iṣẹ́ ìríra àti ìwà àgbèrè rẹ, ìwọ kò rántí ìgbà èwe rẹ, nígbà tí ìwọ wà ní ìhòhò, tó ń jàgùdù nínú ẹ̀jẹ̀.’
23 Et voici ce qui est advenu après toutes tes abominations, dit le Seigneur:
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ‘Ègbé! Ègbé ni fún ọ. Lẹ́yìn gbogbo ìwà búburú rẹ,
24 Tu as bâti pour toi une maison de débauche, et tu t'es affichée toi-même sur toutes les places;
ìwọ kọ́lé amọ̀ fún ara rẹ, ìwọ sì kọ́ ojúbọ gíga sí gbogbo òpin ojú pópó.
25 Et à chaque coin de rue tu as bâti tes lieux de prostitution; et tu as souillé ta beauté, tu as livré les membres à tous les passants, tu as multiplié tes débauches,
Ní gbogbo ìkóríta ni ìwọ lọ kọ ojúbọ gíga sí, tí ìwọ sọ ẹwà rẹ di ìkórìíra, ìwọ sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀ nípa fífi ara rẹ sílẹ̀ fún gbogbo ẹni tó ń kọjá lọ.
26 Et tu t'es prostituée aux fils de l'Égypte, tes voisins, peuple charnu, et tu t'es prostituée de toute manière, au point de provoquer ma colère.
Ìwọ ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú ará Ejibiti tí í ṣe aládùúgbò rẹ láti mú mi bínú ìwọ sì ti sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀.
27 Mais je vais étendre la main contre toi; et je déracinerai tes habitudes, et je te livrerai aux âmes qui te haïssent, aux filles des étrangers, qui rougissent elles-mêmes de la voie où tu as commis tes impiétés.
Nítorí náà ni mo fi na ọwọ́ mi lé ọ lórí, mo sì ti bu oúnjẹ rẹ̀ kù; èmi yóò sì mú ìfẹ́ àwọn to kórìíra rẹ ṣẹ́ lé ọ lórí, àwọn ọmọbìnrin Filistini ti ìwàkiwà rẹ tì lójú.
28 Et tu t'es prostituée avec les filles d'Assur, et même ainsi tu n'as pas été assouvie; tu t'es prostituée, et tu n'as pas été rassasiée.
Nítorí àìnítẹ́lọ́rùn rẹ, ìwọ ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara Asiria; ìwọ ti bá wọn ṣe àgbèrè, síbẹ̀síbẹ̀, kò sì lè tẹ́ ọ lọ́rùn.
29 Et tu as multiplié tes alliances en la terre des Chaldéens, et tu n'as pas été rassasiée.
Ìwọ si ti sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀ láti ilẹ̀ Kenaani dé ilẹ̀ Kaldea; síbẹ̀ èyí kò sì tẹ́ ọ lọ́rùn níhìn-ín yìí.’
30 Comment ferais-je alliance avec ta fille, dit le Seigneur, pendant que tu fais toutes les œuvres d'une femme prostituée? Or tu as triplé, tes débauches en tes filles.
“Olúwa Olódùmarè wí pé, ‘Báwo ni ọkàn rẹ ṣe jẹ aláìlera tó tí o ń ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí, bí iṣẹ́ àwọn agídí alágbèrè!
31 Tu as bâti une maison de débauche à chaque coin de rue; tu as des lieux de prostitution sur toutes les places. Et tu es devenue comme une prostituée, qui met toujours ses faveurs à plus haut prix.
Ni ti pé ìwọ kọ́ ilé gíga rẹ ni gbogbo ìkóríta, tí ìwọ sì ṣe gbogbo ibi gíga rẹ ni gbogbo ìta, ìwọ kò sì wa dàbí panṣágà obìnrin, ní ti pé ìwọ gan ọ̀yà.
32 Une femme adultère te ressemble; elle prend l'argent que gagne son mari,
“‘Ìwọ alágbèrè aya! Ìwọ fẹ́ràn ọkùnrin àjèjì ju ọkọ rẹ lọ!
33 Et le donne à tous ceux à qui elle s'est prostituée. De même tu as donné tes salaires à tous tes amants, et tu les as chargés de présents, pour qu'ils vinssent à toi de toutes parts en ta prostitution.
Àwọn ọkùnrin máa ń sanwó fún àwọn panṣágà ni ṣùgbọ́n ìwọ lo tún ń sanwó fun wọn, tí ó tún ń fún àwọn olólùfẹ́ rẹ lẹ́bùn àti owó ẹ̀yìn kí wọn bá à le máa wá ọ wá láti gbogbo agbègbè fún àgbèrè ṣíṣe.
34 Car tu as agi autrement que les autres femmes en ta prostitution, envers ceux à qui tu t'es prostituée: c'est toi qui les as payés, et aucun salaire ne t'a été donné; et voilà comment a tourné ta perversité.
Nínú àgbèrè rẹ ìwọ yàtọ̀ sí àwọn alágbèrè obìnrin yòókù; nínú àgbèrè rẹ tí ẹnìkan kò tẹ̀lé ọ láti ṣe àgbèrè; àti ní ti pé ìwọ ń tọrẹ tí a kò sì tọrẹ fún ọ, nítorí náà ìwọ yàtọ̀.
35 À cause de cela, prostituée, écoute la parole du Seigneur.
“‘Nítorí náà, ìwọ alágbèrè, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
36 Voici ce que dit le Seigneur: En punition de ce que tu as prodigué ton argent monnayé, ta honte sera dévoilée dans ta prostitution à tes amants, dans toutes tes pensées, dans tes abominations et dans le sang de tes enfants, que tu as livrés à tes idoles.
Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, “Nítorí pé ìwọ tú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ jáde, ìwọ sì fi ìhòhò rẹ hàn, nípa ṣíṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn olólùfẹ́ rẹ, àti nítorí gbogbo òrìṣà ìríra tí o fi ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ rẹ ṣe ìrúbọ fún,
37 À cause de cela, voilà que je vais rassembler contre toi tous les amants à qui tu t'es donnée; et tous ceux que tu as aimés, je les réunirai à ceux que tu haïssais. Et je les placerai en cercle autour de toi, et je leur dévoilerai tes iniquités, et ils verront toute ta honte.
nítorí náà, Èmi yóò ṣa gbogbo àwọn olólùfẹ́ rẹ jọ, àwọn ẹni ti ìwọ ti bá jayé àti gbogbo àwọn tí ìwọ ti fẹ́ àti àwọn tí ìwọ kórìíra. Èmi yóò sa gbogbo wọn káàkiri jọ, láti mú wọn lòdì sí ọ, èmi yóò sí aṣọ rẹ, níwájú wọn, wọn yóò sì rí ìhòhò rẹ.
38 Et je te punirai comme on punit la femme adultère, et je te plongerai dans le sang de la fureur et de la jalousie.
Èmi yóò sì dá ọ lẹ́jọ́, gẹ́gẹ́ bí a ti dá obìnrin tó ba ìgbéyàwó jẹ́, tí wọn sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀; Èmi yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ ìbínú àti owú mi wá sórí rẹ.
39 Et je te livrerai à leurs mains, et ils démoliront ta maison de débauche, et ils détruiront les lieux où tu te prostituais, et ils te dépouilleront de tes vêtements, et ils te prendront ta parure de gloire, et ils te chasseront nue et confuse;
Nígbà náà ni èmi yóò fà ọ lé àwọn olólùfẹ́ rẹ lọ́wọ́, wọn yóò sì wó gbogbo òkìtì rẹ pẹ̀lú àwọn ojúbọ rẹ palẹ̀. Wọn yóò tú aṣọ kúrò lára rẹ̀, gbogbo ọ̀ṣọ́ rẹ ni wọn yóò gbà, wọn yóò sì fi ọ sílẹ̀ ní ìhòhò àti ní àìwọṣọ.
40 Et ils te feront poursuivre par la populace, et ils te lapideront, et ils t'égorgeront avec leurs glaives.
Wọn yóò pe àjọ ènìyàn jọ lé ọ lórí, àwọn tí yóò sọ ọ́ ní òkúta, tiwọn yóò sì fi idà wọn gé ọ sí wẹ́wẹ́.
41 Et ils brûleront ta maison par le feu, et ils tireront vengeance de toi devant un grand nombre de femmes. Et je te détournerai de la débauche, et je ne te permettrai plus de donner des salaires.
Wọn yóò jo gbogbo ilé rẹ palẹ̀ wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ́ ní ojú àwọn obìnrin. Èmi yóò fi òpin sí àgbèrè ṣíṣe rẹ. Ìwọ kò sì ní san owó fún àwọn olólùfẹ́ rẹ mọ́.
42 Alors je ne déchaînerai plus ma fureur contre toi, et ma jalousie se détournera de toi, et je me tiendrai en repos, et je n'aurai plus souci de toi.
Nígbà náà ni ìbínú mi sí o yóò rọ̀, owú ìbínú mi yóò sì kúrò lọ́dọ̀ rẹ; inú mi yóò rọ̀, èmi kò sì ní bínú mọ́.”
43 En punition de ce que tu ne t'es point souvenue de ta jeunesse, et que tu m'as contristé par toutes ces choses, voilà que j'ai rétribué toutes tes voies sur ta tête, dit le Seigneur; car tu as mis le comble à tes désordres par ton impiété.
“‘Nítorí pé ìwọ kò rántí ọjọ́ èwe rẹ ṣùgbọ́n ìwọ ń rí mi fín pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, ó dájú pé, Èmi yóò mú gbogbo ohun tí ìwọ ti ṣe wa sí orí rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí, ìwọ kì yóò sì ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ yìí ni orí gbogbo ohun ìríra rẹ mọ́?
44 Toutes ces choses font que l'on dit de toi en proverbe: Telle fut la mère,
“‘Gbogbo àwọn to ń pòwe, ni yóò máa pòwe yìí mọ́ ọ pé: “Bí ìyá ṣe rí, bẹ́ẹ̀ ni ọmọ rẹ̀ obìnrin.”
45 Telle est la fille de la mère; tu es celle qui as répudié son époux et ses enfants, et les sœurs de tes sœurs ont répudié leurs époux et leurs enfants. Ta mère était Héthéenne, et ton père Amorrhéen.
Ìwọ ni ọmọ ìyá rẹ ti ó kọ ọkọ rẹ̀, àti àwọn ọmọ rẹ̀; ìwọ ni arábìnrin àwọn arábìnrin rẹ tí ó kọ àwọn ọkọ wọn àti àwọn ọmọ wọn: ara Hiti ni ìyá rẹ, ara Amori sì ni baba rẹ.
46 Samarie est votre sœur aînée; elle et sa fille habitent à ta gauche. Et ta plus jeune sœur, qui habite à ta droite, c'est Sodome et ses filles.
Ẹ̀gbọ́n rẹ obìnrin ni Samaria, òun àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ n gbé ni apá àríwá rẹ, àti àbúrò rẹ obìnrin ní ń gbé ọwọ́ òsì rẹ̀, àti àbúrò rẹ obìnrin ti ń gbé ọwọ́ ọ̀tún rẹ ni Sodomu àti àwọn ọmọ rẹ obìnrin.
47 Et tu n'as pas seulement marché comme elles en leurs voies, tu ne t'es pas contentée de leurs abominations; mais encore en tes voies tu les as surpassées.
Kì í sẹ pé ìwọ rìn ni ọ̀nà wọn nìkan, tàbí ṣe àfiwé ìwà ìríra wọn ṣùgbọ́n ní àárín àkókò kúkúrú díẹ̀, ìwọ bàjẹ́ jù wọ́n lọ
48 Par ma vie, dit le Seigneur, Sodome et ses filles n'ont pas fait comme vous avez fait, toi et tes filles.
Olúwa Olódùmarè wí pé, “Bí mo ṣe wà láààyè, Sodomu tí í ṣe ẹ̀gbọ́n rẹ obìnrin àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ kò ṣe to ohun tí ìwọ àti ọmọbìnrin rẹ ṣe.”
49 Or voici l'iniquité de Sodome, ta sœur; c'est l'orgueil; elle et ses filles nageaient dans la prospérité, dans l'abondance du pain, dans l'excès des plaisirs; elles avaient tout cela, et jamais elles n'ont tendu la main au pauvre ni au mendiant.
“‘Wò ó, ẹ̀ṣẹ̀ tí Sodomu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ obìnrin ṣẹ̀ nìyìí. Òun àti àwọn ọmọbìnrin rẹ gbéraga, wọ́n jẹ́ alájẹjù àti aláìbìkítà; wọn kò ran tálákà àti aláìní lọ́wọ́.
50 Elles se sont donc enorgueillies, et elles ont fait des iniquités devant moi, et je les ai détruites comme je l'ai jugé bon.
Nítorí náà, mo mu wọn kúrò níwájú mi lójú mi gẹ́gẹ́ bi ìwọ ti rò ó, nítorí ìgbéraga àti àwọn ohun ìríra tí wọ́n ṣe.
51 Samarie, de son côté, n'a point péché moitié autant que toi; mais tu les as surpassées l'une et l'autre en abominations; et tu as tellement multiplié tes iniquités, que tes sœurs en ont paru justes.
Samaria kò ṣe ìdajì ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Ìwọ ṣe àwọn ohun ìríra ju tirẹ̀ lọ, ìwọ sì jẹ kí àwọn arábìnrin rẹ dàbí olódodo pẹ̀lú gbogbo ìwọ̀nyí tí ìwọ ti ṣe.
52 Reçois donc ton châtiment, parce que tu as corrompu tes sœurs par tes péchés que tu as multipliés plus qu'elles; ce qui les a fait paraître plus justes que toi. Rougis donc, et accepte ton ignominie, car tu as justifié tes sœurs.
Gba ìtìjú rẹ, nítorí ìwọ ti jẹ́ kí arábìnrin rẹ gba ìdáláre. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ti burú ju tí wọn lọ, wọn dàbí olódodo ju ìwọ lọ. Nítorí náà rú ìtìjú rẹ, kí o sì gba ẹ̀gàn rẹ pẹ̀lú nítorí ìwọ ti jẹ́ kí àwọn arábìnrin rẹ dàbí olódodo.
53 Et je ferai revenir leurs captifs; je relèverai Sodome et ses filles, je relèverai Samarie et ses filles, et je te relèverai toi-même au milieu d'elles,
“‘Bi o tilẹ̀ jẹ pe èmi yóò mú ìgbèkùn wọn padà, ìgbèkùn Sodomu àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin, pẹ̀lú Samaria àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin, nígbà náà ni èmi yóò tún mú ìgbèkùn àwọn òǹdè rẹ wá láàrín wọn,
54 Afin que tu acceptes ton châtiment et que tu sois confuse de tout ce que tu as fait pour m'irriter.
kí ó bá à le rú ìtìjú rẹ, àti ẹ̀gàn gbogbo ohun tí ìwọ ṣe láti tù wọ́n nínú.
55 Et ta sœur Sodome et ses filles seront rétablies comme elles étaient au commencement; et toi-même et tes filles, vous serez rétablies comme vous étiez au commencement.
Nígbà tí àwọn arábìnrin rẹ, Sodomu àti àwọn ọmọbìnrin rẹ; Samaria àti àwọn ọmọbìnrin rẹ ba padà si ipò tí wọn wà tẹ́lẹ̀, ìgbà náà ni ìwọ náà yóò padà sí ipò àtijọ́ rẹ.
56 Certes, on n'a pas entendu le nom de Sodome, ta sœur, sortir de ta bouche aux jours de ta superbe,
Ìwọ ko tilẹ̀ ní dárúkọ arábìnrin rẹ Sodomu ni ọjọ́ ìgbéraga rẹ,
57 Avant que tes méchancetés eussent été dévoilées. De même, tu es aujourd'hui un sujet d'opprobre pour les filles de la Syrie et pour les filles de tous ceux qui l'entourent, et pour toutes les filles des Philistins qui forment un cercle autour de toi.
kó tó di pé àṣírí ìwà búburú rẹ tú síta, báyìí ìwọ di ẹni ẹ̀gàn lọ́dọ̀ àwọn ọmọbìnrin Edomu, Siria àti gbogbo agbègbè rẹ, àti lọ́dọ̀ àwọn ọmọbìnrin Filistini àti lọ́dọ̀ àwọn tó yí ọ ká, tiwọn si ń kẹ́gàn rẹ.
58 Quant à tes impiétés et à tes crimes, tu en as porté peine, dit le Seigneur.
Èmi yóò gba ẹ̀san ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti àwọn iṣẹ́ ìríra rẹ ní Olúwa wí.’
59 Or voici ce que dit le Seigneur: Comme tu as agi, j'agirai envers toi, puisque tu méprises tes promesses en violant mon alliance.
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ‘Èmi yóò hùwà sí ọ gẹ́gẹ́ bi ó ṣe tọ́ sí ọ, nítorí ó ti kẹ́gàn ẹ̀jẹ́ nípa dídà májẹ̀mú.
60 Mais je me souviendrai de l'alliance que j'ai faite avec toi dans ta jeunesse, et je la ferai revivre, et ce sera une alliance éternelle.
Síbẹ̀ èmi yóò rántí májẹ̀mú tí mo bá ọ ṣe nígbà èwe rẹ, èmi yóò sì bá ọ dá májẹ̀mú láéláé.
61 Et tu te souviendras de ta voie, et tu seras couverte de honte, lorsque tu recevras tes sœurs aînées et tes sœurs puînées, et je te les donnerai pour que tu les réédifies, mais non par une alliance qui vienne de toi.
Nígbà náà ni ìwọ yóò rántí àwọn ọ̀nà rẹ ojú yóò sì tì ọ́ nígbà tí mo bá gba àwọn ẹ̀gbọ́n àti àbúrò rẹ obìnrin padà. Fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọmọbìnrin, ṣùgbọ́n kì í ṣe lórí májẹ̀mú tí mo bá ọ dá.
62 Et je ferai revivre mon alliance avec toi, et tu connaîtras que je suis le Seigneur;
Èmi yóò gbé májẹ̀mú mi kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì mọ pé èmi ni Olúwa.
63 Afin que tu te souviennes, et que tu rougisses, sans oser même ouvrir la bouche en face de ta honte, lorsque je t'aurai pardonné tout ce que tu as fait, dit le Seigneur.
Nígbà tí mo bá sì ti ṣe ètùtù fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tan, Èmi yóò sì rántí, ojú yóò tì ọ́, ìwọ kò sì ní le ya ẹnu rẹ mọ́ nítorí ìtìjú rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”

< Ézéchiel 16 >